Add parallel Print Page Options

Amasiah ọba Juda

25 (A)Amasiah jẹ́ ẹni ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mọ́kàn-dínlọ́gbọ̀n (29) Orúkọ ìyá rẹ̀ a máa jẹ́ Jehoadani, ó wá láti Jerusalẹmu. Ó ṣe ohun tí ó dára lójú Olúwa, ṣùgbọ́n kì í ṣe tọkàntọkàn. Lẹ́yìn tí ìjọba ti wà ní ìdarí rẹ̀, ó pa àwọn oníṣẹ́ tí ó pa baba rẹ̀ ọba. Síbẹ̀ kò pa àwọn ọmọ wọn, ṣùgbọ́n ó ṣe ní ìbámu pẹ̀lú ohun tí a kọ nínú òfin nínú ìwé Mose, níbi tí Olúwa ti paláṣẹ pé: “A kò gbọdọ̀ pa àwọn baba fún àwọn ọmọ wọn tàbí àwọn ọmọ fún baba wọn; Olúkúlùkù ni kí ó kú fún ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.”

Amasiah, pe gbogbo àwọn ènìyàn Juda pọ̀, ó sì fi iṣẹ́ lé wọn lọ́wọ́ gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn sí àwọn alákòóso ẹgbẹgbẹ̀rún àti àwọn alákòóso ọ̀rọ̀ọ̀rún fún gbogbo Juda àti Benjamini, ó sì gbá iye wọn láti ẹni ogún ọdún àti jù bẹ́ẹ̀ lọ jọ, ó sì rí i pé ọ̀kẹ́ mẹ́ẹ̀ẹ́dógún (300,000) àwọn ọkùnrin ni ó ti múra fún ìsìn ogun, tí ó lè gbá ọ̀kọ̀ àti àpáta mú. Ó sì yá (100,000) ọ̀kẹ́ márùn-ún àwọn ọkùnrin oníjà láti Israẹli fún ọgọ́rùn-ún mẹ́wàá àwọn tálẹ́ǹtì fàdákà.

Ṣùgbọ́n ènìyàn Ọlọ́run kan tọ̀ ọ́ wá ó sì wí pé, “ọba, àwọn ọ̀wọ́ ogun láti Israẹli kò gbọdọ̀ yan pẹ̀lú rẹ, nítorí tí Olúwa kò wà pẹ̀lú Israẹli kì í ṣe pẹ̀lú ẹnìkankan láti Efraimu. Àní, tí ẹ bá lọ jà pẹ̀lú ìmúláyàle ní ojú ogun, Ọlọ́run yóò bì ọ́ ṣubú níwájú àwọn ọ̀tá, nítorí Ọlọ́run ní agbára láti ràn ọ́ lọ́wọ́ àti láti bì ọ́ ṣubú.”

Amasiah sì bi ènìyàn Ọlọ́run pé, “Ọgọ́rùn-ún tálẹ́ǹtì tí mo ti san fún àwọn ọ̀wọ́ ogun àwọn ọmọ Israẹli ńkọ́?”

Ènìyàn Ọlọ́run dáhùn pé “Olúwa lè fún ọ ní èyí tí ó ju ìyẹn lọ.”

10 Bẹ́ẹ̀ ni Amasiah, tú àwọn ọwọ́ ogun tí ó ti wá sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ láti Efraimu ká. Ó sì rán wọn lọ ilé. Wọ́n kún fún ìbínú pẹ̀lú Juda, wọ́n sì padà lọ ilé pẹ̀lú ìbínú ńlá.

11 (B)Nígbà náà, Amasiah ko ogun rẹ jọ àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ lọ sí Àfonífojì iyọ̀, níbi tí ó ti pa ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá (10,000) àwọn ọkùnrin Seiri. 12 Àwọn ọkùnrin Juda pẹ̀lú fi agbára mú àwọn ọkùnrin ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá láààyè. Wọ́n mú wọn lọ sí orí òkè bèbè òkúta, wọ́n jù wọ́n sílẹ̀, kí gbogbo wọn sì fọ́ sí wẹ́wẹ́.

13 Ní báyìí àwọn ọ̀wọ́ ogun tí Amasiah ti rán lọ padà, tí wọn kò nípa nínú ogun gbógun sí àwọn ìlú Juda láti Samaria sí Beti-Horoni. Wọ́n pa ẹgbẹ̀rún mẹ́ta nínú wọn, wọ́n sì kó ọ̀pọ̀ ìkógun ńlá.

