Saamu 89
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
Maskili ti Etani ará Esra.
89 Èmi kọrin títóbi ìfẹ́ Olúwa títí láé;
pẹ̀lú ẹnu mi ní èmi yóò jẹ́ kí a mọ òtítọ́ rẹ láti ìran dé ìran.
2 Èmi ó wí pé, ìfẹ́ rẹ dúró títí láé,
pé ìwọ gbe òtítọ́ rẹ kalẹ̀ ní ọ̀run fúnrarẹ̀.
3 (A)Ìwọ wí pé, “Èmi ti dá májẹ̀mú pẹ̀lú àwọn àyànfẹ́ mi
mo ti búra fún Dafidi ìránṣẹ́ mi.
4 ‘Èmi ó fi ìdí irú-ọmọ rẹ múlẹ̀ títí láé
èmí ó sì máa gbe ìtẹ́ rẹ ró láti ìran dé ìran.’ ”
5 Àwọn ọ̀run yóò máa yin iṣẹ́ ìyanu rẹ, Olúwa,
òtítọ́ rẹ ni ìpéjọpọ̀ àwọn ẹni mímọ́.
6 Ta ni ó wà ní ọ̀run tí a lè fiwé Olúwa?
Ta ni nínú àwọn ọmọ alágbára ti a lè fiwé Olúwa?
7 Nínú àjọ ìgbìmọ̀ ẹni mímọ́, wọ́n bẹ̀rù Ọlọ́run gidigidi;
ó sì ní ìbùyìn fún ju gbogbo àwọn tí ó yí i ká.
8 Olúwa Ọlọ́run alágbára, ta ló dàbí rẹ
ìwọ jẹ́ alágbára, Olúwa, òtítọ́ rẹ sì yí ọ ká.
9 Ìwọ ń darí ríru omi Òkun;
nígbà tí ó ru àwọn omi sókè, ìwọ mú wọn parọ́rọ́.
10 Ìwọ ni ó ti ya Rahabu pẹ́rẹpẹ̀rẹ
bí ẹni tí a pa;
ìwọ ti fi apá ọwọ́ agbára rẹ
tú àwọn ọ̀tá rẹ ká.
11 Tìrẹ ní àwọn ọ̀run, ayé pẹ̀lú jẹ́ tìrẹ:
ayé àti ohun gbogbo tí ó wà nínú rẹ̀:
ìwọ ti gbé wọn kalẹ̀.
12 Gúúsù àti àríwá ìwọ ni ó dá wọn;
Tabori àti Hermoni ń fi ayọ̀ yin orúkọ rẹ.
13 Ìwọ ní apá agbára;
agbára ní ọwọ́ rẹ, gíga ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ.
14 Òdodo àti òtítọ́ ni ìpìlẹ̀ ìtẹ́ rẹ:
ìdúró ṣinṣin ìfẹ́ àti òtítọ́ ń lọ síwájú rẹ.
15 Ìbùkún ni fún àwọn ènìyàn tí wọn mọ ohùn ayọ̀ nì,
Olúwa wọ́n ó máa rìn ní ìmọ́lẹ̀ ojú rẹ.
16 Wọn ń ṣògo nínú orúkọ rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́,
wọn ń yin òdodo rẹ.
17 Nítorí ìwọ ni ògo agbára wọn;
nípa ojúrere ni ìwo wá ń ṣògo.
18 Nítorí ti Olúwa ni asà wa,
ọba wa sì ni Ẹni Mímọ́ Israẹli.
19 Nígbà náà ni ìwọ sọ̀rọ̀ nínú ìran, sí àwọn olóòtítọ́ rẹ, wí pé:
“Èmi ti gbé adé kalẹ̀ sórí ẹni tí ó lágbára,
èmi ti gbé ẹni tí a yàn láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn ga.
20 (B)Èmi ti rí Dafidi ìránṣẹ́ mi;
pẹ̀lú òróró mímọ́ mi ni mo fi yàn án;
21 Ìgbà gbogbo ni ọwọ́ mi yóò máa wà pẹ̀lú rẹ̀
apá mí yóò sì fi agbára fún un.
22 Àwọn ọ̀tá kì yóò borí rẹ̀,
àwọn ènìyàn búburú kì yóò rẹ̀ ẹ́ sílẹ̀
23 Èmi yóò run àwọn ọ̀tá rẹ níwájú rẹ
èmi yóò lu àwọn tí ó kórìíra rẹ bolẹ̀
24 Òtítọ́ mi àti ìdúró ṣinṣin ìfẹ́ yóò wà pẹ̀lú rẹ
àti ní orúkọ mi ni a ó gbé ìwo rẹ ga.
