Add parallel Print Page Options

A o pa Israẹli run

Mo rí Olúwa, ó dúró ní ẹ̀bá pẹpẹ, ó sì wí pé:

“Lu orí àwọn àtẹ́rígbà ìlẹ̀kùn
    kí àwọn òpó kí ó lè mì
fọ́ wọn sí orí àwọn gbogbo ènìyàn
    àwọn tí ó ṣẹ́kù ni èmi yóò fi idà pa,
Ẹni tí ó sálọ nínú wọn kí yóò sá gbé
    Ẹni ti ó sá àsálà nínú wọn kí yóò gbàlà.
Bí wọ́n tilẹ̀ wa ilẹ̀ lọ sí ipò òkú
    Láti ibẹ̀ ni ọwọ́ mi yóò ti tẹ̀ wọ́n
Bí wọ́n tilẹ̀ gun òkè ọ̀run lọ,
    láti ibẹ̀ ni èmi yóò ti mú wọn sọ̀kalẹ̀.
Bí wọ́n tilẹ̀ fi ara wọn pamọ́ ni orí òkè Karmeli,
    èmi yóò wá wọn rí, Èmi yóò si mú wọn kúrò níbẹ̀.
Bí wọ́n tilẹ̀ fi ara pamọ́ fún mi sí ìsàlẹ̀ Òkun,
    láti ibẹ̀ ni Èmi yóò ti pàṣẹ fún ejò kí ó bù wọ́n ṣán.
Bí wọ́n tilẹ̀ lọ sí ìgbèkùn ní iwájú àwọn ọ̀tá wọn
    láti ibẹ̀ ni èmi yóò ti pàṣẹ fún idà kí ó ṣá wọn pa.

“Èmi yóò sì tẹ ojú mi mọ́ wọn fún ìbí,
    kì í sì í ṣe fún rere.”

Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun,
    ẹni ti ó fi ọwọ́ kan ilẹ̀ náà tí ó sì yọ́, tí àwọn olùgbé inú rẹ̀ yóò sì ṣọ̀fọ̀;
gbogbo orílẹ̀-èdè yóò si ru sókè bí ríru odò Naili
    tiwọn yóò sì tẹ̀rì bí odò Ejibiti.
Òun ni ẹni tí ó kọ́ ìtẹ́ rẹ̀ nínú àwọn ọ̀run
    ti ó sì fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ sọlẹ̀ ní ilé ayé
Ẹni ti ó pe àwọn omi Òkun
    ti ó sì tú wọn jáde si orí ilé ayé
    Olúwa ni orúkọ rẹ̀.

“Àbá ẹ̀yin ọmọ Israẹli
    kò ha dàbí àwọn ọmọ Kuṣi sí mi?”
    ni Olúwa wí.
“Èmi kò ha ti mú Israẹli gòkè láti ilẹ̀ Ejibiti jáde wá
    àti àwọn Filistini láti ilẹ̀ Kafitori
    àti àwọn ará Aramu láti Kiri?

“Dájúdájú, ojú Olúwa Olódùmarè
    ń bẹ̀ lára ilẹ̀ ọba tó kún fún ẹ̀ṣẹ̀.
Èmi yóò pa á run kúrò lórí ilẹ̀
    Síbẹ̀ Èmi kò nípa ilé Jakọbu run pátápátá,”
    ni Olúwa wí.
“Nítorí Èmi yóò pàṣẹ,
    Èmi yóò sì mi ilé Israẹli
    ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè
bí a ti ń jọ nǹkan nínú ajọ̀
    tí hóró kín ń kín kì yóò bọ́ sórí ilẹ̀.
10 Gbogbo àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ láàrín àwọn ènìyàn mi
    ni yóò ti ipa idà kú
gbogbo àwọn ti ń wí pé,
    ‘Aburú kì yóò lé wa bá, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò ká wa mọ́.’

Ìmúpadàbọ̀ Israẹli

11 (A)“Ní ọjọ́ náà ní
    Èmi yóò gbé àgọ́ Dafidi tí ó wó ró,
Èmi yóò dí odi rẹ̀ tí ó ya,
    Èmi yóò sì gbé ahoro rẹ̀ sókè,
    Èmi yóò sì kọ bí ti ọjọ́ ìgbàanì,
12 kí wọn le jogún ìyókù Edomu
    àti gbogbo àwọn kèfèrí, ti a ń pè nípa orúkọ mi,”
    ni Olúwa, ẹni tí yóò ṣe nǹkan wọ̀nyí wí.

