Add parallel Print Page Options

Wò mí kí o sì yè

Gbọ́ ọ̀rọ̀ yìí, ìwọ ilé Israẹli, ìpohùnréré ẹkún tí mo ṣe nípa rẹ:

“Wúńdíá Israẹli ṣubú
    láì kò sì le padà dìde
ó di ẹni ìkọ̀tì ní ilẹ̀ rẹ̀
    kò sí ẹni tí yóò gbé e dìde.”

Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí:

“Ìlú tí ẹgbẹ̀rún alágbára ti jáde,
    yóò dín ku ọgọ́ọ̀rún ní Israẹli.
Ìlú tí ọgọ́ọ̀rún alàgbà ti jáde
    yóò ṣẹ́kù ẹni mẹ́wàá.”

Èyí ni ohun tí Olúwa sọ fún ilé Israẹli:

“Wá mi kí o sì yè;
    Ẹ má ṣe wá Beteli,
Ẹ má ṣe lọ sí Gilgali
    Ẹ má ṣe rìnrìn àjò lọ sí Beerṣeba.
Nítorí dájúdájú a ó kó Gilgali ní ìgbèkùn
    A ó sì sọ Beteli di asán.”
Ẹ wá Olúwa, ẹ̀yin yóò sì yè,
    kí ó má ba à gbilẹ̀ bí iná ní Josẹfu
a sì jó o run
    Beteli kò sì ní rí ẹni tí yóò bu omi pa á.

Ẹ̀yin tí ẹ̀ sọ òdodo di ìkorò
    tí ẹ sì gbé olódodo ṣánlẹ̀.

Ẹni tí ó dá ìràwọ̀ Pleiadesi àti Orioni
    ẹni tí ó sọ òru dúdú di òwúrọ̀
    tí ó sọ ọjọ́ dúdú di ìmọ́lẹ̀
ẹni tí ó wọ́ omi Òkun jọ pọ̀
    tí ó sì rọ̀ wọ́n sí orí ilẹ̀
    Olúwa ni orúkọ rẹ̀,
Ó fọ́n ìparun sí ìlú olódi
    tí ó sì sọ àwọn ibùgbé àwọn ọmọ-aládé di ahoro.

10 Ìwọ kórìíra ẹni tí ń bá ni wí ní ẹnu ibodè
    ó sì ń pẹ̀gàn ẹni tí ń sọ òtítọ́.

11 Ìwọ ń tẹ tálákà mọ́lẹ̀
    o ń fi ipá gba ọkà lọ́wọ́ wọn
Nítorí náà, ìwọ ti fi òkúta tí a gbẹ́ kọ́lé
    ṣùgbọ́n ẹ kò sì ní gbé inú wọn
Nítòótọ́ ìwọ ti gbin ọgbà àjàrà tí ó lẹ́wà.
    Ìwọ kò ní mu wáìnì inú wọn
12 Nítorí mo mọ iye àìṣedéédéé rẹ
    mo sì mọ bí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ tí tóbi tó.

Ìwọ ni olódodo lára, ìwọ sì ń gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀
    o sì ń fi òtítọ́ du tálákà ní ilé ẹjọ́
13 Àwọn ọlọ́gbọ́n máa ń dákẹ́ jẹ́ẹ́ ní àkókò wọ̀nyí,
    nítorí búburú ni gbogbo ọjọ́.

14 Wá rere, má ṣe wá búburú
    kí ìwọ ba à le yè
Nígbà náà ni Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun yóò wà pẹ̀lú rẹ.
    Òun yóò sì wà pẹ̀lú rẹ bí ìwọ ṣe wí
15 Kórìíra búburú kí o sì fẹ́ rere
    dúró ní orí òtítọ́ ní ilé ẹjọ́
bóyá Olúwa Ọlọ́run alágbára
    yóò ṣíjú àánú wo ọmọ Josẹfu tó ṣẹ́kù.

16 Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa, Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun wí:

“Ẹkún yóò wà ní àwọn òpópónà
    igbe ìnira yóò sì wà ní àwọn gbàgede ìlú
A ó kó àwọn àgbẹ̀ jọ láti sọkún
    àti àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀ láti pohùnréré ẹkún
17 Ìpohùnréré ẹkún yóò wà ní gbogbo ọgbà àjàrà
    Nítorí èmi yóò la àárín yín kọjá,”
    ni Olúwa wí.

Ọjọ́ Olúwa

18 Ègbé ni fún ìwọ tí ó pẹ́
    nítorí ọjọ́ Olúwa
kí ni ìwọ fi pẹ́ fún ọjọ́ Olúwa?
    Ìmọ́lẹ̀ yóò di òkùnkùn ní ojú ọjọ́
19 Gẹ́gẹ́ bí ènìyàn tí ó sá fún kìnnìún,
    tí ó padà wá bọ́ sí ẹnu àmọ̀tẹ́kùn.
Yóò dàbí ẹni tí ó wọ ilé rẹ̀ lọ
    tí ó sinmi lé ògiri ilé rẹ̀
    tí ejò sì bù ú ṣán.
20 Ǹjẹ́ ọjọ́ Olúwa kò ha ní ṣókùnkùn dípò kí ó ní ìmọ́lẹ̀?
    Tí yóò sì ṣókùnkùn dúdú láìsí ìmọ́lẹ̀ kankan níbẹ̀.

