Añadir traducción en paralelo Imprimir Opciones de la página

Ìgbàgbọ́ tàbí iṣẹ́ òfin

Ẹ̀yin aláìnírònú ará Galatia! Ta ní ha tàn yín jẹ, kí ẹ̀yin má ṣe gba òtítọ́ gbọ́? Ní ojú ẹni tí a fi Jesu Kristi hàn gbangba láàrín yín ni ẹni tí a kàn mọ́ àgbélébùú. Kìkì èyí ni mo fẹ́ béèrè lọ́wọ́ yín: Nípa iṣẹ́ òfin ni ẹ̀yin gba Ẹ̀mí bí, tàbí nípa ìgbọ́ràn pẹ̀lú ìgbàgbọ́? Báyìí ni ẹ̀yin ṣe jẹ òmùgọ̀ tó bí? Ẹ̀yin tí ó ti bẹ̀rẹ̀ ìgbé ayé ìgbàgbọ́ yín nípa ti Ẹ̀mí, ṣé a ti wá sọ yín di pípé nípa ti ara ni? Ẹ̀yin ha ti jìyà ọ̀pọ̀lọpọ̀ nǹkan wọ̀nyí lásán? Bí ó bá ṣe pé nítòótọ́ lásán ni. Ṣé Ọlọ́run fún yín ní Ẹ̀mí rẹ̀, tí ó sì ṣe iṣẹ́ ìyanu láàrín yín nítorí tí ẹ̀yin pa òfin mọ, tàbí nítorí ẹ ní ìgbàgbọ́ sí ohun tí ẹ gbọ́? (A)Gẹ́gẹ́ bí Abrahamu “Ó gba Ọlọ́run gbọ́, a sì kà á sí òdodo fún un.”

Ẹ jẹ́ kí ó yé é yín nígbà náà pé, àwọn ti ó gbàgbọ́, àwọn náà ní í ṣe ọmọ Abrahamu. (B)Bí ìwé mímọ́ sì tí wí tẹ́lẹ̀ pé, Ọlọ́run yóò dá aláìkọlà láre nípa ìgbàgbọ́, ó tí wàásù ìhìnrere ṣáájú fún Abrahamu, ó ń wí pé, “Nínú rẹ̀ ni a ó bùkún fún gbogbo orílẹ̀-èdè.” (C)Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni àwọn tí i ṣe tí ìgbàgbọ́ jẹ́ ẹni alábùkún fún pẹ̀lú Abrahamu olódodo.

10 (D)Nítorí pé iye àwọn tí ń bẹ ni ipa iṣẹ́ òfin ń bẹ lábẹ́ ègún: nítorí tí a tí kọ ọ́ pé, “Ìfibú ni olúkúlùkù ẹni tí kò dúró nínú ohun gbogbo tí a kọ sínú ìwé òfin láti máa ṣe wọ́n. 11 (E)Nítorí ó dánilójú pé, a kò dá ẹnikẹ́ni láre níwájú Ọlọ́run nípa iṣẹ́ òfin: nítorí pé, olódodo yóò yè nípa ìgbàgbọ́.” 12 (F)Òfin kì í sì í ṣe ti ìgbàgbọ́: ṣùgbọ́n “Ẹni tí ó ba ṣe, yóò yè nípa wọn.” 13 (G)Kristi ti rà wá padà kúrò lọ́wọ́ ègún òfin, ẹni tí a fi ṣe ègún fún wa: nítorí tí a ti kọ ọ́ pé, “Ìfibú ni olúkúlùkù ẹni tí a fi kọ́ sórí igi.” 14 Ó gbà wá là ki ìbùkún Abrahamu ba à lè wá sórí àwọn aláìkọlà nípa Kristi Jesu; kí àwa ba à lè gba ìlérí Ẹ̀mí nípa ìgbàgbọ́.

