Add parallel Print Page Options

Àwọn ètò fún kíkọ́ ilé Olúwa

Solomoni pinnu láti kọ́ ilé fún orúkọ Olúwa àti ilé kan fún ìjọba rẹ̀ Solomoni sì yan ẹgbẹ̀rún ní ọ̀nà àádọ́rin àwọn (70,000) ọkùnrin láti ru ẹrù àti ẹgbẹ̀rún ní ọ̀nà ọgọ́rin àwọn (80,000) ọkùnrin gẹ́gẹ́ bi olùgé-òkúta ní àwọn òkè àti ẹgbẹ̀rún mẹ́rìn-dínlógójì (36,000) gẹ́gẹ́ bí àwọn alábojútó lórí wọn.

(A)Solomoni rán iṣẹ́ yìí sí Hiramu ọba Tire:

“Rán àwọn igi kedari sí mi gẹ́gẹ́ bí o ti ṣe fún baba à mi Dafidi. Nígbà tí ó fi igi kedari ránṣẹ́ sí i láti kọ́ ààfin tí ó ń gbé. Nísinsin yìí, èmi n kọ́ ilé kan fún orúkọ Olúwa Ọlọ́run mi àti láti yà á sí mímọ́ fún un àti láti sun tùràrí olóòórùn dídùn níwájú rẹ̀, fún gbígbé àkàrà ìfihàn ìgbàkúgbà, àti fún ṣíṣe ẹbọ sísun ní gbogbo àárọ̀ àti ìrọ̀lẹ́ àti ní ọjọọjọ́ ìsinmi àti oṣù tuntun àti ní àjọ̀dún tí a yàn ti Olúwa Ọlọ́run wa. Èyí ni àṣẹ fún Israẹli láéláé.

“Ilé Olúwa tí èmi yóò kọ́ yóò tóbi, nítorí pé Ọlọ́run wa tóbi ju gbogbo àwọn ọlọ́run mìíràn lọ. Ṣùgbọ́n ta ni ó le è kọ́ ilé fún Olúwa, níwọ̀n ìgbà tí àwọn ọ̀run, àní ọ̀run àwọn ọ̀run tó ga jùlọ, kò le è gbà á? Ta ni èmi nígbà náà láti kọ́ ilé fún Olúwa, bí kò ṣe kìkì àti sun ẹbọ sun ẹbọ níwájú rẹ̀?

“Nítorí náà, rán ọkùnrin kan sí mi, tí a kọ́ láti ṣiṣẹ́ pẹ̀lú wúrà àti fàdákà àti idẹ àti irin, àti ní àwọ̀ àlùkò àti àwọ̀ pupa fòò àti ní àwọ̀ ojú ọ̀run, tí ó jẹ́ onímọ̀ nínú iṣẹ́ igi gbígbẹ́ láti ṣiṣẹ́ ní Juda àti Jerusalẹmu pẹ̀lú àwọn onímọ̀ oníṣọ̀nà tí baba à mi Dafidi pèsè.

“Fi ìtì igi kedari, junifa àti algumu ránṣẹ́ sí mi, láti Lebanoni, nítorí tí mo mọ̀ pé àwọn ọkùnrin rẹ ní ìmọ̀ nínú gígé igi rírẹ́. Àwọn ọkùnrin mi yóò ṣiṣẹ́ pẹ̀lú àwọn ọkùnrin rẹ. Láti pèsè ọ̀pọ̀ igi rírẹ́ fún mi, nítorí ilé Olúwa tí mo kọ́ gbọdọ̀ tóbi kí o sì lógo púpọ̀. 10 Èmi yóò fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ, àwọn ọkùnrin agégi tí ó ń gé ìtì igi náà ni ẹgbàáwàá (20,000), alikama ilẹ̀ àti ẹgbàáwàá (20,000), ọ̀pọ̀lọpọ̀ ti barle; ẹgbàáwàá (20,000), bati ọtí wáìnì àti ẹgbàáwàá (20,000) bati òróró olifi.”

11 Hiramu ọba Tire fèsì padà nípasẹ̀ ìwé sí Solomoni:

“Nítorí tí Olúwa fẹ́ràn àwọn ènìyàn rẹ̀, ó ti ṣe ọ́ ní ọba wọn.”

12 Hiramu fi kún un pe:

“Ìyìn ni fún Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, tí ó dá ọ̀run òun ayé! O ti fún ọba Dafidi ní ọmọ tí ó gbọ́n, tí ó kún fún ìmọ̀ àti òye, tí yóò kọ́ ilé fún Olúwa àti ààfin fún ara rẹ̀.

13 “Èmi ń rán Huramu-Abi, ọkùnrin tí ó kún fún ìmọ̀ àti òye sí ọ. 14 Ọmọbìnrin kan nínú àwọn ọmọbìnrin Dani àti tí baba a rẹ̀ wá láti Tire tí ó gbọ́ngbọ́n àti ṣiṣẹ́ ní wúrà àti ní fàdákà, ní idẹ, ní irin, ní òkúta àti ní ìtì igi, ní èse-àlùkò, ní aláró, àti ní ọ̀gbọ̀ tí ó dára, àti òdòdó, láti gbẹ́ onírúurú ohun gbígbẹ́ pẹ̀lú, àti láti ṣe àwárí ìmọ̀ ẹ̀rọ irú ẹ̀yàkẹ́yà tí a ó fún un ṣe. Òun yóò ṣiṣẹ́ pẹ̀lú àwọn ọlọ́gbọ́n rẹ̀, àti pẹ̀lú àwọn ọlọ́gbọ́n olúwa mi, Dafidi baba a rẹ.

