Add parallel Print Page Options

(A)Nígbà náà ní Olúwa sọ fún Mose pé, “Ní ìsin yìí, ìwọ yóò rí ohun tí èmi yóò ṣe sí Farao pẹ̀lú ọwọ́ agbára ńlá mi ni yóò fi jẹ́ kí wọn lọ; pẹ̀lú ọwọ́ agbára ńlá mi, òun yóò lé wọn jáde kúrò ní orílẹ̀-èdè rẹ̀.”

(B)Ọlọ́run sì tún sọ fún Mose pé, “Èmi ni Olúwa. Mo fi ara hàn Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu bí Ọlọ́run alágbára (Eli-Ṣaddai) ṣùgbọ́n nípa orúkọ mi Olúwa, Èmi kò fi ara Mi hàn wọ́n. Èmí sì tún fi ìdí májẹ̀mú mi múlẹ̀ pẹ̀lú wọn láti fún wọn ní ilẹ̀ Kenaani, ilẹ̀ tí wọn gbé gẹ́gẹ́ bí àjèjì. Èmi sì ti tún gbọ́ kíkùn àwọn ọmọ Israẹli àwọn tí àwọn ará Ejibiti mú gẹ́gẹ́ bí ẹrú, àti pé èmi sì ti rántí májẹ̀mú Mi.

“Sọ fún àwọn ará ilé Israẹli: ‘Èmi ni Olúwa, Èmi yóò sọ yín di òmìnira kúrò nínú àjàgà àwọn ará Ejibiti. Èmi yóò sì gbà yín sílẹ̀ kúrò ní oko ẹrú wọn. Èmi yóò dá a yín sílẹ̀ pẹ̀lú apá nínà (àwọn iṣẹ́ ìyanu) àti pẹ̀lú ìdájọ́ ńlá. Èmi yóò mú un yín bí ènìyàn mi, èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run yín. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín, ẹni tí ó mú un yín jáde kúrò nínú àjàgà àwọn ará Ejibiti. Èmi yóò mú un yín wá ilẹ̀ náà ti èmi ti búra pẹ̀lú ìgbọ́wọ́sókè láti fi fún Abrahamu. Isaaki àti Jakọbu. Èmi yóò fi fún un yín bí ohun ìní, Èmi ni Olúwa.’ ”

Mose sì sọ èyí fún àwọn ará Israẹli, ṣùgbọ́n wọn kò fi etí sílẹ̀ sí Mose nítorí ọkàn wọn tó rẹ̀wẹ̀sì àti nítorí ìgbèkùn búburú bí ohun tí ó ti kọ́ sọ kó wọn sí ní oko ẹrú wọn.

10 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose. 11 “Lọ, sọ fún Farao ọba Ejibiti pé kí ó jẹ́ kí àwọn ará Israẹli lọ kúrò ní orílẹ̀-èdè rẹ̀.”

12 Ṣùgbọ́n Mose sọ fún Olúwa pé, “Nígbà ti àwọn ará Israẹli tó jẹ́ ènìyàn mi kó fetí sí ọ̀rọ̀ mi, báwo ni Farao yóò ṣe fetí sí ọ̀rọ̀ mi, nígbà ti mo jẹ́ akólòlò?”

Àkọsílẹ̀ ìdílé Mose Àti Aaroni

13 Olúwa bá ìran Mose àti Aaroni sọ̀rọ̀ nípa àwọn ará Israẹli àti Farao ọba Ejibiti, ó pàṣẹ fún wọn pé kí wọn kó àwọn Israẹli jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti.

14 Wọ̀nyí ni olórí ìran wọn:

Àwọn ọmọ Reubeni àkọ́bí Israẹli ni:

Hanoku, Pallu, Hesroni àti Karmi.

Àwọn wọ̀nyí ni ìdílé Reubeni.

15 Àwọn ọmọ Simeoni ní:

Jemueli, Jamini, Ohadi, Jakini, Sohari àti Saulu ọmọ obìnrin Kenaani.

Àwọn wọ̀nyí ni ìran Simeoni.

16 (C)Ìwọ̀nyí ni orúkọ àwọn ọmọ Lefi gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ wọn:

Gerṣoni, Kohati àti Merari.

Lefi lo ẹ̀tàndínlógóje (137) ọdún láyé.

17 Àwọn ọmọ Gerṣoni ni ìran wọn ni:

Libni àti Ṣimei.

18 Àwọn ọmọ Kohati ni:

Amramu, Isari, Hebroni àti Usieli.

Kohati lo ẹ̀tàléláádóje (133) ọdún láyé.

19 Àwọn ọmọ Merari ni:

Mahili àti Muṣi.

Ìwọ̀nyí ni ìran Lefi gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ wọn.

20 (D)Amramu sì fẹ́ Jokebedi arábìnrin baba rẹ̀ ní ìyàwó. Jokebedi sì bí Aaroni àti Mose fún un.

Amramu lo ẹ̀tàdínlógóje (137) ọdún láyé.

21 Àwọn ọmọ Isari ni:

Kora, Nefegi àti Sikri.

22 Àwọn ọmọ Usieli ni:

Miṣaeli, Elsafani àti Sitiri.

23 Aaroni fẹ́ Eliṣeba ọmọbìnrin Amminadabu tí í ṣe arábìnrin Nahiṣoni, ó sì bí Nadabu, Abihu, Eleasari àti Itamari.

24 Àwọn ọmọ Kora ni:

Asiri, Elkana àti Abiasafu.

Ìwọ̀nyí ni ìran Kora.

