Add parallel Print Page Options

Babeli idà Ọlọ́run fún ìdájọ́

21 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ mi wá: “Ọmọ ènìyàn, kọ ojú rẹ sí ìhà Jerusalẹmu, kí o sì wàásù lòdì sí ibi mímọ́. Sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí ilẹ̀ Israẹli. Kí ó sì sọ fún un pe: ‘Èyí yìí ni Olúwa wí: Èmi lòdì sí ọ. Èmi yóò fa idà mi yọ kúrò nínú àkọ̀ rẹ̀, Èmi yóò sì ké olódodo àti ènìyàn búburú kúrò ni àárín yín. Nítorí pé, èmi yóò ké olódodo àti olùṣe búburú kúrò, idà mi yóò jáde láti inú àkọ̀ rẹ̀ lòdì sí gbogbo ènìyàn láti gúúsù títí dé àríwá. Nígbà náà gbogbo ènìyàn yóò mọ̀ pé èmi Olúwa ti yọ idà mi kúrò nínú àkọ̀ rẹ̀; kì yóò sì padà sínú rẹ̀ mọ́.’

“Nítorí náà, mí ìmí ẹ̀dùn ìwọ ọmọ ènìyàn! Mí ìmí ẹ̀dùn pẹ̀lú ọkàn ìbànújẹ́ àti ẹ̀dùn ọkàn kíkorò ní iwájú wọn. Bí wọ́n bá sì bi ọ́, wí pé, ‘Kí ni ó dé tí ìwọ fi ń mí ìmí ẹ̀dùn?’ Ìwọ yóò wí pé, ‘Nítorí ìròyìn tí ó ń bẹ. Gbogbo ọkàn ni yóò yọ́, gbogbo ọwọ́ ni yóò sì di aláìlera; gbogbo ọkàn ní yóò dákú, gbogbo eékún ni yóò sì di aláìlera bí omi?’ Ó ń bọ̀! Yóò sì wa sí ìmúṣẹ dandan, ni Olúwa Olódùmarè wí.”

Ọ̀rọ̀ Olúwa si tún tọ̀ mí wá pé: “Ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀ wí pé, Èyí yìí ní Olúwa wí pé:

“ ‘Idà kan, Idà kan,
    tí a pọ́n, tí a sì dán pẹ̀lú,
10 a pọ́n láti pa ènìyàn púpọ̀,
    a dán an láti máa kọ mọ̀nà!

“ ‘Àwa o ha máa ṣe àríyá ọ̀gọ ọmọ mi? Idà gán gbogbo irú igi bẹ́ẹ̀.

11 “ ‘Idà ní a yàn láti pọ́n,
    kí ó lè ṣe é gbámú;
a pọ́n ọn, a sì dán an,
    ó ṣetán fún ọwọ́ àwọn apani.
12 Sọkún síta, kí ó sì pohùnréré ẹ̀kún, ọmọ ènìyàn,
    nítorí yóò wá sórí àwọn ènìyàn mi;
yóò wá sórí gbogbo ọmọ-aládé Israẹli
    ìbẹ̀rù ńlá yóò wá sórí àwọn ènìyàn mi
nítorí idà náà;
    nítorí náà lu oókan àyà rẹ.

13 “ ‘Ìdánwò yóò dé dandan. Tí ọ̀pá aládé Juda èyí tí idà kẹ́gàn, kò bá tẹ̀síwájú mọ́ ńkọ́? Ni Olúwa Olódùmarè wí.’

14 “Nítorí náà, ọmọ ènìyàn,
    sọtẹ́lẹ̀ kí ó sì fi ọwọ́ lu ọwọ́
Jẹ́ kí idà lu ara wọn lẹ́ẹ̀méjì,
    kódà ní ẹ̀ẹ̀mẹta.
Ó jẹ́ idà fún ìpànìyàn
    idà fún ìpànìyàn lọ́pọ̀lọpọ̀
    Tí yóò sé wọn mọ́ níhìn-ín àti lọ́hùnnún.
15 Kí ọkàn kí ó lè yọ́
    kí àwọn tí ó ṣubú le pọ̀,
mo ti gbé idà sí gbogbo bodè fún ìparun
    Háà! A mú kí ó kọ bí ìmọ̀nàmọ́ná,
    a gbá a mú fún ìparun.
16 Ìwọ idà, jà sí ọ̀tún
    kí o sì jà sí òsì
    lọ ibikíbi tí ẹnu rẹ bá dojúkọ
17 Èmi gan an yóò pàtẹ́wọ́
    ìbínú mi yóò sì rẹlẹ̀
    Èmi Olúwa ti sọ̀rọ̀.”