15 “Nísinsin yìí, jẹ́ kí olúwa mi rán àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ ní alikama àti barle àti òróró Olifi náà àti ọtí tí ó ti ṣe ìlérí. 16 Àwa yóò sì gé gbogbo àwọn ìtí igi láti Lebanoni tí ìwọ yóò lò pẹ̀lú a ó gbé wọn fò lójú omi Òkun lọ sí Joppa. Lẹ́yìn náà ìwọ lè kó wọn gòkè lọ sí Jerusalẹmu.”

17 Solomoni ka iye àwọn àjèjì tí ó wà ní Israẹli lẹ́yìn kíka iye wọn tí baba a rẹ̀ Dafidi ti ṣe; a sì ka iye wọn sí ọ̀kẹ́mẹ́jọ ó dín egbèjì-lélọ́gbọ̀n (153,600). 18 Ó sì yan ẹgbàá-márùn-dínlógójì nínú wọn láti ru ẹrù, àti ọ̀kẹ́ mẹ́rin láti ṣe àgọ́ òkúta lórí òkè, àti egbèjìdínlógún alábojútó láti kó àwọn ènìyàn ṣiṣẹ́.

Preparations for Building the Temple(A)

[a]Solomon gave orders to build a temple(B) for the Name of the Lord and a royal palace for himself.(C) He conscripted 70,000 men as carriers and 80,000 as stonecutters in the hills and 3,600 as foremen over them.(D)

Solomon sent this message to Hiram[b](E) king of Tyre:

“Send me cedar logs(F) as you did for my father David when you sent him cedar to build a palace to live in. Now I am about to build a temple(G) for the Name of the Lord my God and to dedicate it to him for burning fragrant incense(H) before him, for setting out the consecrated bread(I) regularly, and for making burnt offerings(J) every morning and evening and on the Sabbaths,(K) at the New Moons(L) and at the appointed festivals of the Lord our God. This is a lasting ordinance for Israel.

“The temple I am going to build will be great,(M) because our God is greater than all other gods.(N) But who is able to build a temple for him, since the heavens, even the highest heavens, cannot contain him?(O) Who then am I(P) to build a temple for him, except as a place to burn sacrifices before him?

“Send me, therefore, a man skilled to work in gold and silver, bronze and iron, and in purple, crimson and blue yarn, and experienced in the art of engraving, to work in Judah and Jerusalem with my skilled workers,(Q) whom my father David provided.

“Send me also cedar, juniper and algum[c] logs from Lebanon, for I know that your servants are skilled in cutting timber there. My servants will work with yours to provide me with plenty of lumber, because the temple I build must be large and magnificent. 10 I will give your servants, the woodsmen who cut the timber, twenty thousand cors[d] of ground wheat, twenty thousand cors[e] of barley, twenty thousand baths[f] of wine and twenty thousand baths of olive oil.(R)

11 Hiram king of Tyre replied by letter to Solomon:

“Because the Lord loves(S) his people, he has made you their king.”

12 And Hiram added:

“Praise be to the Lord, the God of Israel, who made heaven and earth!(T) He has given King David a wise son, endowed with intelligence and discernment, who will build a temple for the Lord and a palace for himself.

13 “I am sending you Huram-Abi,(U) a man of great skill, 14 whose mother was from Dan(V) and whose father was from Tyre. He is trained(W) to work in gold and silver, bronze and iron, stone and wood, and with purple and blue(X) and crimson yarn and fine linen. He is experienced in all kinds of engraving and can execute any design given to him. He will work with your skilled workers and with those of my lord, David your father.

15 “Now let my lord send his servants the wheat and barley and the olive oil(Y) and wine he promised, 16 and we will cut all the logs from Lebanon that you need and will float them as rafts by sea down to Joppa.(Z) You can then take them up to Jerusalem.”

17 Solomon took a census of all the foreigners(AA) residing in Israel, after the census(AB) his father David had taken; and they were found to be 153,600. 18 He assigned(AC) 70,000 of them to be carriers and 80,000 to be stonecutters in the hills, with 3,600 foremen over them to keep the people working.

Footnotes

  1. 2 Chronicles 2:1 In Hebrew texts 2:1 is numbered 1:18, and 2:2-18 is numbered 2:1-17.
  2. 2 Chronicles 2:3 Hebrew Huram, a variant of Hiram; also in verses 11 and 12
  3. 2 Chronicles 2:8 Probably a variant of almug
  4. 2 Chronicles 2:10 That is, probably about 3,600 tons or about 3,200 metric tons of wheat
  5. 2 Chronicles 2:10 That is, probably about 3,000 tons or about 2,700 metric tons of barley
  6. 2 Chronicles 2:10 That is, about 120,000 gallons or about 440,000 liters