Add parallel Print Page Options

Ìkìlọ̀ nítorí àwọn aṣẹ́wó

Ọmọ mi, pa ọ̀rọ̀ mi mọ́,
    sì fi àwọn òfin mi pamọ́ sínú ọkàn rẹ.
Pa òfin mi mọ́, ìwọ yóò sì yè
    tọ́jú ẹ̀kọ́ mi bí ẹyinlójú rẹ
Kọ wọ́n sí ọwọ́ òsì rẹ, má ṣe fi jẹun
    kọ wọ́n sí inú wàláà àyà rẹ.
Wí fún ọgbọ́n pé, “Ìwọ ni arábìnrin mi,”
    sì pe òye ní ìbátan rẹ;
Wọn yóò pa ó mọ́ kúrò lọ́wọ́ obìnrin alágbèrè,
    kúrò lọ́wọ́ àjèjì obìnrin àti ọ̀rọ̀ ìtànjẹ rẹ̀.

Ní ojú fèrèsé ilé è mi
    mo wo ìta láti ojú fèrèsé.
Mo rí i láàrín àwọn aláìmọ̀kan
    mo sì kíyèsi láàrín àwọn ọ̀dọ́kùnrin,
    ọ̀dọ́ kan tí ó ṣe aláìgbọ́n.
Ó ń lọ ní pópónà ní tòsí i ilé alágbèrè obìnrin náà,
    ó ń rìn lọ sí ọ̀nà ilé e rẹ̀
Ní ìrọ̀lẹ́ bí oòrùn ṣe ń wọ̀,
    bí òkùnkùn ṣe ń bo ni lára.

10 Bẹ́ẹ̀ ni obìnrin kan jáde wá láti pàdé rẹ̀,
    ó múra bí panṣágà pẹ̀lú ètè búburú.
11 (Ó jẹ́ aláriwo àti alágídí,
    ìdí rẹ̀ kì í jókòó nílé;
12 bí ó ti ń já níhìn-ín ní ó ń já lọ́hùn ún
    gbogbo orígun ni ó ti ń ba ní ibùba.)
13 Ó dìímú, ó sì fẹnukò ó ní ẹnu
pẹ̀lú ojú díndín ó wí pé:

14 “Mo ní ọrẹ àlàáfíà ní ilé;
    lónìí ni mo san ẹ̀jẹ́ mi.
15 Nítorí náà ni n o ṣe jáde wá pàdé è rẹ;
    mo wá ọ káàkiri mo sì ti rí ọ!
16 Mo ti tẹ́ ibùsùn mi
    pẹ̀lú aṣọ aláràbarà láti ilẹ̀ Ejibiti.
17 Mo ti fi nǹkan olóòórùn dídùn sí ibùsùn mi
    bí i òjìá, aloe àti kinamoni.
18 Wá, jẹ́ kí a lo ìfẹ́ papọ̀ ní kíkún títí di àárọ̀;
    jẹ́ kí a gbádùn ara wa pẹ̀lú ìfẹ́!
19 Ọkọ ọ̀ mi ò sí nílé;
    ó ti lọ sí ìrìnàjò jíjìn.
20 Ó mú owó púpọ̀ lọ́wọ́
    kò sì ní darí dé kí ó tó di ọ̀sán.”

21 Pẹ̀lú ọ̀rọ̀ dídùn ó sì í lọ́nà;
    ó tàn án jẹ pẹ̀lú ẹnu dídùn.
22 Òun sì tọ̀ ọ́ lọ lẹsẹ̀ kan náà,
    bí i màlúù tí ń lọ sí ibùpa,
    tàbí bí (aṣiwèrè) àgbọ̀nrín tí ń lọ sí ibi ọgbọ́n ìfabà kọ́.
23 Títí tí ọ̀kọ̀ fi gún un ní ẹ̀dọ̀,
    bí ẹyẹ ṣe ń fẹ́ wọ inú okùn,
    láìmọ̀ pé yóò gba ẹ̀mí òun.

24 Nítorí náà báyìí ẹ̀yin ọmọ mi, tẹ́tí sí mi
    fọkàn sí nǹkan tí mo sọ.
25 Má ṣe jẹ́ kí ọkàn rẹ kí ó yà sí ọ̀nà rẹ̀,
    tàbí kí ó rìn lọ sí ipa ọ̀nà rẹ̀.
26 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àwọn tí ó ti fà lulẹ̀
    Ogunlọ́gọ̀ àwọn alágbára ni ó ti pa.
27 Ilé e rẹ̀ ni ọ̀nà tààrà sí isà òkú,
    tí ó lọ tààrà sí àgbàlá ikú.

Warning Against the Adulterous Woman

My son,(A) keep my words
    and store up my commands within you.
Keep my commands and you will live;(B)
    guard my teachings as the apple of your eye.
Bind them on your fingers;
    write them on the tablet of your heart.(C)
Say to wisdom, “You are my sister,”
    and to insight, “You are my relative.”
They will keep you from the adulterous woman,
    from the wayward woman with her seductive words.(D)

At the window of my house
    I looked down through the lattice.
I saw among the simple,
    I noticed among the young men,
    a youth who had no sense.(E)
He was going down the street near her corner,
    walking along in the direction of her house
at twilight,(F) as the day was fading,
    as the dark of night set in.

10 Then out came a woman to meet him,
    dressed like a prostitute and with crafty intent.
11 (She is unruly(G) and defiant,
    her feet never stay at home;
12 now in the street, now in the squares,
    at every corner she lurks.)(H)
13 She took hold of him(I) and kissed him
    and with a brazen face she said:(J)

14 “Today I fulfilled my vows,
    and I have food from my fellowship offering(K) at home.
15 So I came out to meet you;
    I looked for you and have found you!
16 I have covered my bed
    with colored linens from Egypt.
17 I have perfumed my bed(L)
    with myrrh,(M) aloes and cinnamon.
18 Come, let’s drink deeply of love till morning;
    let’s enjoy ourselves with love!(N)
19 My husband is not at home;
    he has gone on a long journey.
20 He took his purse filled with money
    and will not be home till full moon.”

21 With persuasive words she led him astray;
    she seduced him with her smooth talk.(O)
22 All at once he followed her
    like an ox going to the slaughter,
like a deer[a] stepping into a noose[b](P)
23     till an arrow pierces(Q) his liver,
like a bird darting into a snare,
    little knowing it will cost him his life.(R)

24 Now then, my sons, listen(S) to me;
    pay attention to what I say.
25 Do not let your heart turn to her ways
    or stray into her paths.(T)
26 Many are the victims she has brought down;
    her slain are a mighty throng.
27 Her house is a highway to the grave,
    leading down to the chambers of death.(U)

Footnotes

  1. Proverbs 7:22 Syriac (see also Septuagint); Hebrew fool
  2. Proverbs 7:22 The meaning of the Hebrew for this line is uncertain.