Òfin àti ìlérí

15 Ará, èmi ń sọ̀rọ̀ bí ènìyàn, gẹ́gẹ́ bi májẹ̀mú ènìyàn ti a ti fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀, kò sí ẹni tí ó lè sọ ọ́ di asán, tàbí tí ó lè fi kún un mọ́. 16 (H)Ǹjẹ́ fún Abrahamu àti fún irú-ọmọ rẹ̀ ni a ti ṣe àwọn ìlérí náà. Ìwé Mímọ́ kò ṣe wí pé, Fún àwọn irú-ọmọ rẹ̀, bí ẹni pé ọ̀pọ̀lọpọ̀; ṣùgbọ́n bí ẹni pé ọ̀kan ṣoṣo, àti fún irú-ọmọ rẹ̀, èyí tí í ṣe Kristi. 17 (I)Èyí tí mò ń wí ni pé: májẹ̀mú tí Ọlọ́run ti fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ níṣàájú, òfin ti ó dé lẹ́yìn ọgbọ̀n-lé-nírinwó ọdún kò lè sọ ọ́ di asán, kí ó sì mú ìlérí náà di aláìlágbára. 18 (J)Nítorí bí ogún náà bá dúró lórí ṣíṣe gẹ́gẹ́ bí í òfin kì í ṣe ti ìlérí mọ́: ṣùgbọ́n Ọlọ́run ti fi í fún Abrahamu nípa ìlérí.

19 (K)Ǹjẹ́ kí ha ni òfin? A fi kún un nítorí ìrékọjá títí irú-ọmọ tí a ti ṣe ìlérí fún yóò fi dé; a sì tipasẹ̀ àwọn angẹli ṣe ìlànà rẹ̀ láti ọwọ́ alárinà kan wá. 20 Ǹjẹ́ onílàjà kì í ṣe alárinà ti ẹnìkan, ṣùgbọ́n ọ̀kan ni Ọlọ́run.

21 (L)Nítorí náà òfin ha lòdì sí àwọn ìlérí Ọlọ́run bí? Kí a má rí i; Nítorí ìbá ṣe pé a ti fi òfin kan fún ni tí ó lágbára láti sọ ni di ààyè nítòótọ́ òdodo ìbá ti tipasẹ̀ òfin wà. 22 (M)Ṣùgbọ́n ìwé mímọ́ ti fi yé wa pé gbogbo ènìyàn ni ń bẹ lábẹ́ ìdè ẹ̀ṣẹ̀, kí a lè fi ìlérí nípa ìgbàgbọ́ nínú Jesu Kristi fún àwọn tí ó gbàgbọ́.

23 Ṣùgbọ́n kí ìgbàgbọ́ tó dé, a ti pa wá mọ́ lábẹ́ òfin, a sì sé wa mọ́ de ìgbàgbọ́ tí a ń bọ̀ wá fihàn. 24 Nítorí náà òfin ti jẹ́ olùtọ́jú láti mú ènìyàn wá sọ́dọ̀ Kristi, kí a lè dá wa láre nípa ìgbàgbọ́. 25 Ṣùgbọ́n lẹ́yìn ìgbà tí ìgbàgbọ́ ti dé, àwa kò sí lábẹ́ olùtọ́jú mọ́.

Ọmọ Ọlọ́run

26 Nítorí pé ọmọ Ọlọ́run ni gbogbo yín, nípa ìgbàgbọ́ nínú Kristi Jesu. 27 Nítorí pé iye ẹ̀yin tí a ti bamitiisi sínú Kristi ti gbé Kristi wọ̀. 28 (N)Kò le sí Júù tàbí Giriki, ẹrú tàbí òmìnira, ọkùnrin tàbí obìnrin nítorí pé ọ̀kan ni nínú Kristi Jesu. 29 Bí ẹ̀yin bá sì jẹ́ ti Kristi, ǹjẹ́ ẹ̀yin ní irú-ọmọ Abrahamu, àti àrólé gẹ́gẹ́ bí ìlérí.

