Add parallel Print Page Options

    nígbà tí èmi ìbá mú Israẹli láradá.
Ẹ̀ṣẹ̀ Efraimu ń farahàn
    ìwà búburú Samaria sì ń hàn síta.
Wọ́n ń ṣe ẹ̀tàn,
    àwọn olè ń fọ́ ilé;
    àwọn ọlọ́ṣà ń jalè ní òpópónà;
Ṣùgbọ́n wọn kò mọ̀ pé
    mo rántí gbogbo ìwà búburú wọn:
Ẹ̀ṣẹ̀ wọn gbé wọn mì pátápátá;
    wọ́n wà níwájú mi nígbà gbogbo.

“Wọ́n ń mú inú ọba dùn pẹ̀lú ìwà búburú wọn,
    àti inú ọmọ-aládé dùn pẹ̀lú irọ́ wọn
Alágbèrè ni gbogbo wọn
    wọ́n gbóná bí ààrò àkàrà
tí a dáwọ́ kíkoná dúró,
    lẹ́yìn ìgbà tí o ti pò ìyẹ̀fun tán, títí ìgbà tí yóò wú.
Ní ọjọ́ àjọ̀dún ọba wa
    wáìnì mú ara ọmọ-aládé gbóná
    ó sì darapọ̀ mọ́ àwọn oníyẹ̀yẹ́.
Ọkàn wọn ń gbóná bí i ààrò
    wọ́n sì tọ̀ ọ́ lọ pẹ̀lú rìkíṣí,
ìbínú wọn pa lọ́lọ́ ní gbogbo òru
    ó sì bú jáde bí ọ̀wọ́-iná ní òwúrọ̀.
Gbogbo wọn gbóná bí ààrò
    wọ́n pa gbogbo olórí wọn run,
gbogbo ọba wọn si ṣubú
    kò sì ṣí ẹnìkan nínú wọn tí ó ké pè mí.

“Efraimu ti darapọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn náà;
    Efraimu jẹ́ àkàrà tí a kò yípadà
Àwọn àlejò ti jẹ agbára rẹ̀ run
    ṣùgbọ́n kò sì mọ̀,
Ewú ti wà ní orí rẹ̀ káàkiri
    bẹ́ẹ̀ ni kò kíyèsi i
10 Ìgbéraga Israẹli ń jẹ́rìí sí i
    ṣùgbọ́n pẹ̀lú gbogbo èyí
kò padà sí ọ̀dọ̀ Olúwa
    Ọlọ́run, tàbí kí ó wá a.

11 “Efraimu dàbí àdàbà
    tó rọrùn láti tànjẹ àti aláìgbọ́n
tó wá ń pé Ejibiti nísinsin yìí
    tó sì tún ń padà lọ si Asiria.
12 Nígbà tí wọ́n bá lọ, èmi ó ta àwọ̀n mi sórí wọn
    Èmi ó fà wọ́n lulẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹyẹ ojú ọ̀run
Nígbà tí mo bá gbọ́ pé wọ́n rìn pọ̀
    Èmi ó nà wọ́n fún iṣẹ́ búburú ọwọ́ wọn.
13 Ègbé ní fún wọn,
    nítorí pé wọ́n ti yà kúrò lọ́dọ̀ mi!
Ìparun wà lórí wọn,
    nítorí pé wọ́n ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi!
Èmi fẹ́ láti rà wọ́n padà.
    Ṣùgbọ́n wọ́n ń parọ́ mọ́ mi
14 Wọn kò kégbe pè mí láti ọkàn wọn,
    Ṣùgbọ́n wọ́n ń pohùnréré ẹkún lórí ibùsùn wọn.
Wọ́n kó ara wọn jọ, nítorí ọkà àti wáìnì
    ṣùgbọ́n wọ́n yípadà kúrò ní ọ̀dọ̀ mi.
15 Mo kọ́ wọn, mo sì fún wọn ní agbára,
    síbẹ̀ wọ́n tún ń dìtẹ̀ mọ́ mi.
16 Wọn kò padà sí ọ̀dọ̀ Ọ̀gá-ògo;
    wọ́n dàbí ọfà tí ó ti bàjẹ́
Àwọn aṣíwájú wọn yóò ti ipa idà ṣubú
    nítorí ìrunú ahọ́n wọn.
Torí èyí, wọn ó fi wọ́n ṣe
    ẹlẹ́yà ní ilẹ̀ Ejibiti.

whenever I would heal Israel,
the sins of Ephraim are exposed
    and the crimes of Samaria revealed.(A)
They practice deceit,(B)
    thieves break into houses,(C)
    bandits rob in the streets;(D)
but they do not realize
    that I remember(E) all their evil deeds.(F)
Their sins engulf them;(G)
    they are always before me.

“They delight the king with their wickedness,
    the princes with their lies.(H)
They are all adulterers,(I)
    burning like an oven
whose fire the baker need not stir
    from the kneading of the dough till it rises.
On the day of the festival of our king
    the princes become inflamed with wine,(J)
    and he joins hands with the mockers.(K)
Their hearts are like an oven;(L)
    they approach him with intrigue.
Their passion smolders all night;
    in the morning it blazes like a flaming fire.
All of them are hot as an oven;
    they devour their rulers.
All their kings fall,(M)
    and none of them calls(N) on me.

“Ephraim mixes(O) with the nations;
    Ephraim is a flat loaf not turned over.
Foreigners sap his strength,(P)
    but he does not realize it.
His hair is sprinkled with gray,
    but he does not notice.
10 Israel’s arrogance testifies against him,(Q)
    but despite all this
he does not return(R) to the Lord his God
    or search(S) for him.

11 “Ephraim is like a dove,(T)
    easily deceived and senseless—
now calling to Egypt,(U)
    now turning to Assyria.(V)
12 When they go, I will throw my net(W) over them;
    I will pull them down like the birds in the sky.
When I hear them flocking together,
    I will catch them.
13 Woe(X) to them,
    because they have strayed(Y) from me!
Destruction to them,
    because they have rebelled against me!
I long to redeem them
    but they speak about me(Z) falsely.(AA)
14 They do not cry out to me from their hearts(AB)
    but wail on their beds.
They slash themselves,[a] appealing to their gods
    for grain and new wine,(AC)
    but they turn away from me.(AD)
15 I trained(AE) them and strengthened their arms,
    but they plot evil(AF) against me.
16 They do not turn to the Most High;(AG)
    they are like a faulty bow.(AH)
Their leaders will fall by the sword
    because of their insolent(AI) words.
For this they will be ridiculed(AJ)
    in the land of Egypt.(AK)

Footnotes

  1. Hosea 7:14 Some Hebrew manuscripts and Septuagint; most Hebrew manuscripts They gather together