25 Èmi ó gbé ọwọ́ rẹ lórí Òkun
àti ọwọ́ ọ̀tún rẹ lórí àwọn odo ńlá
26 Òun yóò kígbe sí mi pé, ‘ìwọ ni baba mi, Ọlọ́run mi, àti àpáta ìgbàlà mi!’
27 (C)Èmi yóò ṣe é ni àkọ́bí mi,
Ẹni gíga ju àwọn ọba ayé.
28 Títí láé ni èmi yóò pa ìfẹ́ dídúró ṣinṣin mọ́ fún un,
àti májẹ̀mú mi pẹ̀lú rẹ̀ yóò dúró gbọingbọin.
29 Èmi ó fi ìdí irú-ọmọ rẹ̀ múlẹ̀ títí láé,
àti ìtẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ọ̀run ti wà láé.
30 “Bí àwọn ọmọ rẹ̀ bá kọ òfin mi sílẹ̀
tí wọn kò sì rìn gẹ́gẹ́ bí ìlànà mi.
31 Tí wọn bá ba ìlànà mi jẹ́
tí wọn kò sì pa àṣẹ mi mọ́,
32 Nígbà náà ni èmi ó fì ọ̀gọ̀ bẹ ìrékọjá wọn wò;
àti ẹ̀ṣẹ̀ wọn pẹ̀lú pàṣán:
33 Ṣùgbọ́n èmi kò ní mú ìfẹ́ mi tí ó dúró ṣinṣin kúrò lọ́dọ̀ rẹ,
bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò jẹ́ kí òtítọ́ mi kí ó yẹ̀.
34 Èmi kì yóò sẹ́ májẹ̀mú mi,
bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò yí ọ̀rọ̀ tí ó ti ẹnu mi jáde padà.
35 Lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo ni èmi ti fi ìwà mímọ́ mi búra;
èmi kì yóò purọ́ fún Dafidi.
36 Irú-ọmọ rẹ yóò dúró títí láé,
àti ìtẹ́ rẹ̀ yóò dúró bí oòrùn níwájú mi.
37 (D)A ó fi múlẹ̀ títí láé bí òṣùpá,
àti bi ẹlẹ́rìí òtítọ́ ni ọ̀run”. Sela.
38 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí ìwọ ti ṣá tì, ìwọ sì kórìíra;
ìwọ kún fún ìrunú sí ẹni ààmì òróró rẹ.
39 Ìwọ ti sọ májẹ̀mú ìránṣẹ́ rẹ di òfo;
ìwọ tàbùkù adé rẹ nínú eruku
40 Ìwọ ti wó gbogbo àwọn odi rẹ̀
ìwọ sọ ibi gíga rẹ̀ di ahoro.
41 Àwọn tí ń kọjá lọ fi ṣe ìjẹ;
ó ti di ẹ̀gàn àwọn olùbágbé rẹ̀.
42 Ìwọ ti gbé ọwọ́ ọ̀tún ọ̀tá rẹ̀ sókè;
ìwọ mú gbogbo ọ̀tá rẹ̀ yọ̀.
43 Pẹ̀lú, ìwọ ti yí ojú idà rẹ̀ padà,
ìwọ kò sì dúró tì í nínú ogun.
44 Ìwọ ti mú ògo rẹ̀ kùnà,
ìwọ si wó ìtẹ́ rẹ̀ palẹ̀ sílẹ̀ẹ́lẹ̀.
45 Ìwọ ti gé ọjọ́ èwe rẹ̀ kúrú;
ìwọ sì fi ìtìjú bò ó.
46 Yóò ti pẹ́ tó, Olúwa?
Tí ìwọ ó ha fi ara rẹ pamọ́ títí láé?
Yóò ti pẹ́ to tí ìbínú rẹ yóò máa jó bí iná?
47 Rántí bí ọjọ́ mi ti kúrú tó
nítorí asán ha ni ìwọ fi ṣẹ̀dá àwọn ènìyàn!
48 Ta ni yóò wà láààyè tí kò ní rí ikú rẹ̀?
Ta ló lè sá kúrò nínú agbára isà òkú?
49 Olúwa, níbo ni ìṣeun ìfẹ́ rẹ àtijọ́ wà,
tí ìwọ ti fi òtítọ́ rẹ búra fún Dafidi?