18 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ mi wá: 19 “Ọmọ ènìyàn la ọ̀nà méjì fún idà ọba Babeli láti gbà, kí méjèèjì bẹ̀rẹ̀ láti ìlú kan náà. Ṣe ààmì sí ìkóríta ọ̀nà tí ó lọ sí ìlú náà. 20 La ọ̀nà kan fún idà láti wá kọlu Rabba ti àwọn ará Ammoni kí òmíràn kọlu Juda, kí ó sì kọlu Jerusalẹmu ìlú olódi. 21 Nítorí ọba Babeli yóò dúró ni ìyànà ní ojú ọ̀nà, ní ìkóríta, láti máa lo àfọ̀ṣẹ: Yóò fi ọfà di ìbò, yóò béèrè lọ́wọ́ àwọn òrìṣà rẹ̀, òun yóò ṣe àyẹ̀wò ẹ̀dọ̀. 22 Nínú ọwọ́ ọ̀tún rẹ ni ìbò Jerusalẹmu yóò ti wá, ní ibi tí yóò ti gbé afárá kalẹ̀, láti pàṣẹ fún àwọn apànìyàn, láti mú ki wọn hó ìhó ogun láti gbé òòlù dí ẹnu-ọ̀nà ibodè, láti mọ odi, àti láti kọ́ ilé ìṣọ́. 23 Àfọ̀ṣẹ náà yóò dàbí ààmì èké sí àwọn tí ó ti búra ìtẹríba fún un, ṣùgbọ́n òun yóò ran wọn létí ẹbí wọn yóò sì mú wọn lọ sí ìgbèkùn.

24 “Nítorí náà èyí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: ‘Nítorí ti ẹ̀yin ti mú ẹ̀bi yín wá sí ìrántí nípa ìṣọ̀tẹ̀ ní gbangba, ní ṣíṣe àfihàn àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ nínú gbogbo ohun tí ó ṣe, nítorí tí ẹ̀yin ti ṣe èyí, a yóò mú yín ní ìgbèkùn.

25 “ ‘Ìwọ aláìmọ́ àti ẹni búburú ọmọ-aládé Israẹli, ẹni ti ọjọ́ rẹ̀ ti dé, ẹni tí àsìkò ìjìyà rẹ̀ ti dé góńgó, 26 Èyí yìí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Tú ìwérí kúrò kí o sì gbé adé kúrò. Kò ní rí bí ti tẹ́lẹ̀: Ẹni ìgbéga ni a yóò sì rẹ̀ sílẹ̀, 27 Ìparun! Ìparun! Èmi yóò ṣé e ni ìparun! Kì yóò padà bọ̀ sípò bí kò ṣe pé tí ó bá wá sí ọ̀dọ̀ ẹni tí ó ní ẹ̀tọ́ láti ni in; òun ni èmi yóò fi fún.’

28 (A)“Àti ìwọ, ọmọ ènìyàn sọtẹ́lẹ̀ kí ó sì wí pé, ‘Èyí yìí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí nípa àwọn ará Ammoni àti àbùkù wọn:

“ ‘Idà kan idà kan
    tí á fa yọ fún ìpànìyàn
tí a dán láti fi ènìyàn ṣòfò
    àti láti kọ bí ìmọ̀nàmọ́ná!
29 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a rí èké nípa yín
    àti àfọ̀ṣẹ èké nípa yín
a yóò gbé e lé àwọn ọrùn
    ènìyàn búburú ti a ó pa,
àwọn tí ọjọ́ wọn ti dé,
    àwọn tí ọjọ́ ìjìyà wọn ti dé góńgó.

30 “ ‘Dá idà padà sínú àkọ̀ rẹ̀
    Níbi tí a gbé ṣẹ̀dá yín,
    ní ibi tí ẹ̀yin ti ṣẹ̀ wá.
31 Níbẹ̀ ni èmi yóò ti ṣe ìdájọ́ yín,
    èmi o sì fi èémí ìbínú gbígbóná
    mi bá yín jà.
32 Ẹ̀yin yóò jẹ́ èpò fún iná náà,
    a yóò ta ẹ̀jẹ̀ yin sórí ilẹ̀ yín,
a kì yóò rántí yín mọ́;
    nítorí èmi Olúwa ní ó ti wí bẹ́ẹ̀.’ ”

Babylon as God’s Sword of Judgment

21 [a]The word of the Lord came to me:(A) “Son of man, set your face against(B) Jerusalem and preach against the sanctuary.(C) Prophesy against(D) the land of Israel and say to her: ‘This is what the Lord says: I am against you.(E) I will draw my sword(F) from its sheath and cut off from you both the righteous and the wicked.(G) Because I am going to cut off the righteous and the wicked, my sword(H) will be unsheathed against everyone from south to north.(I) Then all people will know that I the Lord have drawn my sword(J) from its sheath; it will not return(K) again.’(L)

“Therefore groan, son of man! Groan before them with broken heart and bitter grief.(M) And when they ask you, ‘Why are you groaning?(N)’ you shall say, ‘Because of the news that is coming. Every heart will melt with fear(O) and every hand go limp;(P) every spirit will become faint(Q) and every leg will be wet with urine.’(R) It is coming! It will surely take place, declares the Sovereign Lord.”