21 “Mo kórìíra, mo kẹ́gàn àwọn àsè ẹ̀sìn in yín
    Èmi kò sì ní inú dídùn sí àpéjọ yín
22 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹ mú ẹbọ sísun àti ọrẹ ọkà wá
    Èmi kò ní tẹ́wọ́ gbà wọ́n
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹ mú àṣàyàn ọrẹ àlàáfíà wá.
    Èmi kò ní náání wọn.
23 Ẹ gbé ariwo orin yín sẹ́yìn
    Èmi kò ní fetísí ohun èlò orin yín.
24 Jẹ́ kí òtítọ́ sàn bí odò
    àti òdodo bí ìsun tí kò lé è gbẹ!

25 (A)“Àbí ẹ̀yin mú ẹbọ àti ọrẹ tọ̀ mí wá
    ní ogójì ọdún ní aginjù ìwọ ilé Israẹli?
26 Ẹ̀yin ti gbé ibi ìrúbọ àwọn ọba yín sókè
    ibùgbé àwọn òrìṣà yín
    àní, ti àwọn òrìṣà yín tí ó níyì jùlọ,
    èyí tí ẹ̀yin fi ọwọ́ ara yín ṣe.
27 Nítorí náà èmi yóò rán an yín lọ sí ìgbèkùn ní ìkọjá Damasku,”
    ni Olúwa wí, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Ọlọ́run alágbára.

Lamento su Israele

Ascoltate queste parole,
questo lamento che io pronunzio su di voi,
o casa di Israele!
E' caduta, non si alzerà più,
la vergine d'Israele;
è stesa al suolo,
nessuno la fa rialzare.
Poiché così dice il Signore Dio:
La città che usciva con mille uomini
resterà con cento
e la città di cento
resterà con dieci, nella casa d'Israele.

Senza conversione non c'è salvezza

Poiché così dice il Signore alla casa d'Israele:
Cercate me e vivrete!
Non rivolgetevi a Betel,
non andate a Gàlgala,
non passate a Bersabea,
perchè Gàlgala andrà tutta in esilio
e Betel sarà ridotta al nulla.
Cercate il Signore e vivrete,
perchè egli non irrompa come fuoco
sulla casa di Giuseppe e la consumi
e nessuno spenga Betel!
Essi trasformano il diritto in veleno
e gettano a terra la giustizia.

Dossologia

Colui che ha fatto le Pleiadi e Orione,
cambia il buio in chiarore del mattino
e stende sul giorno l'oscurità della notte;
colui che comanda alle acque del mare
e le spande sulla terra,
Signore è il suo nome.
Egli fa cadere la rovina sulle fortezze
e fa giungere la devastazione sulle cittadelle.

Minacce

10 Essi odiano chi ammonisce alla porta
e hanno in abominio chi parla secondo verità.
11 Poiché voi schiacciate l'indigente
e gli estorcete una parte del grano,
voi che avete costruito case in pietra squadrata,
non le abiterete;
vigne deliziose avete piantato,
ma non ne berrete il vino,
12 perché so che numerosi sono i vostri misfatti,
enormi i vostri peccati.
Essi sono oppressori del giusto, incettatori di ricompense
e respingono i poveri nel tribunale.
13 Perciò il prudente in questo tempo tacerà,
perchè sarà un tempo di sventura.

Esortazioni

14 Cercate il bene e non il male,
se volete vivere,
e così il Signore, Dio degli eserciti,
sia con voi, come voi dite.
15 Odiate il male e amate il bene
e ristabilite nei tribunali il diritto;
forse il Signore, Dio degli eserciti,
avrà pietà del resto di Giuseppe.

Imminenza del castigo

16 Perciò così dice il Signore,
Dio degli eserciti, il Signore:
In tutte le piazze vi sarà lamento,
in tutte le strade si dirà: Ah! ah!
Si chiamerà l'agricoltore a fare il lutto
e a fare il lamento quelli che conoscono la nenia.
17 In tutte le vigne vi sarà lamento,
perchè io passerò in mezzo a te,
dice il Signore.

Il giorno del Signore

18 Guai a coloro che attendono il giorno del Signore!
Che sarà per voi il giorno del Signore?
Sarà tenebre e non luce.
19 Come quando uno fugge davanti al leone
e s'imbatte in un orso;
entra in casa, appoggia la mano sul muro
e un serpente lo morde.
20 Non sarà forse tenebra e non luce
il giorno del Signore,
e oscurità senza splendore alcuno?

Contro il culto esteriore

21 Io detesto, respingo le vostre feste
e non gradisco le vostre riunioni;
22 anche se voi mi offrite olocausti,
io non gradisco i vostri doni
e le vittime grasse come pacificazione
io non le guardo.
23 Lontano da me il frastuono dei tuoi canti:
il suono delle tue arpe non posso sentirlo!
24 Piuttosto scorra come acqua il diritto
e la giustizia come un torrente perenne.
25 Mi avete forse offerto vittime
e oblazioni nel deserto
per quarant'anni, o Israeliti?
26 Voi avete innalzato Siccùt vostro re
e Chiiòn vostro idolo,
la stella dei vostri dei che vi siete fatti.
27 Ora, io vi manderò in esilio
al di là di Damasco, dice il Signore,
il cui nome è Dio degli eserciti.