50 Rántí, Olúwa, bí a ti ń gan àwọn ìránṣẹ́ rẹ;
bí èmi ti gbà ní àyà mi láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn,
51 Ẹ̀gàn tí àwọn ọ̀tá rẹ gàn, Olúwa,
tí wọn gan ipasẹ̀ Ẹni ààmì òróró rẹ.
52 Olùbùkún ní Olúwa títí láé.
Àmín àti Àmín.
Salmos 89
La Biblia de las Américas
El pacto del Señor con David, y las aflicciones de Israel
Masquil[a] de Etán ezraíta[b].
89 Por siempre cantaré de las misericordias del Señor(A);
con mi boca daré a conocer(B) tu fidelidad(C) a todas las generaciones.
2 Porque dije: Para siempre será edificada la misericordia(D);
en los cielos mismos establecerás tu fidelidad(E).
3 Yo he hecho un pacto con mi escogido(F),
he jurado a David mi siervo(G):
4 Estableceré tu descendencia[c] para siempre(H),
y edificaré tu trono(I) por todas las generaciones. (Selah[d])
5 Los cielos alabarán(J) tus maravillas, Señor,
y también tu fidelidad en la asamblea(K) de los santos(L).
6 Porque, ¿quién en el firmamento[e] se puede comparar al Señor(M)?
¿Quién entre los hijos de los poderosos[f](N) es como el Señor,
7 Dios muy temido(O) en el consejo de los santos(P),
e imponente(Q) sobre todos los que están en su derredor?
8 Oh Señor, Dios de los ejércitos, ¿quién como tú(R), poderoso Señor[g]?
Tu fidelidad también te rodea.
9 Tú dominas la soberbia[h] del mar;
cuando sus olas se levantan, tú las calmas(S).
10 Tú aplastaste a Rahab[i](T) como a uno herido de muerte;
esparciste a tus enemigos(U) con tu brazo poderoso[j].
11 Tuyos son los cielos(V), tuya también la tierra;
el mundo y todo lo que en él hay[k](W), tú lo fundaste.
12 El norte y el sur(X), tú los creaste;
el Tabor(Y) y el Hermón(Z) aclamarán con gozo a tu nombre(AA).
13 Tú tienes un brazo fuerte[l];
tu mano es poderosa, tu diestra es exaltada(AB).
14 La justicia y el derecho son el fundamento de tu trono(AC);
la misericordia y la verdad[m] van delante de ti(AD).
15 ¡Cuán bienaventurado es el pueblo que sabe lo que es la voz de júbilo[n](AE)!
Andan, Señor, a la luz de tu rostro(AF).
16 En tu nombre se regocijan todo el día(AG),
y por tu justicia son enaltecidos.
17 Porque tú eres la gloria de su potencia(AH),
y por tu gracia[o] es exaltado nuestro poder[p](AI).
18 Pues del Señor es nuestro escudo(AJ),
y del Santo de Israel nuestro rey(AK).
19 Una vez hablaste en visión a tus santos[q],
y dijiste: He ayudado a[r] un poderoso(AL);
he exaltado a uno escogido de entre el pueblo(AM).
20 He hallado a David mi siervo(AN);
lo he ungido con mi óleo santo(AO),
21 y[s] con él estará siempre[t] mi mano(AP);
mi brazo también lo fortalecerá(AQ).
22 No lo engañará[u] el enemigo,
ni lo afligirá el hijo de maldad[v](AR).
23 Sino que yo aplastaré(AS) a sus adversarios delante de él,
y heriré a los que lo aborrecen.
24 Con él estarán mi fidelidad(AT) y mi misericordia,
y en mi nombre será exaltado su poder[w](AU).
25 Pondré también su mano sobre el mar(AV),
y su diestra sobre los ríos.
26 Él clamará a mí: Mi Padre eres tú(AW),
mi Dios y la roca de mi salvación(AX).
27 Yo también lo haré mi primogénito(AY),
el más excelso de los reyes de la tierra(AZ).
28 Para siempre conservaré mi misericordia hacia él(BA),
y mi pacto(BB) le será confirmado.
29 Así estableceré su descendencia[x] para siempre(BC),
y su trono(BD) como los días de los cielos(BE).
30 Si sus hijos abandonan mi ley(BF)
y no andan en mis juicios,
31 si violan[y] mis estatutos
y no guardan mis mandamientos,
32 entonces castigaré con vara(BG) su transgresión,
y con azotes su iniquidad.
