Add parallel Print Page Options

27 Ó sì súnmọ́ ọn, ó sì fẹnukò ó ní ẹnu. Nígbà tí Isaaki gbọ́ òórùn aṣọ rẹ̀, ó súre fún un ó wí pé:

“Wò ó òórùn ọmọ mi
    dàbí òórùn oko
    Olúwa ti bùkún.
28 Kí Ọlọ́run kí ó fún ọ nínú ìrì ọ̀run
    àti nínú ọ̀rá ilẹ̀
    àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọkà àti wáìnì tuntun.
29 Kí àwọn orílẹ̀-èdè kí ó máa sìn ọ́,
    kí àwọn ènìyàn sì máa tẹríba fún ọ,
máa ṣe olórí àwọn arákùnrin rẹ,
    kí àwọn iyèkan rẹ sì máa wólẹ̀ fún ọ
Fífibú ni àwọn ẹni tó fi ọ́ bú,
    Ìbùkún ni fún àwọn ẹni tí ó súre fún ọ.”

Read full chapter

39 Isaaki baba rẹ̀ sì dá a lóhùn pé,

“Ibùjókòó rẹ
    yóò jìnnà sí ọ̀rá ilẹ̀,
    àti sí ibi ìrì ọ̀run láti òkè wá.
40 Nípa idà rẹ ni ìwọ yóò máa gbé,
    ìwọ yóò sì máa sin àbúrò rẹ,
ṣùgbọ́n ní ìkẹyìn, nígbà tí ìwọ bá di alágbára
    ìwọ yóò já àjàgà rẹ̀
    kúrò lọ́rùn rẹ.”

Read full chapter