Add parallel Print Page Options

Ìdájọ́ fún àwọn ọba búburú

22 Báyìí ni Olúwa wí, “Sọ̀kalẹ̀ lọ sí ààfin ọba Juda, kí o sì sọ ọ̀rọ̀ yìí níbẹ̀: ‘Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ìwọ ọba Juda, tí ó jókòó ní ìtẹ́ Dafidi, ìwọ, àwọn ènìyàn rẹ àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ, tí ó wọlé láti ẹnu ibodè wọ̀nyí. Báyìí ni Olúwa wí: Ṣé ohun tí ó jẹ́ òtítọ́ tí ó sì yẹ, kí o sì gba ẹni tí a fi ẹ̀tọ́ rẹ̀ dù ú kúrò lọ́wọ́ aninilára. Kí ó má ṣe fi agbára àti ìkà lé àlejò, aláìní baba, tàbí opó, ìwọ kò sì gbọdọ̀ ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀ níbí yìí. Nítorí bí ẹ̀yin bá tẹ̀lé àṣẹ wọ̀nyí, nígbà náà ni àwọn ọba tí ó jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi yóò gba inú ààfin láti ẹnu-ọ̀nà, wọn yóò gun kẹ̀kẹ́ àti ẹṣin, àwọn àti ìránṣẹ́ wọn àti àwọn ènìyàn wọn. Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin kò bá tẹ̀lé àṣẹ wọ̀nyí, mo búra fúnra mi pé ààfin yìí yóò di ìparun ni Olúwa wí.’ ”

Nítorí báyìí ni Olúwa wí, nípa ààfin ọba Juda,

“Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé ìwọ dàbí Gileadi sí mi,
    gẹ́gẹ́ bí góńgó òkè Lebanoni,
dájúdájú Èmi yóò sọ ọ́ di aṣálẹ̀,
    àní gẹ́gẹ́ bí ìlú tí a kò gbé inú wọn.
Èmi ó ya àwọn apanirun sọ́tọ̀ fún ọ,
    olúkúlùkù ọkùnrin pẹ̀lú ohun ìjà rẹ̀,
wọn yóò sì gé àṣàyàn igi kedari rẹ lulẹ̀,
    wọn ó sì kó wọn jù sínú iná.

“Àwọn ènìyàn láti ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè yóò rékọjá lẹ́bàá ìlú yìí wọn yóò sì máa bi ara wọn léèrè pé, ‘Èéṣe tí Olúwa ṣe irú èyí sí ìlú ńlá yìí?’ Ìdáhùn wọn yóò sì jẹ́: ‘Nítorí tí wọ́n ti kọ májẹ̀mú Olúwa Ọlọ́run wọn sílẹ̀, wọn ti ń fi orí balẹ̀ fún ọlọ́run mìíràn, wọ́n sì sìn wọ́n.’ ”

10 Nítorí náà má ṣe sọkún nítorí ọba tí ó ti kú tàbí ṣọ̀fọ̀ fún àdánù rẹ̀,
    ṣùgbọ́n ẹ sọkún kíkorò fún ẹni tí a lé kúrò nílùú
nítorí kì yóò padà wá mọ́
    tàbí fi ojú rí ilẹ̀ tí a ti bí i.

11 Nítorí báyìí ni Olúwa wí, nípa Ṣallumu ọmọ Josiah ọba Juda tí ó jẹ ọba lẹ́yìn baba rẹ̀, ṣùgbọ́n tí ó jáde kúrò níhìn-ín: “Òun kì yóò padà wá mọ́. 12 Yóò kú ni ibi tí a mú u ní ìgbèkùn lọ, kì yóò sì rí ilẹ̀ yìí mọ́.”

13 “Ègbé ni fún ẹni tí a kọ́ ààfin rẹ̀ lọ́nà àìṣòdodo,
    àti àwọn yàrá òkè rẹ̀ lọ́nà àìtọ́
tí ó mú kí àwọn ará ìlú rẹ ṣiṣẹ́ lásán
    láìsan owó iṣẹ́ wọn fún wọn.
14 Ó wí pé, ‘Èmi ó kọ́ ààfin ńlá fún ara mi
    àwọn yàrá òkè tí ó fẹ̀,
ojú fèrèsé rẹ̀ yóò tóbi.’
    A ó sì fi igi kedari bò ó,
    a ó fi ohun aláwọ̀ pupa ṣe é ní ọ̀ṣọ́.

