Add parallel Print Page Options

Ìránṣẹ́ Olúwa náà

42 (A)“Ìránṣẹ́ mi nìyìí, ẹni tí mo gbéró,
    àyànfẹ́ mi nínú ẹni tí mo láyọ̀;
Èmi yóò fi Ẹ̀mí mi sínú rẹ̀
    òun yóò sì mú ìdájọ́ wá sórí àwọn orílẹ̀-èdè.
Òun kì yóò pariwo tàbí kígbe sókè,
    tàbí kí ó gbóhùn rẹ̀ sókè ní òpópónà.
Koríko odò títẹ̀ kan ni òun kì yóò fọ́,
    àti òwú-fìtílà tí ń jó tan an lọ lòun kì yóò fẹ́ pa.
Ní òdodo ni yóò mú ìdájọ́ wá;
    òun kì yóò kọsẹ̀ bẹ́ẹ̀ ni kò ní rẹ̀wẹ̀sì
títí tí yóò fi fi ìdájọ́ múlẹ̀ ní ayé.
    Nínú òfin rẹ̀ ni àwọn erékùṣù yóò fi ìrètí wọn sí.”

(B)Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run wí
    Ẹni tí ó dá àwọn ọ̀run tí ó sì tẹ́ wọ́n sóde,
tí ó tẹ́ ilẹ̀ ayé àti ohun gbogbo tí ó jáde nínú wọn,
    Ẹni tí ó fún àwọn ènìyàn rẹ̀ ní èémí
    àti ẹ̀mí fún gbogbo àwọn tí ń rìn nínú rẹ̀:
(C)“Èmi, Olúwa, ti pè ọ́ ní òdodo;
    Èmi yóò di ọwọ́ rẹ mú.
Èmi yóò pa ọ́ mọ́, n ó sì ṣe ọ́
    láti jẹ́ májẹ̀mú fún àwọn ènìyàn
    àti ìmọ́lẹ̀ fún àwọn aláìkọlà
(D)láti la àwọn ojú tí ó fọ́,
    láti tú àwọn òǹdè kúrò nínú túbú
àti láti tú sílẹ̀ kúrò nínú ẹ̀wọ̀n
    àwọn tí ó jókòó nínú òkùnkùn.

“Èmi ni Olúwa; orúkọ mi nìyìí!
    Èmi kì yóò fi ògo mi fún ẹlòmíràn
    tàbí ìyìn mi fún ère òrìṣà.
Kíyèsi i, àwọn nǹkan àtijọ́ ti wáyé,
    àti àwọn nǹkan tuntun ni mo ti wí pé;
kí wọn tó hù jáde
    mo ti kéde rẹ̀ fún ọ.”

Orin ìyìn sí Olúwa

10 Kọ orin tuntun sí Olúwa
    ìyìn rẹ̀ láti òpin ilẹ̀ ayé wá,
ẹ̀yin tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ sínú Òkun, àti
    ohun gbogbo tí ń bẹ nínú rẹ̀
    ẹ̀yin erékùṣù, àti gbogbo àwọn tí ń gbé inú wọn.
11 Jẹ́ kí aginjù àti àwọn ìlú rẹ̀ kí ó gbé ohùn wọn sókè;
    jẹ́ kí ibùdó ti àwọn igi Kedari ń gbé máa yọ̀.
Jẹ́ kí àwọn ènìyàn Sela kọrin fún ayọ̀;
    jẹ́ kí wọn pariwo láti orí òkè.
12 Jẹ́ kí wọn fi ògo fún Olúwa
    àti kí wọn sì kéde ìyìn rẹ̀ ní erékùṣù.
13 Olúwa yóò rìn jáde gẹ́gẹ́ bí i ọkùnrin alágbára,
    yóò ru owú sókè bí ológun;
yóò kígbe nítòótọ́, òun yóò ké igbe ogun,
    òun yóò sì ṣẹ́gun àwọn ọ̀tá rẹ̀.

