Isaiah 49:24-26
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
24 Ǹjẹ́ a le gba ìkógun lọ́wọ́ jagunjagun,
tàbí kí á gba ìgbèkùn lọ́wọ́ akíkanjú?
25 Ṣùgbọ́n ohun tí Olúwa wí nìyìí:
“Bẹ́ẹ̀ ni, a ó gba àwọn ìgbèkùn lọ́wọ́ àwọn jagunjagun,
àti ìkógun lọ́wọ́ àwọn akíkanjú;
Ẹni tí ó bá ọ jà ni èmi ó bá jà,
àti àwọn ọmọ rẹ ni èmi ó gbàlà.
26 Èmi yóò mú kí àwọn aninilára rẹ̀ jẹ
ẹran-ara wọn;
wọn yóò mu ẹ̀jẹ̀ ara wọn yó
bí ẹni mu wáìnì.
Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn yóò mọ̀
pé Èmi, Olúwa, èmi ni Olùgbàlà rẹ,
Olùdáǹdè rẹ, Alágbára kan ṣoṣo ti Jakọbu.”
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.