Add parallel Print Page Options

Ìparun Sodomu àti Gomorra

19 Ní àṣálẹ́, àwọn angẹli méjì sì wá sí ìlú Sodomu, Lọti sì jókòó ní ẹnu ibodè ìlú. Bí ó sì ti rí wọn, ó sì dìde láti pàdé wọn, ó kí wọn, ó sì foríbalẹ̀ fún wọn. Ó wí pé, “Ẹ̀yin olúwa mi, èmi bẹ̀ yín, ẹ yà sí ilé ìránṣẹ́ yín kí ẹ sì wẹ ẹsẹ̀ yín, kí n sì gbà yín lálejò, ẹ̀yin ó sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ láti máa bá ìrìnàjò yín lọ.”

Wọ́n sì wí pé, “Rárá o, àwa yóò dúró ní ìgboro ní òru òní.”

Ṣùgbọ́n Lọti rọ̀ wọ́n gidigidi tó bẹ́ẹ̀ tí wọ́n gbà láti bá a lọ sì ilé. Ó sì ṣe àsè fún wọn, ó sì dín àkàrà aláìwú fún wọ́n, wọ́n sì jẹ. Ṣùgbọ́n kí ó tó di pé wọ́n lọ sùn, àwọn ọkùnrin ìlú Sodomu tọmọdé tàgbà yí ilé náà ká. (A)Wọ́n pe Lọti pé, “Àwọn ọkùnrin tí ó wọ̀ sí ilé rẹ lálẹ́ yìí ńkọ́? Mú wọn jáde fún wa, kí a le ní ìbálòpọ̀ pẹ̀lú wọn.”

Lọti sì jáde láti pàdé wọn, ó sì ti ìlẹ̀kùn lẹ́yìn rẹ̀ bí ó ti jáde. Ó sì wí pé; “Rárá, ẹ̀yin ará mi, ẹ má ṣe ṣe ohun búburú yìí, kíyèsi i, mo ní ọmọbìnrin méjì tí kò mọ ọkùnrin rí, ẹ jẹ́ kí n mú wọn tọ̀ yín wá kí ẹ sì ṣe ohun tí ẹ fẹ́ pẹ̀lú wọn. Ṣùgbọ́n ẹ má ṣe ṣe àwọn ọkùnrin wọ̀nyí ní ibi kan nítorí wọ́n wá wọ̀ lábẹ́ ààbò ní ilé mi.”

Wọ́n sì wí fún pé, “Bì sẹ́yìn fún wa. Èyí yìí wá ṣe àtìpó láàrín wa, òun sì fẹ́ ṣe onídàájọ́! Aburú tí a ó fi ṣe ọ́ yóò pọ̀ ju tí wọn lọ.” Wọn rọ́ lu Lọti, wọ́n sì súnmọ́ ọn láti fọ́ ìlẹ̀kùn.

10 Ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin náà nawọ́ fa Lọti wọlé, wọ́n sì ti ìlẹ̀kùn. 11 (B)Wọ́n sì bu ìfọ́jú lu àwọn ọkùnrin tí ó wà ní ẹnu-ọ̀nà ilé náà, àti èwe àti àgbà: wọ́n kò sì rí ẹnu-ọ̀nà mọ́.

12 Àwọn ọkùnrin náà sì wí fún Lọti pé, “Ǹjẹ́ ó ní ẹlòmíràn ní ìlú yìí bí? Àna rẹ ọkùnrin, àwọn ọmọ rẹ lọ́kùnrin àti lóbìnrin, tàbí ẹnikẹ́ni tí ìwọ ní ní ìlú yìí, kó wọn jáde kúrò ní ibí yìí, 13 nítorí a ó pa ìlú yìí run, nítorí igbe iṣẹ́ búburú wọn ń dí púpọ̀ níwájú Olúwa, Olúwa sì rán wa láti pa á run.”

