Add parallel Print Page Options

Àsọtẹ́lẹ̀ lòdì sí Babeli

13 (A)Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ tí ó kan Babeli

    èyí tí Isaiah ọmọ Amosi rí:
Gbé àsíá sókè ní orí òkè gbẹrẹfu,
    kígbe sí wọn, pè wọ́n
    láti wọlé sí ẹnu-ọ̀nà àwọn ọlọ́lá.
Mo ti pàṣẹ fún àwọn ẹni mímọ́ mi,
    mo ti pe àwọn jagunjagun mi
láti gbé ìbínú mi jáde
    àwọn tí ń yọ̀ nínú ìṣẹ́gun mi.

Gbọ́ ohùn kan ní àwọn orí òkè,
    gẹ́gẹ́ bí i ti ogunlọ́gọ̀ ènìyàn
Gbọ́ ìdàrúdàpọ̀ láàrín àwọn ìjọba,
    gẹ́gẹ́ bí i ti ìkórajọ àwọn orílẹ̀-èdè!
Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti kó ogun rẹ̀ jọ
    àwọn jagunjagun fún ogun.
Wọ́n wá láti ọ̀nà jíjìn réré,
    láti ìpẹ̀kun ọ̀run wá
Olúwa pẹ̀lú àwọn ohun ìjà ìbínú rẹ̀,
    láti pa gbogbo orílẹ̀-èdè náà run.

Ẹ hu, nítorí ọjọ́ Olúwa súnmọ́ tòsí,
    yóò sì wá gẹ́gẹ́ bí ìparun láti ọ̀dọ̀ Alágbára jùlọ.
Nítorí èyí, gbogbo ọwọ́ ni yóò rọ,
    ọkàn ẹnìkọ̀ọ̀kan yóò rẹ̀wẹ̀sì.
Ẹ̀rù yóò gbá wọn mú,
    ìrora àti ìpayínkeke yóò dìwọ́n mú,
wọn yóò kérora gẹ́gẹ́ bí obìnrin tí ó ń rọbí.
    Ẹnìkínní yóò wo ẹnìkejì rẹ̀ pẹ̀lú ìpayà
    ojú wọn á sì gbinájẹ.

Kíyèsi i, ọjọ́ Olúwa ń bọ̀
    ọjọ́ búburú, pẹ̀lú ìbínú
àti ìrunú gbígbóná—
    láti sọ ilẹ̀ náà dahoro,
    àti láti pa àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ inú rẹ̀ run.
10 (B)Àwọn ìràwọ̀ ojú ọ̀run àti ìkójọpọ̀ wọn
    kò sì ní fi ìmọ́lẹ̀ wọn hàn.
Àṣẹ̀ṣẹ̀yọ oòrùn yóò di òkùnkùn
    àti òṣùpá kò ní fi ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ hàn.
11 Èmi yóò jẹ ayé ní ìyà nítorí ibi rẹ̀,
    àwọn ìkà nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
Èmi yóò fi òpin sí gààrù àwọn agbéraga
    èmi ó sì rẹ ìgbéraga àwọn aláìláàánú sílẹ̀.
12 Èmi yóò jẹ́ kí ọkùnrin kí ó wọn
    ju ojúlówóo wúrà lọ,
    yóò sì ṣọ̀wọ́n ju wúrà Ofiri lọ.
13 Nítorí náà èmi yóò jẹ́ kí àwọn ọ̀run kí ó wárìrì;
    ayé yóò sì mì tìtì ní ibùjókòó rẹ̀
láti ọwọ́ ìbínú Olúwa àwọn ọmọ-ogun,
    ní ọjọ́ ìbínú gbígbóná rẹ.

14 Gẹ́gẹ́ bí egbin tí à ń dọdẹ rẹ̀,
    gẹ́gẹ́ bí àgùntàn tí kò ní olùṣọ́,
ọ̀kọ̀ọ̀kan yóò padà tọ àwọn ènìyàn rẹ̀ lọ,
    ọ̀kọ̀ọ̀kan yóò sá padà sí ilẹ̀ abínibí i rẹ̀.
15 Ẹnikẹ́ni tí a bá gbámú ni a ó wọ́ nílẹ̀ tuurutu,
    gbogbo àwọn tí ọwọ́ bá tẹ̀ ni yóò ti ipa idà kú.
16 Àwọn ọ̀dọ́mọdé wọn ni a ó fọ́ sí wẹ́wẹ́ níṣojú wọn,
    gbogbo ilẹ̀ wọn ni a ó kó
    àwọn aya wọn ni a ó sì bá dàpọ̀.

