Add parallel Print Page Options

45 “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ fún ẹni òróró rẹ̀,
    sí Kirusi, ọwọ́ ọ̀tún ẹni tí mo dì mú
láti dojú àwọn orílẹ̀-èdè bolẹ̀ níwájú rẹ̀
    àti láti gba ohun ìjà àwọn ọba lọ́wọ́ wọn,
láti ṣí àwọn ìlẹ̀kùn níwájú rẹ̀
    tí ó fi jẹ́ pé a kì yóò ti àwọn ẹnu-ọ̀nà.
Èmi yóò lọ síwájú rẹ
    èmi ó sì tẹ́ àwọn òkè ńlá pẹrẹsẹ
Èmi yóò fọ gbogbo ẹnu-ọ̀nà idẹ
    èmi ó sì gé ọ̀pá irin.
Èmi yóò sì fún ọ ní àwọn ọrọ̀ ibi òkùnkùn,
    ọrọ̀ tí a kó pamọ́ sí àwọn ibi tí ó fi ara sin,
Tó bẹ́ẹ̀ tí ìwọ yóò fi mọ̀ pé Èmi ni Olúwa,
    Ọlọ́run Israẹli, ẹni tí ó pè ọ́ pẹ̀lú orúkọ rẹ.
Nítorí Jakọbu ìránṣẹ́ mi
    àti Israẹli ẹni tí mo yàn
Mo pè ọ́ pẹ̀lú orúkọ rẹ,
    mo sì gbé oyè kan kà ọ́ lórí
    bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ kò gbà mí.
Èmi ni Olúwa, àti pé kò sí ẹlòmíràn;
    yàtọ̀ sí èmi kò sí ọlọ́run kan,
Èmi yóò fún ọ ní okun,
    bí o kò tilẹ̀ tí ì gbà mí,
tí o fi jẹ́ pé láti ìlà-oòrùn
    títí dé ibi ìwọ̀ rẹ̀
    kí ènìyàn le mọ̀, kò sí ẹnìkan lẹ́yìn mi.
    Èmi ni Olúwa, lẹ́yìn mi kò sí ẹlòmíràn mọ́.
Mo dá ìmọ́lẹ̀, mo sì dá òkùnkùn
    mo mú àlàáfíà wá, mo sì dá àjálù;
    Èmi Olúwa ni ó ṣe nǹkan wọ̀nyí.

“Ìwọ ọ̀run lókè rọ òjò òdodo sílẹ̀;
    jẹ́ kí àwọsánmọ̀ kí ó rọ̀ ọ́ sílẹ̀.
Jẹ́ kí ilẹ̀ kí ó yanu gbagada,
    jẹ́ kí ìgbàlà kí ó dìde sókè,
jẹ́ kí òdodo kí ó dàgbà pẹ̀lú rẹ̀;
    Èmi Olúwa ni ó ti dá a.

(A)“Ègbé ni fún ènìyàn tí ó ń bá Ẹlẹ́dàá rẹ̀ jà,
    ẹni tí òun jẹ́ àpáàdì kan láàrín àwọn àpáàdì tí ó wà lórí ilẹ̀.
Ǹjẹ́ amọ̀ lè sọ fún amọ̀kòkò, pé:
    ‘Kí ni ohun tí ò ń ṣe?’
Ǹjẹ́ iṣẹ́ rẹ lè sọ pé,
    ‘Òun kò ní ọwọ́?’
10 Ègbé ni fún ẹni tí ó sọ fún baba rẹ̀ pé,
    ‘Kí ni o bí?’
tàbí sí ìyá rẹ̀,
    ‘Kí ni ìwọ ti bí?’

11 “Ohun tí Olúwa wí nìyìí
    Ẹni Mímọ́ Israẹli, àti Ẹlẹ́dàá rẹ̀:
Nípa ohun tí ó ń bọ̀,
    ǹjẹ́ o ń bi mí léèrè nípa àwọn ọmọ mi,
    tàbí kí o pàṣẹ fún mi nípa iṣẹ́ ọwọ́ mi bí?
12 Èmi ni ẹni tí ó dá ilẹ̀ ayé
    tí ó sì da ọmọ ènìyàn sórí i rẹ̀.
Ọwọ́ mi ni ó ti ta àwọn ọ̀run
    mo sì kó àwọn àgbájọ ìràwọ̀ rẹ̀ síta
13 Èmi yóò gbé Kirusi sókè nínú òdodo mi:
    Èmi yóò mú kí gbogbo ọ̀nà rẹ̀ kí ó tọ́.
Òun yóò tún ìlú mi kọ́
    yóò sì tú àwọn àtìpó mi sílẹ̀,
ṣùgbọ́n kì í ṣe fún owó tàbí ẹ̀bùn kan,
    ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.”

