Add parallel Print Page Options

“Sọ fún àwọn arákùnrin rẹ, ‘Ènìyàn mi,’ kí o sì wí fún àwọn arábìnrin rẹ ‘àyànfẹ́ mi.’

Ẹ̀sùn tí a fi kan ìyàwó aláìṣòótọ́

“Ẹ bá ìyá yín wí, ẹ bá a wí,
    nítorí pé kì í ṣe ìyàwó mi,
    Èmi náà kì í sì í ṣe ọkọ rẹ̀.
Jẹ́ kí ó yọ àgbèrè rẹ̀ kúrò lójú rẹ̀
    àti àìṣòótọ́ kúrò ní àyà rẹ̀.
Àìṣe bẹ́ẹ̀ èmi yóò tú u sí ìhòhò
    Èmi yóò sì gbé e kalẹ̀ bí ọjọ́ tí a bí i.
Èmi yóò ṣe ọ́ bí i aṣálẹ̀ ilẹ̀,
    Èmi yóò sì sọ ọ́ di ìyàngbẹ ilẹ̀
    Èmi yóò sì fi òǹgbẹ gbẹ ẹ́.
Èmi kò ní fi àánú mi hàn sí àwọn ọmọ rẹ̀
    nítorí ọmọ àgbèrè ni wọ́n jẹ́
Nítorí ìyá wọn ti hùwà àgbèrè,
    ó sì lóyún wọn nínú ìtìjú.
Ó wí pé, ‘èmi ó tún tọ́ àwọn àyànfẹ́ mi lẹ́yìn,
    tó ń fún mi ní oúnjẹ àti omi,
    ní irun àgùntàn mi àti ọ̀gbọ̀ mi,
    òróró mi àti ohun mímu mi.’
Nítorí náà, èmi ó fi ẹ̀gún dì í lọ́nà
    Èmi ó mọ odi yí i ká kí ó má ba à rọ́nà lọ.
Yóò sáré lé àwọn olólùfẹ́ rẹ̀ ṣùgbọ́n kò ní bá wọn;
    Yóò wá wọn ṣùgbọ́n kò ní rí wọn.
Nígbà náà ni yóò sọ pé,
    ‘Èmi ó padà sí ọ̀dọ̀ ọkọ mi àkọ́kọ́
    nítorí pé ó dára fún mi nígbà náà ju ìsinsin yìí lọ.’
Nítorí pé kò tí ì mọ̀ pé èmi ni
    àti ẹni tó fún un ní ọkà,
ọtí wáìnì tuntun àti òróró
    ẹni tí ó fún un ní fàdákà àti wúrà lọ́pọ̀lọpọ̀ Èyí tí wọ́n lò fún Baali.

“Nítorí náà, èmi yóò mú ọkà mi kúrò nígbà tó bá pọ́n,
    èmi yóò sì mú wáìnì mi kúrò ní àsìkò rẹ̀.
Èmi yóò sì gba irun àgùntàn àti ọ̀gbọ̀ mi padà
    ti mo ti fi fún un láti bo ìhòhò rẹ̀.
10 Èmi yóò sì fi ìwà ìtìjú rẹ̀ hàn
    lójú àwọn olólùfẹ́ rẹ̀
    kò sí ẹni tí yóò gbà á sílẹ̀ lọ́wọ́ mi
11 Èmi yóò mú gbogbo ayọ̀ rẹ̀ wá sí òpin:
    àjọ̀dún ọdọọdún rẹ̀, oṣù tuntun rẹ̀,
    ọjọ́ ìsinmi, àti gbogbo àwọn àjọ̀dún tí a yàn.
12 Èmi yóò pa àjàrà àti igi ọ̀pọ̀tọ́ rẹ̀ run,
    èyí tí ó pè ní èrè rẹ̀ láti ọ̀dọ̀ àwọn olólùfẹ́ rẹ̀,
Èmi yóò sọ wọ́n di igbó,
    àwọn ẹranko búburú yóò sì jẹ́ wọn run.
13 Èmi yóò bẹ̀ ọjọ́ Baalimu wò ní ara rẹ̀
    nínú èyí tó ń fi tùràrí jóná fún Baali;
tí ó fi òrùka etí àti ohun ọ̀ṣọ́ rẹ̀, ṣe ara rẹ̀ lọ́ṣọ̀ọ́,
    tó sì tẹ̀lé àwọn olólùfẹ́ rẹ̀ lọ.
    Ṣùgbọ́n èmi ni òun gbàgbé,”
    ni Olúwa wí.

