Jakọbu 1
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
1 Jakọbu, ìránṣẹ́ Ọlọ́run àti ti Jesu Kristi Olúwa,
Sí àwọn ẹ̀yà méjìlá tí ó fọ́n káàkiri, orílẹ̀-èdè.
Àlàáfíà.
Àwọn ìṣòro àti àwọn ìdánwò
2 Ẹ̀yin ará mi, nígbà tí ẹ̀yin bá bọ́ sínú onírúurú ìdánwò, ẹ ka gbogbo rẹ̀ sí ayọ̀; 3 nítorí tí ẹ̀yin mọ̀ pé, ìdánwò ìgbàgbọ́ yín ń ṣiṣẹ́ sùúrù. 4 Ṣùgbọ́n ẹ jẹ́ kí sùúrù kí ó ṣiṣẹ́ àṣepé, kí ẹ̀yin kí ó lè jẹ́ pípé àti aláìlábùkù tí kò ṣe aláìní ohunkóhun. 5 Bí ó bá ku ọgbọ́n fún ẹnikẹ́ni, kí ó béèrè lọ́wọ́ Ọlọ́run ẹni tí fi fún gbogbo ènìyàn ní ọ̀pọ̀lọpọ̀, tí kì í sì ka àlébù sí; a ó sì fi fún un. 6 Ṣùgbọ́n nígbà tí òun bá béèrè ní ìgbàgbọ́, ní àìṣiyèméjì rárá. Nítorí ẹni tí ó ń sé iyèméjì dàbí ìgbì omi Òkun, tí à ń ti ọwọ́ afẹ́fẹ́ bì síwá bì sẹ́yìn, tí a sì ń rú u sókè. 7 Kí irú ènìyàn bẹ́ẹ̀ má ṣe rò pé, òun yóò rí ohunkóhun gbà lọ́wọ́ Olúwa; 8 Ó jẹ ènìyàn oníyèméjì aláìlèdúró ní ọ̀nà rẹ̀ gbogbo.
9 Ṣùgbọ́n jẹ́ kí arákùnrin tí ó ń ṣe onírẹ̀lẹ̀ máa ṣògo ní ipò gíga. 10 (A)Àti ọlọ́rọ̀, ní ìrẹ̀sílẹ̀, nítorí bí ìtànná koríko ni yóò kọjá lọ. 11 Nítorí oòrùn là ti òun ti ooru gbígbóná yóò gbẹ́ koríko, ìtànná rẹ̀ sì rẹ̀ dànù, ẹwà ojú rẹ̀ sì parun: bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú ni ọlọ́rọ̀ yóò ṣègbé ní ọ̀nà rẹ̀.
12 Ìbùkún ni fún ọkùnrin tí ó fi ọkàn rán ìdánwò; nítorí nígbà tí ó bá yege, yóò gba adé ìyè, tí Olúwa ti ṣèlérí fún àwọn tí ó fẹ́ ẹ.
13 Kí ẹnikẹ́ni tí a dánwò kí ó má ṣe wí pé, “Láti ọwọ́ Ọlọ́run ni a ti dán mi wò.” Nítorí a kò lè fi búburú dán Ọlọ́run wò, òun náà kì í sì í dán ẹnikẹ́ni wò; 14 Ṣùgbọ́n olúkúlùkù ni a ń dánwò nígbà tí a bá fi ọwọ́ ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ara rẹ̀ fà á lọ tí a sì tàn án jẹ. 15 Ǹjẹ́, ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ nígbà tí ó bá lóyún a bí ẹ̀ṣẹ̀, àti ẹ̀ṣẹ̀ náà nígbà tí ó bá dàgbà tán, a bí ikú.
16 Kí a má ṣe tàn yín jẹ, ẹ̀yin ará mi olùfẹ́. 17 Gbogbo ẹ̀bùn rere àti gbogbo ẹ̀bùn pípé láti òkè ni ó ti wá, ó sì sọ̀kalẹ̀ láti ọ̀dọ̀ baba ìmọ́lẹ̀ wá, lọ́dọ̀ ẹni tí kò lè yípadà gẹ́gẹ́ bí òjìji àyídà. 18 Ó pinnu láti fi ọ̀rọ̀ òtítọ́ bí wa kí àwa kí ó le jẹ́ àkọ́so nínú ohun gbogbo tí ó dá.
