Add parallel Print Page Options

Fẹ́ràn Olúwa kí o sì gbọ́ tirẹ̀

11 Ẹ fẹ́ràn Olúwa Ọlọ́run yín, kí ẹ sì pa ìfẹ́ rẹ̀, ìlànà rẹ̀, òfin rẹ̀ àti àṣẹ rẹ̀ mọ́ ní ìgbà gbogbo. Ẹ rántí lónìí pé, kì í ṣe àwọn ọmọ yín, ni ó rí ìbáwí Olúwa Ọlọ́run yín; títóbi rẹ̀, ọwọ́ agbára rẹ̀, nína ọwọ́ rẹ̀; iṣẹ́ ààmì rẹ̀ àti ohun tí ó ṣe ní àárín àwọn ará Ejibiti: Sí Farao ọba Ejibiti àti gbogbo orílẹ̀-èdè rẹ̀. Ohun tí ó ṣe sí àwọn jagunjagun Ejibiti, sí kẹ̀kẹ́ ogun àti ẹlẹ́ṣin rẹ̀: bí ó ṣe rì wọ́n sínú Òkun pupa, bí wọ́n ṣe ń lé e yín tí Olúwa fi pa wọ́n run pátápátá títí di òní olónìí yìí. Kì í ṣe àwọn ọmọ yín ni ó rí ohun tí ó ṣe fún un yín ní aginjù, títí ẹ fi dé ìhín yìí, (A)ohun tí ó ṣe sí Datani àti Abiramu, àwọn ọmọ Eliabu, ẹ̀yà Reubeni, bí ilẹ̀ ti lanu ní ojú gbogbo ará Israẹli tí ó sì gbé wọn mì pẹ̀lú gbogbo ìdílé wọn, gbogbo àgọ́ ọ wọn àti gbogbo ohun alààyè tí ó jẹ́ tiwọn. Ṣùgbọ́n ojú u yín gan an ni ó rí gbogbo nǹkan ńlá wọ̀nyí tí Olúwa ti ṣe.

Nítorí náà, ẹ kíyèsi gbogbo àṣẹ tí mo ń fún yín lónìí, kí ẹ ba à lè lágbára àti lọ, kí ẹ sì gba ilẹ̀ náà tí ẹ ó la Jordani kọjá lọ. Kí ẹ ba à lè pẹ́ ní orí ilẹ̀ tí Olúwa ti búra fún àwọn baba ńlá a yín, láti fún àwọn àti àwọn ọmọ wọn: ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin. 10 Ilẹ̀ tí ẹ̀ ń wọ̀ lọ láti gbà kò rí bí ilẹ̀ Ejibiti, níbi tí ẹ ti wá, níbi tó jẹ́ wí pé ẹsẹ̀ yín ni ẹ fi ń rìn lọ bomirin irúgbìn tí ẹ gbìn bí oko ẹ̀fọ́. 11 Ṣùgbọ́n ilẹ̀ tí ẹ ó la Jordani kọjá láti gbà, jẹ́ ilẹ̀ olókè àti pẹ̀tẹ́lẹ̀ tí òjò ń rọ̀ sí latọ̀run. 12 Ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run yín ń mójútó ni, ojú Olúwa Ọlọ́run yín sì ń fi ìgbà gbogbo wà lórí rẹ̀, láti ìbẹ̀rẹ̀ ọdún dé òpin ọdún.

13 (B)Nítorí náà, bí ẹ bá gbọ́rọ̀ sí àṣẹ tí mo fún un yín lónìí tọkàntọkàn: tí ẹ fẹ́ràn Olúwa Ọlọ́run yín, tí ẹ sì sìn ín, pẹ̀lú gbogbo àyà yín àti gbogbo ọkàn yín: 14 nígbà náà, èmi yóò rọ òjò sórí ilẹ̀ ẹ yín lákòókò rẹ̀, àti òjò àkọ́rọ̀ àti ti àrọ̀kẹ́yìn, kí ẹ ba à lè kórè oúnjẹ yín wọlé àní wáìnì tuntun àti òróró. 15 Èmi yóò mú kí koríko hù lórí ilẹ̀ yín fún àwọn ohun ọ̀sìn in yín, ẹ ó sì jẹ, ẹ ó sì yó.