14 Nígbà náà ni Lọti jáde, ó sì wí fún àwọn àna rẹ̀ ọkùnrin tí ó ti bá jẹ́ ẹ̀jẹ́ láti fẹ́ àwọn ọmọ rẹ̀ pé, “Ẹ ṣe kánkán, kí ẹ jáde ní ìlú yìí, nítorí Olúwa fẹ́ pa ìlú yìí run!” Ṣùgbọ́n àwọn ọkọ ọmọ rẹ̀ wọ̀nyí rò pé àwàdà ló ń ṣe.

15 Ní àfẹ̀mọ́júmọ́, àwọn angẹli náà rọ Lọti pé, “Ṣe wéré, mú aya rẹ àti àwọn ọmọbìnrin rẹ méjèèjì tí ó wà níhìn-ín, àìṣe bẹ́ẹ̀, ìwọ yóò parun pẹ̀lú ìlú yìí nígbà tí wọ́n bá ń jìyà ẹ̀ṣẹ̀ wọn.”

16 (C)Nígbà tí ó ń jáfara, àwọn ọkùnrin náà nawọ́ mú un lọ́wọ́, wọ́n sì nawọ́ mú aya rẹ̀ náà lọ́wọ́ àti àwọn ọmọbìnrin rẹ̀ méjèèjì, wọ́n sì mú wọn jáde sẹ́yìn odi ìlú, nítorí Olúwa ṣàánú fún wọn. 17 Ní kété tí wọ́n mú wọn jáde sẹ́yìn odi tán, ọ̀kan nínú wọn wí pé, “Sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ! Má ṣe wo ẹ̀yìn rẹ, bẹ́ẹ̀ ni kí ìwọ kí ó má ṣe dúró ní gbogbo pẹ̀tẹ́lẹ̀! Sá àsálà lọ sí orí òkè, kí ìwọ ó má ba ṣègbé!”

18 Ṣùgbọ́n Lọti wí fún wọn pé, “Rárá, ẹ̀yin Olúwa mi, ẹ jọ̀wọ́! 19 Nígbà tí ìránṣẹ́ rẹ ti rí ojúrere rẹ, tí o sì ti fi àánú rẹ hàn nípa gbígba ẹ̀mí mi là, Èmi kò le è sálọ sórí òkè, kí búburú yìí má ba à lé mi bá, kí n sì kú. 20 Wò ó, ìlú kékeré kan nìyí ní tòsí láti sá sí: jẹ́ kí n sálọ síbẹ̀, ìlú kékeré ha kọ́? Ẹ̀mí mi yóò sì yè.”

21 Ó sì wí fún un pé, “Ó dára, mo gba ẹ̀bẹ̀ rẹ. Èmi kì yóò run ìlú náà tí ìwọ sọ̀rọ̀ rẹ̀. 22 Tètè! Sálọ síbẹ̀, nítorí èmi kò le ṣe ohun kan àyàfi tí ó bá dé ibẹ̀,” (ìdí nìyí tí a fi ń pe ìlú náà ní Soari).

23 Nígbà tí Lọti yóò fi dé ìlú Soari, oòrùn ti yọ. 24 (D)Nígbà náà ni Olúwa rọ̀jò iná àti Sulfuru (òkúta iná) sórí Sodomu àti Gomorra—láti ọ̀run lọ́dọ̀ Olúwa wá. 25 Báyìí ni ó run àwọn ìlú náà àti gbogbo ilẹ̀ pẹ̀tẹ́lẹ̀, pẹ̀lú gbogbo àwọn tí ó wà ní ìlú ńláńlá wọ̀n-ọn-nì àti ohun gbogbo tí ó hù jáde nílẹ̀. 26 (E)Ṣùgbọ́n aya Lọti bojú wo ẹ̀yìn, ó sì di ọ̀wọ́n iyọ̀.

27 Ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, Abrahamu sì dìde ó sì padà lọ sí ibi tí ó gbé dúró níwájú Olúwa. 28 (F)Ó sì wo ìhà Sodomu àti Gomorra àti àwọn ilẹ̀ pẹ̀tẹ́lẹ̀ wọ̀n-ọn-nì, ó sì rí èéfín tí ń ti ibẹ̀ jáde bí èéfín iná ìléru.