25 Eleasari ọmọ Aaroni fẹ́ ọ̀kan lára àwọn ọmọbìnrin Putieli ní ìyàwó, ó sì bí Finehasi fún un.

Ìwọ̀nyí ni olórí àwọn Lefi ni ìdílé ìdílé.

26 Aaroni àti Mose yìí kan náà ni Olúwa sọ fún pé, “Ẹ kó àwọn ará Israẹli jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti ní ìsọ̀rí ìsọ̀rí.” 27 Àwọn ni ó bá Farao ọba Ejibiti sọ̀rọ̀ nípa kíkó àwọn ará Israẹli jáde kúrò ni Ejibiti, àní Mose àti Aaroni yìí kan náà ni.

Aaroni di agbẹnusọ fún Mose

28 Nígbà tí Olúwa bá Mose sọ̀rọ̀ ni Ejibiti, 29 Olúwa sì sọ fún Mose pé, “Èmi ni Olúwa. Sọ ohun gbogbo ti mo ti sọ fún ọ fún Farao ọba Ejibiti.”

30 Ṣùgbọ́n Mose sì wí ní iwájú Olúwa pé, “Níwọ́n ìgbà ti mo jẹ́ akólòlò, ọ̀nà dà ti Farao yóò ṣe fi etí sí mi?”

Then the Lord said to Moses, “Now you will see what I will do to Pharaoh: Because of my mighty hand(A) he will let them go;(B) because of my mighty hand he will drive them out of his country.”(C)

God also said to Moses, “I am the Lord.(D) I appeared to Abraham, to Isaac and to Jacob as God Almighty,[a](E) but by my name(F) the Lord[b](G) I did not make myself fully known to them. I also established my covenant(H) with them to give them the land(I) of Canaan, where they resided as foreigners.(J) Moreover, I have heard the groaning(K) of the Israelites, whom the Egyptians are enslaving, and I have remembered my covenant.(L)

“Therefore, say to the Israelites: ‘I am the Lord, and I will bring you out from under the yoke of the Egyptians.(M) I will free you from being slaves to them, and I will redeem(N) you with an outstretched arm(O) and with mighty acts of judgment.(P) I will take you as my own people, and I will be your God.(Q) Then you will know(R) that I am the Lord your God, who brought you out from under the yoke of the Egyptians. And I will bring you to the land(S) I swore(T) with uplifted hand(U) to give to Abraham, to Isaac and to Jacob.(V) I will give it to you as a possession. I am the Lord.’”(W)

Moses reported this to the Israelites, but they did not listen to him because of their discouragement and harsh labor.(X)

10 Then the Lord said to Moses, 11 “Go, tell(Y) Pharaoh king of Egypt to let the Israelites go out of his country.”(Z)

12 But Moses said to the Lord, “If the Israelites will not listen(AA) to me, why would Pharaoh listen to me, since I speak with faltering lips[c]?”(AB)

Family Record of Moses and Aaron

13 Now the Lord spoke to Moses and Aaron about the Israelites and Pharaoh king of Egypt, and he commanded them to bring the Israelites out of Egypt.(AC)

14 These were the heads of their families[d]:(AD)

The sons of Reuben(AE) the firstborn son of Israel were Hanok and Pallu, Hezron and Karmi. These were the clans of Reuben.

15 The sons of Simeon(AF) were Jemuel, Jamin, Ohad, Jakin, Zohar and Shaul the son of a Canaanite woman. These were the clans of Simeon.

16 These were the names of the sons of Levi(AG) according to their records: Gershon,(AH) Kohath and Merari.(AI) Levi lived 137 years.

17 The sons of Gershon, by clans, were Libni and Shimei.(AJ)

18 The sons of Kohath(AK) were Amram, Izhar, Hebron and Uzziel.(AL) Kohath lived 133 years.

19 The sons of Merari were Mahli and Mushi.(AM)

These were the clans of Levi according to their records.

20 Amram(AN) married his father’s sister Jochebed, who bore him Aaron and Moses.(AO) Amram lived 137 years.

21 The sons of Izhar(AP) were Korah, Nepheg and Zikri.

22 The sons of Uzziel were Mishael, Elzaphan(AQ) and Sithri.

23 Aaron married Elisheba, daughter of Amminadab(AR) and sister of Nahshon,(AS) and she bore him Nadab and Abihu,(AT) Eleazar(AU) and Ithamar.(AV)

24 The sons of Korah(AW) were Assir, Elkanah and Abiasaph. These were the Korahite clans.

25 Eleazar son of Aaron married one of the daughters of Putiel, and she bore him Phinehas.(AX)

These were the heads of the Levite families, clan by clan.

26 It was this Aaron and Moses to whom the Lord said, “Bring the Israelites out of Egypt(AY) by their divisions.”(AZ) 27 They were the ones who spoke to Pharaoh(BA) king of Egypt about bringing the Israelites out of Egypt—this same Moses and Aaron.(BB)

Aaron to Speak for Moses

28 Now when the Lord spoke to Moses in Egypt, 29 he said to him, “I am the Lord.(BC) Tell Pharaoh king of Egypt everything I tell you.”

30 But Moses said to the Lord, “Since I speak with faltering lips,(BD) why would Pharaoh listen to me?”

Footnotes

  1. Exodus 6:3 Hebrew El-Shaddai
  2. Exodus 6:3 See note at 3:15.
  3. Exodus 6:12 Hebrew I am uncircumcised of lips; also in verse 30
  4. Exodus 6:14 The Hebrew for families here and in verse 25 refers to units larger than clans.