Add parallel Print Page Options

Ayọ̀ àwọn ẹni ìràpadà

35 Aginjù àti ìyàngbẹ ilẹ̀ yóò yọ̀ fún wọn;
    aginjù yóò ṣe àjọyọ̀ yóò sì kún fún ìtànná.
    Gẹ́gẹ́ bí ewéko,
Ní títanná yóò tanná;
    yóò yọ ayọ̀ ńláńlá yóò sì kọrin.
Ògo Lebanoni ni a ó fi fún un,
    ẹwà Karmeli àti Ṣaroni;
wọn yóò rí ògo Olúwa,
    àti ẹwà Ọlọ́run wa.

(A)Fún ọwọ́ àìlera lókun,
    mú orúnkún tí ń yẹ̀ lókun:
Sọ fún àwọn oníbẹ̀rù ọkàn pé
    “Ẹ ṣe gírí, ẹ má bẹ̀rù;
Ọlọ́run yín yóò wá,
    òun yóò wá pẹ̀lú ìgbẹ̀san;
pẹ̀lú ìgbẹ̀san mímọ́
    òun yóò wá láti gbà yín là.”

(B)Nígbà náà ni a ó la ojú àwọn afọ́jú
    àti etí àwọn odi kì yóò dákẹ́.
Nígbà náà ni àwọn arọ yóò máa fò bí àgbọ̀nrín,
    àti ahọ́n odi yóò ké fún ayọ̀.
Odò yóò tú jáde nínú aginjù
    àti àwọn odò nínú aṣálẹ̀.
Ilẹ̀ iyanrìn yíyan yóò di àbàtà,
    ilẹ̀ tí ń pòǹgbẹ yóò di orísun omi.
Ní ibùgbé àwọn dragoni,
    níbi tí olúkúlùkù dùbúlẹ̀,
    ni ó jẹ́ ọgbà fún eèsún àti papirusi.

Àti òpópónà kan yóò wà níbẹ̀:
    a ó sì máa pè é ní ọ̀nà Ìwà Mímọ́.
Àwọn aláìmọ́ kì yóò tọ ọ̀nà náà;
    yóò sì wà fún àwọn tí ń rìn ní ọ̀nà náà,
    àwọn ìkà búburú kì yóò gba ibẹ̀ kọjá.
Kì yóò sí kìnnìún níbẹ̀,
    tàbí kí ẹranko búburú kí ó dìde lórí i rẹ̀;
a kì yóò rí wọn níbẹ̀.
    Ṣùgbọ́n àwọn ẹni ìràpadà nìkan ni yóò rìn níbẹ̀,
10 àwọn ẹni ìràpadà Olúwa yóò padà wá.
    Wọn yóò wọ Sioni wá pẹ̀lú orin;
ayọ̀ ayérayé ni yóò dé wọn ní orí.
    Ìdùnnú àti ayọ̀ ni yóò borí i wọn,
    ìkorò àti ìtìjú yóò sì sá kúrò lọ́dọ̀ wọn.

Joy of the Redeemed

35 The desert(A) and the parched land will be glad;
    the wilderness will rejoice and blossom.(B)
Like the crocus,(C) it will burst into bloom;
    it will rejoice greatly and shout for joy.(D)
The glory of Lebanon(E) will be given to it,
    the splendor of Carmel(F) and Sharon;(G)
they will see the glory(H) of the Lord,
    the splendor of our God.(I)

Strengthen the feeble hands,
    steady the knees(J) that give way;
say(K) to those with fearful hearts,(L)
    “Be strong, do not fear;(M)
your God will come,(N)
    he will come with vengeance;(O)
with divine retribution
    he will come to save(P) you.”

Then will the eyes of the blind be opened(Q)
    and the ears of the deaf(R) unstopped.
Then will the lame(S) leap like a deer,(T)
    and the mute tongue(U) shout for joy.(V)
Water will gush forth in the wilderness
    and streams(W) in the desert.
The burning sand will become a pool,
    the thirsty ground(X) bubbling springs.(Y)
In the haunts where jackals(Z) once lay,
    grass and reeds(AA) and papyrus will grow.

And a highway(AB) will be there;
    it will be called the Way of Holiness;(AC)
    it will be for those who walk on that Way.
The unclean(AD) will not journey on it;
    wicked fools will not go about on it.
No lion(AE) will be there,
    nor any ravenous beast;(AF)
    they will not be found there.
But only the redeemed(AG) will walk there,
10     and those the Lord has rescued(AH) will return.
They will enter Zion with singing;(AI)
    everlasting joy(AJ) will crown their heads.
Gladness(AK) and joy will overtake them,
    and sorrow and sighing will flee away.(AL)