Isaiah 23
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
Àsọtẹ́lẹ̀ kan nípa Tire
23 (A)Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ tí ó kan Tire:
Hu, ìwọ ọkọ̀ ojú omi Tarṣiṣi!
Nítorí a ti pa Tire run
láìsí ilé tàbí èbúté.
Láti ilẹ̀ Saipurọsi ni
ọ̀rọ̀ ti wá sọ́dọ̀ wọn.
2 Dákẹ́ jẹ́ẹ́, ẹ̀yin ènìyàn erékùṣù
àti ẹ̀yin oníṣòwò ti Sidoni,
ẹ̀yin tí àwọn a wẹ Òkun ti sọ dọlọ́rọ̀.
3 Láti orí àwọn omi ńlá
ni irúgbìn ìyẹ̀fun ti ilẹ̀ Ṣihori ti wá
ìkórè ti odò Naili ni owóòná Tire,
òun sì ti di ibùjókòó ọjà fún
àwọn orílẹ̀-èdè.
4 Kí ojú kí ó tì ọ́, ìwọ Sidoni àti ìwọ
àní ìwọ ilé ààbò ti Òkun,
nítorí Òkun ti sọ̀rọ̀:
“Èmi kò tí ì wà ní ipò ìrọbí tàbí ìbímọ rí
Èmi kò tí ì wo àwọn ọmọkùnrin
tàbí kí n tọ́ àwọn ọmọbìnrin dàgbà rí.”
5 Nígbà tí ọ̀rọ̀ bá dé Ejibiti,
wọn yóò wà ní ìpayínkeke nípa
ìròyìn láti Tire.
6 Kọjá wá sí Tarṣiṣi;
pohùnréré, ẹ̀yin ènìyàn erékùṣù.
7 Ǹjẹ́ èyí náà ni ìlú àríyá yín,
ògbólógbòó ìlú náà,
èyí tí ẹsẹ̀ rẹ̀ ti sìn ín lọ
láti lọ tẹ̀dó sí ilẹ̀ tí ó jìnnà réré.
8 Ta ló gbèrò èyí sí Tire,
ìlú aládé,
àwọn oníṣòwò ẹni tí ó jẹ́ ọmọ-aládé
tí àwọn oníṣòwò wọ́n jẹ́ ìlúmọ̀míká
ní orílẹ̀ ayé?
9 Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti ṣètò rẹ̀,
láti tẹrí ìgbéraga àti ògo rẹ ba
àti láti rẹ gbogbo àwọn ọlọ́lá
ilé ayé sílẹ̀.
10 Tu ilẹ̀ rẹ gẹ́gẹ́ bí i ti ipadò odò Ejibiti,
Ìwọ ọmọbìnrin Tarṣiṣi,
nítorí ìwọ kò ní èbúté mọ́.
11 Olúwa ti na ọwọ́ rẹ̀ jáde sí orí Òkun
ó sì mú kí àwọn ilẹ̀ ọba wárìrì.
Ó ti pa àṣẹ kan tí ó kan Kenaani
pé kí a pa ilé ààbò rẹ̀ run.
12 Ó wí pé, “Kò sí àríyá fún ọ mọ́”
ìwọ wúńdíá ti Sidoni, tí a ti tẹ̀ mọ́lẹ̀ báyìí!
“Gbéra, rékọjá lọ sí Saipurọsi,
níbẹ̀ pẹ̀lú o kì yóò ní ìsinmi.”
13 Bojú wo ilẹ̀ àwọn ará Babeli,
àwọn ènìyàn tí kò jámọ́ nǹkan kan báyìí
Àwọn Asiria ti sọ ọ́ di
ibùgbé àwọn ohun ẹranko aginjù;
wọn ti gbé ilé ìṣọ́ ìtẹ̀gùn wọn sókè,
wọ́n ti tú odi rẹ̀ sí ìhòhò
wọ́n sì ti sọ ọ́ di ààtàn.
14 Hu, ìwọ ọkọ̀ ojú omi Tarṣiṣi;
wọ́n ti pa odi rẹ̀ run!
15 Ní àkókò náà a ó gbàgbé Tire fún àádọ́rin ọdún, ọjọ́ ayé ọba kan. Ṣùgbọ́n ní òpin àádọ́rin ọdún wọ̀nyí, yóò ṣẹlẹ̀ sí Tire gẹ́gẹ́ bí orin àgbèrè:
16 “Mú dùùrù kan, rìn kọjá láàrín ìlú,
Ìwọ àgbèrè tí a ti gbàgbé;
lu dùùrù dáradára, kọ ọ̀pọ̀ orin,
kí a lè ba à rántí rẹ.”