14 “Fún ìgbà pípẹ́ ni mo ti dákẹ́ jẹ́ẹ́,
    mo ti wà ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́, mo sì kó ara ró.
Ṣùgbọ́n ní àkókò yìí, gẹ́gẹ́ bí obìnrin tí ó ń rọbí,
    mo sọkún, mo sì ń mí hẹlẹ hẹlẹ.
15 Èmi yóò sọ òkè ńlá àti kékeré di ahoro
    tí n ó sì gbẹ gbogbo ewéko rẹ̀ dànù;
Èmi yóò sọ àwọn odò di erékùṣù
    n ó sì gbẹ àwọn adágún.
16 Èmi yóò tọ àwọn afọ́jú ní ọ̀nà tí wọn kò tí ì mọ̀,
    ní ipa ọ̀nà tí ó ṣàjèjì sí wọn ni èmi yóò tọ́ wọn lọ;
Èmi yóò sọ òkùnkùn di ìmọ́lẹ̀ níwájú wọn
    àti ibi pálapàla ni èmi ó sọ di kíkúnná.
Àwọn nǹkan tí máa ṣe nìyìí;
    Èmi kì yóò kọ̀ wọ́n sílẹ̀.
17 Ṣùgbọ́n àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé òrìṣà,
    tí wọ́n wí fún ère pé, ‘Ẹ̀yin ni Ọlọ́run wa,’
    ni a ó dá padà pẹ̀lú ìtìjú.

Israẹli fọ́jú ó dití

18 “Gbọ́, ìwọ adití,
    wò ó, ìwọ afọ́jú, o sì rí!
19 Ta ló fọ́jú bí kò ṣe ìránṣẹ́ mi,
    àti odi gẹ́gẹ́ bí oníṣẹ́ tí mo rán?
Ta ni ó fọ́jú gẹ́gẹ́ bí ẹni tí a fi jìnmí,
    ó fọ́jú gẹ́gẹ́ bí ìránṣẹ́ Olúwa?
20 Ẹ̀yin ti rí ọ̀pọ̀lọpọ̀ nǹkan, ṣùgbọ́n ẹ kò ṣe àkíyèsí;
    etí yín yà sílẹ̀, ṣùgbọ́n ẹ kò gbọ́ nǹkan kan.”
21 Ó dùn mọ́ Olúwa
    nítorí òdodo rẹ̀
    láti mú òfin rẹ lágbára àti ògo.
22 Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn kan nìyìí tí a jà lógun
    tí a sì kó lẹ́rú,
gbogbo wọn ni ó wà nínú ọ̀gbun,
    tàbí tí a fi pamọ́ sínú ẹ̀wọ̀n.
Wọ́n ti di ìkógun,
    láìsí ẹnìkan tí yóò gbà wọ́n sílẹ̀;
wọ́n ti di ìkógun,
    láìsí ẹni tí yóò sọ pé, “Dá wọn padà.”

23 Ta ni nínú yín tí yóò tẹ́tí sí èyí
    tàbí kí ó ṣe àkíyèsí gidi ní àsìkò tí ó ń bọ̀?
24 Ta ni ó fi Jakọbu lélẹ̀ fún ìkógun,
    àti Israẹli sílẹ̀ fún onísùnmọ̀mí?
Kì í ha ṣe Olúwa ni,
    ẹni tí àwa ti ṣẹ̀ sí?
Nítorí pé wọn kò ní tẹ̀lé ọ̀nà rẹ̀;
    wọn kò mú òfin rẹ̀ ṣẹ.
25 Nítorí náà ni ó ṣe rọ̀jò ìbínú un rẹ̀ lé wọn lórí,
    rògbòdìyàn ogun.
Èyí tí ó fi ahọ́n iná yí wọn po, síbẹ̀
    èdè kò yé wọn;
    ó jó wọn run, síbẹ̀ wọn kò fi sọ́kàn wọn rárá.

