Add parallel Print Page Options

Arábìnrin panṣágà méjì

23 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá: “Ọmọ ènìyàn, obìnrin méjì wà, ọmọ ìyá kan náà. Wọn ń ṣe panṣágà ní Ejibiti, wọn ń ṣe panṣágà láti ìgbà èwe wọn. Ní ilẹ̀ yẹn ni wọn ti fi ọwọ́ pa ọyàn wọn, níbẹ̀ ni wọn sì fọwọ́ pa igbá àyà èwe wọn. Èyí ẹ̀gbọ́n ń jẹ́ Ohola, àbúrò rẹ̀ sì ń jẹ́ Oholiba. Tèmi ni wọ́n, wọ́n sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin. Ohola ni Samaria, Oholiba sì ni Jerusalẹmu.

“Ohola ń ṣe panṣágà nígbà tí ó sì jẹ́ tèmi; Ó sì ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí àwọn olólùfẹ́ rẹ̀, àwọn jagunjagun ará Asiria. Aṣọ aláró ni a fi wọ̀ wọ́n, àwọn gómìnà àti àwọn balógun, gbogbo wọn jẹ́ ọ̀dọ́mọkùnrin arẹwà àwọn tí ń gun ẹṣin. O fi ara rẹ̀ fún gbajúmọ̀ ọkùnrin Asiria gẹ́gẹ́ bí panṣágà obìnrin, o fi òrìṣà gbogbo àwọn tí ó ní ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí i sọ ara rẹ̀ di aláìmọ́, kò fi ìwà panṣágà tí ó ti bẹ̀rẹ̀, ni Ejibiti sílẹ̀, ní ìgbà èwe rẹ̀ àwọn ọkùnrin n bá a sùn, wọn fi ọwọ́ pa àyà èwe rẹ̀ lára wọn sì ń ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí i.

“Nítorí náà mo fi i sílẹ̀ fún àwọn olólùfẹ́ rẹ̀, ará Asiria, tí ó ní ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí i. 10 Wọ́n bọ́ ọ sí ìhòhò, wọ́n sì gba àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin rẹ̀ wọn sì pa wọn pẹ̀lú idà. Ó di ẹni ìfisọ̀rọ̀ sọ láàrín àwọn obìnrin wọ́n sì fi ìyà jẹ ẹ́.

11 “Àbúrò rẹ̀ Oholiba rí èyí, síbẹ̀ nínú ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àti panṣágà rẹ̀, Ó ba ara rẹ jẹ́ ju ẹ̀gbọ́n rẹ̀ lọ. 12 Òun náà ní ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí ará Asiria àwọn gómìnà àti àwọn balógun, jagunjagun nínú aṣọ ogun, àwọn tí ń gun ẹṣin, gbogbo àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin arẹwà. 13 Mo rí i pé òun náà ba ara rẹ̀ jẹ́; àwọn méjèèjì rìn ojú ọ̀nà kan náà.

14 “Ṣùgbọ́n ó tẹ̀síwájú nínú ṣíṣe panṣágà. O ri àwòrán àwọn ọkùnrin lára ògiri, àwòrán àwọn ara Kaldea àwòrán pupa, 15 pẹ̀lú ìgbànú ni ìdí wọn àti àwọn ìgbàrí ni orí wọn; gbogbo wọn dàbí olórí kẹ̀kẹ́ ogun Babeli ọmọ ìlú Kaldea. 16 Ní kété tí ó rí wọn, ó ní ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí wọn, ó sì rán oníṣẹ́ sí wọn ni Kaldea. 17 Àwọn ará Babeli wá sọ́dọ̀ rẹ̀, lórí ibùsùn ìfẹ́, nínú ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ wọn, wọ́n bà á jẹ́. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n bà á jẹ́ tán, ó yípadà kúrò lọ́dọ̀ wọn ní ìtìjú. 18 Nígbà tí ó tẹ̀síwájú nínú iṣẹ́ panṣágà rẹ̀ ní gbangba wọ́n sì tú u sí ìhòhò, mo yí padà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀ ní ìtìjú, gẹ́gẹ́ bí mo ti yípadà kúrò lọ́dọ̀ ẹ̀gbọ́n rẹ̀. 19 Síbẹ̀síbẹ̀ ó ń pọ̀ sí i nínú ìdàpọ̀ rẹ̀ bí ó ti ń rántí ìgbà èwe rẹ̀ tí ó jẹ́ panṣágà ní Ejibiti. 20 Nítorí ó fẹ́ olùfẹ́ àwọn olùfẹ́ wọn ní àfẹ́jù, tí àwọn tí nǹkan ọkùnrin wọn dàbí ti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àwọn ẹni tí ìtújáde ara wọn dàbí ti àwọn ẹṣin. 21 Báyìí ni ìwọ pe ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ìgbà èwe rẹ wá sí ìrántí, ní ti rírin orí ọmú rẹ láti ọwọ́ àwọn ará Ejibiti, fún ọmú ìgbà èwe rẹ.

