Add parallel Print Page Options

Ọlọ́run àti àwọn òrìṣà

10 Gbọ́ ọ̀rọ̀ tí Olúwa sọ fún yín ẹ̀yin ilé Israẹli. Báyìí ni Olúwa wí:

“Má ṣe kọ́ ìwà àwọn kèfèrí,
    kí ààmì ọ̀run kí ó má sì dààmú yín,
    nítorí pé wọ́n ń dààmú orílẹ̀-èdè.
Nítorí pé asán ni àṣà àwọn ènìyàn,
    wọ́n gé igi láti inú igbó, oníṣọ̀nà
    sì gbẹ́ ẹ pẹ̀lú àáké rẹ̀.
Wọ́n fi fàdákà àti wúrà ṣe é lọ́ṣọ̀ọ́.
    Wọ́n fi òòlù kàn án àti ìṣó
    kí ó má ba à ṣubú.
Wọ́n wé mọ́ igi bí ẹ̀gúnsí inú oko,
    òrìṣà wọn kò le è fọhùn.
Wọ́n gbọdọ̀ máa gbé
    wọn nítorí pé wọn kò lè rìn.
Má ṣe bẹ̀rù wọn;
    wọn kò le è ṣe ibi kankan
    bẹ́ẹ̀ ni wọn kò si lè ṣe rere kan.”

Kò sí ẹni tí ó dàbí rẹ Olúwa;
    o tóbi orúkọ rẹ sì tóbi lágbára.
Ta ni kò yẹ kí ó bẹ̀rù rẹ ọba àwọn
    orílẹ̀-èdè? Nítorí tìrẹ ni, láàrín àwọn
ọlọ́gbọ́n ènìyàn ní orílẹ̀-èdè àti
    gbogbo ìjọba wọn, kò sí ẹni tí ó dàbí rẹ.

Gbogbo wọn jẹ́ aláìlóye àti aṣiwèrè,
    wọ́n ń kọ́ ẹ̀kọ́ àwọn ère igi tí kò níláárí
Fàdákà tí a ti kàn ni a mú wá láti
    Tarṣiṣi, àti wúrà láti Upasi; èyí tí
àwọn oníṣọ́nà àti alágbẹ̀dẹ ṣe tí wọ́n
    kùn ní àwọ̀ aró àti elése àlùkò,
    èyí jẹ́ iṣẹ́ ọwọ́ àwọn ọlọ́gbọ́n oníṣọ̀nà.
10 Ṣùgbọ́n Olúwa ni Ọlọ́run tòótọ́,
    òun ni Ọlọ́run alààyè, ọba ayérayé.
Nígbà tí ó bá bínú, ayé yóò wárìrì;
    orílẹ̀-èdè kò lè fi ara da ìbínú rẹ̀.

11 “Sọ èyí fún wọn: ‘Àwọn ọlọ́run kéékèèkéé tí kò dá ọ̀run àti ayé ni yóò ṣègbé láti ayé àti ní abẹ́ ọ̀run.’ ”

12 Ọlọ́run dá ayé pẹ̀lú agbára rẹ̀,
    ó dá àgbáyé pẹ̀lú ọgbọ́n rẹ̀,
    ó mú kí ọ̀run kí ó fẹ̀ síta nípa òye rẹ̀.
13 Nígbà tí ó bá sán àrá, àwọn omi
    lọ́run a sì pariwo, ó mú kí ìkùùkuu ru
sókè láti òpin ayé: ó rán mọ̀nàmọ́ná pẹ̀lú òjò,
    ó sì ń mú afẹ́fẹ́ wá láti ilé ìṣúra rẹ̀.

14 Gbogbo ènìyàn jẹ́ aṣiwèrè àti aláìnímọ̀,
    ojú ti gbogbo alágbẹ̀dẹ níwájú ère rẹ̀,
nítorí ère dídá rẹ̀ èké ni,
    kò sì ṣí ẹ̀mí nínú rẹ̀.
15 Asán ni wọ́n, iṣẹ́ ìṣìnà;
    nígbà ìbẹ̀wò wọn, wọn yóò ṣègbé.
16 Ẹni tí ó bá jẹ́ ìpín Jakọbu kò sì dàbí èyí,
    nítorí òun ni ó ṣẹ̀dá ohun gbogbo
àti Israẹli tí ó jẹ́ ẹ̀yà ìjogún rẹ̀.
    Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.

Ìparun tí n bọ̀ wá

17 Kó ẹrù rẹ kúrò láti fi ilẹ̀ náà sílẹ̀
    ìwọ tí o ń gbé ní ìlú tí a dó tì.
18 Nítorí èyí ni Olúwa wí:
    “Ní àkókò yìí,
    èmi yóò gbọn àwọn tí ó ń gbé
ilẹ̀ náà jáde. Èmi yóò mú ìpọ́njú
    bá wọn, kí wọn kí ó lè rí wọn mú.”

