1 Kọrinti 2:7-10
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
7 (A)Bẹ́ẹ̀ kọ́, àwa ń sọ̀rọ̀ ọgbọ́n ti Ọlọ́run tó fi ara sin, ọgbọ́n tí ó ti fi ara pamọ́, èyí tí Ọlọ́run ti lànà sílẹ̀ ṣáájú ìpilẹ̀ṣẹ̀ ayé fún ògo wa. 8 (B)Èyí ti ẹnikẹ́ni nínú àwọn aláṣẹ ayé yìí kò mọ̀. Ìbá ṣe pé wọ́n mọ̀ ọ́n, wọn kì bá tún kan Olúwa ògo mọ́ àgbélébùú. 9 (C)Gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ pé:
“Ojú kò tí ì rí,
etí kò tí í gbọ́,
kò sì ọkàn ènìyàn tí ó tí í mọ̀
ohun tí Ọlọ́run tí pèsè sílẹ̀ fún àwọn tí o fẹ́ Ẹ.”
10 (D)Ṣùgbọ́n Ọlọ́run ti fi í hàn fún wa nípasẹ̀ Ẹ̀mí rẹ̀.
Ẹ̀mí á máa wádìí ohun gbogbo, kódà àwọn àṣírí Ọlọ́run tó jinlẹ̀ jùlọ.
Read full chapter
1 Corinthians 2:7-10
New International Version
7 No, we declare God’s wisdom, a mystery(A) that has been hidden(B) and that God destined for our glory before time began. 8 None of the rulers of this age(C) understood it, for if they had, they would not have crucified the Lord of glory.(D) 9 However, as it is written:
“What no eye has seen,
what no ear has heard,
and what no human mind has conceived”[a]—
the things God has prepared for those who love him—(E)
10 these are the things God has revealed(F) to us by his Spirit.(G)
The Spirit searches all things, even the deep things of God.
Footnotes
- 1 Corinthians 2:9 Isaiah 64:4
Efesu 3:3-5
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
3 bí ó ti ṣe pé nípa ìfihàn ni ó ti fi ohun ìjìnlẹ̀ hàn fún mi gẹ́gẹ́ bí mo ti kọ ṣáájú ni ṣókí, 4 Nígbà tí ẹ̀yin bá kà á, nípa èyí tí ẹ̀yin o fi lè mọ òye mi nínú ìjìnlẹ̀ Kristi. 5 Èyí tí a kò í tí ì fihàn àwọn ọmọ ènìyàn rí nínú ìran mìíràn gbogbo, bí a ti fi wọ́n hàn nísinsin yìí fún àwọn aposteli rẹ̀ mímọ́ àti àwọn wòlíì nípa Ẹ̀mí;
Read full chapter
Ephesians 3:3-5
New International Version
3 that is, the mystery(A) made known to me by revelation,(B) as I have already written briefly. 4 In reading this, then, you will be able to understand my insight(C) into the mystery of Christ, 5 which was not made known to people in other generations as it has now been revealed by the Spirit to God’s holy apostles and prophets.(D)
Efesu 3:9
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
9 (A)àti láti mú kí gbogbo ènìyàn rí ohun tí iṣẹ́ ìríjú ohun ìjìnlẹ̀ náà jásí, èyí tí a ti fi pamọ́ láti ìgbà àtijọ́ nínú Ọlọ́run, ẹni tí ó dá ohun gbogbo nípa Jesu Kristi:
Read full chapter
Ephesians 3:9
New International Version
9 and to make plain to everyone the administration of this mystery,(A) which for ages past was kept hidden in God, who created all things.
Romu 9:18
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
18 (A)Nítorí náà ni ó ṣe ń ṣàánú fún ẹni tí ó wù ú, ẹni tí ó wù ú a sì mú ní ọkàn le.
Read full chapter
Romans 9:18
New International Version
18 Therefore God has mercy on whom he wants to have mercy, and he hardens whom he wants to harden.(A)
Romu 11:7
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
7 (A)Kí ha ni? Ohun tí Israẹli ń wá kiri, òun náà ni kò rí; ṣùgbọ́n àwọn ẹni àyànfẹ́ ti rí i, a sì sé àyà àwọn ìyókù le.
Read full chapter
Romans 11:7
New International Version
7 What then? What the people of Israel sought so earnestly they did not obtain.(A) The elect among them did, but the others were hardened,(B)
Luku 21:24
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
24 (A)Wọn ó sì ti ojú idà ṣubú, a ó sì dìwọ́n ní ìgbèkùn lọ sí orílẹ̀-èdè gbogbo; Jerusalẹmu yóò sì di ìtẹ̀mọ́lẹ̀ lẹ́sẹ̀ àwọn aláìkọlà, títí àkókò àwọn aláìkọlà yóò fi kún.
Read full chapter
Luke 21:24
New International Version
24 They will fall by the sword and will be taken as prisoners to all the nations. Jerusalem will be trampled(A) on by the Gentiles until the times of the Gentiles are fulfilled.
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.
Holy Bible, New International Version®, NIV® Copyright ©1973, 1978, 1984, 2011 by Biblica, Inc.® Used by permission. All rights reserved worldwide.
NIV Reverse Interlinear Bible: English to Hebrew and English to Greek. Copyright © 2019 by Zondervan.