Gbígbọ́ àti ṣíṣe ọrọ̀ náà
19 Kí ẹ mọ èyí, ẹ̀yin ará mi olùfẹ́; jẹ́ kí olúkúlùkù ènìyàn kí ó máa yára láti gbọ́, kí ó lọ́ra láti fọhùn, kí ó si lọ́ra láti bínú; 20 Nítorí ìbínú ènìyàn kì í ṣiṣẹ́ òdodo irú èyí tí Ọlọ́run ń fẹ́. 21 Nítorí náà, ẹ lépa láti borí gbogbo èérí àti ìwà búburú tí ó gbilẹ̀ yíká, kí ẹ sì fi ọkàn tútù gba ọ̀rọ̀ náà tí a gbìn, tí ó lè gba ọkàn yín là.
22 Ẹ má kan jẹ́ olùgbọ́ ọ̀rọ̀ náà lásán, kí ẹ má ba à ti ipa èyí tan ara yín jẹ́. Ẹ ṣe ohun tí ó sọ. 23 Nítorí bí ẹnikẹ́ni bá jẹ́ olùgbọ́ ọ̀rọ̀ náà tí kò sì jẹ́ olùṣe, òun dàbí ọkùnrin tí ó ń ṣàkíyèsí ojú ara rẹ̀ nínú dígí 24 Nítorí, lẹ́yìn tí ó bá ti ṣàkíyèsí ara rẹ̀, tí ó sì bá tirẹ̀ lọ, lójúkan náà òun sì gbàgbé bí òun ti rí. 25 Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá ń wo inú òfin pípé, òfin òmìnira ni, tí ó sì dúró nínú rẹ̀, tí òun kò sì jẹ́ olùgbọ́ tí ń gbàgbé bí kò ṣe olùṣe rẹ̀, òun yóò jẹ́ alábùkún nínú iṣẹ́ rẹ̀.
26 Bí ẹnikẹ́ni bá rò pé òun ń sin Ọlọ́run nígbà tí kò kó ahọ́n rẹ̀ ní ìjánu, ó ń tan ọkàn ara rẹ̀ jẹ, ìsìn rẹ̀ sì jẹ́ asán. 27 Ìsìn mímọ́ àti aláìléèérí níwájú Ọlọ́run àti baba ni èyí, láti máa bojútó àwọn aláìní baba àti àwọn opó nínú ìpọ́njú wọn, àti láti pa ara rẹ̀ mọ́ láìlábàwọ́n kúrò nínú ayé.
James 1
English Standard Version
Greeting
1 (A)James, a servant[a] of God and (B)of the Lord Jesus Christ,
To (C)the twelve tribes in (D)the Dispersion:
Greetings.
Testing of Your Faith
2 (E)Count it all joy, my brothers,[b] when you meet trials (F)of various kinds, 3 for you know that (G)the testing of your faith (H)produces steadfastness. 4 And let steadfastness have its full effect, that you may be (I)perfect and complete, lacking in nothing.
5 (J)If any of you lacks wisdom, (K)let him ask God, (L)who gives generously to all without reproach, and it will be given him. 6 But (M)let him ask in faith, (N)with no doubting, for the one who doubts is like (O)a wave of the sea that is driven and tossed by the wind. 7 For that person must not suppose that he will receive anything from the Lord; 8 (P)he is a double-minded man, (Q)unstable in all his ways.
9 Let the lowly brother boast in his exaltation, 10 and (R)the rich in his humiliation, because (S)like a flower of the grass[c] he will pass away. 11 For the sun rises with its scorching heat and (T)withers the grass; its flower falls, and its beauty perishes. So also will the rich man fade away in the midst of his pursuits.
12 (U)Blessed is the man who remains steadfast under trial, for when he has stood the test he will receive (V)the crown of life, (W)which God has promised to those who love him. 13 Let no one say when he is tempted, “I am being tempted by God,” for God cannot be tempted with evil, and he himself tempts no one. 14 But each person is tempted when he is lured and enticed by his own desire. 15 Then desire (X)when it has conceived gives birth to sin, and (Y)sin when it is fully grown brings forth death.
16 Do not be deceived, my beloved brothers. 17 (Z)Every good gift and every perfect gift is from above, coming down from (AA)the Father of lights, (AB)with whom there is no variation or shadow due to change.[d] 18 (AC)Of his own will he (AD)brought us forth by the word of truth, (AE)that we should be a kind of (AF)firstfruits of his creatures.
Hearing and Doing the Word
19 (AG)Know this, my beloved brothers: let every person (AH)be quick to hear, (AI)slow to speak, (AJ)slow to anger; 20 for the anger of man does not produce the righteousness of God. 21 Therefore (AK)put away all filthiness and rampant wickedness and receive with (AL)meekness the implanted word, (AM)which is able to save your souls.