The Servant of the Lord

42 “Here is my servant,(A) whom I uphold,
    my chosen one(B) in whom I delight;(C)
I will put my Spirit(D) on him,
    and he will bring justice(E) to the nations.(F)
He will not shout or cry out,(G)
    or raise his voice in the streets.
A bruised reed(H) he will not break,(I)
    and a smoldering wick he will not snuff out.(J)
In faithfulness he will bring forth justice;(K)
    he will not falter or be discouraged
till he establishes justice(L) on earth.
    In his teaching(M) the islands(N) will put their hope.”(O)

This is what God the Lord says—
the Creator of the heavens,(P) who stretches them out,
    who spreads out the earth(Q) with all that springs from it,(R)
    who gives breath(S) to its people,
    and life to those who walk on it:
“I, the Lord, have called(T) you in righteousness;(U)
    I will take hold of your hand.(V)
I will keep(W) you and will make you
    to be a covenant(X) for the people
    and a light(Y) for the Gentiles,(Z)
to open eyes that are blind,(AA)
    to free(AB) captives from prison(AC)
    and to release from the dungeon those who sit in darkness.(AD)

“I am the Lord;(AE) that is my name!(AF)
    I will not yield my glory to another(AG)
    or my praise to idols.(AH)
See, the former things(AI) have taken place,
    and new things I declare;
before they spring into being
    I announce(AJ) them to you.”

Song of Praise to the Lord

10 Sing(AK) to the Lord a new song,(AL)
    his praise(AM) from the ends of the earth,(AN)
you who go down to the sea, and all that is in it,(AO)
    you islands,(AP) and all who live in them.
11 Let the wilderness(AQ) and its towns raise their voices;
    let the settlements where Kedar(AR) lives rejoice.
Let the people of Sela(AS) sing for joy;
    let them shout from the mountaintops.(AT)
12 Let them give glory(AU) to the Lord
    and proclaim his praise(AV) in the islands.(AW)
13 The Lord will march out like a champion,(AX)
    like a warrior(AY) he will stir up his zeal;(AZ)
with a shout(BA) he will raise the battle cry
    and will triumph over his enemies.(BB)

14 “For a long time I have kept silent,(BC)
    I have been quiet and held myself back.(BD)
But now, like a woman in childbirth,
    I cry out, I gasp and pant.(BE)
15 I will lay waste(BF) the mountains(BG) and hills
    and dry up all their vegetation;
I will turn rivers into islands
    and dry up(BH) the pools.
16 I will lead(BI) the blind(BJ) by ways they have not known,
    along unfamiliar paths I will guide them;
I will turn the darkness into light(BK) before them
    and make the rough places smooth.(BL)
These are the things I will do;
    I will not forsake(BM) them.
17 But those who trust in idols,
    who say to images, ‘You are our gods,’(BN)
    will be turned back in utter shame.(BO)

Israel Blind and Deaf

18 “Hear, you deaf;(BP)
    look, you blind, and see!
19 Who is blind(BQ) but my servant,(BR)
    and deaf like the messenger(BS) I send?
Who is blind like the one in covenant(BT) with me,
    blind like the servant of the Lord?
20 You have seen many things, but you pay no attention;
    your ears are open, but you do not listen.”(BU)
21 It pleased the Lord
    for the sake(BV) of his righteousness
    to make his law(BW) great and glorious.
22 But this is a people plundered(BX) and looted,
    all of them trapped in pits(BY)
    or hidden away in prisons.(BZ)
They have become plunder,
    with no one to rescue them;(CA)
they have been made loot,
    with no one to say, “Send them back.”

23 Which of you will listen to this
    or pay close attention(CB) in time to come?
24 Who handed Jacob over to become loot,
    and Israel to the plunderers?(CC)
Was it not the Lord,(CD)
    against whom we have sinned?
For they would not follow(CE) his ways;
    they did not obey his law.(CF)
25 So he poured out on them his burning anger,(CG)
    the violence of war.
It enveloped them in flames,(CH) yet they did not understand;(CI)
    it consumed them, but they did not take it to heart.(CJ)