19 Ègbé ni fún mi nítorí ìpalára mi!
    Ọgbẹ́ mi jẹ́ èyí tí kò lè sàn,
bẹ́ẹ̀ ni mọ sọ fún ara mi,
    “Èyí ni àìsàn mi, mo sì gbọdọ̀ fi orí tì í.”
20 Àgọ́ mi bàjẹ́,
    gbogbo okùn rẹ̀ sì já.
    Àwọn ọmọ mi ti lọ lọ́dọ̀ mi, wọn kò sì sí mọ́
Kò sí ẹnìkankan tí yóò na àgọ́ mi ró mọ́,
    tàbí yóò ṣe ibùgbé fún mi
21 Àwọn olùṣọ́-àgùntàn jẹ́ aṣiwèrè,
    wọn kò sì wá Olúwa:
nítorí náà wọn kì yóò ṣe rere
    àti pé gbogbo agbo wọn ni yóò túká.
22 Fetísílẹ̀! ariwo igbe ń bọ̀,
    àti ìdàrúdàpọ̀ ńlá láti ilẹ̀ àríwá wá!
Yóò sì sọ ìlú Juda di ahoro,
    àti ihò ọ̀wàwà.

Àdúrà Jeremiah

23 Èmi mọ̀ Olúwa wí pé ọ̀nà ènìyàn kì í ṣe ti ara rẹ̀,
    kì í ṣe fún ènìyàn láti tọ́ ìgbésẹ̀ ara rẹ̀.
24 Tún mi ṣe Olúwa, pẹ̀lú ìdájọ́ nìkan
    kí o má sì ṣe é nínú ìbínú rẹ,
    kí ìwọ má ṣe sọ mí di òfo.
25 (A)Tú ìbínú rẹ jáde sórí àwọn orílẹ̀-èdè
    tí kò mọ̀ ọ́n,
sórí àwọn ènìyàn tí wọn kò pe orúkọ rẹ.
    Nítorí pé wọ́n ti jẹ Jakọbu run,
    wọ́n ti jẹ ẹ́ run pátápátá,
    wọ́n sì sọ ibùgbé rẹ̀ di ahoro.

God and Idols(A)

10 Hear what the Lord says to you, people of Israel. This is what the Lord says:

“Do not learn the ways of the nations(B)
    or be terrified by signs(C) in the heavens,
    though the nations are terrified by them.
For the practices of the peoples are worthless;
    they cut a tree out of the forest,
    and a craftsman(D) shapes it with his chisel.(E)
They adorn it with silver(F) and gold;
    they fasten it with hammer and nails
    so it will not totter.(G)
Like a scarecrow in a cucumber field,
    their idols cannot speak;(H)
they must be carried
    because they cannot walk.(I)
Do not fear them;
    they can do no harm(J)
    nor can they do any good.”(K)

No one is like you,(L) Lord;
    you are great,(M)
    and your name is mighty in power.
Who should not fear(N) you,
    King of the nations?(O)
    This is your due.
Among all the wise leaders of the nations
    and in all their kingdoms,
    there is no one like you.

They are all senseless(P) and foolish;(Q)
    they are taught by worthless wooden idols.(R)
Hammered silver is brought from Tarshish(S)
    and gold from Uphaz.
What the craftsman and goldsmith have made(T)
    is then dressed in blue and purple—
    all made by skilled workers.
10 But the Lord is the true God;
    he is the living God,(U) the eternal King.(V)
When he is angry,(W) the earth trembles;(X)
    the nations cannot endure his wrath.(Y)

11 “Tell them this: ‘These gods, who did not make the heavens and the earth, will perish(Z) from the earth and from under the heavens.’”[a]

12 But God made(AA) the earth(AB) by his power;
    he founded the world by his wisdom(AC)
    and stretched out the heavens(AD) by his understanding.
13 When he thunders,(AE) the waters in the heavens roar;
    he makes clouds rise from the ends of the earth.
He sends lightning(AF) with the rain(AG)
    and brings out the wind from his storehouses.(AH)

14 Everyone is senseless and without knowledge;
    every goldsmith is shamed(AI) by his idols.
The images he makes are a fraud;(AJ)
    they have no breath in them.
15 They are worthless,(AK) the objects of mockery;
    when their judgment comes, they will perish.
16 He who is the Portion(AL) of Jacob is not like these,
    for he is the Maker of all things,(AM)
including Israel, the people of his inheritance(AN)
    the Lord Almighty is his name.(AO)

Coming Destruction

17 Gather up your belongings(AP) to leave the land,
    you who live under siege.
18 For this is what the Lord says:
    “At this time I will hurl(AQ) out
    those who live in this land;
I will bring distress(AR) on them
    so that they may be captured.”

19 Woe to me because of my injury!
    My wound(AS) is incurable!
Yet I said to myself,
    “This is my sickness, and I must endure(AT) it.”
20 My tent(AU) is destroyed;
    all its ropes are snapped.
My children are gone from me and are no more;(AV)
    no one is left now to pitch my tent
    or to set up my shelter.
21 The shepherds(AW) are senseless(AX)
    and do not inquire of the Lord;(AY)
so they do not prosper(AZ)
    and all their flock is scattered.(BA)
22 Listen! The report is coming—
    a great commotion from the land of the north!(BB)
It will make the towns of Judah desolate,(BC)
    a haunt of jackals.(BD)

Jeremiah’s Prayer

23 Lord, I know that people’s lives are not their own;
    it is not for them to direct their steps.(BE)
24 Discipline me, Lord, but only in due measure—
    not in your anger,(BF)
    or you will reduce me to nothing.(BG)
25 Pour out your wrath on the nations(BH)
    that do not acknowledge you,
    on the peoples who do not call on your name.(BI)
For they have devoured(BJ) Jacob;
    they have devoured him completely
    and destroyed his homeland.(BK)

Footnotes

  1. Jeremiah 10:11 The text of this verse is in Aramaic.