Add parallel Print Page Options

Israẹli kọ Ọlọ́run sílẹ̀

Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá wí pé: “Lọ kí o sì kéde sí etí Jerusalẹmu pé:

“Báyìí ni Olúwa wí,

“ ‘Èmi rántí ìṣeun ìgbà èwe rẹ,
    ìfẹ́ ìgbéyàwó rẹ
àti nígbà tí ìwọ tẹ̀lé mi nínú ijù,
    nínú ìyàngbẹ ilẹ̀.
Israẹli jẹ́ mímọ́ sí Olúwa,
    àkọ́kọ́ èso ìkórè rẹ̀,
gbogbo ẹnikẹ́ni tí ó jẹ run ni a ó dá lẹ́bi,
    ibi yóò sì wá sí orí wọn,’ ”
    bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí.

Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, ẹ̀yin ìdílé Jakọbu
    àti gbogbo ẹ̀yin ará ilé Israẹli.

Báyìí ni Olúwa wí:

“Irú àìṣedéédéé wo ni baba yín rí lọ́wọ́ mi?
Tí wọ́n fi jìnnà sí mi?
    Wọ́n tẹ̀lé àwọn òrìṣà asán,
    àwọn fúnrawọn sì di asán.
Wọn kò béèrè, ‘Níbo ni Olúwa wà,
    tí ó mú wa jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá,
tí ó mú wa la aginjù já,
    tí ó mú wa la àárín pẹ̀tẹ́lẹ̀ àti ihò,
ìyàngbẹ ilẹ̀ àti òkùnkùn biribiri,
    ilẹ̀ ibi tí ẹnikẹ́ni kò là kọjá, tí ẹnikẹ́ni kò sì tẹ̀dó sí?’
Èmi mú yín wá sí ilẹ̀ ọlọ́ràá
    láti máa jẹ èso ibẹ̀ àti ọrọ̀ rẹ̀,
ṣùgbọ́n ẹ̀yin wọ inú rẹ̀, ẹ sì bà á jẹ́,
    ẹ sì sọ ogún mi di ohun ìríra.
Àwọn àlùfáà kò béèrè wí pé,
    ‘Níbo ni Olúwa wà?’
Àwọn tí ń ṣiṣẹ́ pẹ̀lú òfin kò si mọ̀ mí,
    àwọn olùṣọ́ sì ṣẹ̀ sí mi.
Àwọn wòlíì sì ń sọtẹ́lẹ̀ nípa òrìṣà Baali,
    wọ́n sì ń tẹ̀lé àwọn òrìṣà asán.

“Nítorí náà, mo fi ẹ̀sùn kàn yín lẹ́ẹ̀kan sí i,”
    ni Olúwa wí.
    “Èmi ó sì fi ẹ̀sùn kan àwọn ọmọ ọwọ́ rẹ
10 Rékọjá lọ sí erékùṣù àwọn ara Kittimu, kí ẹ sì wò ó,
    ránṣẹ́ lọ sí Kedari, kí ẹ sì kíyèsi gidigidi
kí ẹ wò bí irú nǹkan báyìí bá ń bẹ níbẹ̀?
11 Orílẹ̀-èdè kan ha á pa Ọlọ́run rẹ̀ dà?
    (Síbẹ̀, wọ́n kì í ṣe iṣẹ́ Ọlọ́run)
àwọn ènìyàn mi ti pààrọ̀
    ògo wọn fún àwọn ère tí kò níyì.
12 Àwọn ènìyàn mi ti dẹ́ṣẹ̀ méjì
    kí ẹ sì wárìrì pẹ̀lú ìbẹ̀rù ńlá,”
    ni Olúwa wí.
13 “Àwọn ènìyàn mi ti dẹ́ṣẹ̀ méjì
    Wọ́n ti kọ̀ mí sílẹ̀, Èmi
orísun omi ìyè, wọ́n sì ti
    ṣe àmù, àmù fífọ́ tí kò lè
    gba omi dúró.
14 Israẹli ha á jẹ́ ọmọ ọ̀dọ̀
    ẹrú nípa ìbí? Kí ló ha a
    dé tí ó fi di ìkógun?
15 Àwọn kìnnìún ké ramúramù
    wọ́n sì ń bú mọ́ wọn
wọ́n ti fi ilẹ̀ rẹ̀ ṣòfò
    Ìlú rẹ̀ ti di jíjóná, ó sì
    ti di ìkọ̀sílẹ̀.
16 Bákan náà, àwọn ọkùnrin
    Memfisi àti Tafanesi
    wọ́n ti fa adé orí rẹ yọ.
17 Ẹ̀yin kò ha a ti fa èyí sórí
    ara yín nípa kíkọ Ọlọ́run sílẹ̀
    nígbà tí ó tọ́ ọ lójú ọ̀nà?
18 Kí ló dé tí o ṣe wá lọ Ejibiti
    láti lọ mu omi ní Ṣihori?
Kí ló dé tí o sì fi lọ sí Asiria
    láti lọ mú omi ni odò Eufurate náà?
19 Iṣẹ́ búburú yín yóò fìyà jẹ yín
    ìpadàsẹ́yìn rẹ yóò sì bá ọ wí
mọ̀ kí o sì rí i wí pé ibi àti
    ohun búburú yóò sì jẹ́ tìrẹ
nígbà tí o ti kọ Olúwa Ọlọ́run sílẹ̀,
    ẹ kò sì ní ìbẹ̀rù fún mi,”
    ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.