13 (B)“Ọjọ́ náà ń bọ,” ni Olúwa wí,

“tí ẹni tí ń tulẹ̀ yóò lé ẹni tí ń kórè bá
    Tí ẹni tí ń fún èso àjàrà yóò lé ẹni tí ń gbìn bá
Àwọn òkè ńlá yóò sì kán ọtí wáìnì sílẹ̀
    Tí yóò sì sàn láti ara àwọn òkè kéékèèkéé.
14     Èmi yóò si tún mú ìgbèkùn Israẹli ènìyàn mi padà bọ̀.

“Wọn yóò sì kọ́ ahoro ìlú, wọn yóò sì máa gbé inú wọn
    Wọn yóò sì gbin ọgbà àjàrà, wọn yóò sì mu ọtí wáìnì wọn
    wọn yóò sì ṣe ọgbà pẹ̀lú, wọn yóò sì jẹ èso inú wọn
15 Èmi yóò gbin Israẹli sí orí ilẹ̀ rẹ̀.
    A kì yóò sì fà wọn tu mọ́ láéláé
    kúrò ni orí ilẹ̀ ti mo fi fún wọn,”

ni Olúwa Ọlọ́run rẹ wí.

Israel to Be Destroyed

I saw the Lord standing by the altar, and he said:

“Strike the tops of the pillars
    so that the thresholds shake.
Bring them down on the heads(A) of all the people;
    those who are left I will kill with the sword.
Not one will get away,
    none will escape.(B)
Though they dig down to the depths below,(C)
    from there my hand will take them.
Though they climb up to the heavens above,(D)
    from there I will bring them down.(E)
Though they hide themselves on the top of Carmel,(F)
    there I will hunt them down and seize them.(G)
Though they hide from my eyes at the bottom of the sea,(H)
    there I will command the serpent(I) to bite them.(J)
Though they are driven into exile by their enemies,
    there I will command the sword(K) to slay them.

“I will keep my eye on them
    for harm(L) and not for good.(M)(N)

The Lord, the Lord Almighty—
he touches the earth and it melts,(O)
    and all who live in it mourn;
the whole land rises like the Nile,
    then sinks like the river of Egypt;(P)
he builds his lofty palace[a](Q) in the heavens
    and sets its foundation[b] on the earth;
he calls for the waters of the sea
    and pours them out over the face of the land—
    the Lord is his name.(R)

“Are not you Israelites
    the same to me as the Cushites[c]?”(S)
declares the Lord.
“Did I not bring Israel up from Egypt,
    the Philistines(T) from Caphtor[d](U)
    and the Arameans from Kir?(V)

“Surely the eyes of the Sovereign Lord
    are on the sinful kingdom.
I will destroy(W) it
    from the face of the earth.
Yet I will not totally destroy
    the descendants of Jacob,”
declares the Lord.(X)
“For I will give the command,
    and I will shake the people of Israel
    among all the nations
as grain(Y) is shaken in a sieve,(Z)
    and not a pebble will reach the ground.(AA)
10 All the sinners among my people
    will die by the sword,(AB)
all those who say,
    ‘Disaster will not overtake or meet us.’(AC)

Israel’s Restoration

11 “In that day

“I will restore David’s(AD) fallen shelter(AE)
    I will repair its broken walls
    and restore its ruins(AF)
    and will rebuild it as it used to be,(AG)
12 so that they may possess the remnant of Edom(AH)
    and all the nations that bear my name,[e](AI)
declares the Lord, who will do these things.(AJ)

13 “The days are coming,”(AK) declares the Lord,

“when the reaper(AL) will be overtaken by the plowman(AM)
    and the planter by the one treading(AN) grapes.
New wine(AO) will drip from the mountains
    and flow from all the hills,(AP)
14     and I will bring(AQ) my people Israel back from exile.[f](AR)

“They will rebuild the ruined cities(AS) and live in them.
    They will plant vineyards(AT) and drink their wine;
    they will make gardens and eat their fruit.(AU)
15 I will plant(AV) Israel in their own land,(AW)
    never again to be uprooted(AX)
    from the land I have given them,”(AY)

says the Lord your God.(AZ)

Footnotes

  1. Amos 9:6 The meaning of the Hebrew for this phrase is uncertain.
  2. Amos 9:6 The meaning of the Hebrew for this word is uncertain.
  3. Amos 9:7 That is, people from the upper Nile region
  4. Amos 9:7 That is, Crete
  5. Amos 9:12 Hebrew; Septuagint so that the remnant of people / and all the nations that bear my name may seek me
  6. Amos 9:14 Or will restore the fortunes of my people Israel