16 Ẹ ṣọ́ra, kí a má ba à tàn yín jẹ láti yípadà kí ẹ sì sin ọlọ́run mìíràn àti láti máa foríbalẹ̀ fún wọn. 17 Nígbà náà ni ìbínú Olúwa yóò sì ru sí i yín, Òun yóò ti ìlẹ̀kùn ọ̀run kí òjò má ba à rọ̀, ilẹ̀ kì yóò sì so èso kankan, ẹ ó sì ṣègbé ní ilẹ̀ rere tí Olúwa fi fún un yín. 18 Ẹ fi gbogbo ọ̀rọ̀ mi wọ̀nyí sí àyà a yín, àti ọkàn an yín, ẹ so wọ́n bí ààmì sórí ọwọ́ yín, kí ẹ sì so wọ́n mọ́ iwájú orí yín. 19 Ẹ máa fi wọ́n kọ́ àwọn ọmọ yín, ẹ máa sọ̀rọ̀ nípa wọn bí ẹ bá jókòó nínú ilé, àti ní ojú ọ̀nà bí ẹ bá ń rìn lọ, bí ẹ bá sùn àti bí ẹ bá jí. 20 Kí ìwọ kí ó kọ wọ́n sára òpó ilé rẹ̀, àti sí ara ìlẹ̀kùn ọ̀nà òde rẹ. 21 Kí ọjọ́ ọ yín àti ti àwọn ọmọ yín lè pọ̀ ní ilẹ̀ tí Olúwa ti búra láti fi fún àwọn baba ńlá a yín, ní ìwọ̀n ìgbà tí ọ̀run wà lókè tí ayé sì ń bẹ ní ìsàlẹ̀.

22 Bí ẹ bá fi ara balẹ̀ kíyèsi àwọn òfin tí mo ń fún un yín, láti tẹ̀lé: Láti fẹ́ Olúwa Ọlọ́run yín, láti máa rìn ní gbogbo ọ̀nà rẹ̀ àti láti dìímú ṣinṣin: 23 Olúwa yóò sì lé gbogbo orílẹ̀-èdè wọ̀nyí kúrò níwájú u yín. Ẹ ó sì gba orílẹ̀-èdè tí ó lágbára tí ó sì tóbi jù yín lọ. 24 Gbogbo ibi tí ẹ bá fi ẹsẹ̀ ẹ yín tẹ̀ ni yóò jẹ́ tiyín, ilẹ̀ ẹ yín yóò gbilẹ̀ láti aginjù dé Lebanoni, àti láti odò Eufurate dé Òkun ìwọ̀-oòrùn. 25 Kò sí ẹni náà tí yóò lè kò yín lójú ìjà, Olúwa Ọlọ́run yín yóò fi ẹ̀rù àti ìwárìrì i yín sórí gbogbo ilẹ̀ náà bí ó ti ṣèlérí fún un yín ní gbogbo ibi tí ẹ bá lọ.

26 Ẹ kíyèsi i, mo fi ìbùkún àti ègún lélẹ̀ níwájú u yín lónìí: 27 ìbùkún ni, bí ẹ bá pa òfin Olúwa Ọlọ́run yín, tí mo ń fún un yín lónìí mọ́. 28 Ègún ni, bí ẹ bá ṣàìgbọ́ràn, sí òfin Olúwa Ọlọ́run yín, tí ẹ sì yapa kúrò ní ọ̀nà tí mo ti là sílẹ̀ fún yín lónìí, nípa títẹ̀lé ọlọ́run mìíràn, tí ẹ kò tí ì mọ̀. 29 Nígbà tí Olúwa Ọlọ́run yín bá ti mú un yín dé ilẹ̀ náà tí ẹ ń wọ̀ láti gbà, kí ẹ kéde àwọn ìbùkún náà ní orí òkè Gerisimu, kí ẹ sì kéde àwọn ègún ní orí òkè Ebali. 30 Bí ẹ ti mọ̀ pé àwọn òkè wọ̀nyí wà ní ìkọjá a Jordani ní apá ìwọ̀-oòrùn lójú ọ̀nà lọ sí ìhà ìlà-oòrùn, ní ẹ̀gbẹ́ igi ńlá igbó More, ní ilẹ̀ àwọn ará a Kenaani, tí wọ́n ń gbé ní aginjù, ni agbègbè Gilgali. 31 Ẹ ti ṣetán láti la Jordani kọjá láti lè gba ilẹ̀ náà tí Olúwa Ọlọ́run yín ń fún un yín. Nígbà tí ẹ bá gbà á, tí ẹ bá sì ń gbé ibẹ̀, 32 ẹ rí i dájú pé ẹ̀ ń gbọ́rọ̀ sí gbogbo ìlànà àti òfin tí mo ń gbé kalẹ̀ fún un yín lónìí.

