Add parallel Print Page Options

Ìdájọ́ lórí i Jerusalẹmu àti Juda

Kíyèsi i, Olúwa,
    Olúwa àwọn ọmọ-ogun,
fẹ́ mú ìpèsè àti ìrànlọ́wọ́ kúrò ní Jerusalẹmu àti Juda
    gbogbo ìpèsè oúnjẹ àti ìpèsè omi.
Àwọn akíkanjú àti jagunjagun,
    adájọ́ àti wòlíì,
    aláfọ̀ṣẹ àti alàgbà,
balógun àádọ́ta àti àwọn ènìyàn, onípò gíga
    olùdámọ̀ràn, oníṣọ̀nà tí ó dáńtọ́
    àti ògbójú oníṣègùn.

“Èmi ó sọ àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin di aláṣẹ wọn,
    ọ̀dọ́mọdé lásán làsàn ni yóò sì
    máa jẹ ọba lórí i wọn.”

Àwọn ènìyàn yóò sì máa pọ́n
    ọmọnìkejì wọn lójú
ẹnìkan sí ẹnìkejì rẹ̀, aládùúgbò
    sí aládùúgbò rẹ̀.
Àwọn ọ̀dọ́ yóò gbógun ti àwọn àgbàgbà,
    àwọn mẹ̀kúnnù yóò dìde sí ọlọ́lá.

Ọkùnrin kan yóò di ọ̀kan nínú àwọn
    arákùnrin rẹ̀ mú,
nínú ilé baba rẹ̀, yóò sì wí pé,
    “Ìwọ́ ní aṣọ, ìwọ máa ṣe olórí wa,
    sì mójútó àwọn ahoro wọ̀nyí!”
Ṣùgbọ́n ní ọjọ́ náà ni yóò figbe bọnu pé,
    “Èmi kò ní àtúnṣe kan.
Èmi kò ní oúnjẹ, bẹ́ẹ̀ ni n ó ní aṣọ nílé,
    ẹ má fi mí ṣe olórí àwọn ènìyàn náà.”

Jerusalẹmu ń ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n
    Juda ń ṣubú lọ,
ọ̀rọ̀ àti ìṣe wọn lòdì sí Olúwa,
    láti mú ojú ògo rẹ̀ bínú.
Ìwò ojú wọn ń jẹ́rìí lòdì sí wọn,
    wọ́n ń polongo ẹ̀ṣẹ̀ wọn bí i Sodomu;
wọn ò fi pamọ́!
    Ègbé ni fún wọn!
    Wọ́n ti mú ìparun wá sórí ara wọn.

10 Ẹ sọ fún olódodo pé yóò dára fún wọn,
    nítorí ní àjẹgbádùn ni wọn yóò jẹ èso iṣẹ́ ẹ wọn.
11 Ègbé ni fún ènìyàn búburú! Ìparun wà lórí i wọn
    A ó sì san èrè iṣẹ́ tí ọwọ́ wọn ti ṣe fún wọn.

12 Àwọn ọ̀dọ́mọdé ni o ń pọ́n àwọn ènìyàn mi lójú
    àwọn obìnrin ń jẹ ọba lé wọn lórí.
Háà! Ènìyàn mi àwọn afinimọ̀nà yín ti ṣì yín lọ́nà,
    wọn sì mú yín kúrò ní ipa ọ̀nà yín.

13 Olúwa bọ sí ipò rẹ̀ ní ìtẹ́ ìdájọ́
    Ó dìde láti dá àwọn ènìyàn lẹ́jọ́.
14 Olúwa dojú ẹjọ́ kọ
    àwọn àgbàgbà àti àwọn olórí àwọn ènìyàn rẹ̀.
“Ẹ̀yin ni ẹ ti run ọgbà àjàrà mi,
    ogún àwọn tálákà ń bẹ̀ nínú ilé yín.
15 Kín ni èrò yín láti máa run àwọn ènìyàn mi túútúú
    tí ẹ sì fojú àwọn tálákà ni gbolẹ̀?”
    ni Olúwa wí, Olúwa àwọn ọmọ-ogun.

16 Olúwa wí pé,
    “Àwọn obìnrin Sioni jẹ́ agbéraga,
wọn ń rìn lọ pẹ̀lú ọrùn tí ó nà tàntàn,
    tí wọn ń fojú pe ọkùnrin,
tí wọn ń sọ̀dí bí wọ́n ti ń yan lọ
    pẹ̀lú ohun ọ̀ṣọ́ tí ń mì wọnjanwọnjan lọ́rùn ẹsẹ̀ wọn.
17 Nítorí náà Olúwa yóò mú egbò wá sórí àwọn obìnrin Sioni,
    Olúwa yóò sì pá wọn ní agbárí.”

