Add parallel Print Page Options

Ìbínú Olúwa sí Israẹli

13 Nígbà ti Efraimu bá ń sọ̀rọ̀, àwọn ènìyàn máa ń wárìrì,
    a gbé e ga ní Israẹli
    ṣùgbọ́n ó jẹ̀bi ẹ̀sùn pé ó ń sin òrìṣà Baali, ó sì kú.
Báyìí, wọ́n ń dá ẹ̀ṣẹ̀ kún ẹ̀ṣẹ̀
    wọn fi fàdákà ṣe ère òrìṣà fúnrawọn
ère tí a fi ọgbọ́n dá àrà sí
    gbogbo wọn jẹ́ iṣẹ́ ọwọ́ oníṣọ̀nà
Wọn ń sọ nípa àwọn ènìyàn
    wọ̀nyí. Pé, Jẹ́ kí àwọn
    “Ènìyàn tí ń rú ẹbọ fi ẹnu
    ko àwọn ẹgbọrọ màlúù ni ẹnu.”
Nítorí náà wọn yóò dàbí ìkùùkuu òwúrọ̀,
    bí ìrì òwúrọ̀ kùtùkùtù tó máa ń parẹ́,
    bí i èèpo ìyẹ̀fun tí afẹ́fẹ́ gbé láti ibi ìpakà
    bí èéfín tó rú jáde gba ojú fèrèsé.

“Ṣùgbọ́n Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ̀,
    ẹni tó mú ọ jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá.
Ìwọ̀ kì yóò sì mọ ọlọ́run mìíràn àfi èmi
    kò sí olùgbàlà mìíràn lẹ́yìn mi
Mo ṣe ìtọ́jú rẹ ní aginjù
    ní ilẹ̀ tí ó gbẹ tí kò ní omi
Wọn ni ìtẹ́lọ́rùn nígbà tí mo fún wọn ní oúnjẹ
    Nígbà tí wọ́n ní ìtẹ́lọ́rùn tan wọ́n di agbéraga
    Nígbà náà ni wọ́n sì gbàgbé mi.
Nítorí náà, Èmi yóò dìde sí wọn bí i kìnnìún
    Èmi yóò fi ara pamọ́ dè wọ́n lọ́nà bí i ẹkùn.
Beari igbó tí a já ọmọ rẹ̀ gbà
    Èmi yóò bá wọn jà bí?
Èmi yóò sì fà wọ́n ya
    bí ìgbà tí ẹkùn bá fa ara wọn ya
    bi ẹranko búburú ni èmi yóò fa wọn ya.

“A ti pa ọ́ run, ìwọ Israẹli
    nítorí pé ìwọ lòdì sí mi, ìwọ lòdì sí olùrànlọ́wọ́ rẹ.
10 Níbo ni ọba rẹ gbé wà nísinsin yìí kí ó bá à le gbà ọ là?
    Níbo ni àwọn olórí ìlú yín wà,
àwọn tí ẹ sọ pé,
    ‘Fún wa ní ọba àti ọmọ-aládé’?
11 Nítorí èyí nínú ìbínú mi ni mo fún un yín ní ọba,
    Nínú ìbínú gbígbóná mi, mo sì mú un kúrò.
12 Ẹ̀bi Efraimu ni a tí ko jọ
    gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ wà nínú àkọsílẹ̀
13 Ìrora bí obìnrin tó fẹ́ bímọ ti dé bá a
    Ṣùgbọ́n ó jẹ́ ọmọ tí kò lọ́gbọ́n
Nígbà tí àsìkò tó,
    ó kọ̀ láti jáde síta láti inú.

14 “Èmi yóò rà wọ́n padà kúrò lọ́wọ́ agbára isà òkú.
    Èmi yóò rà wọ́n padà lọ́wọ́ ikú
Ikú, àjàkálẹ̀-ààrùn rẹ dà?
    Isà òkú, ìparun rẹ dà?

“Èmi kò ní ṣàánú mọ́.
15     Bí ó tilẹ̀ gbilẹ̀ láàrín àwọn arákùnrin rẹ̀
afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn láti ọ̀dọ̀ Olúwa yóò wá,
    Yóò fẹ́ wá láti inú aginjù
orísun omi rẹ̀ yóò gbẹ
    kànga rẹ̀ yóò gbẹ
pẹ̀lú olè yóò fọ́ ilé ẹrù
    àti gbogbo ilé ìṣúra rẹ̀
16 Ará Samaria gbọdọ̀ ru ẹ̀bi wọn,
    nítorí pé wọ́n ti ṣọ̀tẹ̀ sí Ọlọ́run wọn.
Wọn ó ti ipa idà ṣubú;
    a ó fọ́ àwọn ọmọ wọn mọ́lẹ̀,
    A ó sì la àwọn aboyún wọn nínú.”

The Lord’s Anger Against Israel

13 When Ephraim spoke, people trembled;(A)
    he was exalted(B) in Israel.
    But he became guilty of Baal worship(C) and died.
Now they sin more and more;
    they make(D) idols for themselves from their silver,(E)
cleverly fashioned images,
    all of them the work of craftsmen.(F)
It is said of these people,
    “They offer human sacrifices!
    They kiss[a](G) calf-idols!(H)
Therefore they will be like the morning mist,
    like the early dew that disappears,(I)
    like chaff(J) swirling from a threshing floor,(K)
    like smoke(L) escaping through a window.

“But I have been the Lord your God
    ever since you came out of Egypt.(M)
You shall acknowledge(N) no God but me,(O)
    no Savior(P) except me.
I cared for you in the wilderness,(Q)
    in the land of burning heat.
When I fed them, they were satisfied;
    when they were satisfied, they became proud;(R)
    then they forgot(S) me.(T)
So I will be like a lion(U) to them,
    like a leopard I will lurk by the path.
Like a bear robbed of her cubs,(V)
    I will attack them and rip them open;
like a lion(W) I will devour them—
    a wild animal will tear them apart.(X)

“You are destroyed, Israel,
    because you are against me,(Y) against your helper.(Z)
10 Where is your king,(AA) that he may save you?
    Where are your rulers in all your towns,
of whom you said,
    ‘Give me a king and princes’?(AB)
11 So in my anger I gave you a king,(AC)
    and in my wrath I took him away.(AD)
12 The guilt of Ephraim is stored up,
    his sins are kept on record.(AE)
13 Pains as of a woman in childbirth(AF) come to him,
    but he is a child without wisdom;
when the time(AG) arrives,
    he doesn’t have the sense to come out of the womb.(AH)

14 “I will deliver this people from the power of the grave;(AI)
    I will redeem them from death.(AJ)
Where, O death, are your plagues?
    Where, O grave, is your destruction?(AK)

“I will have no compassion,
15     even though he thrives(AL) among his brothers.
An east wind(AM) from the Lord will come,
    blowing in from the desert;
his spring will fail
    and his well dry up.(AN)
His storehouse will be plundered(AO)
    of all its treasures.
16 The people of Samaria(AP) must bear their guilt,(AQ)
    because they have rebelled(AR) against their God.
They will fall by the sword;(AS)
    their little ones will be dashed(AT) to the ground,
    their pregnant women(AU) ripped open.”[b]

Footnotes

  1. Hosea 13:2 Or “Men who sacrifice / kiss
  2. Hosea 13:16 In Hebrew texts this verse (13:16) is numbered 14:1.