14 Nígbà tí Amasiah padà láti ibi pípa àwọn ará Edomu, ó mú àwọn ọlọ́run àwọn ènìyàn Seiri padà wá. Ó gbé wọn kalẹ̀ gẹ́gẹ́ bi àwọn ọlọ́run tirẹ̀. Ó tẹríba fún wọn, ó sì rú ẹbọ fún wọn. 15 Ìbínú Olúwa ru sí Amasiah, ó sì rán wòlíì kan sí i, tí ó wí pé, “kí ni ó dé tí ìwọ fi ń béèrè lọ́wọ́ àwọn ọlọ́run àwọn ènìyàn yìí, tí wọn kò le gba àwọn ènìyàn tiwọn kúrò lọ́wọ́ rẹ?”

16 Bí ó ti n sọ̀rọ̀, ọba wí fún un pé, “Ṣé a yàn ọ́ ní olùgba ọba lámọ̀ràn ni? Dúró! Èéṣe tí a ó fi lù ọ́ bolẹ̀?”

Bẹ́ẹ̀ ni, wòlíì náà dúró ṣùgbọ́n ó wí pé, “Èmi mọ̀ pé Ọlọ́run ti pinnu láti pa ọ́ run nítorí ìwọ ti ṣe èyí, ìwọ kò sì tẹ́tí sí ìmọ̀ràn mi.”

17 (C)Lẹ́yìn tí Amasiah ọba Juda ti béèrè lọ́wọ́ àwọn olùdámọ̀ràn, ó rán ìpèníjà yìí sí Jehoaṣi ọmọ Jehoahasi ọmọ Jehu, ọba Israẹli pé: “Wá bá mi lójúkojú.”

18 Ṣùgbọ́n Jehoaṣi ọba Israẹli fèsì padà sí Amasiah ọba Juda pé, “koríko kékeré kan ní Lebanoni rán iṣẹ́ sí igi kedari ní Lebanoni, fi ọmọbìnrin rẹ fún ọmọkùnrin mi ní ìgbéyàwó. Nígbà náà, ẹhànnà ẹranko ènìyàn ni Lebanoni wá, ó sì tẹ òṣùṣú náà lábẹ́ ẹsẹ̀. 19 Ìwọ wí fún ara à rẹ wí pé, ìwọ ti ṣẹ́gun Edomu àti nísinsin yìí ìwọ ní ìhàlẹ̀ àti ìgbéraga. Ṣùgbọ́n dúró ní ilé! Kí ni ó dé tí ìwọ fi ń wá wàhálà tí o sì fi ń fa ìṣubú rẹ àti ti Juda pẹ̀lú?”

20 Amasiah, bí ó tì wù kí ó rí kò tẹ́tí nítorí Ọlọ́run ṣe é kí ó lè gbé wọn lé Jehoaṣi lọ́wọ́: nítorí wọ́n wá àwọn ọlọ́run Edomu. 21 Bẹ́ẹ̀ ni Jehoaṣi, ọba Israẹli: òun àti Amasiah ọba Juda dojúkọ ara wọn ní Beti-Ṣemeṣi ní Juda. 22 Àwọn ọmọ Israẹli da Juda rú, gbogbo olúkúlùkù ènìyàn sì sálọ sí ìlú rẹ̀. 23 Jehoaṣi ọba Israẹli fi agbára mú Amasiah ọba Juda, ọmọ Joaṣi ọmọ Ahasiah ní Beti-Ṣemeṣi. Nígbà náà Joaṣi mú u wá sí Jerusalẹmu. Ó sì wó ògiri Jerusalẹmu lulẹ̀ láti ẹnu-ọ̀nà Efraimu sí igun ẹnu-ọ̀nà apá kan títí ń lọ sí ọgọ́rùn-ún mẹ́fà ẹsẹ̀ bàtà ní gígùn. 24 Ọba kó gbogbo wúrà àti fàdákà àti gbogbo ohun èlò tí wọ́n rí ni ilé Ọlọ́run tí ọ́ wà ní àbojútó Obedi-Edomu, lápapọ̀ pẹ̀lú àwọn ìṣúra ààfin àti àwọn ògo pẹ̀lú, ó sì padà lọ sí Samaria.

25 (D)Amasiah ọmọ Joaṣi ọba Juda gbé fún ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dógún lẹ́yìn ikú Jehoaṣi ọmọ Jehoahasi ọba Israẹli. 26 Fún ti iṣẹ́ mìíràn ti ìjọba Amasiah láti ìbẹ̀rẹ̀ dé ìparí, ṣé a kò kọ wọ́n sínú ìwé àwọn ọba Juda àti Israẹli? 27 Láti ìgbà tí Amasiah ti yípadà kúrò láti máa tẹ̀lé Olúwa, wọ́n dìtẹ̀ sí i ní Jerusalẹmu, ó sì sálọ sí Lakiṣi ṣùgbọ́n, wọ́n rán àwọn ọkùnrin tẹ̀lé e lọ sí Lakiṣi, wọ́n sì pa á síbẹ̀. 28 A gbé e padà pẹ̀lú ẹṣin. A sì sin ín pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀ ní ìlú ńlá ti Juda.