22 “Nítorí náà, Oholiba, báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Èmi yóò gbé olólùfẹ́ rẹ dìde sí ọ, àwọn tí o kẹ́yìn si ní ìtìjú, èmi yóò sì mú wọn dojúkọ ọ́ ní gbogbo ọ̀nà 23 àwọn ará Babeli àti gbogbo ara Kaldea àwọn ọkùnrin Pekodi àti Ṣoa àti Koa àti gbogbo ará Asiria pẹ̀lú wọn, àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin arẹwà, gbogbo àwọn gómìnà àti balógun, olórí oníkẹ̀kẹ́ ogun àti àwọn onípò gíga, gbogbo àwọn tí ń gun ẹṣin. 24 Wọn yóò wa dojúkọ ọ pẹ̀lú ohun ìjà, kẹ̀kẹ́ ogun pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ ẹrù àti pẹ̀lú ìwọ́jọpọ̀ ènìyàn; wọn yóò mú ìdúró wọn lòdì sí ọ ní gbogbo ọ̀nà pẹ̀lú asà ńlá àti kékeré pẹ̀lú àṣíborí. Èmi yóò yí ọ padà sí wọn fun ìjìyà, wọn yóò sì fi ìyà jẹ ọ gẹ́gẹ́ bí wọn tí tó. 25 Èmi yóò sì dojú ìbínú owú mi kọ ọ́, wọn yóò sì fìyà jẹ ọ́ ní ìrunú. Wọ́n yóò gé àwọn imú àti àwọn etí yín kúrò, àwọn tí ó kù nínú yín yóò ti ipá idà ṣubú. Wọn yóò mú àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọkùnrin yín lọ, àwọn tí o kù nínú yín ni iná yóò jórun. 26 Wọn yóò sì kó àwọn aṣọ àti àwọn ohun ọ̀ṣọ́ iyebíye yín. 27 Èmi yóò sì fi òpin sí ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àti iṣẹ́ panṣágà tí ẹ bẹ̀rẹ̀ ni Ejibiti. Ẹ̀yin kò ní wo àwọn nǹkan wọ̀nyí pẹ̀lú ìpòùngbẹ, bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò ní rántí Ejibiti mọ.

28 “Nítorí báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmi yóò fi ọ lé ọwọ́ àwọn tí ó kórìíra, lọ́wọ́ àwọn ẹni tí ọkàn rẹ ti ṣí kúrò. 29 Wọn yóò fìyà jẹ ọ́ pẹ̀lú ìkórìíra, wọn yóò sì kó gbogbo ohun tí o ṣiṣẹ́ fún lọ. Wọn yóò fi ọ́ sílẹ̀ ní ìhòhò goloto, ìtìjú iṣẹ́ panṣágà rẹ ni yóò farahàn. Ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ rẹ̀ àti panṣágà rẹ. 30 Èmi yóò ṣe gbogbo nǹkan wọ̀nyí sí ọ, nítorí ìwọ ti bá àwọn kèfèrí ṣe àgbèrè lọ, o sì fi àwọn òrìṣà wọn ba ara rẹ̀ jẹ́. 31 Ìwọ ti rin ọ̀nà ti ẹ̀gbọ́n rẹ rìn; Èmi yóò sì fi ago rẹ̀ lé ọ lọ́wọ́.

