Add parallel Print Page Options

Jesu pọ̀ ju Mose lọ

Nítorí náà ẹ̀yin ará mímọ́, alábápín ìpè ọ̀run, ẹ gba ti aposteli àti olórí àlùfáà ìjẹ́wọ́ wa rò, àní Jesu; (A)Ẹni tí o ṣe olóòtítọ́ si ẹni tí ó yàn án, bí Mose pẹ̀lú tí ṣe olóòtítọ́ nínú iṣẹ́ rẹ̀ gbogbo nínú ilé Ọlọ́run. Nítorí a ka ọkùnrin yìí ni yíyẹ sí ògo ju Mose lọ níwọ̀n bí ẹni tí ó kọ́ ilé ti lọ́lá ju ilé lọ. Láti ọwọ́ ènìyàn kan ni a sá à ti kọ́ olúkúlùkù ilé; ṣùgbọ́n ẹni tí ó kọ́ ohun gbogbo ni Ọlọ́run. (B)Mose nítòótọ́ sì ṣe olóòtítọ́ nínú gbogbo iṣẹ́ rẹ̀ nínú ilé Ọlọ́run, bí ìránṣẹ́, fún ẹ̀rí ohun tí a ó sọ̀rọ̀ wọ́n ní ìgbà ìkẹyìn. Ṣùgbọ́n Kristi jẹ́ olóòtítọ́ gẹ́gẹ́ bí ọmọ lórí ilé Ọlọ́run; ilé ẹni tí àwa jẹ́, bí àwa bá gbẹ́kẹ̀lé e, tí a sì di ìṣògo ìrètí wa mu ṣinṣin títí dé òpin.

Ìkìlọ̀ fún aláìgbàgbọ́

(C)Nítorí náà gẹ́gẹ́ bi Ẹ̀mí Mímọ́ tí wí:

“Lónìí bí ẹ̀yin bá gbọ́ ohùn rẹ̀,
    Ẹ má ṣe sé ọkàn yín le,
bí ìgbà ìṣọ̀tẹ̀,
    bí i ní ọjọ́ ìdánwò ní aginjù:
Níbi tí àwọn baba yín ti dán mi wò,
    tí wọ́n sì rí iṣẹ́ mi ní ogójì ọdún.
10 Nítorí náà a mú inú bí mi si ìran náà,
    mo sì wí pé, ‘Nígbà gbogbo ni wọn ṣìnà ní ọkàn wọn;
    wọn kò sì mọ ọ̀nà mi.’
11 Bí mo tí búra nínú ìbínú mi,
    ‘wọn kí yóò wọ inú ìsinmi mi.’ ”

12 Ẹ kíyèsára, ará, kí ọkàn búburú ti àìgbàgbọ́ má ṣe wà nínú ẹnikẹ́ni yín, ní lílọ kúrò lọ́dọ̀ Ọlọ́run alààyè. 13 Ṣùgbọ́n ẹ máa gba ara yín ní ìyànjú ní ojoojúmọ́, níwọ̀n ìgbà tí a bá ń pè ní “Òní,” kí a má ba à sé ọkàn ẹnikẹ́ni nínú yín le nípa ẹ̀tàn ẹ̀ṣẹ̀. 14 Nítorí àwa di alábápín pẹ̀lú Kristi, bí àwa bá di ìpilẹ̀ṣẹ̀ ìgbẹ́kẹ̀lé wa mú ṣinṣin títí dé òpin; 15 (D)Nígbà tí a ń wí pé:

“Lónìí bí ẹ̀yin bá gbọ́ ohùn rẹ̀,
    ẹ má sé ọkàn yin le,
bí ìgbà ìṣọ̀tẹ̀.”

16 (E)Àwọn ta ni ó gbọ́ tí ó sì tún ṣọ̀tẹ̀? Kì í ha ṣe gbogbo àwọn tí o jáde kúrò ní Ejibiti ní abẹ́ àkóso Mose? 17 (F)Àwọn ta ni ó sì bínú sí fún ogójì ọdún? Kì í ha ṣe sí àwọn tí ó dẹ́ṣẹ̀, òkú àwọn tí ó sùn ní aginjù? 18 Àwọn wo ni ó búra fún pé wọn kì yóò wọ inú ìsinmi òun, bí kò ṣe fún àwọn tí ó ṣe àìgbọ́ràn? 19 Àwa sì rí i pé wọn kò lè wọ inú rẹ̀ nítorí àìgbàgbọ́.

Jesus Greater Than Moses

Therefore, holy brothers and sisters,(A) who share in the heavenly calling,(B) fix your thoughts on Jesus, whom we acknowledge(C) as our apostle and high priest.(D) He was faithful to the one who appointed him, just as Moses was faithful in all God’s house.(E) Jesus has been found worthy of greater honor than Moses,(F) just as the builder of a house has greater honor than the house itself. For every house is built by someone, but God is the builder of everything.(G) “Moses was faithful as a servant(H) in all God’s house,”[a](I) bearing witness to what would be spoken by God in the future. But Christ is faithful as the Son(J) over God’s house. And we are his house,(K) if indeed we hold firmly(L) to our confidence and the hope(M) in which we glory.

Warning Against Unbelief

So, as the Holy Spirit says:(N)

“Today, if you hear his voice,
    do not harden your hearts(O)
as you did in the rebellion,
    during the time of testing in the wilderness,
where your ancestors tested and tried me,
    though for forty years they saw what I did.(P)
10 That is why I was angry with that generation;
    I said, ‘Their hearts are always going astray,
    and they have not known my ways.’
11 So I declared on oath in my anger,(Q)
    ‘They shall never enter my rest.’ (R)[b](S)

12 See to it, brothers and sisters, that none of you has a sinful, unbelieving heart that turns away from the living God.(T) 13 But encourage one another daily,(U) as long as it is called “Today,” so that none of you may be hardened by sin’s deceitfulness.(V) 14 We have come to share in Christ, if indeed we hold(W) our original conviction firmly to the very end.(X) 15 As has just been said:

“Today, if you hear his voice,
    do not harden your hearts
    as you did in the rebellion.”[c](Y)

16 Who were they who heard and rebelled? Were they not all those Moses led out of Egypt?(Z) 17 And with whom was he angry for forty years? Was it not with those who sinned, whose bodies perished in the wilderness?(AA) 18 And to whom did God swear that they would never enter his rest(AB) if not to those who disobeyed?(AC) 19 So we see that they were not able to enter, because of their unbelief.(AD)

Footnotes

  1. Hebrews 3:5 Num. 12:7
  2. Hebrews 3:11 Psalm 95:7-11
  3. Hebrews 3:15 Psalm 95:7,8