Amosi 2
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
2 (A)Èyí ni ohun tí Olúwa wí:
“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Moabu,
àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà,
Nítorí ó ti sun ún, di eérú,
egungun ọba Edomu
2 Èmi yóò rán iná sí orí Moabu
èyí tí yóò jó àwọn ààfin Kerioti run.
Moabu yóò sì kú pẹ̀lú ariwo
pẹ̀lú igbe àti pẹ̀lú ìró ìpè
3 Èmi yóò ké onídàájọ́ rẹ̀ kúrò
Èmi yóò sì pa gbogbo àwọn ọmọ-aládé rẹ́ nínú rẹ̀,”
ni Olúwa wí.
4 Èyí ni ohun tí Olúwa wí:
“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Juda,
àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà
Nítorí wọn ti kọ òfin Olúwa sílẹ̀
wọn kò sì pa àwọn ìlànà rẹ̀ mọ́
Nítorí àwọn òrìṣà ti sì wọ́n lọ́nà
òrìṣà tí àwọn Baba ńlá wọn ń tẹ̀lé
5 Èmi yóò rán iná sí orí Juda
èyí tí yóò jó àwọn ààfin Jerusalẹmu run.”
Ìdájọ́ tí yóò wá sórí Israẹli
6 Èyí ni ohun tí Olúwa wí:
“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta Israẹli
àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà.
Wọ́n ta olódodo fún fàdákà
àti aláìní fún bàtà ẹsẹ̀ méjèèjì.
7 Wọ́n fi ẹsẹ̀ tẹ orí àwọn tálákà mọ́lẹ̀
bí wọ́n ti ń tẹ erùpẹ̀ ilẹ̀
tí wọ́n ko sì ṣe òtítọ́ si àwọn tí a ni lára
Baba àti ọmọ ń wọlé tọ wúńdíá kan náà
Láti ba orúkọ mímọ́ mi jẹ́
8 Wọ́n dùbúlẹ̀ lẹ́bàá a pẹpẹ
Lórí aṣọ tí wọ́n ti jẹ́ ẹ̀jẹ́
ní ilé òrìṣà wọn
wọ́n sì mu ọtí tí wọ́n san fún ìtánràn.
9 “Mo pa àwọn ará Amori run níwájú wọn
gíga ẹni tí ó dàbí igi kedari.
Òun sì le koko bí igi óákù
mo pa èso rẹ̀ run láti òkè wá
àti egbò rẹ̀ láti ìsàlẹ̀ wá.
10 Èmi mú un yín gòkè láti ilẹ̀ Ejibiti wá,
mo sì sìn yín la aginjù já ní ogójì ọdún
láti fi ilẹ̀ àwọn ará Amori fún un yín.
11 “Èmi sì tún gbé àwọn wòlíì dìde láàrín àwọn ọmọ yín
àti láàrín àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin yín láti jẹ Nasiri
èyí kò ha jẹ́ òtítọ́ bí ará Israẹli?”
ni Olúwa wí.
12 “Ṣùgbọ́n ẹ̀yin fún àwọn Nasiri ní ọtí mu
e sì pàṣẹ fún àwọn wòlíì kí wọ́n má ṣe sọtẹ́lẹ̀.
13 “Ní báyìí, èmi yóò tẹ̀ yín mọ́lẹ̀
bí kẹ̀kẹ́ tí ó kún fún ìtí ti í tẹ̀.
14 Ẹni tí ó yára bí àṣá kò ní rí ọ̀nà àbáyọ
alágbára kò ní le è dúró lé agbára rẹ̀
jagunjagun kì yóò le gba ẹ̀mí ara rẹ̀ là
15 Tafàtafà kì yóò dúró lórí ẹsẹ̀ rẹ̀
bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ó gún ẹṣin
kì yóò gba ẹ̀mí ara rẹ̀ là
16 Àní jagunjagun tí ó gbóyà jùlọ
yóò sálọ ní ìhòhò ní ọjọ́ náà,”
ni Olúwa wí.
Amos 2
English Standard Version
2 Thus says the Lord:
(A)“For three transgressions of (B)Moab,
and for four, I will not revoke the punishment,[a]
because (C)he burned to lime
the bones of the king of Edom.
2 So I will send a fire upon Moab,
and it shall devour the strongholds of (D)Kerioth,
and Moab shall die amid uproar,
amid shouting and the sound of the trumpet;
3 (E)I will cut off the ruler from its midst,
and will kill (F)all its princes[b] with him,”
says the Lord.
Judgment on Judah
4 Thus says the Lord:
(G)“For three transgressions of Judah,
and for four, I will not revoke the punishment,
because (H)they have rejected the law of the Lord,
and have not kept his statutes,
but (I)their lies have led them astray,
those after which their fathers walked.
5 So (J)I will send a fire upon Judah,
and it shall devour the strongholds of Jerusalem.”
Judgment on Israel
6 Thus says the Lord:
(K)“For three transgressions of Israel,
and for four, I will not revoke the punishment,
because (L)they sell the righteous for (M)silver,
and the needy for a pair of sandals—
7 those who trample the head of the poor (N)into the dust of the earth
and (O)turn aside the way of the afflicted;
(P)a man and his father go in to the same girl,
so that my holy name is profaned;
8 they lay themselves down beside every altar
on garments (Q)taken in pledge,
and in the house of their God they drink
the wine of those who have been fined.
9 “Yet (R)it was I who destroyed the Amorite before them,
(S)whose height was like the height of the cedars
and who was as strong as the oaks;
(T)I destroyed his fruit above
and his roots beneath.
10 (U)Also it was I who brought you up out of the land of Egypt
(V)and led you forty years in the wilderness,
(W)to possess the land of the Amorite.
11 And I raised up some of your sons for prophets,
and some of your young men for (X)Nazirites.
Is it not indeed so, O people of Israel?”
declares the Lord.
12 “But you made the Nazirites (Y)drink wine,
and commanded the prophets,
saying, (Z)‘You shall not prophesy.’
13 “Behold, I will press you down in your place,
as a cart full of sheaves presses down.
14 (AA)Flight shall perish from the swift,
(AB)and the strong shall not retain his strength,
(AC)nor shall the mighty save his life;
15 he who handles the bow shall not stand,
and he who is (AD)swift of foot shall not save himself,
(AE)nor shall he who rides the horse save his life;
16 and he who is stout of heart among the mighty
shall flee away naked in that day,”
declares the Lord.
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.
The ESV® Bible (The Holy Bible, English Standard Version®), © 2001 by Crossway, a publishing ministry of Good News Publishers. ESV Text Edition: 2025.