32 “Èyí yìí ní ohun ti Olúwa Olódùmarè:

“Ìwọ yóò mu nínú ago ẹ̀gbọ́n rẹ,
    ago tí ó tóbi tí ó sì jinnú:
yóò mú ìfiṣẹ̀sín àti ìfiṣe ẹlẹ́yà wá,
    nítorí tí ago náà gba nǹkan púpọ̀.
33 Ìwọ yóò mu àmupara àti ìbànújẹ́,
    ago ìparun àti ìsọdahoro
    ago ẹ̀gbọ́n rẹ Samaria.
34 Ìwọ yóò mú un ni àmugbẹ;
    ìwọ yóò sì fọ sí wẹ́wẹ́
ìwọ yóò sì fa ọmú rẹ̀ ya.

Èmi ti sọ̀rọ̀ ni Olúwa Olódùmarè wí.

35 “Nítorí náà báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Níwọ́n bí ìwọ ti gbàgbé mi, tí ìwọ sì ti fi mi sí ẹ̀yìn rẹ, ìwọ gbọdọ̀ gba àbájáde ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àti panṣágà rẹ.”

36 Olúwa sọ fún mi pé: “Ọmọ ènìyàn, ń jẹ́ ìwọ yóò ṣe ìdájọ́ Ohola àti Oholiba? Nítorí náà dojúkọ wọn nípa ìkórìíra tí wọn ń ṣe, 37 nítorí wọn ti dá ẹ̀ṣẹ̀ panṣágà ẹ̀jẹ̀ sì wà ní ọwọ́ wọn. Wọn dá ẹ̀ṣẹ̀ panṣágà pẹ̀lú àwọn òrìṣà wọn; kódà wọ́n fi àwọn ọmọ wọn tí wọn bí fún ni ṣe ìrúbọ, gẹ́gẹ́ bí oúnjẹ fún wọn. 38 Bákan náà ni wọ́n ti ṣe èyí náà sí mi: Ní àkókò kan náà wọn ba ibi mímọ́ mi jẹ́, wọ́n sì lo ọjọ́ ìsinmi mi ní àìmọ́. 39 Ní ọjọ́ náà gan an wọ́n fi àwọn ọmọ wọn rú ẹbọ sí àwọn òrìṣà, wọn wọ ibi mímọ́ mi lọ wọn sì lò ó ní ìlòkulò. Ìyẹn ní wọn ṣe ní ilé mi.

40 “Wọn tilẹ̀ rán oníṣẹ́ sí àwọn ènìyàn tí wọ́n wá láti ọ̀nà jíjìn, nígbà tí wọ́n dé, ìwọ wẹ ara rẹ fún wọn, ìwọ kún ojú rẹ, ìwọ sì fi ọ̀ṣọ́ iyebíye sára, 41 Ìwọ jókòó lórí ibùsùn ti o lẹ́wà, pẹ̀lú tábìlì tí a tẹ́ ní iwájú rẹ lórí, èyí tí o gbé tùràrí àti òróró tí ó jẹ́ tèmi kà.

42 “Ariwo ìjọ ènìyàn tí kò bìkítà wà ní àyíká rẹ̀; a mú àwọn ara Sabeani láti aginjù pẹ̀lú àwọn ọkùnrin láti ara àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn aláìníláárí, wọ́n sì mú àwọn ẹ̀gbà ọrùn ọwọ́ sí àwọn ọwọ́ obìnrin náà àti ẹ̀gbọ́n rẹ̀, adé dáradára sì wà ní orí wọn. 43 Lẹ́yìn náà mo sọ̀rọ̀ nípa èyí tí ó lo ara rẹ̀ sá nípa panṣágà ṣíṣe, ‘Nísinsin yìí jẹ kí wọn lo o bí panṣágà, nítorí gbogbo ohun tí ó jẹ́ nìyẹn.’ 44 Wọn ba sùn bí ọkùnrin ti bá panṣágà sùn, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣe sùn pẹ̀lú obìnrin onífẹ̀kúfẹ̀ẹ́, Ohola àti Oholiba. 45 Ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin olódodo yóò pàṣẹ pé kí wọ́n fi ìyà jẹ àwọn obìnrin tí ó dá ẹ̀ṣẹ̀ àgbèrè tí ó sì ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀ nítorí pé panṣágà ni wọ́n ẹ̀jẹ̀ sì wà ní ọwọ́ wọn.

