Add parallel Print Page Options

善恶互论垂为箴言

15 回答柔和使怒消退,言语暴戾触动怒气。 智慧人的舌善发知识,愚昧人的口吐出愚昧。 耶和华的眼目无处不在,恶人善人他都鉴察。 温良的舌是生命树,乖谬的嘴使人心碎。 愚妄人藐视父亲的管教,领受责备的得着见识。 义人家中多有财宝,恶人得利反受扰害。 智慧人的嘴播扬知识,愚昧人的心并不如此。 恶人献祭为耶和华所憎恶,正直人祈祷为他所喜悦。 恶人的道路为耶和华所憎恶,追求公义的为他所喜爱。 10 舍弃正路的必受严刑,恨恶责备的必致死亡。 11 阴间和灭亡尚在耶和华眼前,何况世人的心呢? 12 亵慢人不爱受责备,他也不就近智慧人。 13 心中喜乐,面带笑容;心里忧愁,灵被损伤。 14 聪明人心求知识,愚昧人口吃愚昧。 15 困苦人的日子都是愁苦,心中欢畅的常享丰筵。 16 少有财宝敬畏耶和华,强如多有财宝烦乱不安。 17 吃素菜彼此相爱,强如吃肥牛彼此相恨。 18 暴怒的人挑起争端,忍怒的人止息纷争。 19 懒惰人的道像荆棘的篱笆,正直人的路是平坦的大道。 20 智慧子使父亲喜乐,愚昧人藐视母亲。 21 无知的人以愚妄为乐,聪明的人按正直而行。 22 不先商议,所谋无效;谋士众多,所谋乃成。 23 口善应对,自觉喜乐;话合其时,何等美好。 24 智慧人从生命的道上升,使他远离在下的阴间。 25 耶和华必拆毁骄傲人的家,却要立定寡妇的地界。 26 恶谋为耶和华所憎恶,良言乃为纯净。 27 贪恋财利的扰害己家,恨恶贿赂的必得存活。 28 义人的心思量如何回答,恶人的口吐出恶言。 29 耶和华远离恶人,却听义人的祷告。 30 眼有光使心喜乐,好信息使骨滋润。 31 听从生命责备的,必常在智慧人中。 32 弃绝管教的,轻看自己的生命;听从责备的,却得智慧。 33 敬畏耶和华是智慧的训诲,尊荣以前必有谦卑。

15 Ìdáhùn pẹ̀lẹ́ yí ìbínú padà
    ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ líle máa ń ru ìbínú sókè.

Ahọ́n ọlọ́gbọ́n a máa gbé ìmọ̀ jáde
    ṣùgbọ́n ẹnu aláìgbọ́n ń tú ọ̀rọ̀ ọ òmùgọ̀ jáde.

Ojú Olúwa wà níbi gbogbo,
    Ó ń wo àwọn ẹni búburú àti àwọn ẹni rere.

Ahọ́n tí ń mú ìtura wá jẹ́ igi ìyè
    ṣùgbọ́n ahọ́n ẹ̀tàn ń pa ẹ̀mí run.

Aláìgbọ́n ọmọ kọ ìbáwí baba rẹ̀
    ṣùgbọ́n ẹni tí ó gbọ́ ìbáwí jẹ́ ọlọ́gbọ́n.

Ilé olódodo kún fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ohun ìṣúra,
    ṣùgbọ́n èrè àwọn ènìyàn búburú ń mú ìyọnu wá fún wọn.

Ètè olódodo ń tan ìmọ̀ kalẹ̀;
    ṣùgbọ́n kò rí bẹ́ẹ̀ fún ọkàn aláìgbọ́n.

Olúwa kórìíra ìrúbọ àwọn ènìyàn búburú
    ṣùgbọ́n àdúrà olódodo tẹ́ ẹ lọ́rùn.

Olúwa kórìíra ọ̀nà àwọn ènìyàn búburú,
    ṣùgbọ́n ó fẹ́ràn àwọn tí ń lépa òdodo.

10 Ẹni tí ó kúrò lójú ọ̀nà yóò rí ìbáwí gan an,
    ẹni tí ó kórìíra ìbáwí yóò kú.