22 But be (AN)doers of the word, and not hearers only, deceiving yourselves. 23 For if anyone is a hearer of the word and not a doer, he is like a man who looks intently at his natural face in a mirror. 24 For he looks at himself and goes away and at once forgets what he was like. 25 But the one who looks into the perfect law, (AO)the law of liberty, and perseveres, being no hearer who forgets but a doer who acts, (AP)he will be blessed in his doing.
26 If anyone thinks he is religious (AQ)and does not bridle his tongue but deceives his heart, this person's (AR)religion is worthless. 27 Religion that is pure and undefiled before God the Father is this: (AS)to visit (AT)orphans and widows in their affliction, and (AU)to keep oneself (AV)unstained from the world.
Footnotes
- James 1:1 For the contextual rendering of the Greek word doulos, see Preface
- James 1:2 Or brothers and sisters. In New Testament usage, depending on the context, the plural Greek word adelphoi (translated “brothers”) may refer either to brothers or to brothers and sisters; also verses 16, 19
- James 1:10 Or a wild flower
- James 1:17 Some manuscripts variation due to a shadow of turning
James 1
New King James Version
Greeting to the Twelve Tribes
1 James, (A)a bondservant of God and of the Lord Jesus Christ,
To the twelve tribes which are scattered abroad:
Greetings.
Profiting from Trials
2 My brethren, (B)count it all joy (C)when you fall into various trials, 3 (D)knowing that the testing of your faith produces [a]patience. 4 But let patience have its perfect work, that you may be [b]perfect and complete, lacking nothing. 5 (E)If any of you lacks wisdom, (F)let him ask of God, who gives to all liberally and without reproach, and (G)it will be given to him. 6 (H)But let him ask in faith, with no doubting, for he who doubts is like a wave of the sea driven and tossed by the wind. 7 For let not that man suppose that he will receive anything from the Lord; 8 he is (I)a double-minded man, unstable in all his ways.
The Perspective of Rich and Poor
9 Let the lowly brother glory in his exaltation, 10 but the rich in his humiliation, because (J)as a flower of the field he will pass away. 11 For no sooner has the sun risen with a burning heat than it withers the grass; its flower falls, and its beautiful appearance perishes. So the rich man also will fade away in his pursuits.
Loving God Under Trials
12 (K)Blessed is the man who endures temptation; for when he has been approved, he will receive (L)the crown of life (M)which the Lord has promised to those who love Him. 13 Let no one say when he is tempted, “I am tempted by God”; for God cannot be tempted by evil, nor does He Himself tempt anyone. 14 But each one is tempted when he is drawn away by his own desires and enticed. 15 Then, (N)when desire has conceived, it gives birth to sin; and sin, when it is full-grown, (O)brings forth death.
16 Do not be deceived, my beloved brethren. 17 (P)Every good gift and every perfect gift is from above, and comes down from the Father of lights, (Q)with whom there is no variation or shadow of turning. 18 (R)Of His own will He brought us forth by the (S)word of truth, (T)that we might be a kind of firstfruits of His creatures.
Qualities Needed in Trials
19 [c]So then, my beloved brethren, let every man be swift to hear, (U)slow to speak, (V)slow to wrath; 20 for the wrath of man does not produce the righteousness of God.
Doers—Not Hearers Only
21 Therefore (W)lay aside all filthiness and [d]overflow of wickedness, and receive with meekness the implanted word, (X)which is able to save your souls.
22 But (Y)be doers of the word, and not hearers only, deceiving yourselves. 23 For (Z)if anyone is a hearer of the word and not a doer, he is like a man observing his natural face in a mirror; 24 for he observes himself, goes away, and immediately forgets what kind of man he was. 25 But (AA)he who looks into the perfect law of liberty and continues in it, and is not a forgetful hearer but a doer of the work, (AB)this one will be blessed in what he does.
26 If anyone [e]among you thinks he is religious, and (AC)does not bridle his tongue but deceives his own heart, this one’s religion is useless. 27 (AD)Pure and undefiled religion before God and the Father is this: (AE)to visit orphans and widows in their trouble, (AF)and to keep oneself unspotted from the world.
Footnotes
- James 1:3 endurance or perseverance
- James 1:4 mature
- James 1:19 NU Know this or This you know
- James 1:21 abundance
- James 1:26 NU omits among you
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.
The ESV® Bible (The Holy Bible, English Standard Version®), © 2001 by Crossway, a publishing ministry of Good News Publishers. ESV Text Edition: 2025.
Scripture taken from the New King James Version®. Copyright © 1982 by Thomas Nelson. Used by permission. All rights reserved.

