Añadir traducción en paralelo Imprimir Opciones de la página

Gbígbé ìgbé ayé tó wu Ọlọ́run

Ní ìparí, ará, a sọ fún un yín bí ẹ ti ń gbé láti wu Ọlọ́run, àní gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin tí ń ṣe. Nísinsin yìí, a béèrè, a sì ń rọ̀ yín nínú Jesu Olúwa láti ṣe bẹ́ẹ̀ àti bẹ́ẹ̀ sí. Nítorí pé, ẹ̀yin mọ àṣẹ tí a pa fún yín láti ọ̀dọ̀ Olúwa Jesu.

(A)Nítorí ìfẹ́ Ọlọ́run ni pé kí ẹ jẹ́ mímọ́, kí ẹ sì yàgò kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ àgbèrè, (B)kí ẹnìkọ̀ọ̀kan yín kọ́ láti ṣàkóso ara rẹ̀ ní ọ̀nà mímọ́ àti pẹ̀lú ọlá, kì í ṣe ní ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ gẹ́gẹ́ bí àwọn aláìkọlà, ẹni tí kò mọ Ọlọ́run; àti pé nínú ọ̀rọ̀ yìí, kí ẹnikẹ́ni nínú yín máa ṣe rẹ arákùnrin rẹ̀ jẹ nípa ohunkóhun. Olúwa yóò jẹ àwọn ènìyàn ní yà fún gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ wọn, gẹ́gẹ́ bí a ti ń sọ fún un yín tẹ́lẹ̀tẹ́lẹ̀. Nítorí Ọlọ́run kò pè wá sínú ìwà èérí, bí kò ṣe sínú ìgbé ayé mímọ́. Nítorí náà, ẹnikẹ́ni tí ó kọ òfin yìí, kì í ṣe òfin ènìyàn ni ẹni náà kọ̀, bí kò ṣe òfin Ọlọ́run ẹni tí ó fi Ẹ̀mí Mímọ́ rẹ̀ fún ni.

Ṣùgbọ́n nípa ìfẹ́ ará, a kò ní láti tún kọ̀wé sí i yín, ìdí ni pé, Ọlọ́run pàápàá ń kọ́ yín láti fẹ́ràn ara yín. 10 Nítòótọ́, ẹ ní ìfẹ́ fún àwọn arákùnrin tí ó wà káàkiri Makedonia. Síbẹ̀síbẹ̀ àwa ń bẹ̀ yín, ará, pé kí ẹ̀yin kí ó máa tẹ̀síwájú nínú rẹ̀. 11 (C)Ẹ jẹ́ kí èyí jẹ́ ìfẹ́ ọkàn yín láti gbé jẹ́ẹ́ àti láti mọ ti ara yín àti kí olúkúlùkù kọjú sí iṣẹ́ rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí a ti wí fún yín. 12 Èyí yóò mú kí àwọn tí kì í ṣe onígbàgbọ́ gbẹ́kẹ̀lé yín àti láti bu ọlá fún yín pẹ̀lú. Bí ẹ bá ṣe bẹ́ẹ̀, ẹ kò ní máa wo ojú ẹnikẹ́ni láti fún yín ni owó tí ẹ ó fi san gbèsè.

Ìpadàbọ̀ wá olúwa

13 (D)Ẹ̀yin ará, àwa kò fẹ́ kí ẹ̀yin kí ó jẹ́ òpè ní ti àwọn tí ó ti sùn, pé kí ẹ máa banújẹ́ gẹ́gẹ́ bí àwọn yòókù tí kò ní ìrètí. 14 (E)A gbàgbọ́ pé, Jesu kú, ó sì tún jíǹde, àti pé Ọlọ́run yóò mú gbogbo àwọn tí ó ti sùn nínú rẹ̀ padà wá. 15 Gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa, pé àwa tí ó wà láààyè, tí a sì kù lẹ́yìn de à ti wá Olúwa, bí ó ti wù kí ó rí, kì yóò ṣáájú àwọn tí ó sùn láti pàdé rẹ̀. 16 (F)Nítorí pé, Olúwa fúnrarẹ̀ yóò sọ̀kalẹ̀ láti ọ̀run wá, pẹ̀lú ariwo àṣẹ ńlá àti ohùn àwọn angẹli ti àwọn angẹli ti àwọn ti ìpè Ọlọ́run, àwọn òkú nínú Kristi yóò sì kọ́kọ́ jíǹde. 17 Nígbà náà ni a ó gba àwa tí ó sì wà láààyè sókè nínú àwọsánmọ̀ láti ọwọ́ Olúwa. A ó sì wà pẹ̀lú rẹ̀ títí láéláé. 18 Nítorí náà, ẹ tu ara yín nínú, kí ẹ sì máa gba ara yín níyànjú pẹ̀lú ọ̀rọ̀ wọ̀nyí.

Living to Please God

As for other matters, brothers and sisters,(A) we instructed you how to live(B) in order to please God,(C) as in fact you are living. Now we ask you and urge you in the Lord Jesus to do this more and more. For you know what instructions we gave you by the authority of the Lord Jesus.

It is God’s will(D) that you should be sanctified: that you should avoid sexual immorality;(E) that each of you should learn to control your own body[a](F) in a way that is holy and honorable, not in passionate lust(G) like the pagans,(H) who do not know God;(I) and that in this matter no one should wrong or take advantage of a brother or sister.[b](J) The Lord will punish(K) all those who commit such sins,(L) as we told you and warned you before. For God did not call us to be impure, but to live a holy life.(M) Therefore, anyone who rejects this instruction does not reject a human being but God, the very God who gives you his Holy Spirit.(N)

Now about your love for one another(O) we do not need to write to you,(P) for you yourselves have been taught by God(Q) to love each other.(R) 10 And in fact, you do love all of God’s family throughout Macedonia.(S) Yet we urge you, brothers and sisters, to do so more and more,(T) 11 and to make it your ambition to lead a quiet life: You should mind your own business and work with your hands,(U) just as we told you, 12 so that your daily life may win the respect of outsiders(V) and so that you will not be dependent on anybody.

Believers Who Have Died

13 Brothers and sisters, we do not want you to be uninformed(W) about those who sleep in death,(X) so that you do not grieve like the rest of mankind, who have no hope.(Y) 14 For we believe that Jesus died and rose again,(Z) and so we believe that God will bring with Jesus those who have fallen asleep in him.(AA) 15 According to the Lord’s word, we tell you that we who are still alive, who are left until the coming of the Lord,(AB) will certainly not precede those who have fallen asleep.(AC) 16 For the Lord himself will come down from heaven,(AD) with a loud command, with the voice of the archangel(AE) and with the trumpet call of God,(AF) and the dead in Christ will rise first.(AG) 17 After that, we who are still alive and are left(AH) will be caught up together with them in the clouds(AI) to meet the Lord in the air. And so we will be with the Lord(AJ) forever. 18 Therefore encourage one another(AK) with these words.

Notas al pie

  1. 1 Thessalonians 4:4 Or learn to live with your own wife; or learn to acquire a wife
  2. 1 Thessalonians 4:6 The Greek word for brother or sister (adelphos) refers here to a believer, whether man or woman, as part of God’s family.