Add parallel Print Page Options

Ègbé ni fún ìlú Dafidi

29 Ègbé ni fún ọ, Arieli, Arieli,
    ìlú níbi tí Dafidi tẹ̀dó sí!
Fi ọdún kún ọdún
    sì jẹ́ kí àwọn àkọlùkọgbà àjọ̀dún un rẹ tẹ̀síwájú.
Síbẹ̀síbẹ̀ èmi yóò dó ti Arieli
    òun yóò ṣọ̀fọ̀ yóò sì sọkún,
    òun yóò sì dàbí pẹpẹ ọkàn sí mi.
Èmi yóò sì wà ní bùba yí ọ ká níbi gbogbo;
    Èmi yóò sì fi ilé ìṣọ́ yí ọ ká:
    èmi yóò sì fi iṣẹ́ ìdó ti ni mi dojúkọ ọ́.
Ní ìrẹ̀sílẹ̀, ìwọ ó sì máa sọ̀rọ̀ láti ilẹ̀ wá;
    ọ̀rọ̀ rẹ yóò sì máa kùn jáde láti inú erùpẹ̀.
Ohun rẹ yóò máa jáde bí i ti ẹnìkan tó ní ẹ̀mí àfọ̀ṣẹ láti ilẹ̀ jáde wá,
    láti inú erùpẹ̀ ni ohùn rẹ
    yóò máa wá wúyẹ́wúyẹ́.

Ṣùgbọ́n àwọn ọ̀tá rẹ, yóò dàbí yanrìn kíkúnná,
    agbo àwọn aláìláàánú bí ìyàngbò tí a fẹ́ dànù.
    Lójijì, ní ìṣẹ́jú kan,
Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò wá
    pẹ̀lú àrá, ilẹ̀-rírì àti ariwo ńlá
àti ẹ̀fúùfù líle àti iná ajónirun
    Lẹ́yìn náà,
    ọ̀gọ̀ọ̀rọ̀ ènìyàn tí gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó bá Arieli jà,
tí ó dojú ìjà kọ òun àti ilé olódi rẹ̀
    tí ó sì dó tì í,
yóò dàbí ẹni pé nínú àlá,
    bí ìran ní òru
àti bí ìgbà tí ẹni tí ebi ń pa ń lá àlá pé òun ń jẹun,
    ṣùgbọ́n ó jí, ebi rẹ̀ sì wà pẹ̀lú rẹ̀;
tàbí bí ìgbà tí ẹni tí òǹgbẹ ń gbẹ lá àlá pé òun ń mu omi,
    ṣùgbọ́n nígbà tí ó jí, sì wò ó, ó dákú, òǹgbẹ sì ń gbẹ ọkàn rẹ̀.
Bẹ́ẹ̀ ni yóò sì rí fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè
    tí ń bá òkè Sioni jà.

Ẹ bẹ̀rù kí ẹnu kí ó yà yín,
    ẹ fọ́ ara yín lójú kí ẹ má sì ríran;
ẹ mutí yó kì í ṣe ọtí wáìnì,
    ẹ ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n, ṣùgbọ́n kì í ṣe ti ọtí líle.
10 Olúwa ti mú oorun ìjìká wá sórí i yín:
    ó ti dì yín lójú ẹ̀yin wòlíì;
    ó ti bo orí yín ẹ̀yin aríran.

11 Fún un yín gbogbo ìran yìí kò yàtọ̀ sí àwọn ọ̀rọ̀ tí a fi èdìdì dì sínú ìwé kíká. Bí ẹ bá sì fún ẹni tí ó lè ka ìwé kíká náà, tí ẹ sì sọ fún un pé, “Jọ̀wọ́ ka èyí,” òun yóò dáhùn pé, “Èmi kò lè kà á; a ti dì í ní èdìdì.” 12 Tàbí bí ẹ bá fún ẹni tí kò lè ka ìwé kíká náà tí ẹ sì sọ pé, “Jọ̀wọ́ ka èyí,” òun yóò dáhùn pé, “Èmi kò mọ̀ ọ́n kà.”

