Add parallel Print Page Options

Jakọbu àti Esau pàdé

33 Jakọbu sì gbójú sókè, ó sì rí Esau àti irínwó ọkùnrin tí wọ́n ń bọ̀, ó sì pín àwọn ọmọ fún Lea, Rakeli àti àwọn ìránṣẹ́bìnrin méjèèjì. Ó sì ti àwọn ìránṣẹ́bìnrin àti àwọn ọmọ wọn síwájú, Lea àti àwọn ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọ̀wọ́ kejì tí ó tẹ̀lé wọn, Rakeli àti Josẹfu sì wà lẹ́yìn pátápátá. Jakọbu fúnrarẹ̀ wa lọ síwájú pátápátá, ó sì tẹríba ní ìgbà méje bí ó ti ń súnmọ́ Esau, arákùnrin rẹ̀.

Ṣùgbọ́n Esau sáré pàdé Jakọbu, ó sì dì mọ́ ọn, ó rọ̀ mọ́ ọn lọ́rùn, ó sì fẹnukò ó lẹ́nu. Àwọn méjèèjì sì sọkún. Nígbà tí Esau sì ṣe àkíyèsí àwọn ìyàwó àti ọmọ Jakọbu, ó béèrè lọ́wọ́ Jakọbu pé, “Ti ta ni àwọn wọ̀nyí?”

Jakọbu sì fèsì wí pé, “Èyí ni àwọn ọmọ tí Ọlọ́run nínú àánú rẹ̀ ti fi fún ìránṣẹ́ rẹ.”

Nígbà náà ni àwọn ìránṣẹ́bìnrin àti àwọn ọmọ wọn súnmọ́ tòsí, wọ́n sì tẹríba. Lẹ́yìn náà ni Lea àti àwọn ọmọ rẹ̀ pẹ̀lú dé, wọ́n sì tún tẹríba. Ní ìkẹyìn ni Josẹfu àti Rakeli dé, wọ́n sì tún tẹríba pẹ̀lú.

Esau sì béèrè pé, “Kí ni èrò rẹ tí o fi to àwọn ọ̀wọ̀ọ̀wọ́ tí mo pàdé wọ̀nyí?”

Jakọbu dáhùn pé, “Kí n ba le rí ojúrere rẹ ni olúwa mi.”

Ṣùgbọ́n Esau wí pé, “Tèmi ti tó mi, pa èyí tí o ní mọ́ fún ara rẹ.”

10 Jakọbu bẹ̀ ẹ́ wí pé, “Rárá bẹ́ẹ̀ kọ́, bí ó bá ṣe pé, mo rí ojúrere rẹ, jọ̀wọ́ gba ọrẹ lọ́wọ́ mi. Bí mo ṣe rí ojú rẹ̀ yìí, ó dàbí wí pé mo rí ojú Ọlọ́run ni báyìí, tí inú rẹ̀ ti dùn sí mi. 11 Jọ̀wọ́ gba àwọn ohun tí mo mú wá wọ̀nyí lọ́wọ́ mi. Nítorí Ọlọ́run ti fi oore-ọ̀fẹ́ rẹ̀ hàn sí mi, gbogbo ohun tí mo fẹ́ sì ni mo ní.” Nígbà tí Jakọbu sì rọ̀ ọ́ pé Esau gbọdọ̀ gbà wọ́n, Esau sì gbà á.

12 Nígbà náà ni Esau wí pé, “Jẹ́ kí a máa lọ, n ó sìn ọ.”

13 Ṣùgbọ́n Jakọbu wí fún un pé, “Ṣe ìwọ náà ṣe àkíyèsí pé ọ̀pọ̀ nínú àwọn ọmọ wọ̀nyí kéré, àwọn màlúù àti àgùntàn pẹ̀lú sì ní àwọn ọmọ kéékèèkéé. Bí a bá dà wọ́n rìn jìnnà ju bí agbára wọn ṣe mọ lọ, wọ́n lè kú. 14 Èmi bẹ̀ ọ́, máa lọ síwájú ìránṣẹ́ rẹ, àwọn ó sì máa rọra bọ̀, títí èmi àti àwọn ọmọ yóò fi dé ọ̀dọ̀ olúwa mi ní Seiri.”