11 Ikú àti ìparun ṣí sílẹ̀ níwájú Olúwa,
    mélòó mélòó ní nínú ọkàn àwọn ènìyàn.

12 Ẹlẹ́gàn kò fẹ́ ẹni tí ń ba wí:
    kò ní gbàmọ̀ràn lọ́dọ̀ ọlọ́gbọ́n.

13 Inú dídùn máa ń mú kí ojú túká
    ṣùgbọ́n ìbànújẹ́ ọkàn máa ń pa ẹ̀mí run.

14 Ọkàn olóye ń wá ìmọ̀
    ṣùgbọ́n ẹnu aláìgbọ́n ń fẹ́ ìwà òmùgọ̀ bí ẹní jẹun.

15 Gbogbo ọjọ́ àwọn olùpọ́njú jẹ́ ibi,
    ṣùgbọ́n onínúdídùn ń jẹ àlàáfíà ní ìgbà gbogbo.

16 Ó sàn kí ó má pọ̀, kí ìbẹ̀rù Olúwa sì wà
    ju ọrọ̀ púpọ̀ pẹ̀lú ìyọnu.

17 Oúnjẹ ewébẹ̀ níbi tí ìfẹ́ wà
    sàn ju àbọ́pa màlúù tòun ti ìríra.

18 Ènìyàn onínú ríru dá ìjà sílẹ̀
    ṣùgbọ́n onísùúrù paná ìjà.

19 Ọ̀nà ọ̀lẹ ni ẹ̀gún dí,
    ṣùgbọ́n ọ̀nà olódodo já geerege ni.

20 Ọlọ́gbọ́n ọmọ mú inú baba rẹ̀ dùn,
    ṣùgbọ́n aṣiwèrè ènìyàn kẹ́gàn ìyá rẹ̀.

21 Inú ènìyàn aláìlóye a máa dùn sí ìwà òmùgọ̀;
    ṣùgbọ́n olóye ènìyàn a máa rin ọ̀nà tààrà.

22 Ìgbèrò a máa dasán níbi tí kò sí ìmọ̀ràn;
    ṣùgbọ́n a máa yege níbi tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ olùbádámọ̀ràn wà.

23 Inú ènìyàn a máa dùn nígbà tí ó bá fèsì tó yẹ
    ọ̀rọ̀ tí ó bá sì wá lásìkò tó yẹ dára púpọ̀!

24 Ọ̀nà ìyè ń lọ sókè fún ọlọ́gbọ́n
    láti sọ kí ó má bá à sọ̀kalẹ̀ lọ sí ipò òkú.

25 Olúwa fa ilé onígbèéraga ya lulẹ̀,
    ṣùgbọ́n ó pa ààlà opó onírẹ̀lẹ̀ mọ́ láìyẹ̀.

26 Olúwa kórìíra èrò ènìyàn búburú, ṣùgbọ́n mímọ́ ni ọ̀rọ̀ ẹni pípé.

27 Ọ̀kánjúwà ènìyàn mú ìyọnu bá ilé rẹ̀
    ṣùgbọ́n ẹni tí ó kórìíra àbẹ̀tẹ́lẹ̀ yóò yè.

28 Ọkàn olódodo ń wọn ìdáhùn wò
    ṣùgbọ́n ẹnu ènìyàn búburú ń tú ibi jáde.

29 Olúwa jìnnà sí ènìyàn búburú
    ṣùgbọ́n ó ń gbọ́ àdúrà olódodo.

30 Ojú tó túká máa ń mú ayọ̀ wá fún ọkàn,
    ìròyìn ayọ̀ sì ń mú ìlera wá sínú egungun.

31 Ẹni tí ó fetí sí ìbáwí tí ń fún ni ní ìyè,
    yóò wà ní àpéjọpọ̀ àwọn ọlọ́gbọ́n.

32 Ẹni tí ó kọ̀ ìbáwí kẹ́gàn ara rẹ̀,
    Ṣùgbọ́n ẹni tí ó gbọ́ ìbáwí yóò ní ìmọ̀ sí i.

33 Ìbẹ̀rù Olúwa kọ́ ènìyàn ní ọgbọ́n,
    Ìrẹ̀lẹ̀ sì ni ó máa ń ṣáájú ọlá.