Hosea 11
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
Ìfẹ́ Ọlọ́run sí Israẹli
11 (A)“Nígbà tí Israẹli wà ní ọmọdé mo fẹ́ràn rẹ̀,
mo sì pe ọmọ mi jáde láti Ejibiti wá.
2 Bí a ti ń pe wọn,
bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣe ń sá kúrò lọ́dọ̀ mi,
wọn rú ẹbọ sí Baali,
wọn sì fi tùràrí jóná sí ère fínfín.
3 Lóòtítọ́ mo kọ́ Efraimu pẹ̀lú ní ìrìn
mo di wọ́n mú ní apá,
ṣùgbọ́n wọn kò mọ̀
pé mo ti mú wọn láradá.
4 Mo fi okùn ènìyàn fà wọ́n
àti ìdè ìfẹ́.
Mo mú àjàgà kúrò ni ọrùn wọn
Mo sì fi ara balẹ̀ fún wọn ni oúnjẹ.
5 “Ṣé wọn ò wá ní padà sí Ejibiti bí
Ṣé Asiria kò sì ní jẹ ọba lé wọn lórí bí
nítorí pé wọ́n kọ̀ jálẹ̀ láti ronúpìwàdà?
6 Idà yóò kọ mọ̀nà ní gbogbo ìlú wọn
yóò si bá gbogbo irin ẹnu odi ìlú wọn jẹ́
yóò sì fi òpin sí gbogbo èrò wọn.
7 Àwọn ènìyàn mi ti pinnu láti pẹ̀yìndà kúrò lọ́dọ̀ mi
bí wọ́n tilẹ̀ pè wọ́n sọ́dọ̀ Ọ̀gá-ògo jùlọ,
kò ní gbé wọn ga rárá.
8 “Báwo ni èmi ó ṣe fi ọ́ sílẹ̀, Efraimu?
Báwo ni èmi ó ṣe yọ̀ǹda rẹ̀, Israẹli
Báwo ni mo ṣe lè ṣe ọ bi i Adma?
Báwo ni mo ṣe lè ṣe ọ bi i Ṣeboimu?
Ọkàn mi yípadà nínú mi
àánú mi sì ru sókè
9 Èmi kò ni mú ìbínú gbígbóná mi ṣẹ,
tàbí kí èmi wá sọ Efraimu di ahoro.
Nítorí pé èmi ni Ọlọ́run, àní, èmi kì í ṣe ènìyàn
Ẹni mímọ́ láàrín yín,
Èmi kò ní í wá nínú ìbínú
10 Wọn yóò máa tẹ̀lé Olúwa;
òun yóò bú ramúramù bí i kìnnìún
Nígbà tó bá bú
àwọn ọmọ rẹ yóò wá ní ìwárìrì láti ìwọ̀-oòrùn.
11 Wọn ó wá pẹ̀lú ẹ̀rù
bí i ẹyẹ láti Ejibiti
bí i àdàbà láti Asiria
Èmi ó mú wọn padà sí ilé wọn,”
ni Olúwa wí.
Ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli
12 Efraimu tí fi irọ́ yí mi ká
ilé Israẹli pẹ̀lú ẹ̀tàn.
Ṣùgbọ́n Juda sì dúró ṣinṣin pẹ̀lú Ọlọ́run
Ó sì ṣe olóòtítọ́ sí Ẹni mímọ́ Israẹli.
Hosea 11
The Message
Israel Played at Religion with Toy Gods
11 1-9 “When Israel was only a child, I loved him.
I called out, ‘My son!’—called him out of Egypt.
But when others called him,
he ran off and left me.
He worshiped the popular sex gods,
he played at religion with toy gods.
Still, I stuck with him. I led Ephraim.
I rescued him from human bondage,
But he never acknowledged my help,
never admitted that I was the one pulling his wagon,
That I lifted him, like a baby, to my cheek,
that I bent down to feed him.
Now he wants to go back to Egypt or go over to Assyria—
anything but return to me!
That’s why his cities are unsafe—the murder rate skyrockets
and every plan to improve things falls to pieces.
My people are hell-bent on leaving me.
They pray to god Baal for help.
He doesn’t lift a finger to help them.
But how can I give up on you, Ephraim?
How can I turn you loose, Israel?
How can I leave you to be ruined like Admah,
devastated like luckless Zeboim?
I can’t bear to even think such thoughts.
My insides churn in protest.
And so I’m not going to act on my anger.
I’m not going to destroy Ephraim.
And why? Because I am God and not a human.
I’m The Holy One and I’m here—in your very midst.
10-12 “The people will end up following God.
I will roar like a lion—
Oh, how I’ll roar!
My frightened children will come running from the west.
Like frightened birds they’ll come from Egypt,
from Assyria like scared doves.
I’ll move them back into their homes.”
God’s Word!
Soul-Destroying Lies
Ephraim tells lies right and left.
Not a word of Israel can be trusted.
Judah, meanwhile, is no better,
addicted to cheap gods.
* * *
Copyright © 2004 by World Bible Translation Center
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.
Copyright © 1993, 2002, 2018 by Eugene H. Peterson