Amosi 3
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
Ẹ̀rí jíjẹ́ nípa àwọn ọmọ Israẹli
3 Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ tí Ọlọ́run ti sọ nípa rẹ̀, ẹ̀yin ènìyàn Israẹli nípa àwọn ìdílé tí mo mú jáde láti Ejibiti:
2 “Ìwọ nìkan ni ẹni tí mo yàn
nínú gbogbo àwọn ìran ayé yìí;
nígbà náà èmi ó jẹ ọ́ ní yà
fún gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ.”
3 Ẹni méjì ha à le rìn pọ̀
láìjẹ́ pé wọ́n ti pinnu láti ṣe bẹ?
4 Ǹjẹ́ Kìnnìún yóò ha bú ramúramù nínú igbó,
bí kò bá ní ohun ọdẹ?
Ọmọ kìnnìún yóò ha ké jáde nínú ìhó rẹ̀
bí kò bá rí ohun kan mú?
5 Ǹjẹ́ ẹyẹ ṣubú sínú okùn ọdẹ lórí ilẹ̀
nígbà tí a kò dẹ okùn ọdẹ fún un?
Okùn ọdẹ ha lè hù jáde lórí ilẹ̀
nígbà tí kò sí ohun tí yóò mú?
6 Nígbà tí ìpè bá dún ní ìlú,
àwọn ènìyàn kò ha bẹ̀rù?
Tí ewu bá wa lórí ìlú
kò ha ṣe Olúwa ni ó fà á?
7 (A)Nítòótọ́ Olúwa Olódùmarè kò ṣe ohun kan
láìfi èrò rẹ̀ hàn
fun àwọn wòlíì ìránṣẹ́ rẹ̀.
8 Kìnnìún ti bú ramúramù
ta ni kì yóò bẹ̀rù?
Olúwa Olódùmarè ti sọ̀rọ̀
ta ni le ṣe àìsọ àsọtẹ́lẹ̀?
9 Ẹ kéde ní ààfin Aṣdodu
àti ní ààfin ní ilẹ̀ Ejibiti.
“Ẹ kó ara yín jọ sí orí òkè ńlá Samaria;
Kí ẹ sì wo ìrọ́kẹ̀kẹ̀ ńlá láàrín rẹ̀
àti ìnilára láàrín àwọn ènìyàn rẹ.”
10 “Wọn kò mọ bí wọ́n ṣe ń ṣe rere,” ni Olúwa wí,
“àwọn ẹni tí ó gba àwọn ìwà ipá àti olè sí ààfin rẹ̀.”
11 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí:
“Àwọn ọ̀tá yóò pa ilẹ̀ náà run;
yóò wó ibi gíga yín palẹ̀
a ó sì ba ààfin rẹ̀ jẹ́.”
12 Èyí ni ohun tí Olúwa wí:
“Bí olusọ-àgùntan ti ń gbà itan méjì
kúrò ní ẹnu kìnnìún tàbí ẹ̀là etí kan
bẹ́ẹ̀ ni a ó mú àwọn ọmọ Israẹli,
tí ń gbé Samaria kúrò
ní igun ibùsùn wọn
ní orí àga ìrọ̀gbọ̀kú wọn ní Damasku.”
13 “Gbọ́ èyí kí o sì jẹ́rìí nípa ilé Jakọbu,” ni Olúwa wí, Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun.
14 “Ní ọjọ́ tí mo fìyà jẹ Israẹli lórí ẹ̀ṣẹ̀ wọn,
Èmi yóò pa pẹpẹ Beteli run;
ìwo pẹpẹ ni a ó ké kúrò
yóò sì wó lulẹ̀.
15 Èmi yóò wó ilé òtútù
lulẹ̀ pẹ̀lú ilé ooru;
ilé tí a fi eyín erin ṣe lọ́ṣọ̀ọ́ yóò ṣègbé
a ó sì pa ilé ńlá náà run,”
ni Olúwa wí.
Amos 3
New International Version
Witnesses Summoned Against Israel
3 Hear this word, people of Israel, the word the Lord has spoken against you(A)—against the whole family I brought up out of Egypt:(B)
2 “You only have I chosen(C)
of all the families of the earth;
therefore I will punish(D) you
for all your sins.(E)”
3 Do two walk together
unless they have agreed to do so?
4 Does a lion roar(F) in the thicket
when it has no prey?(G)
Does it growl in its den
when it has caught nothing?
5 Does a bird swoop down to a trap on the ground
when no bait(H) is there?
Does a trap spring up from the ground
if it has not caught anything?
6 When a trumpet(I) sounds in a city,
do not the people tremble?
When disaster(J) comes to a city,
has not the Lord caused it?(K)
7 Surely the Sovereign Lord does nothing
without revealing his plan(L)
to his servants the prophets.(M)
8 The lion(N) has roared(O)—
who will not fear?
The Sovereign Lord has spoken—
who can but prophesy?(P)
9 Proclaim to the fortresses of Ashdod(Q)
and to the fortresses of Egypt:
“Assemble yourselves on the mountains of Samaria;(R)
see the great unrest within her
and the oppression among her people.”
10 “They do not know how to do right,(S)” declares the Lord,
“who store up in their fortresses(T)
what they have plundered(U) and looted.”
11 Therefore this is what the Sovereign Lord says:
“An enemy will overrun your land,
pull down your strongholds
and plunder your fortresses.(V)”
12 This is what the Lord says:
“As a shepherd rescues from the lion’s(W) mouth
only two leg bones or a piece of an ear,
so will the Israelites living in Samaria be rescued,
with only the head of a bed
and a piece of fabric[a] from a couch.[b](X)”
13 “Hear this and testify(Y) against the descendants of Jacob,” declares the Lord, the Lord God Almighty.
14 “On the day I punish(Z) Israel for her sins,
I will destroy the altars of Bethel;(AA)
the horns(AB) of the altar will be cut off
and fall to the ground.
15 I will tear down the winter house(AC)
along with the summer house;(AD)
the houses adorned with ivory(AE) will be destroyed
and the mansions(AF) will be demolished,(AG)”
declares the Lord.(AH)
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.
Holy Bible, New International Version®, NIV® Copyright ©1973, 1978, 1984, 2011 by Biblica, Inc.® Used by permission. All rights reserved worldwide.
NIV Reverse Interlinear Bible: English to Hebrew and English to Greek. Copyright © 2019 by Zondervan.