15 “Ìwọ ó ha jẹ ọba
    kí ìwọ kí ó lè ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ igi kedari?
    Baba rẹ kò ha ní ohun jíjẹ àti mímu?
    Ó ṣe ohun tí ó tọ́ àti òdodo,
    nítorí náà ó dára fún un.
16 Ó gbèjà òtòṣì àti aláìní,
    ohun gbogbo sì dára fún un.
Bí a ti mọ̀ mí kọ́ ni èyí?”
    ni Olúwa wí.
17 “Ṣùgbọ́n ojú rẹ àti ọkàn rẹ
    wà lára èrè àìṣòótọ́
láti ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀
    ìnilára àti ìlọ́nilọ́wọ́gbà.”

18 Nítorí náà báyìí ni Olúwa wí, nípa Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda:

“Wọn kì yóò ṣọ̀fọ̀ fún un:
    wí pé, ‘Ó ṣe, arákùnrin mi! Ó ṣe, arábìnrin mi!’
    Wọn kì yóò ṣọ̀fọ̀ fún un:
    wí pé, ‘Ó ṣe, olúwa tàbí ó ṣe ọlọ́lá!’
19 A ó sin òkú rẹ̀ bí i kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́
    tí a wọ́ sọnù láti ẹnu ibodè
    Jerusalẹmu.”

20 “Gòkè lọ sí Lebanoni, kígbe síta
    kí a sì gbọ́ ohùn rẹ ní Baṣani,
kí o kígbe sókè láti Abarimu,
    nítorí a ti ṣẹ́ gbogbo olùfẹ́ rẹ túútúú.
21 Èmi ti kìlọ̀ fún ọ nígbà tí o rò pé kò séwu,
    ṣùgbọ́n o sọ pé, ‘Èmi kì yóò fetísílẹ̀!’
Èyí ni iṣẹ́ rẹ láti ìgbà èwe rẹ,
    ìwọ kò fìgbà kan gba ohùn mi gbọ́.
22 Ẹ̀fúùfù yóò lé gbogbo àwọn olùṣọ́-àgùntàn rẹ̀ lọ,
    gbogbo àwọn olùfẹ́ rẹ yóò lọ sí ìgbèkùn,
nígbà náà ni a ó kẹ́gàn rẹ, ojú yóò tì ọ́
    nítorí gbogbo ìwà búburú rẹ.
23 Ìwọ tí ń gbé ‘Lebanoni,’
    tí ó tẹ́ ìtẹ́ sí orí igi kedari,
ìwọ yóò ti kérora pẹ́ tó, nígbà tí ìrora bá dé bá ọ,
    ìrora bí i ti obìnrin tí ń rọbí!

24 “Dájúdájú bí èmi ti wà láààyè,” ni Olúwa wí, “Bí Koniah ọmọ Jehoiakimu ọba Juda tilẹ̀ jẹ́ òrùka èdìdì lọ́wọ́ ọ̀tún mi, síbẹ̀ èmi ó fà ọ́ tu kúrò níbẹ̀. 25 Èmi ó sì fà ọ́ lé ọwọ́ àwọn tí ó ń wá ẹ̀mí rẹ, àwọn tí ìwọ bẹ̀rù, àní lé ọwọ́ Nebukadnessari, ọba Babeli àti ọwọ́ àwọn ará Babeli. 26 Èmi ó fi ìwọ àti ìyá tí ó bí ọ sọ̀kò sí ilẹ̀ mìíràn, níbi tí a kò bí ẹnikẹ́ni nínú yín sí. Níbẹ̀ ni ẹ̀yin méjèèjì yóò kú sí. 27 Ẹ̀yin kì yóò padà sí ilẹ̀ tí ẹ̀yin fẹ́ mọ́ láéláé.”

28 Ǹjẹ́ Jehoiakini ẹni ẹ̀gàn yàtọ̀ sí ìkòkò òfìfo,
    ohun èlò tí ẹnìkan kò fẹ́?
Èéṣe tí a fi òun àti àwọn ọmọ rẹ̀ sókè
    sí ilẹ̀ tí wọn kò mọ̀.
29 Ìwọ ilẹ̀, ilẹ̀, ilẹ̀,
    gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa!
30 Báyìí ni Olúwa wí:
“Kọ àkọsílẹ̀ ọkùnrin yìí sínú ìwé gẹ́gẹ́ bí aláìlọ́mọ,
    ẹni tí kì yóò ṣe rere ní ọjọ́ ayé rẹ̀;
nítorí ọ̀kan nínú irú-ọmọ rẹ̀ kì yóò ṣe rere,
    èyíkéyìí wọn kì yóò jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi
    tàbí jẹ ọba ní Juda mọ́.”