29 Ọlọ́run sì rántí Abrahamu, nígbà tí ó run ìlú pẹ̀tẹ́lẹ̀ wọ̀n-ọn-nì tan, ó sì mú Lọti jáde kúrò láàrín ìparun náà, tí ó kọlu ìlú tí Lọti ti gbé.

Lọti àti àwọn ọmọ rẹ̀ obìnrin

30 Lọti àti àwọn ọmọ rẹ̀ obìnrin méjèèjì sì kúrò ní Soari, wọ́n sì ń lọ gbé ní orí òkè ní inú ihò àpáta, nítorí ó bẹ̀rù láti gbé ní ìlú Soari. 31 Ní ọjọ́ kan, èyí ẹ̀gbọ́n sọ fún àbúrò rẹ̀ pé, “Baba wa ti dàgbà, kò sì sí ọkùnrin kankan ní agbègbè yìí tí ìbá bá wa lòpọ̀, bí ìṣe gbogbo ayé. 32 Wá, jẹ́ kí a mú baba wa mu ọtí yó, kí ó ba à le bá wa lòpọ̀, kí àwa kí ó lè bí ọmọ, kí ìran wa má ba à parẹ́.”

33 Ní òru ọjọ́ náà, wọ́n rọ baba wọn ní ọtí yó. Èyí ẹ̀gbọ́n sì wọlé tọ̀ ọ́, ó sì bá a lòpọ̀, baba wọn kò mọ̀ ìgbà tí ó sùn ti òun àti ìgbà tí ó dìde.

34 Ní ọjọ́ kejì èyí ẹ̀gbọ́n wí fún àbúrò rẹ̀ pé, “Ní àná mo sùn ti baba mi. Jẹ́ kí a tún wọlé tọ̀ ọ́, kí a lè ní irú-ọmọ láti ọ̀dọ̀ baba wa.” 35 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n tún fún baba wọn ní ọtí mu yó ni alẹ́ ọjọ́ náà, èyí àbúrò náà sì wọlé tọ̀ ọ́ lọ, ó sì bá a lòpọ̀, kò sì tún mọ ìgbà tí ó wọlé sùn ti òun tàbí ìgbà tí ó dìde.

36 Àwọn ọmọbìnrin Lọti méjèèjì sì lóyún fún baba wọn. 37 Èyí ẹ̀gbọ́n sì bí ọmọkùnrin, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Moabu. Òun ni baba ńlá àwọn ará Moabu lónìí. 38 Èyí àbúrò náà sì bí ọmọkùnrin, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Bene-Ami. Òun ni baba ńlá àwọn ará Ammoni lónìí.

Sodom’s Depravity

19 Now (A)the two angels came to Sodom in the evening, and (B)Lot was sitting in the gate of Sodom. When Lot saw them, he rose to meet them, and he bowed himself with his face toward the ground. And he said, “Here now, my lords, please (C)turn in to your servant’s house and spend the night, and (D)wash your feet; then you may rise early and go on your way.”

And they said, (E)“No, but we will spend the night in the open square.”

But he insisted strongly; so they turned in to him and entered his house. (F)Then he made them a feast, and baked (G)unleavened bread, and they ate.

Now before they lay down, the men of the city, the men of Sodom, both old and young, all the people from every quarter, surrounded the house. (H)And they called to Lot and said to him, “Where are the men who came to you tonight? (I)Bring them out to us that we (J)may know them carnally.

So (K)Lot went out to them through the doorway, shut the door behind him, and said, “Please, my brethren, do not do so wickedly! (L)See now, I have two daughters who have not known a man; please, let me bring them out to you, and you may do to them as you wish; only do nothing to these men, (M)since this is the reason they have come under the shadow of my roof.”

And they said, “Stand back!” Then they said, “This one (N)came in to [a]stay here, (O)and he keeps acting as a judge; now we will deal worse with you than with them.” So they pressed hard against the man Lot, and came near to break down the door. 10 But the men reached out their hands and pulled Lot into the house with them, and shut the door. 11 And they (P)struck the men who were at the doorway of the house with blindness, both small and great, so that they became weary trying to find the door.