Love and Serve the Lord

11 (A)“You shall therefore love the Lord your God and (B)keep his charge, his statutes, his rules, and his commandments always. And consider today (since I am not speaking to (C)your children who have not known or seen it), consider the discipline[a] of the Lord your God, (D)his greatness, (E)his mighty hand and his outstretched arm, (F)his signs and his deeds that he did in Egypt to Pharaoh the king of Egypt and to all his land, and what he did to the army of Egypt, to their horses and to their chariots, (G)how he made the water of the Red Sea flow over them as they pursued after you, and how the Lord has destroyed them to this day, and (H)what he did to you in the wilderness, until you came to this place, and (I)what he did to Dathan and Abiram the sons of Eliab, son of Reuben, how the earth opened its mouth and swallowed them up, with their households, their tents, and every living thing that followed them, in the midst of all Israel. For your eyes have seen (J)all the great work of the Lord that he did.

“You shall therefore keep the whole commandment that I command you today, that you may (K)be strong, and go in and take possession of the land that you are going over to possess, and (L)that you may live long in the land (M)that the Lord swore to your fathers to give to them and to their offspring, (N)a land flowing with milk and honey. 10 For the land that you are entering to take possession of it is not like the land of Egypt, from which you have come, where you sowed your seed and irrigated it,[b] like a garden of vegetables. 11 (O)But the land that you are going over to possess is a land of hills and valleys, which drinks water by the rain from heaven, 12 a land that the Lord your God cares for. (P)The eyes of the Lord your God are always upon it, from the beginning of the year to the end of the year.

13 “And if you will indeed obey my commandments that I command you today, (Q)to love the Lord your God, and to serve him with all your heart and with all your soul, 14 (R)he[c] will give the rain for your land in its season, (S)the early rain and the later rain, that you may gather in your grain and your wine and your oil. 15 (T)And he will give grass in your fields for your livestock, and (U)you shall eat and be full. 16 Take care (V)lest your heart be deceived, and you turn aside and (W)serve other gods and worship them; 17 then (X)the anger of the Lord will be kindled against you, and he (Y)will shut up the heavens, so that there will be no rain, and the land will yield no fruit, and (Z)you will perish quickly off the good land that the Lord is giving you.

18 (AA)“You shall therefore lay up these words of mine in your heart and in your soul, and (AB)you shall bind them as a sign on your hand, and they shall be as frontlets between your eyes. 19 You shall teach them to your children, talking of them when you are sitting in your house, and when you are walking by the way, and when you lie down, and when you rise. 20 (AC)You shall write them on the doorposts of your house and on your gates, 21 (AD)that your days and the days of your children may be multiplied in the land that the Lord swore to your fathers to give them, (AE)as long as the heavens are above the earth. 22 For if (AF)you will be careful to do all this commandment that I command you to do, loving the Lord your God, walking in all his ways, and (AG)holding fast to him, 23 then the Lord (AH)will drive out all these nations before you, and you will (AI)dispossess nations greater and mightier than you. 24 (AJ)Every place on which the sole of your foot treads shall be yours. Your territory shall be (AK)from the wilderness to[d] the Lebanon, and from the River, the river Euphrates, to the western sea. 25 (AL)No one shall be able to stand against you. The Lord your God will lay (AM)the fear of you and the dread of you on all the land that you shall tread, (AN)as he promised you.

26 (AO)“See, I am setting before you today a blessing and a curse: 27 (AP)the blessing, if you obey the commandments of the Lord your God, which I command you today, 28 and (AQ)the curse, if you do not obey the commandments of the Lord your God, but turn aside from the way that I am commanding you today, (AR)to go after other gods that you have not known. 29 And when the Lord your God brings you into the land that you are entering to take possession of it, you shall set (AS)the blessing on Mount Gerizim and the curse on Mount Ebal. 30 Are they not beyond the Jordan, west of the road, toward the going down of the sun, in the land of the Canaanites who live in the (AT)Arabah, opposite Gilgal, beside (AU)the oak[e] of Moreh? 31 For you are (AV)to cross over the Jordan to go in to take possession of the land that the Lord your God is giving you. And when you possess it and live in it, 32 you shall be careful (AW)to do all the statutes and the rules that I am setting before you today.

Footnotes

  1. Deuteronomy 11:2 Or instruction
  2. Deuteronomy 11:10 Hebrew watered it with your feet
  3. Deuteronomy 11:14 Samaritan, Septuagint, Vulgate; Hebrew I; also verse 15
  4. Deuteronomy 11:24 Hebrew and
  5. Deuteronomy 11:30 Septuagint, Syriac; see Genesis 12:6. Hebrew oaks, or terebinths