2 Kronika 7
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
Ìyàsímímọ́ ilé Olúwa
7 Nígbà tí Solomoni sì ti parí àdúrà, iná sọ̀kalẹ̀ láti ọ̀run ó sì jó ẹbọ sísun àti ẹbọ, ògo Ọlọ́run sì kún ilé Olúwa. 2 Àwọn àlùfáà kò sì le wo ilé Olúwa náà nítorí pé ògo Olúwa kún un. 3 Nígbà tí gbogbo àwọn ọmọ Israẹli rí iná tí ó ń sọ̀kalẹ̀ àti ògo Olúwa lórí ilé Olúwa náà, wọ́n sì kúnlẹ̀ lórí eékún wọn pẹ̀lú ojú ni dídàbolẹ̀, wọ́n sì sin Olúwa, wọ́n sì fi ìyìn fún Olúwa wí pé,
“Nítorí tí ó dára;
àánú rẹ̀ sì dúró títí láéláé.”
4 (A)Nígbà náà ọba àti gbogbo àwọn ènìyàn sì rú ẹbọ níwájú Olúwa. 5 Ọba Solomoni sì rú ẹbọ ti ẹgbàá-mọ́kànlá (22,000), orí màlúù àti àgùntàn àti ọ̀kẹ́ mẹ́fà àgùntàn àti ẹranko. Bẹ́ẹ̀ ni ọba àti gbogbo àwọn ènìyàn ya ilé Ọlọ́run sí mímọ́. 6 Àwọn àlùfáà dúró ní ààyè wọn, gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ Lefi ti ṣe pẹ̀lú ohun èlò orin Olúwa, tí ọba Dafidi ti ṣe fún ìyìn Olúwa àti tí á lò nígbà tí ó dúpẹ́, wí pé, “àánú rẹ̀ sì dúró láéláé,” níwájú àwọn ọmọ Lefi, àwọn àlùfáà sì fọn ìpè, gbogbo àwọn ọmọ Israẹli sì dúró.
7 Solomoni sì yà àgbàlá níwájú ilé Olúwa sọ́tọ̀, níbẹ̀ sì ni ó ti ṣe ìrúbọ ẹbọ sísun àti ọ̀rá ẹbọ àlàáfíà, nítorí pẹpẹ idẹ tí ó ti ṣe kò lè gba ẹbọ sísun, àti ọrẹ oúnjẹ, àti ọ̀rá náà.
8 Bẹ́ẹ̀ ni Solomoni ṣe àsè ní àkókò náà fún ọjọ́ méje àti gbogbo àwọn ọmọ Israẹli pẹ̀lú rẹ̀ àti ìjọ ènìyàn ńlá, àwọn ènìyàn láti Lebo-Hamati títí dé odò Ejibiti. 9 Ní ọjọ́ kẹjọ, wọ́n sì pe ìjọ ènìyàn jọ nítorí tí wọ́n pe àpèjẹ ìyàsímímọ́ ti orí pẹpẹ fún ọjọ́ méje àti àsè náà fún ọjọ́ méje sí i. 10 Ní ọjọ́ kẹtàlélógún tí oṣù keje, ó sì rán àwọn ènìyàn padà sí ilé wọn, pẹ̀lú ayọ̀ àti ìdùnnú nínú wọn fún ohun rere tí Olúwa ti ṣe fún Dafidi àti Solomoni, àti fún àwọn ènìyàn Israẹli.
Olúwa fi ara han Solomoni
11 (B)Nígbà tí Solomoni ti parí ilé Olúwa àti ibi ilé ọba, nígbà tí ó sì ti ṣe àṣeyọrí láti gbé jáde gbogbo ohun tí ó ní lọ́kàn láti ṣe nínú ilé Olúwa àti nínú ilé òun tìkára rẹ̀, 12 Olúwa sì farahàn Solomoni ní òru ó sì wí pé:
“Èmi ti gbọ́ àdúrà rẹ mo sì ti yàn ibí yìí fún ara mi gẹ́gẹ́ bí ilé fún ẹbọ.
13 “Nígbà tí mo bá sé ọ̀run kí ó ma bá à sí òjò, tàbí láti pàṣẹ fún eṣú láti jẹ ilẹ̀ náà run tàbí rán àjàkálẹ̀-ààrùn sí àárín àwọn ènìyàn mi, 14 tí àwọn ènìyàn, tí a fi orúkọ mi pè, tí wọ́n bá rẹ ara wọn sílẹ̀, tí wọ́n sì gbàdúrà, tí wọ́n sì rí ojú mi, tí wọ́n sì yí kúrò nínú ọ̀nà búburú wọn, nígbà náà, èmi yóò gbọ́ láti ọ̀run, èmi yóò sì dárí ẹ̀ṣẹ̀ wọn jì wọ́n èmi yóò sì wo ilẹ̀ wọn sàn. 15 Nísinsin yìí, ojú mi yóò sì là etí mi yóò sì là, sí àdúrà ọrẹ níbí yìí. 16 Èmi sì ti yàn, èmi sì ti ya ilé yìí sí mímọ́ bẹ́ẹ̀ ni kí orúkọ mi kí ó le wà níbẹ̀ títí láéláé.
17 “Ní ti bí ìwọ bá rìn níwájú mi gẹ́gẹ́ bí Dafidi baba rẹ ti ṣe, tí o sì ṣe gbogbo ohun tí mo paláṣẹ, tí ìwọ sì ṣe àkíyèsí àṣẹ mi láti ọ̀run: 18 Èmi yóò fi ìdí ìtẹ́ ìjọba rẹ múlẹ̀, gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe pẹ̀lú Dafidi baba rẹ nígbà tí mo bá a dá májẹ̀mú wí pé, ìwọ kò ní fẹ́ ẹnìkan kù láti ṣe alákòóso lórí Israẹli.