46 “Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Mú àgbájọ àwọn ènìyànkénìyàn wá sọ́dọ̀ wọn ki ó sì fi wọn lé ọwọ́ ìpayà àti ìkógun. 47 Àwọn ènìyànkénìyàn náà yóò sọ wọ́n ni òkúta, yóò sì gé wọn lulẹ̀ pẹ̀lú idà wọn; wọn ó sì pa àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wọn, wọ́n ó sì jó àwọn ilé wọn kanlẹ̀.

48 “Èmi yóò sì fi òpin sí ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ni ilẹ̀ náà, kí gbogbo àwọn obìnrin le gba ìkìlọ̀ kí wọn kí ó ma sì ṣe fi ara wé ọ. 49 Ìwọ yóò sì jìyà fún ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ rẹ, ìwọ yóò sì gba àbájáde àwọn ẹ̀ṣẹ̀ panṣágà tí o dá. Nígbà náà ìwọ yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa Olódùmarè.”

Two Adulterous Sisters

23 The word of the Lord came to me: “Son of man, there were two women, daughters of the same mother.(A) They became prostitutes in Egypt,(B) engaging in prostitution(C) from their youth.(D) In that land their breasts were fondled and their virgin bosoms caressed.(E) The older was named Oholah, and her sister was Oholibah. They were mine and gave birth to sons and daughters. Oholah is Samaria, and Oholibah is Jerusalem.(F)

“Oholah engaged in prostitution while she was still mine; and she lusted after her lovers, the Assyrians(G)—warriors(H) clothed in blue, governors and commanders, all of them handsome young men, and mounted horsemen. She gave herself as a prostitute to all the elite of the Assyrians and defiled herself with all the idols of everyone she lusted after.(I) She did not give up the prostitution she began in Egypt,(J) when during her youth men slept with her, caressed her virgin bosom and poured out their lust on her.(K)

“Therefore I delivered her into the hands(L) of her lovers,(M) the Assyrians, for whom she lusted.(N) 10 They stripped(O) her naked, took away her sons and daughters and killed her with the sword. She became a byword among women,(P) and punishment was inflicted(Q) on her.(R)

11 “Her sister Oholibah saw this,(S) yet in her lust and prostitution she was more depraved than her sister.(T) 12 She too lusted after the Assyrians—governors and commanders, warriors in full dress, mounted horsemen, all handsome young men.(U) 13 I saw that she too defiled herself; both of them went the same way.(V)

14 “But she carried her prostitution still further. She saw men portrayed on a wall,(W) figures of Chaldeans[a] portrayed in red,(X) 15 with belts(Y) around their waists and flowing turbans on their heads; all of them looked like Babylonian chariot officers, natives of Chaldea.[b] 16 As soon as she saw them, she lusted after them and sent messengers(Z) to them in Chaldea.(AA) 17 Then the Babylonians(AB) came to her, to the bed of love, and in their lust they defiled her. After she had been defiled by them, she turned away from them in disgust.(AC) 18 When she carried on her prostitution openly and exposed her naked body,(AD) I turned away(AE) from her in disgust, just as I had turned away from her sister.(AF) 19 Yet she became more and more promiscuous as she recalled the days of her youth, when she was a prostitute in Egypt. 20 There she lusted after her lovers, whose genitals were like those of donkeys and whose emission was like that of horses. 21 So you longed for the lewdness of your youth, when in Egypt your bosom was caressed and your young breasts fondled.[c](AG)

