耶利米书 21
Chinese Contemporary Bible (Simplified)
预言耶路撒冷的沦陷
21 西底迦王派玛基雅的儿子巴施户珥和玛西雅的儿子西番雅祭司来见耶利米的时候,耶利米听到了耶和华的话。当时,他们对耶利米说: 2 “请你为我们求问耶和华,因为巴比伦王尼布甲尼撒来攻打我们,或许耶和华会像以往一样行神迹,使敌人撤军。”
3 耶利米对他们说:“你们要告诉西底迦, 4 以色列的上帝耶和华说,‘看啊,你们与围城的巴比伦王及其率领的迦勒底人作战,我要把你们的兵器掉转过来,我要把它们收集在城中心。 5 我要在烈怒中伸出大能的臂膀下手击打你们, 6 我要击打这城里的居民和牲畜,使他们死于瘟疫。 7 然后,我要把犹大王西底迦及其臣仆以及城中逃过瘟疫、战争和饥荒的人都交给巴比伦王尼布甲尼撒等仇敌,使他们落在想杀灭他们的人手中。巴比伦王必残酷无情地杀戮他们。这是耶和华说的。’
8 “耶利米啊,你要告诉百姓,‘耶和华说,看啊,我把生命之路和死亡之路摆在你们面前, 9 留在这城里的必死于战争、饥荒和瘟疫,出城向迦勒底人投降的必保全性命、逃过一死。 10 我必严惩这城,向它降祸不降福。它必落在巴比伦王手中,被付之一炬。这是耶和华说的。’
11 “你要对犹大的王室说,‘你们要听耶和华的话。 12 大卫家啊,耶和华说,
“‘你们要天天秉公行义,
从压迫者手中解救受剥削的人,
免得你们的恶行激起我的怒火,
如烈焰燃起,无人能灭。
13 耶和华说,耶路撒冷啊,
你坐落在山谷之上,
如平原的磐石,
自以为无人能攻击你,
无人能闯入你的住处。
但我要攻击你,
14 照你的所作所为惩罚你;
我要点燃你的树林,
烧光你周围的一切。
这是耶和华说的。’”
Jeremiah 21
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
Ọlọ́run kọ ìbéèrè Sedekiah sílẹ̀
21 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jeremiah wá nígbà tí ọba Sedekiah rán Paṣuri ọmọ Malkiah àti àlùfáà Sefaniah ọmọ Maaseiah sí i; wọ́n wí pé: 2 “Wádìí lọ́wọ́ Olúwa fún wa nítorí Nebukadnessari ọba Babeli ń kọlù wá. Bóyá Olúwa yóò ṣe ìyanu fún wa gẹ́gẹ́ bí ti àtẹ̀yìnwá, kí ó sì yípadà kúrò lọ́dọ̀ wa.”
3 Ṣùgbọ́n Jeremiah dáhùn wí pé, “Sọ fún Sedekiah, 4 ‘Èyí ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli wí: Èmi fẹ́ kọjú idà tí ó wà lọ́wọ́ yín sí yín, èyí tí ẹ̀ ń lò láti bá ọba àti àwọn ará Babeli tí wọ́n wà lẹ́yìn odi jà, Èmi yóò sì kó wọn jọ sínú ìlú yìí. 5 Èmi gan an yóò sì bá yín jà pẹ̀lú ohun ìjà olóró nínú ìbínú àti ìrunú líle. 6 Èmi yóò sì lu gbogbo ìlú yìí, ènìyàn àti ẹranko, gbogbo wọn ni àjàkálẹ̀-ààrùn yóò kọlù tí wọn yóò sì kú. 7 Olúwa sọ pé lẹ́yìn èyí, èmi yóò fi Sedekiah ọba Juda, àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àti àwọn ènìyàn, àti àwọn tí ó kù ní ìlú yìí lọ́wọ́ àjàkálẹ̀-ààrùn àti lọ́wọ́ idà, àti lọ́wọ́ ìyàn; èmi yóò fi wọ́n lé Nebukadnessari ọba Babeli lọ́wọ́, àti lé ọwọ́ àwọn ọ̀tá wọn, àti lé ọwọ́ àwọn tí ń lépa ẹ̀mí wọn, òun yóò sì fi ojú idà pa wọ́n, kì yóò sì dá wọn sí, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò ní ìyọ́nú tàbí ṣàánú wọn.’
8 “Síwájú sí i, sọ fún àwọn ènìyàn, ‘Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó sọ: Wò ó, Èmi ń fi ọ̀nà ìyè àti ikú hàn yín. 9 Ẹnikẹ́ni tí ó bá dúró sí ìlú yìí yóò ti ipa idà, ìyàn tàbí àjàkálẹ̀-ààrùn kú. Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá jáde tí ó sì jọ̀wọ́ ara rẹ̀ fún àwọn Babeli tí ó ń lépa yín yóò sì yè. Òun yóò sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ̀. 10 Mo ti pinnu láti jẹ ìlú yìí ní yà, ni Olúwa wí. A ó sì gbé e fún ọba Babeli, yóò sì run ún pẹ̀lú iná.’
11 “Ẹ̀wẹ̀, wí fún ìdílé ọba Juda pé, ‘Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa. 12 Ilé Dafidi èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa sọ:
“ ‘Ṣe ìdájọ́ tí ó tọ́ ní àràárọ̀;
yọ ọ́ kúrò lọ́wọ́ ẹni tí ó ń ni í lára
ẹni tí a ti jà lólè
bí bẹ́ẹ̀ kọ́ ìbínú mi yóò jáde síta, yóò sì jó bí iná.
Nítorí ibi tí a ti ṣe yóò sì jó
láìsí ẹni tí yóò pa á.
13 Mo kẹ̀yìn sí ọ, Jerusalẹmu
ìwọ tí o gbé lórí àfonífojì
lórí òkúta tí ó tẹ́jú, ni Olúwa wí.
Ìwọ tí o ti wí pé, “Ta ni ó le dojúkọ wá?
Ta ni yóò wọ inú ibùgbé wa?”
14 Èmi yóò jẹ ọ ní ìyà gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀
ni Olúwa wí.
Èmi yóò mú kí iná jó ilé rẹ̀;
yóò si jó gbogbo ohun tí ó wà ní àyíká rẹ.’ ”
Chinese Contemporary Bible Copyright © 1979, 2005, 2007, 2011 by Biblica® Used by permission. All rights reserved worldwide.
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.