33 Pero no quitaré de él mi misericordia(BH),
ni obraré falsamente en mi fidelidad.
34 No quebrantaré[z] mi pacto(BI),
ni cambiaré la palabra[aa](BJ) de mis labios.
35 Una vez[ab] he jurado por mi santidad(BK);
no mentiré a David.
36 Su descendencia[ac] será para siempre(BL),
y su trono como el sol(BM) delante de mí.
37 Será establecido para siempre como la luna(BN),
fiel testigo(BO) en el cielo. (Selah[ad])
38 Pero tú lo has rechazado y desechado(BP),
contra[ae] tu ungido(BQ) te has enfurecido.
39 Has despreciado(BR) el pacto de tu siervo;
has profanado(BS) su corona(BT) echándola por tierra.
40 Has derribado(BU) todos sus muros;
has convertido en ruinas sus fortalezas(BV).
41 Todos los que pasan por el camino(BW) lo saquean;
ha venido a ser una afrenta(BX) para sus vecinos.
42 Tú has exaltado(BY) la diestra de sus adversarios;
has hecho regocijarse a todos sus enemigos(BZ).
43 Has retirado también el filo de su espada,
y no le has hecho estar firme en la batalla(CA).
44 Has hecho cesar su esplendor[af](CB),
y has echado por tierra su trono.
45 Has acortado los días de su juventud(CC);
lo has cubierto de ignominia(CD). (Selah)
46 ¿Hasta cuándo, Señor?
¿Te esconderás para siempre(CE)?
¿Arderá como el fuego tu furor(CF)?
47 Recuerda cuán breve es mi vida[ag](CG);
¡con qué propósito vano(CH) has creado a todos los hijos de los hombres![ah]
48 ¿Qué hombre podrá vivir y no ver la muerte(CI)?
¿Podrá librar su alma(CJ) del poder[ai] del Seol[aj]? (Selah)
49 ¿Dónde están, Señor, tus misericordias de antes,
que en tu fidelidad juraste a David(CK)?
50 Recuerda, Señor, el oprobio de tus siervos(CL);
cómo llevo dentro de mí[ak] el oprobio de muchos[al] pueblos,
51 con el cual tus enemigos(CM), oh Señor, han injuriado,
con el cual han injuriado los pasos de tu ungido(CN).
52 ¡Bendito sea el Señor para siempre!
Amén y amén(CO).
Footnotes
- Salmos 89:1 Posiblemente, Salmo didáctico, o contemplativo
- Salmos 89:1 Véase 1 Rey. 4:31; Sal. 88:Subtítulo
- Salmos 89:4 Lit., simiente
- Salmos 89:4 Posiblemente, Pausa, Crescendo, o Interludio
- Salmos 89:6 O, cielo
- Salmos 89:6 O, dioses
- Salmos 89:8 Heb., Yah
- Salmos 89:9 Lit., la subida
- Salmos 89:10 I.e., Egipto
- Salmos 89:10 Lit., tu brazo de tu poder
- Salmos 89:11 Lit., y su plenitud
- Salmos 89:13 Lit., un brazo con fuerza
- Salmos 89:14 O, fidelidad
- Salmos 89:15 O, el sonido de la trompeta
- Salmos 89:17 O, favor
- Salmos 89:17 Lit., cuerno
- Salmos 89:19 Algunos mss. dicen: tu santo
- Salmos 89:19 Lit., He puesto ayuda sobre
- Salmos 89:21 Lit., que
- Salmos 89:21 O, establecida
- Salmos 89:22 O, No lo explotará
- Salmos 89:22 O, el hombre malvado
- Salmos 89:24 Lit., cuerno
- Salmos 89:29 Lit., simiente
- Salmos 89:31 Lit., profanan
- Salmos 89:34 Lit., profanaré
- Salmos 89:34 Lit., lo que sale
- Salmos 89:35 O, Una cosa
- Salmos 89:36 Lit., simiente
- Salmos 89:37 Posiblemente, Pausa, Crescendo, o Interludio
- Salmos 89:38 Lit., con
- Salmos 89:44 Lit., lustre
- Salmos 89:47 Lit., de qué duración yo soy
- Salmos 89:47 O, ¿has creado para vanidad...hombres?
- Salmos 89:48 Lit., de la mano
- Salmos 89:48 I.e., región de los muertos
- Salmos 89:50 Lit., en mi seno
- Salmos 89:50 Lit., todos los muchos
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.
