Add parallel Print Page Options

Olùgbàlà Israẹli kan ṣoṣo

43 Ṣùgbọ́n ní ìsinsin yìí, ohun tí Olúwa wí nìyìí
    ẹni tí ó dá ọ, ìwọ Jakọbu
    ẹni tí ó mọ ọ́, Ìwọ Israẹli:
“Má bẹ̀rù, nítorí Èmi ti dá ọ nídè;
    Èmi ti pè ọ́ ní orúkọ; tèmi ni ìwọ ṣe.
Nígbà tí ìwọ bá ń la omi kọjá,
    Èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ;
àti nígbà tí ìwọ bá ń la odò kọjá
    wọn kì yóò bò ọ́ mọ́lẹ̀.
Nígbà tí ìwọ bá la iná kọjá,
    kò ní jó ọ;
    ahọ́n iná kò ní jó ọ lára.
Nítorí Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ,
    Ẹni Mímọ́ Israẹli Olùgbàlà rẹ;
Èmi fi Ejibiti ṣe ìràpadà rẹ,
    Kuṣi àti Seba dípò rẹ.
Nítorí pé o ṣe iyebíye àti ọ̀wọ́n níwájú mi,
    àti nítorí pé mo fẹ́ràn rẹ,
Èmi yóò fi ènìyàn rọ́pò fún ọ,
    àti ènìyàn dípò ẹ̀mí rẹ.
Má bẹ̀rù nítorí èmi wà pẹ̀lú rẹ;
    Èmi yóò mú àwọn ọmọ rẹ láti ìlà-oòrùn wá
    èmi ó sì kó ọ jọ láti ìwọ̀-oòrùn.
Èmi yóò sọ fún àríwá pé, ‘Fi wọ́n sílẹ̀!’
    Àti fún gúúsù, ‘Má ṣe dá wọn dúró.’
Mú àwọn ọmọkùnrin mi láti ọ̀nà jíjìn wá
    àti àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin mi láti ìpẹ̀kun ilẹ̀ ayé—
ẹnikẹ́ni tí a ń pe orúkọ mi mọ́,
    tí mo dá fún ògo mi,
    tí mo mọ̀ àti tí mo ṣe.”

Sin àwọn tí ó ní ojú ṣùgbọ́n tí wọ́n fọ́jú jáde,
    tí wọ́n ní etí ṣùgbọ́n tí wọn dití.
Gbogbo orílẹ̀-èdè kó ra wọn jọ
    àwọn ènìyàn sì kó ra wọn papọ̀.
Ta ni nínú wọn tó sọ àsọtẹ́lẹ̀ yìí
    tí ó sì kéde fún wa àwọn nǹkan ti tẹ́lẹ̀?
Jẹ́ kí wọ́n mú àwọn ẹlẹ́rìí wọn wọlé wá
    láti fihàn pé wọ́n tọ̀nà
tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn mìíràn yóò gbọ́, tí
    wọn yóò sọ pé, “Òtítọ́ ni.”
10 “Ẹ̀yin ni ẹlẹ́rìí mi,” ni Olúwa wí,
    “Àti ìránṣẹ́ mi tí èmi ti yàn,
tó bẹ́ẹ̀ tí ẹ̀yin yóò fi mọ̀ àti tí ẹ̀yin ó fi gbà mí gbọ́
    tí yóò sì yé e yín pé èmi ni ẹni náà.
Ṣáájú mi kò sí ọlọ́run tí a dá,
    tàbí a ó wa rí òmíràn lẹ́yìn mi.
11 Èmi, àní Èmi, Èmi ni Olúwa,
    yàtọ̀ sí èmi, kò sí olùgbàlà mìíràn.
12 Èmi ti fihàn, mo gbàlà mo sì ti kéde
    Èmi, kì í sì í ṣe àwọn àjèjì òrìṣà láàrín yín.
Ẹ̀yin ni ẹlẹ́rìí mi,” ni Olúwa wí, “Pé Èmi ni Ọlọ́run.
13     Bẹ́ẹ̀ ni, àti láti ayérayé Èmi ni ẹni náà.
Kò sí ẹnikẹ́ni tí ó lè gbà kúrò lọ́wọ́ mi.
    Nígbà tí mo bá ṣe nǹkan, ta ni ó lè yí i padà?”