17 (B)Ní òpin àádọ́rin ọdún náà, Olúwa yóò bá Tire jà. Òun yóò sì padà sí àyálò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí panṣágà, yóò sì máa ṣe òwò rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ilẹ̀ ọba tí ó wà ní ilẹ̀ ayé. 18 Síbẹ̀síbẹ̀ èrè rẹ̀ àti owó iṣẹ́ rẹ̀ ni a ó yà sọ́tọ̀ fún Olúwa; a kò ní kó wọn pamọ́ tàbí kí a há wọn mọ́wọ́. Ère rẹ̀ ni a ó fi fún àwọn tí ó ń gbé níwájú Olúwa, fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ oúnjẹ àti aṣọ.
Isaiah 23
New International Version
A Prophecy Against Tyre
23 A prophecy against Tyre:(A)
Wail,(B) you ships(C) of Tarshish!(D)
For Tyre is destroyed(E)
and left without house or harbor.
From the land of Cyprus
word has come to them.
2 Be silent,(F) you people of the island
and you merchants(G) of Sidon,(H)
whom the seafarers have enriched.
3 On the great waters
came the grain of the Shihor;(I)
the harvest of the Nile[a](J) was the revenue of Tyre,(K)
and she became the marketplace of the nations.
4 Be ashamed, Sidon,(L) and you fortress of the sea,
for the sea has spoken:
“I have neither been in labor nor given birth;(M)
I have neither reared sons nor brought up daughters.”
5 When word comes to Egypt,
they will be in anguish(N) at the report from Tyre.(O)
6 Cross over to Tarshish;(P)
wail, you people of the island.
7 Is this your city of revelry,(Q)
the old, old city,
whose feet have taken her
to settle in far-off lands?
8 Who planned this against Tyre,
the bestower of crowns,
whose merchants(R) are princes,
whose traders(S) are renowned in the earth?
9 The Lord Almighty planned(T) it,
to bring down(U) her pride in all her splendor
and to humble(V) all who are renowned(W) on the earth.
10 Till[b] your land as they do along the Nile,
Daughter Tarshish,
for you no longer have a harbor.
11 The Lord has stretched out his hand(X) over the sea
and made its kingdoms tremble.(Y)
He has given an order concerning Phoenicia
that her fortresses be destroyed.(Z)
12 He said, “No more of your reveling,(AA)
Virgin Daughter(AB) Sidon, now crushed!
“Up, cross over to Cyprus;(AC)
even there you will find no rest.”
13 Look at the land of the Babylonians,[c](AD)
this people that is now of no account!
The Assyrians(AE) have made it
a place for desert creatures;(AF)
they raised up their siege towers,(AG)
they stripped its fortresses bare
and turned it into a ruin.(AH)
15 At that time Tyre(AL) will be forgotten for seventy years,(AM) the span of a king’s life. But at the end of these seventy years, it will happen to Tyre as in the song of the prostitute:
16 “Take up a harp, walk through the city,
you forgotten prostitute;(AN)
play the harp well, sing many a song,
so that you will be remembered.”
17 At the end of seventy years,(AO) the Lord will deal with Tyre. She will return to her lucrative prostitution(AP) and will ply her trade with all the kingdoms on the face of the earth.(AQ) 18 Yet her profit and her earnings will be set apart for the Lord;(AR) they will not be stored up or hoarded. Her profits will go to those who live before the Lord,(AS) for abundant food and fine clothes.(AT)
Footnotes
- Isaiah 23:3 Masoretic Text; Dead Sea Scrolls Sidon, / who cross over the sea; / your envoys 3 are on the great waters. / The grain of the Shihor, / the harvest of the Nile,
- Isaiah 23:10 Dead Sea Scrolls and some Septuagint manuscripts; Masoretic Text Go through
- Isaiah 23:13 Or Chaldeans
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.
Holy Bible, New International Version®, NIV® Copyright ©1973, 1978, 1984, 2011 by Biblica, Inc.® Used by permission. All rights reserved worldwide.
NIV Reverse Interlinear Bible: English to Hebrew and English to Greek. Copyright © 2019 by Zondervan.