14 “Nítorí náà, èmi yóò tàn án
    Èmi ó sì mú u lọ sí ilẹ̀ aṣálẹ̀
    Èmi ó fi pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́ bá a sọ̀rọ̀
15 Níbẹ̀ ni èmi yóò ti dá ọgbà àjàrà rẹ̀ padà fún un,
    Èmi yóò fi Àfonífojì Akori ṣe ìlẹ̀kùn ìrètí fún un.
Yóò sì kọrin níbẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìgbà èwe rẹ̀
    gẹ́gẹ́ bí ìgbà tó kúrò ní Ejibiti.

16 “Yóò sì ṣe ní ọjọ́ náà,
    Ìwọ yóò pè mí ní ‘ọkọ mi’;
    Ìwọ kò sì ní pè mí ní ‘olúwa à mi mọ́,’
    ni Olúwa wí.
17 Èmi yóò mú orúkọ, àwọn òrìṣà Baali kúrò lẹ́nu rẹ̀;
    ìwọ kò sì ní rí orúkọ òrìṣà Baali pè mọ́
18 Ní ọjọ́ náà, èmi yóò ṣe májẹ̀mú
    fún wọn àti àwọn ẹranko igbó àti ẹyẹ ojú ọ̀run àti
    àwọn ẹ̀dá tí ń rìn lórí ilẹ̀.
Kí wọn má bà á bẹ̀rù ara wọn mọ́
    Ọfà, idà àti ogun jíjà ni èmi ó parun ní ilẹ̀ náà
    kí gbogbo ènìyàn bá a lè wà ní àìléwu.
19 Èmi yóò fẹ́ ọ fún ara mi títí láé.
    Èmi ó fẹ́ ọ ní ìwà òdodo àti
    òtítọ́, ní ìfẹ́ àti àánú.
20 Èmi yóò fẹ́ ọ fún ara mi ní òtítọ́
    ìwọ yóò sì mọ Olúwa.

21 “Èmi yóò sì dáhùn ní ọjọ́ náà”
    ni Olúwa wí.
“Èmi yóò dá àwọn ọ̀run lóhùn
    àwọn ọ̀run yóò sì dá ilẹ̀ lóhùn;
22 Ilẹ̀ náà yóò sì dá ọkà,
    wáìnì tuntun àti òróró lóhùn
    Gbogbo wọn ó sì dá Jesreeli lóhùn.
23 Èmi ó sì gbìn ín fún ara mi lórí ilẹ̀ náà
    Èmi yóò ṣàánú fún ẹni tí kò tì í ri ‘àánú Gbà.’
Èmi yóò sọ fún àwọn tí ‘Kì í ṣe ènìyàn mi pé,’
    ‘Ẹ̀yin ni ènìyàn mi’; àwọn náà yóò sì wí pé, ‘Ìwọ ni Ọlọ́run mi.’ ”

[a]“Say of your brothers, ‘My people,’ and of your sisters, ‘My loved one.’(A)