Àánú Ọlọ́run àti àìṣòdodo Israẹli

14 Èyí ni ohun tí Olúwa
    olùràpadà rẹ, Ẹni Mímọ́ ti Israẹli;
“Nítorí rẹ Èmi yóò ránṣẹ́ sí Babeli
    láti mú wọn sọ̀kalẹ̀ wá gẹ́gẹ́ bí ìsáǹsá,
gbogbo ará Babeli
    nínú ọkọ̀ ojú omi nínú èyí tí wọ́n fi ń ṣe ìgbéraga.
15 Èmi ni Olúwa, Ẹni Mímọ́ rẹ,
    Ẹlẹ́dàá Israẹli, ọba rẹ.”

16 Èyí ni ohun tí Olúwa
    Ẹni náà tí ó la ọ̀nà nínú Òkun,
    ipa ọ̀nà láàrín alagbalúgbú omi,
17 ẹni tí ó wọ́ àwọn kẹ̀kẹ́ àti ẹṣin jáde,
    àwọn jagunjagun àti ohun ìjà papọ̀,
wọ́n sì sùn síbẹ̀, láìní lè dìde mọ́,
    wọ́n kú pirá bí òwú-fìtílà:
18 “Gbàgbé àwọn ohun àtẹ̀yìnwá;
    má ṣe gbé nínú ohun àtijọ́.
19 Wò ó, Èmi ń ṣe ohun tuntun!
    Nísinsin yìí ó ti yọ sókè; àbí o kò rí i bí?
Èmi ń ṣe ọ̀nà kan nínú aṣálẹ̀
    àti odò nínú ilẹ̀ ṣíṣá.
20 Àwọn ẹhànnà ẹranko bọ̀wọ̀ fún mi,
    àwọn ajáko àti àwọn òwìwí,
nítorí pé mo pèsè omi nínú aṣálẹ̀
    àti odò nínú ilẹ̀ sísá,
láti fi ohun mímu fún àwọn ènìyàn mi, àyànfẹ́ mi,
21     àwọn ènìyàn tí mo dá fún ara mi
    kí wọn kí ó lè kéde ìyìn mi.

22 “Síbẹ̀síbẹ̀ ìwọ kò tí ì ké pè mí,
    ìwọ Jakọbu,
àárẹ̀ kò tí ì mú ọ nítorí mi
    ìwọ Israẹli.
23 Ìwọ kò tí ì mú àgùntàn wá fún mi fún ẹbọ sísun,
    tàbí kí o bọ̀wọ̀ fún mi pẹ̀lú ẹbọ rẹ.
Èmi kò tí ì wàhálà rẹ pẹ̀lú ọrẹ ìyẹ̀fun
    tàbí kí n dààmú rẹ pẹ̀lú ìbéèrè fún tùràrí.
24 Ìwọ kò tí ì ra kalamusi olóòórùn dídùn fún mi,
    tàbí kí o da ọ̀rá ẹbọ rẹ bò mí.
Ṣùgbọ́n ẹ ti wàhálà mi pẹ̀lú ẹ̀ṣẹ̀ yín
    ẹ sì ti dààmú mi pẹ̀lú àìṣedéédéé yín.

25 “Èmi, àní Èmi, Èmi ni ẹni tí ó wẹ
    àwọn àìṣedéédéé rẹ nù, nítorí èmi fún ara mi,
    tí n kò sì rántí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ mọ́.
26 Bojú wo ẹ̀yìn rẹ fún mi,
    jẹ́ kí a jọ ṣe àríyànjiyàn ọ̀rọ̀ náà papọ̀;
    ro ẹjọ́ láti fihàn pé o kò lẹ́sẹ̀ lọ́rùn.
27 Baba yín àkọ́kọ́ dẹ́ṣẹ̀;
    àwọn agbẹnusọ yín ṣọ̀tẹ̀ sí mi.
28 Nítorí náà, èmi ti sọ àwọn olórí ibi mímọ́ náà di àìmọ́,
    bẹ́ẹ̀ ni èmi ti fi Jakọbu fún ègún
    àti Israẹli fún ẹ̀gàn.