20 “Nígbà àtijọ́, o ti fọ́ àjàgà
    rẹ sọnù, ìwọ sì já ìdè rẹ
ìwọ wí pé, ‘Èmi kì yóò sìn ọ́!’
    Lóòtítọ́, lórí gbogbo òkè gíga ni
àti lábẹ́ igi tí ó tànkálẹ̀
    ni ìwọ dùbúlẹ̀ sí gẹ́gẹ́ bí panṣágà.
21 Èmi ti gbìn ọ́ gẹ́gẹ́ bí
    àjàrà ọ̀tọ̀, gẹ́gẹ́ bí ìṣúra ọlọ́lá,
Báwo wá ni ìwọ ṣe yípadà sí mi
    di àjàrà búburú àti aláìmọ́?
22 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé o wẹ ara rẹ pẹ̀lú sódà
    tí o sì lo ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọṣẹ
síbẹ̀síbẹ̀ èérí ni ẹ̀ṣẹ̀ rẹ níwájú,”
    ni Olúwa Olódùmarè wí.
23 “Báwo ni ìwọ ṣe wí pé, ‘Èmi kò ṣe aláìmọ́;
    Èmi kò sá à tẹ̀lé àwọn Baali’?
Wo bí o ṣe hùwà ní àfonífojì;
    wo ohun tí o ṣe.
Ìwọ jẹ́ abo ìbákasẹ
    tí ń sá síhìn-ín sọ́hùn-ún.
24 Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó tí ń gbé aginjù
    tí ń fa ẹ̀fúùfù ìfẹ́ sí i mu rẹ,
ta ni ó le è mú dúró ní àkókò rẹ̀?
    Kí gbogbo àwọn akọ ẹran tí o wá a kiri kì ó má ṣe dá ara wọn lágara,
    nítorí wọn yóò rí ní àkókò oṣù rẹ̀.
25 Dá ẹsẹ̀ dúró láìwọ bàtà,
    àti ọ̀fun rẹ nínú òǹgbẹ.
Ṣùgbọ́n ìwọ wí pé, ‘Asán ni!
    Èmi fẹ́ràn àwọn ọlọ́run àjèjì,
    àwọn ni èmi yóò tọ̀ lẹ́yìn.’

26 “Gẹ́gẹ́ bí a ṣe ń dójútì olè nígbà tí a bá mú u,
bẹ́ẹ̀ náà ni ojú yóò ti ilé Israẹli—
    àwọn ọba àti àwọn ìjòyè wọn,
    àwọn àlùfáà àti wòlíì wọn pẹ̀lú.
27 Wọ́n sọ fún igi pé, ‘Ìwọ ni baba mi,’
    àti sí òkúta wí pé, ‘Ìwọ ni ó bí mi,’
wọ́n ti kọ ẹ̀yìn wọn sí mi,
    wọn kò kọ ojú sí mi
síbẹ̀ nígbà tí wọ́n bá wà nínú ìṣòro,
    wọn yóò wí pé, ‘Wá kí o sì gbà wá!’
28 Níbo wá ni àwọn ọlọ́run tí
    ẹ ṣe fúnrayín ha a wà?
Jẹ́ kí wọ́n wá kí wọ́n sì
    gbà yín nígbà tí ẹ bá
wà nínú ìṣòro! Nítorí pé
    ẹ̀yin ní àwọn ọlọ́run púpọ̀, gẹ́gẹ́
    bí ẹ ti ṣe ni àwọn ìlú, ìwọ Juda.