The word of the Lord came to me: “Son of man, prophesy and say, ‘This is what the Lord says:

“‘A sword, a sword,
    sharpened and polished—
10 sharpened for the slaughter,(S)
    polished to flash like lightning!

“‘Shall we rejoice in the scepter of my royal son? The sword despises every such stick.(T)

11 “‘The sword is appointed to be polished,(U)
    to be grasped with the hand;
it is sharpened and polished,
    made ready for the hand of the slayer.
12 Cry out and wail, son of man,
    for it is against my people;
    it is against all the princes of Israel.
They are thrown to the sword
    along with my people.
Therefore beat your breast.(V)

13 “‘Testing will surely come. And what if even the scepter, which the sword despises, does not continue? declares the Sovereign Lord.’

14 “So then, son of man, prophesy
    and strike your hands(W) together.
Let the sword strike twice,
    even three times.
It is a sword for slaughter—
    a sword for great slaughter,
    closing in on them from every side.(X)
15 So that hearts may melt with fear(Y)
    and the fallen be many,
I have stationed the sword for slaughter[b]
    at all their gates.
Look! It is forged to strike like lightning,
    it is grasped for slaughter.(Z)
16 Slash to the right, you sword,
    then to the left,
    wherever your blade is turned.
17 I too will strike my hands(AA) together,
    and my wrath(AB) will subside.
I the Lord have spoken.(AC)

18 The word of the Lord came to me: 19 “Son of man, mark out two roads for the sword(AD) of the king of Babylon to take, both starting from the same country. Make a signpost(AE) where the road branches off to the city. 20 Mark out one road for the sword to come against Rabbah of the Ammonites(AF) and another against Judah and fortified Jerusalem. 21 For the king of Babylon will stop at the fork in the road, at the junction of the two roads, to seek an omen: He will cast lots(AG) with arrows, he will consult his idols,(AH) he will examine the liver.(AI) 22 Into his right hand will come the lot for Jerusalem, where he is to set up battering rams, to give the command to slaughter, to sound the battle cry,(AJ) to set battering rams against the gates, to build a ramp(AK) and to erect siege works.(AL) 23 It will seem like a false omen to those who have sworn allegiance to him, but he will remind(AM) them of their guilt(AN) and take them captive.

24 “Therefore this is what the Sovereign Lord says: ‘Because you people have brought to mind your guilt by your open rebellion, revealing your sins in all that you do—because you have done this, you will be taken captive.

25 “‘You profane and wicked prince of Israel, whose day has come,(AO) whose time of punishment has reached its climax,(AP) 26 this is what the Sovereign Lord says: Take off the turban, remove the crown.(AQ) It will not be as it was: The lowly will be exalted and the exalted will be brought low.(AR) 27 A ruin! A ruin! I will make it a ruin! The crown will not be restored until he to whom it rightfully belongs shall come;(AS) to him I will give it.’(AT)

28 “And you, son of man, prophesy and say, ‘This is what the Sovereign Lord says about the Ammonites(AU) and their insults:

“‘A sword,(AV) a sword,
    drawn for the slaughter,
polished to consume
    and to flash like lightning!
29 Despite false visions concerning you
    and lying divinations(AW) about you,
it will be laid on the necks
    of the wicked who are to be slain,
whose day has come,
    whose time of punishment has reached its climax.(AX)

30 “‘Let the sword return to its sheath.(AY)
    In the place where you were created,
in the land of your ancestry,(AZ)
    I will judge you.
31 I will pour out my wrath on you
    and breathe(BA) out my fiery anger(BB) against you;
I will deliver you into the hands of brutal men,
    men skilled in destruction.(BC)
32 You will be fuel for the fire,(BD)
    your blood will be shed in your land,
you will be remembered(BE) no more;
    for I the Lord have spoken.’”

Footnotes

  1. Ezekiel 21:1 In Hebrew texts 21:1-32 is numbered 21:6-37.
  2. Ezekiel 21:15 Septuagint; the meaning of the Hebrew for this word is uncertain.