Add parallel Print Page Options

43 Nígbà tí Jeremiah parí sísọ ọ̀rọ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rán an sí wọn tan. Asariah ọmọ Hoṣaiah àti Johanani ọmọ Karea, àti gbogbo àwọn agbéraga ọkùnrin sọ fún Jeremiah pé, “Ìwọ ń pa irọ́! Olúwa Ọlọ́run wa kò rán ọ láti sọ pé, ‘Ẹ má lọ sí Ejibiti láti ṣàtìpó níbẹ̀.’ Ṣùgbọ́n Baruku, ọmọ Neriah, ni ó fi ọ̀rọ̀ sí ọ lẹ́nu sí wa, láti fà wá lé àwọn ará Babeli lọ́wọ́, láti pa wá àti láti kó wa ní ìgbèkùn lọ sí Babeli.”

Nítorí náà, Johanani ti Karea àti gbogbo àwọn olórí ogun, àti gbogbo àwọn ènìyàn tàpá sí àṣẹ Olúwa nípa dídúró sí Juda. Dípò bẹ́ẹ̀, Johanani ọmọ Karea àti gbogbo àwọn olórí ogun sì ko àwọn àjẹkù Juda tí wọ́n wá láti gbé ilẹ̀ Juda láti orílẹ̀-èdè gbogbo tí wọ́n ti tú wọn ká. Wọ́n tún kó àwọn ọkùnrin, àwọn obìnrin àti àwọn ọmọdé, àti àwọn ọmọ ọba tí ó jẹ́ obìnrin èyí tí Nebusaradani balógun ẹ̀ṣọ́ ti fi sílẹ̀ pẹ̀lú Gedaliah ọmọ Ahikamu, ọmọ Ṣafani, àti Jeremiah wòlíì náà àti Baruku ọmọ Neriah. Nítorí náà, wọn wọ Ejibiti pẹ̀lú àìgbọ́ràn sí àṣẹ Olúwa, wọ́n sì lọ títí dé Tafanesi.

Ní Tafanesi ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá: “Nígbà tí àwọn Júù ń wòye mú àwọn òkúta pẹ̀lú rẹ, kí o sì rì wọ́n mọ́ inú amọ̀ tí ó wà nínú bíríkì tí ó wà níbi pèpéle ẹnu-ọ̀nà ààfin Farao ní Tafanesi. 10 Báyìí kí o sì sọ fún wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Ọlọ́run alágbára, Ọlọ́run Israẹli wí: Èmi yóò ránṣẹ́ sí ìránṣẹ́ mi Nebukadnessari ọba Babeli Èmi yóò gbé ìjọba rẹ̀ ka orí àwọn òkúta; èyí tí mo ti rì sí ibí yìí, yóò tan ìjọba rẹ̀ jù wọ́n lọ. 11 Yóò gbé ogun sí Ejibiti; yóò mú ikú bá àwọn tí ó yan ikú; ìgbèkùn fún àwọn tí ó ti yan ìgbèkùn, àti idà fún àwọn tí ó yan idà. 12 Yóò dá, iná sun tẹmpili àwọn òrìṣà Ejibiti, yóò sun tẹmpili àwọn òrìṣà Ejibiti, yóò sì mú wọn lọ ìgbèkùn. Gẹ́gẹ́ bí olùṣọ́-àgùntàn, yóò ró aṣọ rẹ̀ mọ́ra, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni yóò ró Ejibiti òun yóò sì lọ kúrò níbẹ̀ ní àlàáfíà 13 Ní tẹmpili ni yóò ti fọ́ ère ilé oòrùn tí ó wà ní ilẹ̀ Ejibiti túútúú, yóò sì sun àwọn tẹmpili àwọn òrìṣà Ejibiti.’ ”

43 When Jeremiah had finished telling the people all the words of the Lord their God—everything the Lord had sent him to tell them(A) Azariah son of Hoshaiah(B) and Johanan(C) son of Kareah and all the arrogant(D) men said to Jeremiah, “You are lying!(E) The Lord our God has not sent you to say, ‘You must not go to Egypt to settle there.’(F) But Baruch(G) son of Neriah is inciting you against us to hand us over to the Babylonians,[a] so they may kill us or carry us into exile to Babylon.”(H)

So Johanan son of Kareah and all the army officers and all the people(I) disobeyed the Lord’s command(J) to stay in the land of Judah.(K) Instead, Johanan son of Kareah and all the army officers led away all the remnant of Judah who had come back to live in the land of Judah from all the nations where they had been scattered.(L) They also led away all those whom Nebuzaradan commander of the imperial guard had left with Gedaliah son of Ahikam, the son of Shaphan—the men, the women,(M) the children and the king’s daughters. And they took Jeremiah the prophet and Baruch(N) son of Neriah along with them. So they entered Egypt(O) in disobedience to the Lord and went as far as Tahpanhes.(P)

In Tahpanhes(Q) the word of the Lord came to Jeremiah: “While the Jews are watching, take some large stones(R) with you and bury them in clay in the brick(S) pavement at the entrance to Pharaoh’s palace(T) in Tahpanhes. 10 Then say to them, ‘This is what the Lord Almighty, the God of Israel, says: I will send for my servant(U) Nebuchadnezzar(V) king of Babylon, and I will set his throne(W) over these stones I have buried here; he will spread his royal canopy(X) above them. 11 He will come and attack Egypt,(Y) bringing death(Z) to those destined(AA) for death, captivity to those destined for captivity,(AB) and the sword to those destined for the sword.(AC) 12 He will set fire(AD) to the temples(AE) of the gods(AF) of Egypt; he will burn their temples and take their gods captive.(AG) As a shepherd picks(AH) his garment clean of lice, so he will pick Egypt clean and depart. 13 There in the temple of the sun[b](AI) in Egypt he will demolish the sacred pillars(AJ) and will burn down the temples of the gods of Egypt.’”

Footnotes

  1. Jeremiah 43:3 Or Chaldeans
  2. Jeremiah 43:13 Or in Heliopolis