Faith or Works of the Law

You foolish(A) Galatians!(B) Who has bewitched you?(C) Before your very eyes Jesus Christ was clearly portrayed as crucified.(D) I would like to learn just one thing from you: Did you receive the Spirit(E) by the works of the law,(F) or by believing what you heard?(G) Are you so foolish? After beginning by means of the Spirit, are you now trying to finish by means of the flesh?[a] Have you experienced[b] so much in vain—if it really was in vain? So again I ask, does God give you his Spirit and work miracles(H) among you by the works of the law, or by your believing what you heard?(I) So also Abraham “believed God, and it was credited to him as righteousness.”[c](J)

Understand, then, that those who have faith(K) are children of Abraham.(L) Scripture foresaw that God would justify the Gentiles by faith, and announced the gospel in advance to Abraham: “All nations will be blessed through you.”[d](M) So those who rely on faith(N) are blessed along with Abraham, the man of faith.(O)

10 For all who rely on the works of the law(P) are under a curse,(Q) as it is written: “Cursed is everyone who does not continue to do everything written in the Book of the Law.”[e](R) 11 Clearly no one who relies on the law is justified before God,(S) because “the righteous will live by faith.”[f](T) 12 The law is not based on faith; on the contrary, it says, “The person who does these things will live by them.”[g](U) 13 Christ redeemed us from the curse of the law(V) by becoming a curse for us, for it is written: “Cursed is everyone who is hung on a pole.”[h](W) 14 He redeemed us in order that the blessing given to Abraham might come to the Gentiles through Christ Jesus,(X) so that by faith we might receive the promise of the Spirit.(Y)

The Law and the Promise

15 Brothers and sisters,(Z) let me take an example from everyday life. Just as no one can set aside or add to a human covenant that has been duly established, so it is in this case. 16 The promises were spoken to Abraham and to his seed.(AA) Scripture does not say “and to seeds,” meaning many people, but “and to your seed,”[i](AB) meaning one person, who is Christ. 17 What I mean is this: The law, introduced 430 years(AC) later, does not set aside the covenant previously established by God and thus do away with the promise. 18 For if the inheritance depends on the law, then it no longer depends on the promise;(AD) but God in his grace gave it to Abraham through a promise.

19 Why, then, was the law given at all? It was added because of transgressions(AE) until the Seed(AF) to whom the promise referred had come. The law was given through angels(AG) and entrusted to a mediator.(AH) 20 A mediator,(AI) however, implies more than one party; but God is one.

21 Is the law, therefore, opposed to the promises of God? Absolutely not!(AJ) For if a law had been given that could impart life, then righteousness would certainly have come by the law.(AK) 22 But Scripture has locked up everything under the control of sin,(AL) so that what was promised, being given through faith in Jesus Christ, might be given to those who believe.

Children of God

23 Before the coming of this faith,[j] we were held in custody(AM) under the law, locked up until the faith that was to come would be revealed.(AN) 24 So the law was our guardian until Christ came(AO) that we might be justified by faith.(AP) 25 Now that this faith has come, we are no longer under a guardian.(AQ)

26 So in Christ Jesus you are all children of God(AR) through faith, 27 for all of you who were baptized into Christ(AS) have clothed yourselves with Christ.(AT) 28 There is neither Jew nor Gentile, neither slave nor free,(AU) nor is there male and female,(AV) for you are all one in Christ Jesus.(AW) 29 If you belong to Christ,(AX) then you are Abraham’s seed,(AY) and heirs(AZ) according to the promise.(BA)

Notas al pie

  1. Galatians 3:3 In contexts like this, the Greek word for flesh (sarx) refers to the sinful state of human beings, often presented as a power in opposition to the Spirit.
  2. Galatians 3:4 Or suffered
  3. Galatians 3:6 Gen. 15:6
  4. Galatians 3:8 Gen. 12:3; 18:18; 22:18
  5. Galatians 3:10 Deut. 27:26
  6. Galatians 3:11 Hab. 2:4
  7. Galatians 3:12 Lev. 18:5
  8. Galatians 3:13 Deut. 21:23
  9. Galatians 3:16 Gen. 12:7; 13:15; 24:7
  10. Galatians 3:23 Or through the faithfulness of Jesus … 23 Before faith came