Judgment Against Wicked Kings

22 This is what the Lord says: “Go down to the palace of the king(A) of Judah and proclaim this message there: ‘Hear(B) the word of the Lord to you, king of Judah, you who sit on David’s throne(C)—you, your officials and your people who come through these gates.(D) This is what the Lord says: Do what is just(E) and right. Rescue from the hand of the oppressor(F) the one who has been robbed. Do no wrong or violence to the foreigner, the fatherless or the widow,(G) and do not shed innocent blood(H) in this place. For if you are careful to carry out these commands, then kings(I) who sit on David’s throne will come through the gates of this palace, riding in chariots and on horses, accompanied by their officials and their people. But if you do not obey(J) these commands, declares the Lord, I swear(K) by myself that this palace will become a ruin.’”

For this is what the Lord says about the palace of the king of Judah:

“Though you are like Gilead(L) to me,
    like the summit of Lebanon,(M)
I will surely make you like a wasteland,(N)
    like towns not inhabited.
I will send destroyers(O) against you,
    each man with his weapons,
and they will cut(P) up your fine cedar beams
    and throw them into the fire.(Q)

“People from many nations will pass by this city and will ask one another, ‘Why has the Lord done such a thing to this great city?’(R) And the answer will be: ‘Because they have forsaken the covenant of the Lord their God and have worshiped and served other gods.(S)’”

10 Do not weep for the dead(T) king or mourn(U) his loss;
    rather, weep bitterly for him who is exiled,
because he will never return(V)
    nor see his native land again.

11 For this is what the Lord says about Shallum[a](W) son of Josiah, who succeeded his father as king of Judah but has gone from this place: “He will never return. 12 He will die(X) in the place where they have led him captive; he will not see this land again.”

13 “Woe(Y) to him who builds(Z) his palace by unrighteousness,
    his upper rooms by injustice,
making his own people work for nothing,
    not paying(AA) them for their labor.
14 He says, ‘I will build myself a great palace(AB)
    with spacious upper rooms.’
So he makes large windows in it,
    panels it with cedar(AC)
    and decorates it in red.(AD)

15 “Does it make you a king
    to have more and more cedar?
Did not your father have food and drink?
    He did what was right and just,(AE)
    so all went well(AF) with him.
16 He defended the cause of the poor and needy,(AG)
    and so all went well.
Is that not what it means to know(AH) me?”
    declares the Lord.
17 “But your eyes and your heart
    are set only on dishonest gain,(AI)
on shedding innocent blood(AJ)
    and on oppression and extortion.”(AK)

18 Therefore this is what the Lord says about Jehoiakim son of Josiah king of Judah:

“They will not mourn(AL) for him:
    ‘Alas, my brother! Alas, my sister!’
They will not mourn for him:
    ‘Alas, my master! Alas, his splendor!’
19 He will have the burial(AM) of a donkey—
    dragged away and thrown(AN)
    outside the gates of Jerusalem.”

20 “Go up to Lebanon and cry out,(AO)
    let your voice be heard in Bashan,(AP)
cry out from Abarim,(AQ)
    for all your allies(AR) are crushed.
21 I warned you when you felt secure,(AS)
    but you said, ‘I will not listen!’
This has been your way from your youth;(AT)
    you have not obeyed(AU) me.
22 The wind(AV) will drive all your shepherds(AW) away,
    and your allies(AX) will go into exile.
Then you will be ashamed and disgraced(AY)
    because of all your wickedness.
23 You who live in ‘Lebanon,[b](AZ)
    who are nestled in cedar buildings,
how you will groan when pangs come upon you,
    pain(BA) like that of a woman in labor!

24 “As surely as I live,” declares the Lord, “even if you, Jehoiachin[c](BB) son of Jehoiakim king of Judah, were a signet ring(BC) on my right hand, I would still pull you off. 25 I will deliver(BD) you into the hands of those who want to kill you, those you fear—Nebuchadnezzar king of Babylon and the Babylonians.[d] 26 I will hurl(BE) you and the mother(BF) who gave you birth into another country, where neither of you was born, and there you both will die. 27 You will never come back to the land you long to return(BG) to.”

28 Is this man Jehoiachin(BH) a despised, broken pot,(BI)
    an object no one wants?
Why will he and his children be hurled(BJ) out,
    cast into a land(BK) they do not know?
29 O land,(BL) land, land,
    hear the word of the Lord!
30 This is what the Lord says:
“Record this man as if childless,(BM)
    a man who will not prosper(BN) in his lifetime,
for none of his offspring(BO) will prosper,
    none will sit on the throne(BP) of David
    or rule anymore in Judah.”

Footnotes

  1. Jeremiah 22:11 Also called Jehoahaz
  2. Jeremiah 22:23 That is, the palace in Jerusalem (see 1 Kings 7:2)
  3. Jeremiah 22:24 Hebrew Koniah, a variant of Jehoiachin; also in verse 28
  4. Jeremiah 22:25 Or Chaldeans