29 “Kí ló dé tí o ṣe wá ń fi ẹ̀sùn kàn mí?
    Gbogbo yín ni ó ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi,”
    ni Olúwa wí.
30 “Nínú asán mo fìyà jẹ àwọn ènìyàn yín,
    wọn kò sì gba ìbáwí.
Idà yín ti pa àwọn wòlíì yín run,
    gẹ́gẹ́ bí kìnnìún tí ń bú ramúramù.

31 “Ẹ̀yin ìran yìí, ẹ kíyèsi ọ̀rọ̀ Olúwa:

“Mo ha ti di aginjù sí Israẹli
    tàbí mo jẹ ilẹ̀ olókùnkùn biribiri?
Èéṣe tí àwọn ènìyàn mi ṣe wí pé,
    ‘A ní àǹfààní láti máa rìn kiri;
àwa kì yóò tọ̀ ọ́ wá mọ́?’
32 Wúńdíá ha le gbàgbé ohun ọ̀ṣọ́ rẹ̀,
    tàbí ìyàwó ohun ọ̀ṣọ́ ìgbéyàwó rẹ̀?
Síbẹ̀, àwọn ènìyàn mi ti gbàgbé mi ní ọjọ́ àìníye.
33 Ìwọ ti jẹ́ ọlọ́gbọ́n tó nípa ọ̀rọ̀ ìfẹ́!
    Àwọn obìnrin búburú yóò kẹ́kọ̀ọ́ nípa ọ̀nà rẹ
34 Lórí aṣọ rẹ ni wọ́n bá ẹ̀jẹ̀
    àwọn tálákà aláìṣẹ̀
bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ kò ká wọn mọ́
    níbi tí wọ́n ti ń rùn wọlé
35 Síbẹ̀ nínú gbogbo èyí
    ìwọ sọ wí pé, ‘Èmi jẹ́ aláìṣẹ̀
kò sì bínú sí mi.’
    Èmi yóò mú ìdájọ́ mi wá sórí rẹ
    nítorí pé ìwọ wí pé, ‘Èmi kò dẹ́ṣẹ̀.’
36 Èéṣe tí ìwọ fi ń lọ káàkiri
    láti yí ọ̀nà rẹ padà?
Ejibiti yóò dójútì ọ́
    gẹ́gẹ́ bí i ti Asiria
37 Ìwọ yóò sì fi ibẹ̀ sílẹ̀
    pẹ̀lú kíkáwọ́ rẹ lé orí rẹ,
nítorí pé Olúwa ti kọ̀ àwọn
    tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé sílẹ̀,
kì yóò sí ìrànlọ́wọ́ kankan
    fún ọ láti ọ̀dọ̀ wọn.

Israel Forsakes God

The word(A) of the Lord came to me: “Go and proclaim in the hearing of Jerusalem:

“This is what the Lord says:

“‘I remember the devotion of your youth,(B)
    how as a bride you loved me
and followed me through the wilderness,(C)
    through a land not sown.
Israel was holy(D) to the Lord,(E)
    the firstfruits(F) of his harvest;
all who devoured(G) her were held guilty,(H)
    and disaster overtook them,’”
declares the Lord.

Hear the word of the Lord, you descendants of Jacob,
    all you clans of Israel.

This is what the Lord says:

“What fault did your ancestors find in me,
    that they strayed so far from me?
They followed worthless idols(I)
    and became worthless(J) themselves.
They did not ask, ‘Where is the Lord,
    who brought us up out of Egypt(K)
and led us through the barren wilderness,
    through a land of deserts(L) and ravines,(M)
a land of drought and utter darkness,
    a land where no one travels(N) and no one lives?’
I brought you into a fertile land
    to eat its fruit and rich produce.(O)
But you came and defiled my land
    and made my inheritance detestable.(P)
The priests did not ask,
    ‘Where is the Lord?’
Those who deal with the law did not know me;(Q)
    the leaders(R) rebelled against me.
The prophets prophesied by Baal,(S)
    following worthless idols.(T)