17 Kíyèsi i, èmi yóò ru àwọn Media sókè sí wọn,
    àwọn tí kò bìkítà fún fàdákà
    tí kò sì ní inú dídùn sí wúrà.
18 Ọrùn wọn yóò ré àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin lulẹ̀;
    wọn kò ní ṣàánú àwọn ọ̀dọ́mọdé
    tàbí kí wọn ṣíjú àánú wo àwọn ọmọdé.
19 Babeli, ohun ọ̀ṣọ́ àwọn ìjọba
    ògo ìgbéraga àwọn ará Babeli
ni Ọlọ́run yóò da ojú rẹ̀ bolẹ̀
    gẹ́gẹ́ bí Sodomu àti Gomorra.
20 A kì yóò tẹ̀ ibẹ̀ dó mọ́
    tàbí kí á gbé inú rẹ̀ láti ìrandíran;
    Ará Arabia kì yóò pa àgọ́ níbẹ̀ mọ́,
    olùṣọ́-àgùntàn kan kì yóò kó ẹran rẹ̀ sinmi níbẹ̀.
21 (C)Ṣùgbọ́n àwọn ẹranko igbó ni yóò dùbúlẹ̀ níbẹ̀,
    àwọn ajáko yóò kún inú ilé wọn,
níbẹ̀ ni àwọn òwìwí yóò máa gbé
    níbẹ̀ ni àwọn ewúrẹ́ igbó yóò ti máa bẹ́ kiri.
22 Ìkookò yóò máa gbó ní ibùba wọn,
    àwọn ajáko nínú arẹwà ààfin wọn.

A Prophecy Against Babylon

13 A prophecy(A) against Babylon(B) that Isaiah son of Amoz(C) saw:(D)

Raise a banner(E) on a bare hilltop,
    shout to them;
beckon to them
    to enter the gates(F) of the nobles.
I have commanded those I prepared for battle;
    I have summoned my warriors(G) to carry out my wrath(H)
    those who rejoice(I) in my triumph.

Listen, a noise on the mountains,
    like that of a great multitude!(J)
Listen, an uproar(K) among the kingdoms,
    like nations massing together!
The Lord Almighty(L) is mustering(M)
    an army for war.
They come from faraway lands,
    from the ends of the heavens(N)
the Lord and the weapons(O) of his wrath(P)
    to destroy(Q) the whole country.

Wail,(R) for the day(S) of the Lord is near;
    it will come like destruction(T) from the Almighty.[a](U)
Because of this, all hands will go limp,(V)
    every heart will melt with fear.(W)
Terror(X) will seize them,
    pain and anguish will grip(Y) them;
    they will writhe like a woman in labor.(Z)
They will look aghast at each other,
    their faces aflame.(AA)

See, the day(AB) of the Lord is coming
    —a cruel(AC) day, with wrath(AD) and fierce anger(AE)
to make the land desolate
    and destroy the sinners within it.
10 The stars of heaven and their constellations
    will not show their light.(AF)
The rising sun(AG) will be darkened(AH)
    and the moon will not give its light.(AI)
11 I will punish(AJ) the world for its evil,
    the wicked(AK) for their sins.
I will put an end to the arrogance of the haughty(AL)
    and will humble(AM) the pride of the ruthless.(AN)
12 I will make people(AO) scarcer than pure gold,
    more rare than the gold of Ophir.(AP)
13 Therefore I will make the heavens tremble;(AQ)
    and the earth will shake(AR) from its place
at the wrath(AS) of the Lord Almighty,
    in the day of his burning anger.(AT)

14 Like a hunted(AU) gazelle,
    like sheep without a shepherd,(AV)
they will all return to their own people,
    they will flee(AW) to their native land.(AX)
15 Whoever is captured will be thrust through;
    all who are caught will fall(AY) by the sword.(AZ)
16 Their infants(BA) will be dashed to pieces before their eyes;
    their houses will be looted and their wives violated.(BB)

17 See, I will stir up(BC) against them the Medes,(BD)
    who do not care for silver
    and have no delight in gold.(BE)
18 Their bows(BF) will strike down the young men;(BG)
    they will have no mercy(BH) on infants,
    nor will they look with compassion on children.(BI)
19 Babylon,(BJ) the jewel of kingdoms,(BK)
    the pride and glory(BL) of the Babylonians,[b]
will be overthrown(BM) by God
    like Sodom and Gomorrah.(BN)
20 She will never be inhabited(BO)
    or lived in through all generations;
there no nomads(BP) will pitch their tents,
    there no shepherds will rest their flocks.
21 But desert creatures(BQ) will lie there,
    jackals(BR) will fill her houses;
there the owls(BS) will dwell,
    and there the wild goats(BT) will leap about.
22 Hyenas(BU) will inhabit her strongholds,(BV)
    jackals(BW) her luxurious palaces.
Her time is at hand,(BX)
    and her days will not be prolonged.(BY)

Footnotes

  1. Isaiah 13:6 Hebrew Shaddai
  2. Isaiah 13:19 Or Chaldeans