瓦瓶的比喻

19 耶和华对我说: “你去向陶匠买一个瓦瓶,带着百姓和祭司中的一些首领到哈珥西[a]城门旁的欣嫩子谷,在那里宣告我的话。 你要说,‘犹大王和耶路撒冷的居民啊,你们要听耶和华的话!以色列的上帝——万军之耶和华说,看啊,我要在这里降下灾祸,听见这消息的人都必耳鸣。 因为他们背弃了我,玷污了这地方。他们向自己、自己的祖先及犹大君王都不认识的神明烧香,使这地方流满了无辜人的血。 他们为巴力建丘坛,烧死自己的儿子作燔祭献给巴力。我从未吩咐他们这样做,连提都没提过,连想都没想过。 因此,看啊,时候将到,这地方不再叫陀斐特或欣嫩子谷,要叫杀戮谷。这是耶和华说的。 我要在这地方挫败犹大人和耶路撒冷居民的计谋,使他们丧身在敌人刀下,死在仇敌手中,尸体成为飞鸟和野兽的食物。 我必摧毁这城,使它令人惊惧、嗤笑,它的满目疮痍必令路人惊惧、嗤笑。 我必使他们在敌人的围困之下陷入绝境,吃儿女和亲友的肉。’

10 “耶利米啊,你要在同去的人面前打碎瓦瓶, 11 然后告诉他们万军之耶和华说,‘我要把这百姓和这城打得粉碎,正如人打碎瓦瓶一样,再也不能修复。人们要在陀斐特埋死人,直到无处可埋。 12 我必这样惩罚这城和其中的居民,使这城像陀斐特一样。这是耶和华说的。 13 耶路撒冷的房屋和犹大君王的宫殿将被玷污,像陀斐特一样,因为他们在房顶向天上的万象烧香,向别的神明奠酒。’”

14 耶利米奉耶和华之命到陀斐特说预言回来后,站在耶和华殿的院子中对百姓说: 15 “以色列的上帝——万军之耶和华说,‘看啊,我要把我说过的灾祸降在这城及其周围的村庄,因为他们顽固不化,不肯听我的话。’”

Footnotes

  1. 19:2 哈珥西”意思是“碎陶片”。

19 Èyí ní ohun tí Olúwa wí: “Lọ ra ìkòkò lọ́dọ̀ alámọ̀, mú dání lára àwọn àgbàgbà ọkùnrin àti wòlíì. Kí o sì lọ sí Àfonífojì ọmọ Beni-Hinnomu, níwájú ẹnu ibodè Harsiti, níbẹ̀ ni kí o sì kéde gbogbo ọ̀rọ̀ tí èmi yóò sọ fún ọ. Kí o sì wí pé ‘Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ẹ̀yin ọba àwọn Juda àti ẹ̀yin ará Jerusalẹmu. Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli sọ. Dẹtí sí mi! Èmi yóò mú ìparun wá síbí, etí gbogbo wọn tó bá gbọ́ ọ yóò hó yaya. Nítorí wọ́n ti gbàgbé mi, wọ́n sì ti sọ ibí di ilé fún òrìṣà àjèjì; wọ́n ti sun ẹbọ nínú rẹ̀ fún òrìṣà tí àwọn baba wọn tàbí tí ọba Juda kò mọ̀ rí, wọ́n ti fi ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ kún ilẹ̀ yìí. Wọ́n ti kọ́ ibi gíga fún Baali láti sun ọmọkùnrin wọn gẹ́gẹ́ bí ohun ẹbọ sísun sí Baali—èyí tí èmi kò pàṣẹ láti ṣe, tí èmi kò sì sọ, tàbí tí kò sì ru sókè láti inú ọkàn mi. Nítorí náà ṣọ́ra ọjọ́ ń bọ̀ ni Olúwa wí nígbà tí àwọn ènìyàn kì yóò pe ibí ní Tofeti mọ́ tàbí Àfonífojì ọmọ Hinnomu, ṣùgbọ́n Àfonífojì Ìpakúpa.

“ ‘Ní ibí yìí ni èmi yóò ti pa èrò Juda àti Jerusalẹmu run. Èmí yóò mú wọn ṣubú nípa idà níwájú àwọn ọ̀tá wọn, lọ́wọ́ àwọn tí ó ń wá ẹ̀mí wọn. Èmi yóò sì fi òkú wọn ṣe oúnjẹ fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run àti ẹranko ilẹ̀. Èmi yóò sọ ìlú yìí di ahoro àti ohun ẹ̀gàn, gbogbo àwọn tí ń kọjá yóò bẹ̀rù wọn yóò sì máa fòyà nítorí gbogbo ọgbẹ́ rẹ̀. Èmi yóò mú kí wọ́n jẹ ẹran-ara ọmọ wọn ọkùnrin àti ẹran-ara ọmọ wọn obìnrin, ẹnìkínní yóò sì jẹ ẹran-ara ẹnìkejì, nígbà ìdótì àti ìhámọ́ láti ọwọ́ ọ̀tá wọn, àti àwọn tí ó ń wá ẹ̀mí wọn.’

10 “Nígbà náà ni ìwọ yóò fọ́ ìkòkò náà ní ojú àwọn tí ó bá ọ lọ. 11 Kí o sì sọ fún wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. Èmi a fọ́ orílẹ̀-èdè yìí àti ìlú yìí gẹ́gẹ́ bí ìkòkò amọ̀ yìí ṣe fọ́ tí kò sì ní sí àtúnṣe. Wọn a sì sin àwọn òkú sí Tofeti títí tí kò fi ní sí ààyè mọ́. 12 Èyí ni ohun tí èmi yóò ṣe sí ibí yìí àti àwọn tí ń gbé ní ibí yìí ni Olúwa wí. Èmi yóò mú ìlú yìí dàbí Tofeti. 13 (A)Àwọn ilé tí ó wà ní Jerusalẹmu àti ti ọba ìlú Juda ni a ó sọ di àìmọ́ bí Tofeti, gbogbo ilé tí wọ́n ti ń sun tùràrí ni orí òrùlé sí gbogbo ogun ọ̀run, tí a sì ń rú ẹbọ mímu sí ọlọ́run mìíràn.’ ”

14 Jeremiah sì padà láti Tofeti níbi tí Olúwa rán an sí láti sọ àsọtẹ́lẹ̀ ó sì dúró ní gbangba tẹmpili Olúwa, ó sì sọ fún gbogbo ènìyàn pé, 15 “Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Tẹ́tí sílẹ̀! Èmi yóò mú ìdààmú tí mo ti sọ àsọtẹ́lẹ̀ rẹ̀ bá ìlú yìí àti ìgbèríko tí ó yí i ká, nítorí ọlọ́rùn líle ni wọ́n, wọn kò si ní fẹ́ fetí sí ọ̀rọ̀ mi.’ ”