13 (A)Olúwa wí pé:

“Àwọn ènìyàn yìí súnmọ́ ọ̀dọ̀ mi pẹ̀lú ẹnu wọn,
    wọ́n sì bọ̀wọ̀ fún mi pẹ̀lú ètè wọn,
ṣùgbọ́n ọkàn wọn jìnnà sí mi.
    Ìsìn wọn si mi
ni a gbé ka orí òfin tí àwọn
    ọkùnrin kọ́ ni.
14 (B)Nítorí náà lẹ́ẹ̀kan sí i èmi yóò ya
    àwọn ènìyàn yìí lẹ́nu
pẹ̀lú ìyanu lórí ìyanu;
    ọgbọ́n àwọn ọlọ́gbọ́n ni yóò ṣègbé,
    ìmọ̀ àwọn onímọ̀ ni yóò pòórá.”
15 Ègbé ni fún àwọn tí ó lọ sí ọ̀gbun
    láti fi ètò wọn pamọ́ kúrò lójú Olúwa,
tí wọ́n ń ṣe iṣẹ́ ẹ wọn nínú òkùnkùn
    tí wọ́n sì rò pé,
    “Ta ló rí wa? Ta ni yóò mọ̀?”
16 (C)Ẹ̀yin dojú nǹkan délẹ̀,
    bí ẹni pé wọ́n rò pé amọ̀kòkò dàbí amọ̀!
Ǹjẹ́ ohun tí a ṣe le sọ fún olùṣe pé
    “Òun kọ́ ló ṣe mí”?
Ǹjẹ́ ìkòkò lè sọ nípa amọ̀kòkò pé,
    “kò mọ nǹkan”?

17 Ní àìpẹ́ jọjọ, ǹjẹ́
    a kò ní sọ Lebanoni di pápá ẹlẹ́tù lójú
    àti pápá ẹlẹ́tù lójú yóò dàbí aginjù?
18 (D)Ní ọjọ́ náà adití yóò gbọ́ ọ̀rọ̀ ìwé kíká náà,
    láti inú fìrífìrí àti òkùnkùn
    ni àwọn ojú afọ́jú yóò ríran.
19 Lẹ́ẹ̀kan sí i àwọn onírẹ̀lẹ̀ yóò yọ̀ nínú Olúwa:
    àwọn aláìní yóò yọ̀ nínú Ẹni Mímọ́ ti Israẹli.
20 Aláìláàánú yóò pòórá,
    àwọn tí ń ṣẹlẹ́yà yóò di àwátì,
    gbogbo àwọn tí ó ní ojú ibi ni a ó ké lulẹ̀—
21 àwọn tí wọ́n fi ọ̀rọ̀ kan mú ẹnìkan di ẹlẹ́bi,
    ẹni tí ń dẹkùn mú olùgbèjà ní ilé ẹjọ́
    tí ẹ fi ẹ̀rí èké dun aláìṣẹ̀ ní ìdájọ́.

22 Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa, ẹni tí ó ra Abrahamu padà sọ sí ilé Jakọbu:

    “Ojú kì yóò ti Jakọbu mọ́;
    ojú wọn kì yóò sì rẹ̀wẹ̀sì mọ́.
23 Nígbà tí wọ́n bá rí i láàrín àwọn ọmọ wọn,
    àwọn iṣẹ́ ọwọ́ mi,
wọn yóò ya orúkọ mi sí mímọ́,
    wọn yóò tẹ́wọ́gbà mímọ́ Ẹni Mímọ́ Jakọbu
    wọn yóò dìde dúró ní ìbọ̀wọ̀ fún Ọlọ́run Israẹli.
24 Gbogbo àwọn tí ń rìn ségesège ní yóò jèrè ìmọ̀;
    gbogbo àwọn tí ń ṣe àròyé yóò gba ìtọ́sọ́nà.”