“Therefore I bring charges(U) against you again,”
declares the Lord.
    “And I will bring charges against your children’s children.
10 Cross over to the coasts of Cyprus(V) and look,
    send to Kedar[a](W) and observe closely;
    see if there has ever been anything like this:
11 Has a nation ever changed its gods?
    (Yet they are not gods(X) at all.)
But my people have exchanged their glorious(Y) God
    for worthless idols.
12 Be appalled at this, you heavens,
    and shudder with great horror,”
declares the Lord.
13 “My people have committed two sins:
They have forsaken(Z) me,
    the spring of living water,(AA)
and have dug their own cisterns,
    broken cisterns that cannot hold water.
14 Is Israel a servant, a slave(AB) by birth?
    Why then has he become plunder?
15 Lions(AC) have roared;
    they have growled at him.
They have laid waste(AD) his land;
    his towns are burned(AE) and deserted.(AF)
16 Also, the men of Memphis(AG) and Tahpanhes(AH)
    have cracked your skull.
17 Have you not brought this on yourselves(AI)
    by forsaking(AJ) the Lord your God
    when he led you in the way?
18 Now why go to Egypt(AK)
    to drink water from the Nile[b]?(AL)
And why go to Assyria(AM)
    to drink water from the Euphrates?(AN)
19 Your wickedness will punish you;
    your backsliding(AO) will rebuke(AP) you.
Consider then and realize
    how evil and bitter(AQ) it is for you
when you forsake(AR) the Lord your God
    and have no awe(AS) of me,”
declares the Lord, the Lord Almighty.

20 “Long ago you broke off your yoke(AT)
    and tore off your bonds;(AU)
    you said, ‘I will not serve you!’(AV)
Indeed, on every high hill(AW)
    and under every spreading tree(AX)
    you lay down as a prostitute.(AY)
21 I had planted(AZ) you like a choice vine(BA)
    of sound and reliable stock.
How then did you turn against me
    into a corrupt,(BB) wild vine?
22 Although you wash(BC) yourself with soap(BD)
    and use an abundance of cleansing powder,
    the stain of your guilt is still before me,”
declares the Sovereign Lord.(BE)
23 “How can you say, ‘I am not defiled;(BF)
    I have not run after the Baals’?(BG)
See how you behaved in the valley;(BH)
    consider what you have done.
You are a swift she-camel
    running(BI) here and there,
24 a wild donkey(BJ) accustomed to the desert,(BK)
    sniffing the wind in her craving—
    in her heat who can restrain her?
Any males that pursue her need not tire themselves;
    at mating time they will find her.
25 Do not run until your feet are bare
    and your throat is dry.
But you said, ‘It’s no use!(BL)
    I love foreign gods,(BM)
    and I must go after them.’(BN)

26 “As a thief is disgraced(BO) when he is caught,
    so the people of Israel are disgraced—
they, their kings and their officials,
    their priests(BP) and their prophets.(BQ)
27 They say to wood,(BR) ‘You are my father,’
    and to stone,(BS) ‘You gave me birth.’
They have turned their backs(BT) to me
    and not their faces;(BU)
yet when they are in trouble,(BV) they say,
    ‘Come and save(BW) us!’
28 Where then are the gods(BX) you made for yourselves?
    Let them come if they can save you
    when you are in trouble!(BY)
For you, Judah, have as many gods
    as you have towns.(BZ)

29 “Why do you bring charges against me?
    You have all(CA) rebelled against me,”
declares the Lord.
30 “In vain I punished your people;
    they did not respond to correction.(CB)
Your sword has devoured your prophets(CC)
    like a ravenous lion.

31 “You of this generation, consider the word of the Lord:

“Have I been a desert to Israel
    or a land of great darkness?(CD)
Why do my people say, ‘We are free to roam;
    we will come to you no more’?(CE)
32 Does a young woman forget her jewelry,
    a bride her wedding ornaments?
Yet my people have forgotten(CF) me,
    days without number.
33 How skilled you are at pursuing(CG) love!
    Even the worst of women can learn from your ways.
34 On your clothes is found
    the lifeblood(CH) of the innocent poor,
    though you did not catch them breaking in.(CI)
Yet in spite of all this
35     you say, ‘I am innocent;(CJ)
    he is not angry with me.’
But I will pass judgment(CK) on you
    because you say, ‘I have not sinned.’(CL)
36 Why do you go about so much,
    changing(CM) your ways?
You will be disappointed by Egypt(CN)
    as you were by Assyria.
37 You will also leave that place
    with your hands on your head,(CO)
for the Lord has rejected those you trust;
    you will not be helped(CP) by them.

Footnotes

  1. Jeremiah 2:10 In the Syro-Arabian desert
  2. Jeremiah 2:18 Hebrew Shihor; that is, a branch of the Nile