15 Esau wí pé, “Jẹ́ kí n fi díẹ̀ sílẹ̀ fún ọ nínú àwọn ọkùnrin mi nígbà náà.”

Jakọbu wí pé, “Èéṣe, àní kí n sá à rí ojúrere olúwa mi?”

16 Ní ọjọ́ náà gan an ni Esau padà lọ sí Seiri. 17 Jakọbu sì lọ sí Sukkoti, ó sì kọ́ ilé fún ara rẹ̀, ó sì ṣe ọgbà fún àwọn ẹran. Ìdí èyí ní a fi ń pe ibẹ̀ ní Sukkoti.

18 Lẹ́yìn ìgbà tí Jakọbu tí Padani-Aramu dé: Àlàáfíà ni Jakọbu dé ìlú Ṣekemu ní ilẹ̀ Kenaani, ó sì pàgọ́ sí itòsí ìlú náà. 19 (A)Ó sì ra ilẹ̀ kan tí ó pàgọ́ sí ni ọgọ́rùn-ún owó fàdákà lọ́wọ́ àwọn ọmọ Hamori tí í ṣe baba Ṣekemu. 20 Níbẹ̀ ni ó gbé tẹ́ pẹpẹ kan tí ó pè ní El Elohe Israẹli (Ọlọ́run Israẹli).

Jacob and Esau Meet

33 Now Jacob lifted his eyes and looked, and there, (A)Esau was coming, and with him were four hundred men. So he divided the children among Leah, Rachel, and the two maidservants. And he put the maidservants and their children in front, Leah and her children behind, and Rachel and Joseph last. Then he crossed over before them and (B)bowed himself to the ground seven times, until he came near to his brother.

(C)But Esau ran to meet him, and embraced him, (D)and fell on his neck and kissed him, and they wept. And he lifted his eyes and saw the women and children, and said, “Who are these with you?”

So he said, “The children (E)whom God has graciously given your servant.” Then the maidservants came near, they and their children, and bowed down. And Leah also came near with her children, and they bowed down. Afterward Joseph and Rachel came near, and they bowed down.

Then Esau said, “What do you mean by (F)all this company which I met?”

And he said, “These are (G)to find favor in the sight of my lord.”

But Esau said, “I have enough, my brother; keep what you have for yourself.”

10 And Jacob said, “No, please, if I have now found favor in your sight, then receive my present from my hand, inasmuch as I (H)have seen your face as though I had seen the face of God, and you were pleased with me. 11 Please, take (I)my blessing that is brought to you, because God has dealt (J)graciously with me, and because I have [a]enough.” (K)So he urged him, and he took it.

12 Then Esau said, “Let us take our journey; let us go, and I will go before you.”

13 But Jacob said to him, “My lord knows that the children are weak, and the flocks and herds which are nursing are with me. And if the men should drive them hard one day, all the flock will die. 14 Please let my lord go on ahead before his servant. I will lead on slowly at a pace which the livestock that go before me, and the children, [b]are able to endure, until I come to my lord (L)in Seir.”

15 And Esau said, “Now let me leave with you some of the people who are with me.”

But he said, “What need is there? (M)Let me find favor in the sight of my lord.” 16 So Esau returned that day on his way to Seir. 17 And Jacob journeyed to (N)Succoth, built himself a house, and made [c]booths for his livestock. Therefore the name of the place is called [d]Succoth.

Jacob Comes to Canaan

18 Then Jacob came [e]safely to (O)the city of (P)Shechem, which is in the land of Canaan, when he came from Padan Aram; and he pitched his tent before the city. 19 And (Q)he bought the parcel of [f]land, where he had pitched his tent, from the children of Hamor, Shechem’s father, for one hundred pieces of money. 20 Then he erected an altar there and called it (R)El[g] Elohe Israel.

Footnotes

  1. Genesis 33:11 Lit. all
  2. Genesis 33:14 can stand
  3. Genesis 33:17 shelters
  4. Genesis 33:17 Lit. Booths
  5. Genesis 33:18 Or to Shalem, a city of
  6. Genesis 33:19 Lit. the field
  7. Genesis 33:20 Lit. God, the God of Israel