Add parallel Print Page Options

Àsọtẹ́lẹ̀ lòdì sí Ejibiti

19 (A)Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ tí ó kan Ejibiti:

Kíyèsi i, Olúwa gun àwọsánmọ̀ tí ó yára lẹ́ṣin
    ó sì ń bọ̀ wá sí Ejibiti.
Àwọn ère òrìṣà Ejibiti wárìrì níwájú rẹ̀,
    ọkàn àwọn ará Ejibiti sì ti domi nínú wọn.

“Èmi yóò rú àwọn ará Ejibiti sókè sí ara wọn
    arákùnrin yóò bá arákùnrin rẹ̀ jà,
aládùúgbò yóò dìde sí aládùúgbò rẹ̀,
    ìlú yóò dìde sí ìlú,
    ilẹ̀ ọba sí ilẹ̀ ọba.
Àwọn ará Ejibiti yóò sọ ìrètí nù,
    èmi yóò sì sọ èrò wọn gbogbo di òfo;
wọn yóò bá àwọn òrìṣà àti ẹ̀mí àwọn òkú sọ̀rọ̀,
    àwọn awoṣẹ́ àti àwọn abókùúsọ̀rọ̀.
Èmi yóò fi Ejibiti lé agbára
    àwọn ìkà amúnisìn lọ́wọ́,
ọba aláìláàánú ni yóò jẹ ọba lé wọn lórí,”
    ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.

Gbogbo omi inú odò ni yóò gbẹ,
    gbogbo ilẹ̀ àyíká odò ni yóò gbẹ tí yóò sì sáàpá.
Adágún omi yóò sì di rírùn;
    àwọn odò ilẹ̀ Ejibiti yóò máa dínkù
wọn yóò sì gbẹ.
    Àwọn koríko odò àti ìrẹ̀tẹ̀ yóò gbẹ,
àwọn igi ipadò Naili pẹ̀lú,
    tí ó wà ní orísun odò,
gbogbo oko tí a dá sí ipadò Naili
    yóò gbẹ dànù tí yóò sì fẹ́ dànù
    tí kò sì ní sí mọ́.
Àwọn apẹja yóò sọkún kíkorò,
    àti gbogbo àwọn tí ó ń ju ìwọ̀ sínú odò;
    odò náà yóò sì máa rùn.
Àwọn tí ó ń ṣiṣẹ́ pẹ̀lú ọ̀gbọ̀ yóò kọminú
    àwọn ahunṣọ ọ̀gbọ̀ yóò sọ ìrètí nù.
10 Àwọn tí ń ṣiṣẹ́ aṣọ yóò rẹ̀wẹ̀sì,
    gbogbo àwọn oníṣẹ́ oṣù ni àìsàn ọkàn yóò ṣe.

11 Àwọn oníṣẹ́ Ṣoani ti di aláìgbọ́n,
    àwọn ọlọ́gbọ́n olùdámọ̀ràn Farao
ń mú ìmọ̀ràn àìgbọ́n wá.
    Báwo ló ṣe lè sọ fún Farao pé,
“Mo jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn ọlọ́gbọ́n ènìyàn,
    ọ̀kan nínú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn àwọn ọba àtijọ́.”

12 Níbo ni àwọn ọlọ́gbọ́n ènìyàn rẹ wà báyìí?
    Jẹ́ kí wọn fihàn ọ́ kí wọn sì sọ ọ́ di mí mọ̀
ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun
    ti pinnu lórí Ejibiti.
13 Àwọn ọmọ-aládé Ṣoani ti di aṣiwèrè,
    a ti tan àwọn ọmọ-aládé Memfisi jẹ;
àwọn òkúta igun ilé tí í ṣe ti ẹ̀yà rẹ
    ti ṣi Ejibiti lọ́nà.
14 Olúwa ti da ẹ̀mí òòyì sínú wọn;
    wọ́n mú Ejibiti ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n nínú
ohun gbogbo tí ó ń ṣe,
    gẹ́gẹ́ bí ọ̀mùtí ti í ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n nínú èébì rẹ̀.
15 Kò sí ohun tí Ejibiti le ṣe—
    orí tàbí ìrù, ọ̀wá ọ̀pẹ tàbí koríko odò.

16 Ní ọjọ́ náà ni àwọn ará Ejibiti yóò dàbí obìnrin. Wọn yóò gbọ̀n jìnnìjìnnì pẹ̀lú ẹ̀rù nítorí ọwọ́ Olúwa àwọn ọmọ-ogun tí a gbé sókè sí wọn. 17 Ilẹ̀ Juda yóò sì di ẹ̀rù fún Ejibiti; gbogbo àwọn tí a bá ti dárúkọ Juda létí wọn ni yóò wárìrì, nítorí ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun gbèrò láti ṣe sí wọn.

18 Ní ọjọ́ náà ìlú márùn-ún ní ilẹ̀ Ejibiti yóò sọ èdè àwọn ará Kenaani, wọn yóò sì búra àtìlẹ́yìn fún Olúwa àwọn ọmọ-ogun. Ọ̀kan nínú wọn ni a ó sì máa pè ní ìlú ìparun.