Woe to David’s City

29 Woe(A) to you, Ariel, Ariel,(B)
    the city(C) where David settled!
Add year to year
    and let your cycle of festivals(D) go on.
Yet I will besiege Ariel;(E)
    she will mourn and lament,(F)
    she will be to me like an altar hearth.[a](G)
I will encamp against you on all sides;
    I will encircle(H) you with towers
    and set up my siege works(I) against you.
Brought low, you will speak from the ground;
    your speech will mumble(J) out of the dust.(K)
Your voice will come ghostlike(L) from the earth;
    out of the dust your speech will whisper.(M)

But your many enemies will become like fine dust,(N)
    the ruthless(O) hordes like blown chaff.(P)
Suddenly,(Q) in an instant,
    the Lord Almighty will come(R)
with thunder(S) and earthquake(T) and great noise,
    with windstorm and tempest(U) and flames of a devouring fire.(V)
Then the hordes of all the nations(W) that fight against Ariel,(X)
    that attack her and her fortress and besiege her,
will be as it is with a dream,(Y)
    with a vision in the night—
as when a hungry person dreams of eating,
    but awakens(Z) hungry still;
as when a thirsty person dreams of drinking,
    but awakens faint and thirsty still.(AA)
So will it be with the hordes of all the nations
    that fight against Mount Zion.(AB)

Be stunned and amazed,(AC)
    blind yourselves and be sightless;(AD)
be drunk,(AE) but not from wine,(AF)
    stagger,(AG) but not from beer.
10 The Lord has brought over you a deep sleep:(AH)
    He has sealed your eyes(AI) (the prophets);(AJ)
    he has covered your heads (the seers).(AK)

11 For you this whole vision(AL) is nothing but words sealed(AM) in a scroll. And if you give the scroll to someone who can read, and say, “Read this, please,” they will answer, “I can’t; it is sealed.” 12 Or if you give the scroll to someone who cannot read, and say, “Read this, please,” they will answer, “I don’t know how to read.”

13 The Lord says:

“These people(AN) come near to me with their mouth
    and honor me with their lips,(AO)
    but their hearts are far from me.(AP)
Their worship of me
    is based on merely human rules they have been taught.[b](AQ)
14 Therefore once more I will astound these people
    with wonder upon wonder;(AR)
the wisdom of the wise(AS) will perish,
    the intelligence of the intelligent will vanish.(AT)
15 Woe to those who go to great depths
    to hide(AU) their plans from the Lord,
who do their work in darkness and think,
    “Who sees us?(AV) Who will know?”(AW)
16 You turn things upside down,
    as if the potter were thought to be like the clay!(AX)
Shall what is formed say to the one who formed(AY) it,
    “You did not make me”?
Can the pot say to the potter,(AZ)
    “You know nothing”?(BA)

17 In a very short time,(BB) will not Lebanon(BC) be turned into a fertile field(BD)
    and the fertile field seem like a forest?(BE)
18 In that day(BF) the deaf(BG) will hear the words of the scroll,
    and out of gloom and darkness(BH)
    the eyes of the blind will see.(BI)
19 Once more the humble(BJ) will rejoice in the Lord;
    the needy(BK) will rejoice in the Holy One(BL) of Israel.
20 The ruthless(BM) will vanish,(BN)
    the mockers(BO) will disappear,
    and all who have an eye for evil(BP) will be cut down—
21 those who with a word make someone out to be guilty,
    who ensnare the defender in court(BQ)
    and with false testimony(BR) deprive the innocent of justice.(BS)

22 Therefore this is what the Lord, who redeemed(BT) Abraham,(BU) says to the descendants of Jacob:

“No longer will Jacob be ashamed;(BV)
    no longer will their faces grow pale.(BW)
23 When they see among them their children,(BX)
    the work of my hands,(BY)
they will keep my name holy;(BZ)
    they will acknowledge the holiness of the Holy One(CA) of Jacob,
    and will stand in awe of the God of Israel.
24 Those who are wayward(CB) in spirit will gain understanding;(CC)
    those who complain will accept instruction.”(CD)

Footnotes

  1. Isaiah 29:2 The Hebrew for altar hearth sounds like the Hebrew for Ariel.
  2. Isaiah 29:13 Hebrew; Septuagint They worship me in vain; / their teachings are merely human rules