Add parallel Print Page Options

Agbọ̀n èso pípọ́n

Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè fihàn mi: agbọ̀n èso pípọ́n. Ó béèrè pé, “Amosi kí ni ìwọ rí.”

Mo sì dáhùn pé, “Agbọ̀n èso pípọ́n.”

Nígbà náà ni Olúwa wí fún mi pé, “Àsìkò náà pọ́n tó fún àwọn ènìyàn mi Israẹli; Èmi kì yóò dá wọn sí mọ́.”

Olúwa Olódùmarè wí pé, “Ní ọjọ́ náà, àwọn orin tẹmpili yóò yí padà sí ohùn réré ẹkún. Ọ̀pọ̀, àní ọ̀pọ̀ ara òkú ni yóò wà ni ibi gbogbo! Àní ni ìdákẹ́ jẹ́ẹ́!”

Ẹ gbọ́ èyí, ẹ̀yin tí ń tẹ aláìní lórí ba,
    tí ẹ sì ń sọ tálákà di ilẹ̀.

Tí ẹ ń wí pé,

“Nígbà wo ni oṣù tuntun yóò parí
    kí àwa bá à lè ta ọkà
kí ọjọ́ ìsinmi kí ó lè dópin
    kí àwa bá à le ta jéró?”
Kí a sì dín ìwọ̀n wa kù
    kí a gbéraga lórí iye tí a ó tà á
    kí a sì fi òṣùwọ̀n èké yàn wọ́n jẹ
Kí àwa lè fi fàdákà ra àwọn tálákà
    kí a sì fi bàtà ẹsẹ̀ méjèèjì ra aláìní
    kí a sì ta jéró tí a kó mọ́ ilẹ̀.

Olúwa ti fi ìgbéraga Jakọbu búra pé: “Èmi kì yóò gbàgbé ọ̀kan nínú ohun tí wọ́n ṣe.

“Ǹjẹ́ ilẹ̀ náà kì yóò ha wárìrì fún èyí?
    Àwọn tí ń gbé inú rẹ̀ kì yóò ha ṣọ̀fọ̀?
Gbogbo ilẹ̀ yóò ru sókè bí omi Naili,
    yóò sì ru ú sókè pátápátá bí ìkún omi
    a ó sì tì í jáde, a ó sì tẹ̀ ẹ́ rì gẹ́gẹ́ bí odò Ejibiti.

“Yóò sì ṣe ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa Olódùmarè wí,

“Èmi yóò mú oòrùn wọ̀ ní ọ̀sán,
    Èmi yóò mú kí ayé ṣókùnkùn ní ọ̀sán gangan.
10 Èmí yóò yí àsè ẹ̀sìn yín padà sí ọ̀fọ̀,
    gbogbo orin yín ni èmi yóò sọ di ẹkún.
Èmi yóò mú kí gbogbo yín wọ aṣọ ọ̀fọ̀,
    kí a sì fá orí yín.
Èmi yóò mú kí ìgbà náà rí bí ìṣọ̀fọ̀ fún ọmọkùnrin
    kan ṣoṣo tí a bí àti òpin rẹ̀ bí ọjọ́ kíkorò.

11 “Ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa Olódùmarè wí,
    “nígbà tí èmi yóò rán ìyàn sí ilẹ̀ náà,
kì í ṣe ìyàn oúnjẹ tàbí òǹgbẹ fún omi.
    Ṣùgbọ́n ìyàn gbígbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa.
12 Àwọn ènìyàn yóò rìn kiri láti Òkun dé Òkun
    wọn yóò sì máa rìn ká láti gúúsù sí àríwá,
wọn yóò máa wá ọ̀rọ̀ Olúwa
    ṣùgbọ́n wọn kì yóò rí i.

13 “Ní ọjọ́ náà

“àwọn arẹwà wúńdíá àti àwọn alágbára ọ̀dọ́mọkùnrin
    yóò dákú fún òǹgbẹ omi.
14 Àwọn tí ó fi ẹ̀ṣẹ̀ Samaria búra,
    tí wọ́n sì wí pé, ‘Bí ó ti dájú pé ọlọ́run rẹ ń bẹ láààyè, ìwọ Dani,’
    Bí ó ti dájú pè ọlọ́run rẹ ń bẹ láààyè, ìwọ Beerṣeba
Wọ́n yóò ṣubú,
    Wọn kì yóò si tún dìde mọ.”

A Basket of Ripe Fruit

This is what the Sovereign Lord showed me:(A) a basket of ripe fruit. “What do you see,(B) Amos?(C)” he asked.

“A basket(D) of ripe fruit,” I answered.

Then the Lord said to me, “The time is ripe for my people Israel; I will spare them no longer.(E)

“In that day,” declares the Sovereign Lord, “the songs in the temple will turn to wailing.[a](F) Many, many bodies—flung everywhere! Silence!(G)

Hear this, you who trample the needy
    and do away with the poor(H) of the land,(I)

saying,

“When will the New Moon(J) be over
    that we may sell grain,
and the Sabbath be ended
    that we may market(K) wheat?”(L)
skimping on the measure,
    boosting the price
    and cheating(M) with dishonest scales,(N)
buying the poor(O) with silver
    and the needy for a pair of sandals,
    selling even the sweepings with the wheat.(P)

The Lord has sworn by himself, the Pride of Jacob:(Q) “I will never forget(R) anything they have done.(S)

“Will not the land tremble(T) for this,
    and all who live in it mourn?
The whole land will rise like the Nile;
    it will be stirred up and then sink
    like the river of Egypt.(U)

“In that day,” declares the Sovereign Lord,

“I will make the sun go down at noon
    and darken the earth in broad daylight.(V)
10 I will turn your religious festivals(W) into mourning
    and all your singing into weeping.(X)
I will make all of you wear sackcloth(Y)
    and shave(Z) your heads.
I will make that time like mourning for an only son(AA)
    and the end of it like a bitter day.(AB)

11 “The days are coming,”(AC) declares the Sovereign Lord,
    “when I will send a famine through the land—
not a famine of food or a thirst for water,
    but a famine(AD) of hearing the words of the Lord.(AE)
12 People will stagger from sea to sea
    and wander from north to east,
searching for the word of the Lord,
    but they will not find it.(AF)

13 “In that day

“the lovely young women and strong young men(AG)
    will faint because of thirst.(AH)
14 Those who swear by the sin of Samaria(AI)
    who say, ‘As surely as your god lives, Dan,’(AJ)
    or, ‘As surely as the god[b] of Beersheba(AK) lives’—
    they will fall,(AL) never to rise again.(AM)

Footnotes

  1. Amos 8:3 Or “the temple singers will wail
  2. Amos 8:14 Hebrew the way