19 Ní ọjọ́ náà pẹpẹ kan yóò wà fún Olúwa ní àárín gbùngbùn Ejibiti, àti ọ̀wọ́n kan fún Olúwa ní etí bodè rẹ̀. 20 Yóò sì jẹ́ ààmì àti ẹ̀rí sí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ní ilẹ̀ Ejibiti. Nígbà tí wọ́n bá ké pe Olúwa nítorí àwọn aninilára wọn, yóò rán olùgbàlà àti olùgbèjà kan sí wọn tí yóò sì gbà wọ́n sílẹ̀. 21 Báyìí ni Olúwa yóò sọ ara rẹ̀ di mí mọ̀ fún àwọn ará Ejibiti àti ní ọjọ́ náà ni wọn yóò gba Olúwa gbọ́. Wọn yóò sìn ín pẹ̀lú ẹbọ ọrẹ ìyẹ̀fun, wọn yóò jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún Olúwa wọn yóò sì mú un ṣẹ. 22 Olúwa yóò fi àjàkálẹ̀-ààrùn kan bá Ejibiti jà; yóò bá wọn jà yóò sì tún wò wọ́n sàn. Wọn yóò yípadà sí Olúwa, Òun yóò sì gbọ́ ẹ̀bẹ̀ wọn yóò sì wò wọ́n sàn.

23 Ní ọjọ́ náà òpópónà kan yóò wá láti Ejibiti lọ sí Asiria. Àwọn ará Asiria yóò lọ sí Ejibiti àti àwọn ará Ejibiti lọ sí Asiria. Àwọn ará Ejibiti àti ará Asiria yóò jọ́sìn papọ̀. 24 Ní ọjọ́ náà Israẹli yóò di ẹ̀kẹta pẹ̀lú Ejibiti àti Asiria, àní orísun ìbùkún ní ilẹ̀ ayé. 25 Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò bùkún wọn yóò wí pé, “Ìbùkún ni fún Ejibiti ènìyàn mi, Asiria iṣẹ́ ọwọ́ mi, àti Israẹli ìní mi.”

A Prophecy Against Egypt

19 A prophecy(A) against Egypt:(B)

See, the Lord rides on a swift cloud(C)
    and is coming to Egypt.
The idols of Egypt tremble before him,
    and the hearts of the Egyptians melt(D) with fear.

“I will stir up Egyptian against Egyptian—
    brother will fight against brother,(E)
    neighbor against neighbor,
    city against city,
    kingdom against kingdom.(F)
The Egyptians will lose heart,(G)
    and I will bring their plans(H) to nothing;(I)
they will consult the idols and the spirits of the dead,
    the mediums and the spiritists.(J)
I will hand the Egyptians over
    to the power of a cruel master,
and a fierce king(K) will rule over them,”
    declares the Lord, the Lord Almighty.

The waters of the river will dry up,(L)
    and the riverbed will be parched and dry.(M)
The canals will stink;(N)
    the streams of Egypt will dwindle and dry up.(O)
The reeds(P) and rushes will wither,(Q)
    also the plants(R) along the Nile,
    at the mouth of the river.
Every sown field(S) along the Nile
    will become parched, will blow away and be no more.(T)
The fishermen(U) will groan and lament,
    all who cast hooks(V) into the Nile;
those who throw nets on the water
    will pine away.
Those who work with combed flax(W) will despair,
    the weavers of fine linen(X) will lose hope.
10 The workers in cloth will be dejected,
    and all the wage earners will be sick at heart.

11 The officials of Zoan(Y) are nothing but fools;
    the wise counselors(Z) of Pharaoh give senseless advice.(AA)
How can you say to Pharaoh,
    “I am one of the wise men,(AB)
    a disciple of the ancient kings”?

12 Where are your wise men(AC) now?
    Let them show you and make known
what the Lord Almighty
    has planned(AD) against Egypt.
13 The officials of Zoan(AE) have become fools,
    the leaders of Memphis(AF) are deceived;
the cornerstones(AG) of her peoples
    have led Egypt astray.
14 The Lord has poured into them
    a spirit of dizziness;(AH)
they make Egypt stagger in all that she does,
    as a drunkard staggers(AI) around in his vomit.
15 There is nothing Egypt can do—
    head or tail, palm branch or reed.(AJ)

16 In that day(AK) the Egyptians will become weaklings.(AL) They will shudder with fear(AM) at the uplifted hand(AN) that the Lord Almighty raises against them. 17 And the land of Judah will bring terror to the Egyptians; everyone to whom Judah is mentioned will be terrified,(AO) because of what the Lord Almighty is planning(AP) against them.

18 In that day(AQ) five cities(AR) in Egypt will speak the language of Canaan and swear allegiance(AS) to the Lord Almighty. One of them will be called the City of the Sun.[a](AT)

19 In that day(AU) there will be an altar(AV) to the Lord in the heart of Egypt,(AW) and a monument(AX) to the Lord at its border. 20 It will be a sign and witness(AY) to the Lord Almighty in the land of Egypt. When they cry out to the Lord because of their oppressors, he will send them a savior(AZ) and defender, and he will rescue(BA) them. 21 So the Lord will make himself known to the Egyptians, and in that day they will acknowledge(BB) the Lord. They will worship(BC) with sacrifices and grain offerings; they will make vows to the Lord and keep them.(BD) 22 The Lord will strike(BE) Egypt with a plague;(BF) he will strike them and heal them. They will turn(BG) to the Lord, and he will respond to their pleas and heal(BH) them.

23 In that day(BI) there will be a highway(BJ) from Egypt to Assyria.(BK) The Assyrians will go to Egypt and the Egyptians to Assyria. The Egyptians and Assyrians will worship(BL) together. 24 In that day(BM) Israel will be the third, along with Egypt and Assyria,(BN) a blessing[b](BO) on the earth. 25 The Lord Almighty will bless(BP) them, saying, “Blessed be Egypt my people,(BQ) Assyria my handiwork,(BR) and Israel my inheritance.(BS)

Footnotes

  1. Isaiah 19:18 Some manuscripts of the Masoretic Text, Dead Sea Scrolls, Symmachus and Vulgate; most manuscripts of the Masoretic Text City of Destruction
  2. Isaiah 19:24 Or Assyria, whose names will be used in blessings (see Gen. 48:20); or Assyria, who will be seen by others as blessed