Israel’s Only Savior

43 But now, this is what the Lord says—
    he who created(A) you, Jacob,
    he who formed(B) you, Israel:(C)
“Do not fear, for I have redeemed(D) you;
    I have summoned you by name;(E) you are mine.(F)
When you pass through the waters,(G)
    I will be with you;(H)
and when you pass through the rivers,
    they will not sweep over you.
When you walk through the fire,(I)
    you will not be burned;
    the flames will not set you ablaze.(J)
For I am the Lord your God,(K)
    the Holy One(L) of Israel, your Savior;(M)
I give Egypt(N) for your ransom,
    Cush[a](O) and Seba(P) in your stead.(Q)
Since you are precious and honored(R) in my sight,
    and because I love(S) you,
I will give people in exchange for you,
    nations in exchange for your life.
Do not be afraid,(T) for I am with you;(U)
    I will bring your children(V) from the east
    and gather(W) you from the west.(X)
I will say to the north, ‘Give them up!’
    and to the south,(Y) ‘Do not hold them back.’
Bring my sons from afar
    and my daughters(Z) from the ends of the earth(AA)
everyone who is called by my name,(AB)
    whom I created(AC) for my glory,(AD)
    whom I formed and made.(AE)

Lead out those who have eyes but are blind,(AF)
    who have ears but are deaf.(AG)
All the nations gather together(AH)
    and the peoples assemble.
Which of their gods foretold(AI) this
    and proclaimed to us the former things?
Let them bring in their witnesses to prove they were right,
    so that others may hear and say, “It is true.”
10 “You are my witnesses,(AJ)” declares the Lord,
    “and my servant(AK) whom I have chosen,
so that you may know(AL) and believe me
    and understand that I am he.
Before me no god(AM) was formed,
    nor will there be one after me.(AN)
11 I, even I, am the Lord,(AO)
    and apart from me there is no savior.(AP)
12 I have revealed and saved and proclaimed—
    I, and not some foreign god(AQ) among you.
You are my witnesses,(AR)” declares the Lord, “that I am God.
13     Yes, and from ancient days(AS) I am he.(AT)
No one can deliver out of my hand.
    When I act, who can reverse it?”(AU)

God’s Mercy and Israel’s Unfaithfulness

14 This is what the Lord says—
    your Redeemer,(AV) the Holy One(AW) of Israel:
“For your sake I will send to Babylon
    and bring down as fugitives(AX) all the Babylonians,[b](AY)
    in the ships in which they took pride.
15 I am the Lord,(AZ) your Holy One,
    Israel’s Creator,(BA) your King.(BB)

16 This is what the Lord says—
    he who made a way through the sea,
    a path through the mighty waters,(BC)
17 who drew out(BD) the chariots and horses,(BE)
    the army and reinforcements together,(BF)
and they lay(BG) there, never to rise again,
    extinguished, snuffed out like a wick:(BH)
18 “Forget the former things;(BI)
    do not dwell on the past.
19 See, I am doing a new thing!(BJ)
    Now it springs up; do you not perceive it?
I am making a way in the wilderness(BK)
    and streams in the wasteland.(BL)
20 The wild animals(BM) honor me,
    the jackals(BN) and the owls,
because I provide water(BO) in the wilderness
    and streams in the wasteland,
to give drink to my people, my chosen,
21     the people I formed(BP) for myself(BQ)
    that they may proclaim my praise.(BR)

22 “Yet you have not called on me, Jacob,
    you have not wearied(BS) yourselves for[c] me, Israel.(BT)
23 You have not brought me sheep for burnt offerings,(BU)
    nor honored(BV) me with your sacrifices.(BW)
I have not burdened(BX) you with grain offerings
    nor wearied you with demands(BY) for incense.(BZ)
24 You have not bought any fragrant calamus(CA) for me,
    or lavished on me the fat(CB) of your sacrifices.
But you have burdened me with your sins
    and wearied(CC) me with your offenses.(CD)

25 “I, even I, am he who blots out
    your transgressions,(CE) for my own sake,(CF)
    and remembers your sins(CG) no more.(CH)
26 Review the past for me,
    let us argue the matter together;(CI)
    state the case(CJ) for your innocence.
27 Your first father(CK) sinned;
    those I sent to teach(CL) you rebelled(CM) against me.
28 So I disgraced the dignitaries of your temple;
    I consigned Jacob to destruction[d](CN)
    and Israel to scorn.(CO)

Footnotes

  1. Isaiah 43:3 That is, the upper Nile region
  2. Isaiah 43:14 Or Chaldeans
  3. Isaiah 43:22 Or Jacob; / surely you have grown weary of
  4. Isaiah 43:28 The Hebrew term refers to the irrevocable giving over of things or persons to the Lord, often by totally destroying them.