22 “Therefore, Oholibah, this is what the Sovereign Lord says: I will stir up your lovers(AH) against you, those you turned away from in disgust, and I will bring them against you from every side(AI) 23 the Babylonians(AJ) and all the Chaldeans,(AK) the men of Pekod(AL) and Shoa and Koa, and all the Assyrians with them, handsome young men, all of them governors and commanders, chariot officers and men of high rank, all mounted on horses.(AM) 24 They will come against you with weapons,[d] chariots and wagons(AN) and with a throng of people; they will take up positions against you on every side with large and small shields and with helmets. I will turn you over to them for punishment,(AO) and they will punish you according to their standards. 25 I will direct my jealous anger(AP) against you, and they will deal with you in fury. They will cut off your noses and your ears, and those of you who are left will fall by the sword. They will take away your sons and daughters,(AQ) and those of you who are left will be consumed by fire.(AR) 26 They will also strip(AS) you of your clothes and take your fine jewelry.(AT) 27 So I will put a stop(AU) to the lewdness and prostitution you began in Egypt. You will not look on these things with longing or remember Egypt anymore.

28 “For this is what the Sovereign Lord says: I am about to deliver you into the hands(AV) of those you hate, to those you turned away from in disgust. 29 They will deal with you in hatred and take away everything you have worked for. They will leave you stark naked,(AW) and the shame of your prostitution will be exposed.(AX) Your lewdness(AY) and promiscuity(AZ) 30 have brought this on you, because you lusted after the nations and defiled yourself with their idols.(BA) 31 You have gone the way of your sister; so I will put her cup(BB) into your hand.(BC)

32 “This is what the Sovereign Lord says:

“You will drink your sister’s cup,
    a cup large and deep;
it will bring scorn and derision,(BD)
    for it holds so much.(BE)
33 You will be filled with drunkenness and sorrow,
    the cup of ruin and desolation,
    the cup of your sister Samaria.(BF)
34 You will drink it(BG) and drain it dry
    and chew on its pieces—
    and you will tear your breasts.

I have spoken, declares the Sovereign Lord.(BH)

35 “Therefore this is what the Sovereign Lord says: Since you have forgotten(BI) me and turned your back on me,(BJ) you must bear(BK) the consequences of your lewdness and prostitution.”

36 The Lord said to me: “Son of man, will you judge Oholah and Oholibah? Then confront(BL) them with their detestable practices,(BM) 37 for they have committed adultery and blood is on their hands. They committed adultery with their idols; they even sacrificed their children, whom they bore to me, as food for them.(BN) 38 They have also done this to me: At that same time they defiled my sanctuary(BO) and desecrated my Sabbaths.(BP) 39 On the very day they sacrificed their children to their idols, they entered my sanctuary and desecrated(BQ) it. That is what they did in my house.(BR)

40 “They even sent messengers for men who came from far away,(BS) and when they arrived you bathed yourself for them, applied eye makeup(BT) and put on your jewelry.(BU) 41 You sat on an elegant couch,(BV) with a table(BW) spread before it on which you had placed the incense(BX) and olive oil that belonged to me.(BY)

42 “The noise of a carefree(BZ) crowd was around her; drunkards(CA) were brought from the desert along with men from the rabble, and they put bracelets(CB) on the wrists of the woman and her sister and beautiful crowns on their heads.(CC) 43 Then I said about the one worn out by adultery, ‘Now let them use her as a prostitute,(CD) for that is all she is.’ 44 And they slept with her. As men sleep with a prostitute, so they slept with those lewd women, Oholah and Oholibah. 45 But righteous judges will sentence them to the punishment of women who commit adultery and shed blood,(CE) because they are adulterous and blood is on their hands.(CF)

46 “This is what the Sovereign Lord says: Bring a mob(CG) against them and give them over to terror and plunder.(CH) 47 The mob will stone them and cut them down with their swords; they will kill their sons and daughters(CI) and burn(CJ) down their houses.(CK)

48 “So I will put an end(CL) to lewdness in the land, that all women may take warning and not imitate you.(CM) 49 You will suffer the penalty for your lewdness and bear the consequences of your sins of idolatry.(CN) Then you will know that I am the Sovereign Lord.(CO)

Footnotes

  1. Ezekiel 23:14 Or Babylonians
  2. Ezekiel 23:15 Or Babylonia; also in verse 16
  3. Ezekiel 23:21 Syriac (see also verse 3); Hebrew caressed because of your young breasts
  4. Ezekiel 23:24 The meaning of the Hebrew for this word is uncertain.