Israel Punished and Restored

“Rebuke your mother,(B) rebuke her,
    for she is not my wife,
    and I am not her husband.
Let her remove the adulterous(C) look from her face
    and the unfaithfulness from between her breasts.
Otherwise I will strip(D) her naked
    and make her as bare as on the day she was born;(E)
I will make her like a desert,(F)
    turn her into a parched land,
    and slay her with thirst.
I will not show my love to her children,(G)
    because they are the children of adultery.(H)
Their mother has been unfaithful
    and has conceived them in disgrace.
She said, ‘I will go after my lovers,(I)
    who give me my food and my water,
    my wool and my linen, my olive oil and my drink.’(J)
Therefore I will block her path with thornbushes;
    I will wall her in so that she cannot find her way.(K)
She will chase after her lovers but not catch them;
    she will look for them but not find them.(L)
Then she will say,
    ‘I will go back to my husband(M) as at first,(N)
    for then I was better off(O) than now.’
She has not acknowledged(P) that I was the one
    who gave her the grain, the new wine and oil,(Q)
who lavished on her the silver and gold(R)
    which they used for Baal.(S)

“Therefore I will take away my grain(T) when it ripens,
    and my new wine(U) when it is ready.
I will take back my wool and my linen,
    intended to cover her naked body.
10 So now I will expose(V) her lewdness
    before the eyes of her lovers;(W)
    no one will take her out of my hands.(X)
11 I will stop(Y) all her celebrations:(Z)
    her yearly festivals, her New Moons,
    her Sabbath days—all her appointed festivals.(AA)
12 I will ruin her vines(AB) and her fig trees,(AC)
    which she said were her pay from her lovers;(AD)
I will make them a thicket,(AE)
    and wild animals will devour them.(AF)
13 I will punish her for the days
    she burned incense(AG) to the Baals;(AH)
she decked herself with rings and jewelry,(AI)
    and went after her lovers,(AJ)
    but me she forgot,(AK)
declares the Lord.(AL)

14 “Therefore I am now going to allure her;
    I will lead her into the wilderness(AM)
    and speak tenderly to her.
15 There I will give her back her vineyards,
    and will make the Valley of Achor[b](AN) a door of hope.
There she will respond[c](AO) as in the days of her youth,(AP)
    as in the day she came up out of Egypt.(AQ)

16 “In that day,” declares the Lord,
    “you will call me ‘my husband’;(AR)
    you will no longer call me ‘my master.[d]
17 I will remove the names of the Baals from her lips;(AS)
    no longer will their names be invoked.(AT)
18 In that day I will make a covenant for them
    with the beasts of the field, the birds in the sky
    and the creatures that move along the ground.(AU)
Bow and sword and battle
    I will abolish(AV) from the land,
    so that all may lie down in safety.(AW)
19 I will betroth(AX) you to me forever;
    I will betroth you in[e] righteousness and justice,(AY)
    in[f] love and compassion.(AZ)
20 I will betroth you in[g] faithfulness,
    and you will acknowledge(BA) the Lord.(BB)

21 “In that day I will respond,”
    declares the Lord
“I will respond(BC) to the skies,
    and they will respond to the earth;
22 and the earth will respond to the grain,
    the new wine and the olive oil,(BD)
    and they will respond to Jezreel.[h](BE)
23 I will plant(BF) her for myself in the land;
    I will show my love to the one I called ‘Not my loved one.[i](BG)
I will say to those called ‘Not my people,[j]’ ‘You are my people’;(BH)
    and they will say, ‘You are my God.(BI)’”

Footnotes

  1. Hosea 2:1 In Hebrew texts 2:1-23 is numbered 2:3-25.
  2. Hosea 2:15 Achor means trouble.
  3. Hosea 2:15 Or sing
  4. Hosea 2:16 Hebrew baal
  5. Hosea 2:19 Or with
  6. Hosea 2:19 Or with
  7. Hosea 2:20 Or with
  8. Hosea 2:22 Jezreel means God plants.
  9. Hosea 2:23 Hebrew Lo-Ruhamah (see 1:6)
  10. Hosea 2:23 Hebrew Lo-Ammi (see 1:9)