Isaiah 46
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
Àwọn Ọlọ́run Babeli
46 Beli tẹrí i rẹ̀ ba, Nebo bẹ̀rẹ̀ mọ́lẹ̀;
àwọn ère wọn ni àwọn ẹranko rù.
Àwọn ère tí wọ́n ń rù káàkiri ti di
àjàgà sí wọn lọ́rùn,
ẹrù fún àwọn tí àárẹ̀ mú.
2 Wọ́n bẹ̀rẹ̀ wọ́n sì foríbalẹ̀ papọ̀;
wọn kò lè gba ẹrù náà,
àwọn pẹ̀lú ni a kó lọ ní ìgbèkùn.
3 “Tẹ́tí sí mi, ìwọ ilé Jakọbu,
Gbogbo ẹ̀yin tí ó ṣẹ́kù nínú ilé Israẹli,
Ìwọ tí mo ti gbéró láti ìgbà tí o ti wà nínú oyún,
tí mo sì ti ń pọ̀n láti ìgbà tí a ti bí ọ.
4 Pẹ̀lúpẹ̀lú sí àwọn arúgbó àti ewú orí yín
Èmi ni ẹni náà, Èmi ni ẹni tí yóò gbé ọ ró.
Èmi ti mọ ọ́, èmi yóò sì gbé ọ;
Èmi yóò dì ọ́ mú èmi ó sì gbà ọ́ sílẹ̀.
5 “Ta ni ìwọ yóò fi mí wé tàbí ta ni èmi yóò bá dọ́gba?
Ta ni ìwọ yóò fi ṣe àkàwé mi
tí àwa yóò jọ fi ara wé ara?
6 Ọ̀pọ̀ da wúrà sílẹ̀ nínú àpò wọn
wọ́n sì wọn fàdákà lórí òṣùwọ̀n;
wọ́n bẹ alágbẹ̀dẹ lọ́wẹ̀ láti fi wọ́n ṣe òrìṣà,
wọn sì tẹríba láti sìn ín.
7 Wọ́n gbé e lé èjìká wọn, wọ́n rù wọ́n,
wọ́n sì gbé e sí ààyè rẹ̀ níbẹ̀ ni ó sì dúró sí.
Láti ibẹ̀ náà kò le è paradà
Bí ènìyàn tilẹ̀ pariwo lé e lórí, òun kò le è dáhùn;
òun kò lè gbà á nínú ìyọnu rẹ̀.
8 “Rántí èyí, fi í sí ọkàn rẹ,
fi sí ọkàn rẹ, ẹ̀yin ọlọ̀tẹ̀.
9 Rántí àwọn nǹkan àtẹ̀yìnwá, àwọn ti àtijọ́-tijọ́;
Èmi ni Ọlọ́run, kò sì sí ẹlòmíràn;
Èmi ni Ọlọ́run, kò sí ẹlòmíràn bí ì mi.
10 Mo fi òpin hàn láti ìbẹ̀rẹ̀ wá,
láti àtètèkọ́ṣe, ohun tí ó sì ń bọ̀ wá.
Mo wí pé: Ète mi yóò dúró,
àti pé èmi yóò ṣe ohun tí ó wù mí.
11 Láti ìlà-oòrùn wá ni mo ti pe ẹyẹ ajẹran wá;
láti ọ̀nà jíjìn réré, ọkùnrin kan tí yóò mú ète mi ṣẹ.
Ohun tí mo ti sọ, òun ni èmi yóò mú ṣẹ;
èyí tí mo ti gbèrò, òun ni èmi yóò ṣe.
12 Gbọ́ tèmi, ẹ̀yin alágídí ọkàn,
ìwọ tí ó jìnnà sí òdodo.
13 Èmi ń mú òdodo mi bọ̀ nítòsí,
kò tilẹ̀ jìnnà rárá;
àti ìgbàlà mi ni a kì yóò dádúró.
Èmi yóò fún Sioni ní ìgbàlà
ògo mi fún Israẹli.
Isaiah 46
The Message
This Is Serious Business, Rebels
46 1-2 The god Bel falls down, god Nebo slumps.
The no-god hunks of wood are loaded on mules
And have to be hauled off,
wearing out the poor mules—
Dead weight, burdens who can’t bear burdens,
hauled off to captivity.
3-4 “Listen to me, family of Jacob,
everyone that’s left of the family of Israel.
I’ve been carrying you on my back
from the day you were born,
And I’ll keep on carrying you when you’re old.
I’ll be there, bearing you when you’re old and gray.
I’ve done it and will keep on doing it,
carrying you on my back, saving you.
5-7 “So to whom will you compare me, the Incomparable?
Can you picture me without reducing me?
People with a lot of money
hire craftsmen to make them gods.
The artisan delivers the god,
and they kneel and worship it!
They carry it around in holy parades,
then take it home and put it on a shelf.
And there it sits, day in and day out,
a dependable god, always right where you put it.
Say anything you want to it, it never talks back.
Of course, it never does anything either!
8-11 “Think about this. Wrap your minds around it.
This is serious business, rebels. Take it to heart.
Remember your history,
your long and rich history.
I am God, the only God you’ve had or ever will have—
incomparable, irreplaceable—
From the very beginning
telling you what the ending will be,
All along letting you in
on what is going to happen,
Assuring you, ‘I’m in this for the long haul,
I’ll do exactly what I set out to do,’
Calling that eagle, Cyrus, out of the east,
from a far country the man I chose to help me.
I’ve said it, and I’ll most certainly do it.
I’ve planned it, so it’s as good as done.
12-13 “Now listen to me:
You’re a hardheaded bunch and hard to help.
I’m ready to help you right now.
Deliverance is not a long-range plan.
Salvation isn’t on hold.
I’m putting salvation to work in Zion now,
and glory in Israel.”
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.
Copyright © 1993, 2002, 2018 by Eugene H. Peterson