14 (B)Ohun tí Olúwa wí nìyìí:

“Àwọn èròjà ilẹ̀ Ejibiti àti àwọn ọjà ilẹ̀ Kuṣi,
    àti àwọn Sabeani—
wọn yóò wá sọ́dọ̀ rẹ
    wọn yóò sì jẹ́ tìrẹ;
wọn yóò máa wọ́ tẹ̀lé ọ lẹ́yìn,
    wọn yóò máa wá lọ́wọ̀ọ̀wọ́.
Wọn yóò máa foríbalẹ̀ níwájú rẹ̀,
    wọn yóò sì máa bẹ̀bẹ̀ níwájú rẹ pé,
‘Nítòótọ́ Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ kò sì ṣí ẹlòmíràn;
    kò sí ọlọ́run mìíràn.’ ”

15 Nítòótọ́ ìwọ jẹ́ Ọlọ́run tí ó fi ara rẹ̀ pamọ́,
    Ìwọ Ọlọ́run àti Olùgbàlà Israẹli
16 Gbogbo àwọn tí ó ń gbẹ́ ère ni ojú yóò tì
    wọn yóò sì kan àbùkù;
    gbogbo wọn ni yóò bọ́ sínú àbùkù papọ̀.
17 (C)Ṣùgbọ́n Israẹli ni a ó gbàlà láti ọwọ́ Olúwa
    pẹ̀lú ìgbàlà ayérayé;
a kì yóò kàn yín lábùkù tàbí kí a dójútì yín,
    títí ayé àìnípẹ̀kun.

18 Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa wí—
    ẹni tí ó dá àwọn ọ̀run,
Òun ni Ọlọ́run;
    ẹni tí ó mọ tí ó sì dá ayé,
Òun ló ṣe é;
    Òun kò dá a láti wà lófo,
ṣùgbọ́n ó ṣe é kí a lè máa gbé ibẹ̀—
    Òun wí pé:
“Èmi ni Olúwa,
    kò sì ṣí ẹlòmíràn.
19 Èmi kò sọ̀rọ̀ níbi tí ó fi ara sin,
    láti ibìkan ní ilẹ̀ òkùnkùn;
Èmi kò tí ì sọ fún àwọn ìran Jakọbu pé
    ‘Ẹ wá mi lórí asán.’
Èmi Olúwa sọ òtítọ́;
    Mo sì sọ èyí tí ó tọ̀nà.

20 “Ẹ kó ara yín jọ kí ẹ sì wá;
    ẹ kórajọ, ẹ̀yin ìsáǹsá láti àwọn
orílẹ̀-èdè wá.
    Aláìmọ̀kan ni àwọn tí ó ń ru ère igi káàkiri,
    tí wọ́n gbàdúrà sí àwọn òrìṣà tí kò le gba ni.
21 (D)Jẹ́ kí a mọ ohun tí yóò ṣẹlẹ̀, fihàn wá
    jẹ́ kí wọn jọ dámọ̀ràn papọ̀.
Ta ló ti sọ èyí lọ́jọ́ tí o ti pẹ́,
    ta ló ti wí èyí láti àtètèkọ́ṣe?
Kì í ha á ṣe Èmi, Olúwa?
    Àti pé kò sí Ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn mi,
Ọlọ́run olódodo àti olùgbàlà;
    kò sí ẹlòmíràn àfi èmi.

22 “Yípadà sí mi kí a sì gbà ọ́ là,
    ẹ̀yin ìpẹ̀kun ilẹ̀ ayé;
    nítorí Èmi ni Ọlọ́run kò sì ṣí ẹlòmíràn.
23 (E)Nípa èmi tìkára mi ni mo ti búra,
    ẹnu mi ni ó ti sọ ọ́ pẹ̀lú gbogbo ipá mi,
ọ̀rọ̀ náà tí a kì yóò lè parẹ́:
    Níwájú mi ni gbogbo orúnkún yóò wólẹ̀;
    nípa mi ni gbogbo ahọ́n yóò búra.
24 Wọn yóò sọ ní ti èmi, ‘Nínú Olúwa nìkan ni
    òdodo àti agbára wà.’ ”
Gbogbo àwọn tí ó ti bínú sí;
    yóò wá sọ́dọ̀ rẹ̀ a ó sì dójútì wọn.
25 Ṣùgbọ́n nínú Olúwa gbogbo àwọn ìran Israẹli
    ni a ó rí ní òdodo, a o sì gbé wọn ga.