19 “Ṣùgbọ́n tí ìwọ bá yípadà tí o sì kọ òfin mi sílẹ̀ àti àṣẹ tí mo ti fi fún yín tí ẹ sì lọ sókè láti lọ sin ọlọ́run mìíràn tí ẹ sì bọ wọ́n, 20 Nígbà náà ni èmi yóò fa Israẹli tu kúrò láti ilẹ̀ mi, èyí tí èmi ti fi fún wọn, èmi yóò sì kọ̀ ilé náà sílẹ̀ èyí tí èmi ti yà sọ́tọ̀ fún orúkọ mi, èmi yóò sì fi ṣe ọ̀rọ̀ òwe, n ó fi ṣe ẹlẹ́yà láàrín gbogbo ènìyàn, 21 Àti ní gbogbo àyíká ilé yìí nísinsin yìí, bẹ́ẹ̀ ni yóò di ohun ìtànjẹ; gbogbo àwọn tí ó bá sì kọjá níbẹ̀ ni yóò jáláyà, wọn yóò sì wí pé, ‘Kí ni ó dé tí Olúwa fì ṣe irú èyí sí ilẹ̀ yí àti sí ilé yìí?’ 22 Àwọn ènìyàn yóò sì dáhùn wí pé: ‘Nítorí tí wọ́n ti kọ̀ Olúwa sílẹ̀, Ọlọ́run baba wọn ẹni tí ó mú wọn jáde láti Ejibiti wá, wọ́n sì ti fi ọwọ́ gba ọlọ́run mìíràn mọ́ra, wọ́n bọ wọ́n, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì ń sìn wọ́n, ìdí nìyí tí ó fi mú gbogbo ìjàǹbá náà wá sórí wọn.’ ”
2 Chronicles 7
English Standard Version
Fire from Heaven
7 (A)As soon as Solomon finished his prayer, (B)fire came down from heaven and consumed the burnt offering and the sacrifices, (C)and the glory of the Lord filled the temple. 2 And the priests could not enter the house of the Lord, because the glory of the Lord filled the Lord's house. 3 When all the people of Israel saw the fire come down and the glory of the Lord on the temple, they bowed down with their faces to the ground on the pavement and worshiped and gave thanks to the Lord, saying, “For he is good, (D)for his steadfast love endures forever.”
The Dedication of the Temple
4 (E)Then the king and all the people offered sacrifice before the Lord. 5 King Solomon offered as a sacrifice 22,000 oxen and 120,000 sheep. So the king and all the people dedicated the house of God. 6 The priests stood at their posts; (F)the Levites also, with the instruments for music to the Lord that King David had made for giving thanks to the Lord—(G)for his steadfast love endures forever—whenever David offered praises by their ministry;[a] (H)opposite them the priests sounded trumpets, and all Israel stood.
7 (I)And Solomon consecrated the middle of the court that was before the house of the Lord, for there he offered the burnt offering and the fat of the peace offerings, because the bronze altar Solomon had made could not hold the burnt offering and the grain offering and the fat.
8 At that time Solomon held the feast for seven days, and all Israel with him, a very great assembly, from (J)Lebo-hamath to the (K)Brook of Egypt. 9 And on the eighth day they held a solemn assembly, for they had kept the dedication of the altar seven days and the feast seven days. 10 On the twenty-third day of the seventh month he sent the people away to their homes, joyful and glad of heart for the prosperity[b] that the Lord had granted to David and to Solomon and to Israel his people.
If My People Pray
11 (L)Thus Solomon finished the house of the Lord and the king's house. All that Solomon had planned to do in the house of the Lord and in his own house he successfully accomplished. 12 Then the Lord appeared to Solomon in the night and said to him: “I have heard your prayer (M)and have chosen this place for myself as a house of sacrifice. 13 (N)When I shut up the heavens so that there is no rain, or command the locust to devour the land, or send pestilence among my people, 14 if my people who are called by my name (O)humble themselves, and pray and seek my face and turn from their wicked ways, then I will hear from heaven and will forgive their sin and heal their land. 15 (P)Now my eyes will be open and my ears attentive to the prayer that is made in this place. 16 (Q)For now I have chosen and consecrated this house that my name may be there forever. My eyes and my heart will be there for all time. 17 And as for you, if you will walk before me as David your father walked, doing according to all that I have commanded you and keeping my statutes and my rules, 18 then I will establish your royal throne, as I covenanted with David your father, saying, (R)‘You shall not lack a man to rule Israel.’
19 (S)“But if you[c] turn aside and forsake my statutes and my commandments that I have set before you, and go and serve other gods and worship them, 20 (T)then I will pluck you[d] up from my land that I have given you, and this house that I have consecrated for my name, I will cast out of my sight, and I will make it (U)a proverb and a byword among all peoples. 21 And at this house, which was exalted, everyone passing by will be astonished and say, (V)‘Why has the Lord done thus to this land and to this house?’ 22 Then they will say, ‘Because they abandoned the Lord, the God of their fathers who brought them out of the land of Egypt, and laid hold on other gods and worshiped them and served them. Therefore he has brought all this disaster on them.’”
Footnotes
- 2 Chronicles 7:6 Hebrew by their hand
- 2 Chronicles 7:10 Or good
- 2 Chronicles 7:19 The Hebrew for you is plural here
- 2 Chronicles 7:20 Hebrew them; twice in this verse
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.
The ESV® Bible (The Holy Bible, English Standard Version®), © 2001 by Crossway, a publishing ministry of Good News Publishers. ESV Text Edition: 2025.
