Add parallel Print Page Options

Ìsọtẹ́lẹ̀ sí àwọn òkè Israẹli

Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá wí pé: “Ọmọ ènìyàn, dojúkọ àwọn òkè Israẹli; kí o sì sọtẹ́lẹ̀ lòdì sí wọn wí pé: ‘Ẹ̀yin òkè Israẹli, ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Olódùmarè. Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí sí ẹ̀yin òkè ńlá àti àwọn òkè kéékèèkéé, sí àwọn odò ṣíṣàn àti sí Àfonífojì, èmi yóò mú idà wa sórí yín, èmí yóò sì pa ibi gíga yín run. Èmi yóò wó pẹpẹ yín lulẹ̀, èmi yóò sì fọ́ pẹpẹ tùràrí yín túútúú; èmi yóò sì pa àwọn ènìyàn yín síwájú àwọn òrìṣà wọn. Èmi yóò tẹ́ òkú àwọn ará Israẹli síwájú òrìṣà wọn, èmi yóò sì fọ́n egungun wọn yí pẹpẹ wọn ká. Gbogbo ibi tí ẹ ń gbé àti àwọn ibi gíga yín ni yóò di píparun, gbogbo pẹpẹ yín ni yóò di ahoro, àwọn òrìṣà yín yóò di fífọ́ túútúú, àwọn pẹpẹ tùràrí yín ni a ó gé lulẹ̀, gbogbo iṣẹ́ yín yóò parẹ́. Àwọn ènìyàn yín yóò ṣubú láàrín yín, ẹ ó sì mọ̀ pé Èmi ni Olúwa.

“ ‘Ṣùgbọ́n èmi yóò dá àwọn kan sí nítorí pé díẹ̀ nínú yín ni yóò bọ́ lọ́wọ́ idà, nígbà tí a bá fọ́n yín ká sí gbogbo ilẹ̀ àti orílẹ̀-èdè. Àwọn ti ó bọ́ nínú yin yóò sì rántí mi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè níbi tí wọn yóò dìwọ́n ní ìgbèkùn lọ, nítorí wọ́n yóò máa rántí mi bí wọ́n ti bà mí lọ́kàn jẹ́ nípa àgbèrè wọn, tí ó yà wọ́n kúrò lọ́dọ̀ mi àti nípa ojú wọn tí ó ṣàfẹ́rí àwọn òrìṣà. Wọn yóò sì ṣú ara wọn nítorí ìwà ibi tí wọ́n ti hù nípa gbogbo ìríra wọn. 10 Wọn yóò sì mọ̀ pé Èmi ni Olúwa; àti pé kì í ṣe lásán ni mo ń lérí pé èmi yóò mú ìdààmú bá wọn.

11 “ ‘Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Pàtẹ́wọ́ kí o tún fẹsẹ̀ janlẹ̀, kí o wá kígbe síta pé, “Ó ṣe!” Ilé Israẹli yóò ṣubú nípa idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn nítorí gbogbo ìwà ìríra búburú tí wọ́n hù. Wọn yóò ṣubú nípa idà àti ìyàn. 12 Ẹni tó wà lókèèrè yóò kú pẹ̀lú àjàkálẹ̀-ààrùn, àti ẹni tó wà nítòsí yóò ṣubú pẹ̀lú idà, ìyàn ni yóò pa ẹni tó bá ṣẹ́kù sílẹ̀. Báyìí ni èmi yóò ṣe mú ìbínú gbígbóná mi wá sórí wọn. 13 Wọn yóò sì mọ̀ pé Èmi ni Olúwa, nígbà tí òkú àwọn ènìyàn wọn bá wà níbẹ̀ láàrín òrìṣà wọn yí pẹpẹ wọn ká, lórí àwọn òkè gíga gbogbo, àti lórí góńgó òkè àti lábẹ́ igi tútù àti lábẹ́ igi óákù, níbi tí wọ́n ti ń fi tùràrí olóòórùn dídùn rú ẹbọ sí gbogbo òrìṣà wọn. 14 Èmi yóò na ọwọ́ mi jáde sí wọn láti mú kí ilẹ̀ náà ṣòfò, kí ó sì dahoro dé aṣálẹ̀ ìhà Dibila—ní gbogbo ibùgbé wọn. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé Èmi ni Olúwa.’ ”

Doom for the Mountains of Israel

The word of the Lord came to me: “Son of man, set your face(A) against the mountains(B) of Israel; prophesy against them(C) and say: ‘You mountains of Israel, hear the word of the Sovereign Lord. This is what the Sovereign Lord says to the mountains and hills, to the ravines and valleys:(D) I am about to bring a sword against you, and I will destroy your high places.(E) Your altars will be demolished and your incense altars(F) will be smashed; and I will slay your people in front of your idols.(G) I will lay the dead bodies of the Israelites in front of their idols, and I will scatter your bones(H) around your altars.(I) Wherever you live,(J) the towns will be laid waste and the high places(K) demolished, so that your altars will be laid waste and devastated, your idols(L) smashed and ruined, your incense altars(M) broken down, and what you have made wiped out.(N) Your people will fall slain(O) among you, and you will know that I am the Lord.(P)

“‘But I will spare some, for some of you will escape(Q) the sword when you are scattered among the lands and nations.(R) Then in the nations where they have been carried captive, those who escape will remember(S) me—how I have been grieved(T) by their adulterous hearts, which have turned away from me, and by their eyes, which have lusted after their idols.(U) They will loathe themselves for the evil(V) they have done and for all their detestable practices.(W) 10 And they will know that I am the Lord;(X) I did not threaten in vain to bring this calamity on them.(Y)

11 “‘This is what the Sovereign Lord says: Strike your hands together and stamp your feet and cry out “Alas!” because of all the wicked and detestable practices of the people of Israel, for they will fall by the sword, famine and plague.(Z) 12 One who is far away will die of the plague, and one who is near will fall by the sword, and anyone who survives and is spared will die of famine. So will I pour out my wrath(AA) on them.(AB) 13 And they will know that I am the Lord, when their people lie slain among their idols(AC) around their altars, on every high hill and on all the mountaintops, under every spreading tree and every leafy oak(AD)—places where they offered fragrant incense to all their idols.(AE) 14 And I will stretch out my hand(AF) against them and make the land a desolate waste from the desert to Diblah[a]—wherever they live. Then they will know that I am the Lord.(AG)’”

Footnotes

  1. Ezekiel 6:14 Most Hebrew manuscripts; a few Hebrew manuscripts Riblah