45 “This is what the Lord says to his anointed,(A)
    to Cyrus,(B) whose right hand I take hold(C) of
to subdue nations(D) before him
    and to strip kings of their armor,
to open doors before him
    so that gates will not be shut:
I will go before you(E)
    and will level(F) the mountains[a];
I will break down gates(G) of bronze
    and cut through bars of iron.(H)
I will give you hidden treasures,(I)
    riches stored in secret places,(J)
so that you may know(K) that I am the Lord,
    the God of Israel, who summons you by name.(L)
For the sake of Jacob my servant,(M)
    of Israel my chosen,
I summon you by name
    and bestow on you a title of honor,
    though you do not acknowledge(N) me.
I am the Lord, and there is no other;(O)
    apart from me there is no God.(P)
I will strengthen you,(Q)
    though you have not acknowledged me,
so that from the rising of the sun
    to the place of its setting(R)
people may know(S) there is none besides me.(T)
    I am the Lord, and there is no other.
I form the light and create darkness,(U)
    I bring prosperity and create disaster;(V)
    I, the Lord, do all these things.

“You heavens above, rain(W) down my righteousness;(X)
    let the clouds shower it down.
Let the earth open wide,
    let salvation(Y) spring up,
let righteousness flourish with it;
    I, the Lord, have created it.

“Woe to those who quarrel(Z) with their Maker,(AA)
    those who are nothing but potsherds(AB)
    among the potsherds on the ground.
Does the clay say to the potter,(AC)
    ‘What are you making?’(AD)
Does your work say,
    ‘The potter has no hands’?(AE)
10 Woe to the one who says to a father,
    ‘What have you begotten?’
or to a mother,
    ‘What have you brought to birth?’

11 “This is what the Lord says—
    the Holy One(AF) of Israel, and its Maker:(AG)
Concerning things to come,
    do you question me about my children,
    or give me orders about the work of my hands?(AH)
12 It is I who made the earth(AI)
    and created mankind on it.
My own hands stretched out the heavens;(AJ)
    I marshaled their starry hosts.(AK)
13 I will raise up Cyrus[b](AL) in my righteousness:
    I will make all his ways straight.(AM)
He will rebuild my city(AN)
    and set my exiles free,
but not for a price or reward,(AO)
    says the Lord Almighty.”

14 This is what the Lord says:

“The products(AP) of Egypt and the merchandise of Cush,[c]
    and those tall Sabeans(AQ)
they will come over to you(AR)
    and will be yours;
they will trudge behind you,(AS)
    coming over to you in chains.(AT)
They will bow down before you
    and plead(AU) with you, saying,
‘Surely God is with you,(AV) and there is no other;
    there is no other god.(AW)’”

15 Truly you are a God who has been hiding(AX) himself,
    the God and Savior(AY) of Israel.
16 All the makers of idols will be put to shame and disgraced;(AZ)
    they will go off into disgrace together.
17 But Israel will be saved(BA) by the Lord
    with an everlasting salvation;(BB)
you will never be put to shame or disgraced,(BC)
    to ages everlasting.

18 For this is what the Lord says—
he who created the heavens,
    he is God;
he who fashioned and made the earth,(BD)
    he founded it;
he did not create it to be empty,(BE)
    but formed it to be inhabited(BF)
he says:
“I am the Lord,
    and there is no other.(BG)
19 I have not spoken in secret,(BH)
    from somewhere in a land of darkness;(BI)
I have not said to Jacob’s descendants,(BJ)
    ‘Seek(BK) me in vain.’
I, the Lord, speak the truth;
    I declare what is right.(BL)

20 “Gather together(BM) and come;
    assemble, you fugitives from the nations.
Ignorant(BN) are those who carry(BO) about idols of wood,
    who pray to gods that cannot save.(BP)
21 Declare what is to be, present it—
    let them take counsel together.
Who foretold(BQ) this long ago,
    who declared it from the distant past?(BR)
Was it not I, the Lord?
    And there is no God apart from me,(BS)
a righteous God(BT) and a Savior;(BU)
    there is none but me.

22 “Turn(BV) to me and be saved,(BW)
    all you ends of the earth;(BX)
    for I am God, and there is no other.(BY)
23 By myself I have sworn,(BZ)
    my mouth has uttered in all integrity(CA)
    a word that will not be revoked:(CB)
Before me every knee will bow;(CC)
    by me every tongue will swear.(CD)
24 They will say of me, ‘In the Lord alone
    are deliverance(CE) and strength.(CF)’”
All who have raged against him
    will come to him and be put to shame.(CG)
25 But all the descendants(CH) of Israel
    will find deliverance(CI) in the Lord
    and will make their boast in him.(CJ)

Footnotes

  1. Isaiah 45:2 Dead Sea Scrolls and Septuagint; the meaning of the word in the Masoretic Text is uncertain.
  2. Isaiah 45:13 Hebrew him
  3. Isaiah 45:14 That is, the upper Nile region