Amaziah Reigns in Judah

25 (A)Amaziah was twenty-five years old when he began to reign, and he reigned twenty-nine years in Jerusalem. His mother's name was Jehoaddan of Jerusalem. And he did what was right in the eyes of the Lord, (B)yet not with a whole heart. And as soon as the royal power was firmly his, he killed his servants who had struck down the king his father. But he did not put their children to death, according to what is written in the Law, in the Book of Moses, where the Lord commanded, (C)“Fathers shall not die because of their children, nor children die because of their fathers, but each one shall die for his own sin.”

Amaziah's Victories

Then Amaziah assembled the men of Judah and set them by fathers' houses under commanders of thousands and of hundreds for all Judah and Benjamin. He mustered those (D)twenty years old and upward, and found that they were (E)300,000 choice men, fit for war, (F)able to handle spear and shield. He hired also 100,000 mighty men of valor from Israel for 100 talents[a] of silver. But (G)a man of God came to him and said, “O king, do not let the army of Israel go with you, for the Lord is not with Israel, with all these Ephraimites. But go, act, be strong for the battle. Why should you suppose that God will cast you down before the enemy? (H)For God has power to help or to cast down.” And Amaziah said to the man of God, “But what shall we do about the hundred talents that I have given to the army of Israel?” The man of God answered, “The Lord is able to give you much more than this.” 10 Then Amaziah discharged the army that had come to him from Ephraim to go home again. And they became very angry with Judah and returned home in fierce anger. 11 But Amaziah took courage and led out his people and went to the (I)Valley of Salt and struck down (J)10,000 men of Seir. 12 The men of Judah captured another 10,000 alive and took them to the top of a rock and threw them down from the top of the rock, and they were all dashed to pieces. 13 But the men of the army whom Amaziah sent back, not letting them go with him to battle, raided the cities of Judah, (K)from Samaria to Beth-horon, and struck down 3,000 people in them and took much spoil.

Amaziah's Idolatry

14 After Amaziah came from striking down the Edomites, (L)he brought the gods (M)of the men of Seir and set them up as his gods and worshiped them, making offerings to them. 15 Therefore the Lord was angry with Amaziah and sent to him a prophet, who said to him, “Why have you sought the gods of a people (N)who did not deliver their own people from your hand?” 16 But as he was speaking, the king said to him, “Have we made you a royal counselor? Stop! Why should you be struck down?” So the prophet stopped, but said, “I know that (O)God has determined to destroy you, because you have done this and have not listened to my counsel.”

Israel Defeats Amaziah

17 (P)Then Amaziah king of Judah took counsel and sent to Joash the son of Jehoahaz, son of Jehu, king of Israel, saying, “Come, let us look one another in the face.” 18 And Joash the king of Israel sent word to Amaziah king of Judah, (Q)“A thistle on Lebanon sent to a cedar on Lebanon, saying, ‘Give your daughter to my son for a wife,’ and a wild beast of Lebanon passed by and trampled down the thistle. 19 You say, ‘See, I[b] have struck down Edom,’ and (R)your heart has lifted you up in boastfulness. But now stay at home. Why should you provoke trouble so that you fall, you and Judah with you?”

20 But Amaziah would not listen, for it was of God, in order that he might give them into the hand of their enemies, (S)because they had sought the gods of Edom. 21 So Joash king of Israel went up, and he and Amaziah king of Judah faced one another in battle at Beth-shemesh, which belongs to Judah. 22 And Judah was defeated by Israel, and every man fled to his home. 23 And Joash king of Israel captured Amaziah king of Judah, the son of Joash, son of (T)Ahaziah, at Beth-shemesh, and brought him to Jerusalem and broke down the wall of Jerusalem for 400 cubits,[c] from (U)the Ephraim Gate to the Corner Gate. 24 And he seized all the gold and silver, and all the vessels that were found in the house of God, in the care of (V)Obed-edom. He seized also the treasuries of the king's house, also hostages, and he returned to Samaria.

25 (W)Amaziah the son of Joash, king of Judah, lived fifteen years after the death of Joash the son of Jehoahaz, king of Israel. 26 Now the rest of the deeds of Amaziah, from first to last, are they not written in the Book of the Kings of Judah and Israel? 27 From the time when he turned away from the Lord they made a conspiracy against him in Jerusalem, and he fled to Lachish. But they sent after him to Lachish and put him to death there. 28 And they brought him upon horses, and he was buried with his fathers in the city of David.[d]

Footnotes

  1. 2 Chronicles 25:6 A talent was about 75 pounds or 34 kilograms
  2. 2 Chronicles 25:19 Hebrew you
  3. 2 Chronicles 25:23 A cubit was about 18 inches or 45 centimeters
  4. 2 Chronicles 25:28 Hebrew of Judah