Sodom and Gomorrah Destroyed(Q)

12 Then the men said to Lot, “Have you anyone else here? Son-in-law, your sons, your daughters, and whomever you have in the city—(R)take them out of this place! 13 For we will destroy this place, because the (S)outcry against them has grown great before the face of the Lord, and (T)the Lord has sent us to destroy it.”

14 So Lot went out and spoke to his sons-in-law, (U)who had married his daughters, and said, (V)“Get up, get out of this place; for the Lord will destroy this city!” (W)But to his sons-in-law he seemed to be joking.

15 When the morning dawned, the angels urged Lot to hurry, saying, (X)“Arise, take your wife and your two daughters who are here, lest you be consumed in the punishment of the city.” 16 And while he lingered, the men (Y)took hold of his hand, his wife’s hand, and the hands of his two daughters, the (Z)Lord being merciful to him, (AA)and they brought him out and set him outside the city. 17 So it came to pass, when they had brought them outside, that [b]he said, (AB)“Escape for your life! (AC)Do not look behind you nor stay anywhere in the plain. Escape (AD)to the mountains, lest you be [c]destroyed.”

18 Then Lot said to them, “Please, (AE)no, my lords! 19 Indeed now, your servant has found favor in your sight, and you have increased your mercy which you have shown me by saving my life; but I cannot escape to the mountains, lest some evil overtake me and I die. 20 See now, this city is near enough to flee to, and it is a little one; please let me escape there (is it not a little one?) and my soul shall live.”

21 And he said to him, “See, (AF)I have favored you concerning this thing also, in that I will not overthrow this city for which you have spoken. 22 Hurry, escape there. For (AG)I cannot do anything until you arrive there.”

Therefore (AH)the name of the city was called [d]Zoar.

23 The sun had risen upon the earth when Lot entered Zoar. 24 Then the Lord rained (AI)brimstone and (AJ)fire on Sodom and Gomorrah, from the Lord out of the heavens. 25 So He [e]overthrew those cities, all the plain, all the inhabitants of the cities, and (AK)what grew on the ground.

26 But his wife looked back behind him, and she became (AL)a pillar of salt.

27 And Abraham went early in the morning to the place where (AM)he had stood before the Lord. 28 Then he looked toward Sodom and Gomorrah, and toward all the land of the plain; and he saw, and behold, (AN)the smoke of the land which went up like the smoke of a furnace. 29 And it came to pass, when God destroyed the cities of the plain, that God (AO)remembered Abraham, and sent Lot out of the midst of the overthrow, when He overthrew the cities in which Lot had dwelt.

The Descendants of Lot

30 Then Lot went up out of Zoar and (AP)dwelt in the mountains, and his two daughters were with him; for he was afraid to dwell in Zoar. And he and his two daughters dwelt in a cave. 31 Now the firstborn said to the younger, “Our father is old, and there is no man on the earth (AQ)to come in to us as is the custom of all the earth. 32 Come, let us make our father drink wine, and we will lie with him, that we (AR)may preserve the [f]lineage of our father.” 33 So they made their father drink wine that night. And the firstborn went in and lay with her father, and he did not know when she lay down or when she arose.

34 It happened on the next day that the firstborn said to the younger, “Indeed I lay with my father last night; let us make him drink wine tonight also, and you go in and lie with him, that we may preserve the [g]lineage of our father.” 35 Then they made their father drink wine that night also. And the younger arose and lay with him, and he did not know when she lay down or when she arose.

36 Thus both the daughters of Lot were with child by their father. 37 The firstborn bore a son and called his name Moab; (AS)he is the father of the Moabites to this day. 38 And the younger, she also bore a son and called his name Ben-Ammi; (AT)he is the father of the people of Ammon to this day.

Footnotes

  1. Genesis 19:9 As a resident alien
  2. Genesis 19:17 LXX, Syr., Vg. they
  3. Genesis 19:17 Lit. swept away
  4. Genesis 19:22 Lit. Little or Insignificant
  5. Genesis 19:25 devastated
  6. Genesis 19:32 Lit. seed
  7. Genesis 19:34 Lit. seed