1 Samuẹli 12:22
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
22 Nítorí orúkọ ńlá rẹ̀ Olúwa kì yóò kọ àwọn ènìyàn rẹ̀ sílẹ̀, nítorí tí inú Olúwa dùn láti fi yín ṣe ènìyàn rẹ̀.
Read full chapter
1 Samuel 12:22
New International Version
22 For the sake(A) of his great name(B) the Lord will not reject(C) his people, because the Lord was pleased to make(D) you his own.
Jeremiah 31:37
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
37 Èyí ni ohun tí Olúwa wí:
“Àyàfi tí a bá lé àwọn ọ̀run lókè
tí ìpìlẹ̀ ayé sì di àwárí ní ìsàlẹ̀,
ni èmi yóò kọ àwọn Israẹli
nítorí ohun gbogbo tí wọ́n ti ṣe,”
ni Olúwa wí.
Jeremiah 31:37
New International Version
37 This is what the Lord says:
Jeremiah 33:24-26
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
24 “Ǹjẹ́ ìwọ kò kíyèsi pé àwọn ènìyàn wọ̀nyí ń sọ pé: ‘Olúwa ti kọ àwọn ọba méjèèjì tí ó yàn sílẹ̀’? Nítorí náà, ni wọ́n ti ṣe kẹ́gàn àwọn ènìyàn mi. Wọn kò sì mọ̀ wọ́n gẹ́gẹ́ bí orílẹ̀-èdè kan. 25 Báyìí ni Olúwa wí: ‘Bí èmi kò bá ti da májẹ̀mú mi pẹ̀lú ọ̀sán àti òru àti pẹ̀lú òfin ọ̀run àti ayé tí kò lè yẹ̀. 26 Nígbà náà ni èmi ó kọ ọmọlẹ́yìn Jakọbu àti Dafidi ìránṣẹ́ mi tí èmi kò sì ní yan ọ̀kan nínú ọmọkùnrin rẹ̀ láti jẹ́ alákòóso lórí àwọn ọmọ Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu; nítorí èmi ó mú ìkólọ wọn padà; èmi ó sì ṣàánú fún wọn.’ ”
Read full chapter
Jeremiah 33:24-26
New International Version
24 “Have you not noticed that these people are saying, ‘The Lord has rejected the two kingdoms[a](A) he chose’? So they despise(B) my people and no longer regard them as a nation.(C) 25 This is what the Lord says: ‘If I have not made my covenant with day and night(D) and established the laws(E) of heaven and earth,(F) 26 then I will reject(G) the descendants of Jacob(H) and David my servant and will not choose one of his sons to rule over the descendants of Abraham, Isaac and Jacob. For I will restore their fortunes[b](I) and have compassion(J) on them.’”
Footnotes
- Jeremiah 33:24 Or families
- Jeremiah 33:26 Or will bring them back from captivity
2 Kọrinti 11:22
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
22 Heberu ni wọ́n bí? Bẹ́ẹ̀ ni èmi. Israẹli ni wọ́n bí? Bẹ́ẹ̀ ni èmi. Irú-ọmọ Abrahamu ní òun bí? Bẹ́ẹ̀ ni èmi.
Read full chapter
2 Corinthians 11:22
New International Version
22 Are they Hebrews? So am I.(A) Are they Israelites? So am I.(B) Are they Abraham’s descendants? So am I.(C)
Filipi 3:5
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
5 Ẹni tí a kọ nílà ní ọjọ́ kẹjọ, láti inú kùkùté Israẹli wá, láti inú ẹ̀yà Benjamini, Heberu láti inú Heberu wá; nítorí, ní ti òfin Farisi ni èmi;
Read full chapter
Philippians 3:5
New International Version
5 circumcised(A) on the eighth day, of the people of Israel,(B) of the tribe of Benjamin,(C) a Hebrew of Hebrews; in regard to the law, a Pharisee;(D)
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.
Holy Bible, New International Version®, NIV® Copyright ©1973, 1978, 1984, 2011 by Biblica, Inc.® Used by permission. All rights reserved worldwide.
NIV Reverse Interlinear Bible: English to Hebrew and English to Greek. Copyright © 2019 by Zondervan.