18 Ní ọjọ́ náà, Olúwa yóò já ọ̀ṣọ́ wọn gbà kúrò ti ọwọ́ àti gèlè àti ẹ̀gbà ọrùn tí ó dàbí òṣùpá 19 gbogbo yẹtí, ẹ̀gbà ọwọ́ àti ìbòjú, 20 gbogbo gèlè, ẹ̀gbà ọrùn, ẹsẹ̀ àti àyà, àwọn ìgò tùràrí àti òògùn, 21 òrùka ọwọ́ àti ti imú, 22 àwọn àtàtà aṣọ, àwọ̀lékè, agbádá àti àpamọ́wọ́, 23 Dígí wọn, aṣọ funfun nigínnigín ìbòrí àti ìbòjú.

24 Dípò òórùn dídùn, òórùn búburú ni yóò wá,
    okùn ni yóò wà dípò àmùrè,
orí pípá ni yóò dípò irun ti a ṣe ní ọ̀ṣọ́
    aṣọ ọ̀fọ̀ ni yóò dípò aṣọ ẹ̀yẹ ìjóná dípò ẹwà.
25 Àwọn ọkùnrin rẹ yóò ti ipa idà ṣubú,
    àti àwọn jagunjagun rẹ̀ lójú ogun.
26 Àwọn bodè Sioni yóò sọkún kíkorò, wọn ó ṣọ̀fọ̀,
    nítorí ó dahoro, yóò jókòó ní orí ilẹ̀.

Judgment on Jerusalem and Judah

See now, the Lord,
    the Lord Almighty,
is about to take from Jerusalem and Judah
    both supply and support:(A)
all supplies of food(B) and all supplies of water,(C)
    the hero and the warrior,(D)
the judge and the prophet,
    the diviner(E) and the elder,(F)
the captain of fifty(G) and the man of rank,(H)
    the counselor, skilled craftsman(I) and clever enchanter.(J)

“I will make mere youths their officials;
    children will rule over them.”(K)

People will oppress each other—
    man against man, neighbor against neighbor.(L)
The young will rise up against the old,
    the nobody against the honored.

A man will seize one of his brothers
    in his father’s house, and say,
“You have a cloak, you be our leader;
    take charge of this heap of ruins!”
But in that day(M) he will cry out,
    “I have no remedy.(N)
I have no food(O) or clothing in my house;
    do not make me the leader of the people.”(P)

Jerusalem staggers,
    Judah is falling;(Q)
their words(R) and deeds(S) are against the Lord,
    defying(T) his glorious presence.
The look on their faces testifies(U) against them;
    they parade their sin like Sodom;(V)
    they do not hide it.
Woe to them!
    They have brought disaster(W) upon themselves.

10 Tell the righteous it will be well(X) with them,
    for they will enjoy the fruit of their deeds.(Y)
11 Woe to the wicked!(Z)
    Disaster(AA) is upon them!
They will be paid back(AB)
    for what their hands have done.(AC)

12 Youths(AD) oppress my people,
    women rule over them.
My people, your guides lead you astray;(AE)
    they turn you from the path.

13 The Lord takes his place in court;(AF)
    he rises to judge(AG) the people.
14 The Lord enters into judgment(AH)
    against the elders and leaders of his people:
“It is you who have ruined my vineyard;
    the plunder(AI) from the poor(AJ) is in your houses.
15 What do you mean by crushing my people(AK)
    and grinding(AL) the faces of the poor?”(AM)
declares the Lord, the Lord Almighty.(AN)

16 The Lord says,
    “The women of Zion(AO) are haughty,
walking along with outstretched necks,(AP)
    flirting with their eyes,
strutting along with swaying hips,
    with ornaments jingling on their ankles.
17 Therefore the Lord will bring sores on the heads of the women of Zion;
    the Lord will make their scalps bald.(AQ)

18 In that day(AR) the Lord will snatch away their finery: the bangles and headbands and crescent necklaces,(AS) 19 the earrings and bracelets(AT) and veils,(AU) 20 the headdresses(AV) and anklets and sashes, the perfume bottles and charms, 21 the signet rings and nose rings,(AW) 22 the fine robes and the capes and cloaks,(AX) the purses 23 and mirrors, and the linen garments(AY) and tiaras(AZ) and shawls.

24 Instead of fragrance(BA) there will be a stench;(BB)
    instead of a sash,(BC) a rope;
instead of well-dressed hair, baldness;(BD)
    instead of fine clothing, sackcloth;(BE)
    instead of beauty,(BF) branding.(BG)
25 Your men will fall by the sword,(BH)
    your warriors in battle.(BI)
26 The gates(BJ) of Zion will lament and mourn;(BK)
    destitute,(BL) she will sit on the ground.(BM)