Add parallel Print Page Options

Àsọtẹ́lẹ̀ òdì sí Ammoni

25 (A)Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé: “Ọmọ ènìyàn, kọ ojú rẹ sí àwọn ará Ammoni kí ó sì sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí wọn. Sì wí fún àwọn ará Ammoni pé, ‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Olódùmarè tí ó wí pé: Nítorí tí ìwọ wí pé, “Á hà!” Sí ibi mímọ́ mi nígbà tí ó di àìlọ́wọ̀ àti sí orí ilẹ̀ Israẹli nígbà tí ó di ahoro; àti sí ilẹ̀ Juda, nígbà tí wọ́n lọ sí ìgbèkùn, kíyèsi i, nítorí náà ni èmi yóò fi fi ọ lé àwọn ènìyàn ìlà-oòrùn lọ́wọ́ ni ohun ìní. Wọn yóò sì gbé ààfin wọn kalẹ̀ nínú rẹ, wọn yóò sì gbé ibùgbé wọn nínú rẹ: wọn yóò jẹ èso rẹ, wọn yóò sì mu wàrà rẹ. Èmi yóò sì sọ Rabba di ibùjẹ, fún àwọn ìbákasẹ àti àwọn ọmọ Ammoni di ibùsùn fún agbo ẹran. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé Èmi ni Olúwa. Nítorí báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Nítorí pé ìwọ pàtẹ́wọ́, ìwọ sì jan ẹsẹ̀ mọ́lẹ̀, tí ìwọ ń yọ̀ pẹ̀lú gbogbo àrankàn rẹ sí ilẹ̀ Israẹli nítorí náà, èmi yóò na ọwọ́ mi lé ọ, èmi yóò sì fi ọ fún àwọn aláìkọlà fún ìkógun. Èmi yóò sì gé ọ kúrò láàrín àwọn ènìyàn, èmi yóò sì jẹ́ kí o parun kúrò ni ilẹ̀ gbogbo. Èmi yóò sì pa ọ́ run, ìwọ yóò sì mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’ ”

Àsọtẹ́lẹ̀ òdì sí Moabu

(B)“Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: ‘Nítorí pé Moabu àti Seiri sọ wí pé, “Wò ó, ilé Juda ti dàbí gbogbo àwọn kèfèrí,” nítorí náà Èmi yóò ṣí Moabu sílẹ̀ láti àwọn ìlú gbogbo tí ó wà ní ààlà rẹ̀, ògo ilẹ̀ náà, Beti-Jeṣimoti, Baali-Meoni àti Kiriataimu. 10 Èmi yóò fi Moabu pẹ̀lú àwọn ará Ammoni lé àwọn ènìyàn ìlà-oòrùn ní ìní, kí a má bà á lè rántí àwọn ará Ammoni láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo; 11 Èmi yóò sì mú ìdájọ́ sẹ sí Moabu lára, wọn yóò sì mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’ ”

Àsọtẹ́lẹ̀ òdì sí Edomu

12 (C)“Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí pé: ‘Nítorí pé Edomu gbẹ̀san lára ilé Juda, ó sì jẹ̀bi gidigidi nípa ṣíṣe bẹ́ẹ̀, 13 nítorí náà báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí pé: Èmi yóò na ọwọ́ mi sórí Edomu èmi yóò sì pa àwọn ènìyàn àti àwọn ẹranko rẹ̀. Èmi yóò fi ṣófo láti Temani dé Dedani yóò ti ipa idà ṣubú. 14 Èmi yóò gbẹ̀san lára Edomu láti ọwọ́ àwọn ènìyàn mi Israẹli, wọn sì ṣe sí Edomu gẹ́gẹ́ bí ìbínú àti ìrunú mi: wọn yóò mọ̀ ìgbẹ̀san mi ní Olúwa Olódùmarè wí.’ ”

Àsọtẹ́lẹ̀ òdì sí Filistia

15 (D)“Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí pé: ‘Nítorí tí àwọn ará Filistini hùwà ẹ̀san tí wọ́n sì gbẹ̀san pẹ̀lú odì ní ọkàn wọn, àti pẹ̀lú ìkórìíra gbangba àtijọ́ ní wíwá ọ̀nà láti pa Juda run, 16 nítorí náà báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí pé: Èmi ti ṣetán láti na ọwọ́ mi jáde sí àwọn ará Filistini, èmi yóò sì ké àwọn ará Kereti kúrò, èmi yóò sì pa àwọn tí ó kù ní etí kún run. 17 Èmi yóò sì gbẹ̀san ńlá lára wọn nípa ìbáwí gbígbóná; wọn yóò sì mọ̀ wí pé, Èmi ni Olúwa. Nígbà tí èmi yóò gba ẹ̀san lára wọn.’ ”

A Prophecy Against Ammon

25 The word of the Lord came to me: “Son of man, set your face against(A) the Ammonites(B) and prophesy against them.(C) Say to them, ‘Hear the word of the Sovereign Lord. This is what the Sovereign Lord says: Because you said “Aha!(D)” over my sanctuary when it was desecrated(E) and over the land of Israel when it was laid waste and over the people of Judah when they went into exile,(F) therefore I am going to give you to the people of the East(G) as a possession. They will set up their camps(H) and pitch their tents among you; they will eat your fruit and drink your milk.(I) I will turn Rabbah(J) into a pasture for camels and Ammon into a resting place for sheep.(K) Then you will know that I am the Lord. For this is what the Sovereign Lord says: Because you have clapped your hands(L) and stamped your feet, rejoicing with all the malice of your heart against the land of Israel,(M) therefore I will stretch out my hand(N) against you and give you as plunder(O) to the nations. I will wipe you out from among the nations and exterminate you from the countries. I will destroy(P) you, and you will know that I am the Lord.(Q)’”

A Prophecy Against Moab

“This is what the Sovereign Lord says: ‘Because Moab(R) and Seir(S) said, “Look, Judah has become like all the other nations,” therefore I will expose the flank of Moab, beginning at its frontier towns—Beth Jeshimoth(T), Baal Meon(U) and Kiriathaim(V)—the glory of that land. 10 I will give Moab along with the Ammonites to the people of the East as a possession, so that the Ammonites will not be remembered(W) among the nations; 11 and I will inflict punishment on Moab. Then they will know that I am the Lord.’”(X)

A Prophecy Against Edom

12 “This is what the Sovereign Lord says: ‘Because Edom(Y) took revenge on Judah and became very guilty by doing so, 13 therefore this is what the Sovereign Lord says: I will stretch out my hand(Z) against Edom and kill both man and beast.(AA) I will lay it waste, and from Teman(AB) to Dedan(AC) they will fall by the sword.(AD) 14 I will take vengeance on Edom by the hand of my people Israel, and they will deal with Edom in accordance with my anger(AE) and my wrath; they will know my vengeance, declares the Sovereign Lord.’”(AF)

A Prophecy Against Philistia

15 “This is what the Sovereign Lord says: ‘Because the Philistines(AG) acted in vengeance and took revenge with malice(AH) in their hearts, and with ancient hostility sought to destroy Judah, 16 therefore this is what the Sovereign Lord says: I am about to stretch out my hand against the Philistines,(AI) and I will wipe out the Kerethites(AJ) and destroy those remaining along the coast.(AK) 17 I will carry out great vengeance(AL) on them and punish(AM) them in my wrath. Then they will know that I am the Lord,(AN) when I take vengeance on them.(AO)’”