Add parallel Print Page Options

21 Ọkàn ọba ń bẹ lọ́wọ́ Olúwa;
    a máa darí rẹ̀ lọ ibi tí ó fẹ́ bí ipa omi.

Gbogbo ọ̀nà ènìyàn dàbí i pé ó dára lójú rẹ̀
    ṣùgbọ́n, Olúwa ló ń díwọ̀n ọkàn.

Ṣíṣe ohun tí ó dára tí ó sì tọ̀nà
    ó ṣe ìtẹ́wọ́gbà sí Olúwa ju ẹbọ lọ.

Ojú tí ó gbéga àti ọkàn ìgbéraga,
    ìmọ́lẹ̀ àwọn ènìyàn búburú, ẹ̀ṣẹ̀ ni!

Ètè àwọn olóye jásí èrè
    bí ìkánjú ṣe máa ń fa òsì kíákíá.

Ìṣúra tí a kójọ nípasẹ̀ ahọ́n tí ń parọ́
    jẹ́ ìrì lásán àti ìkẹ́kùn ikú.

Ìwà ipá àwọn ènìyàn búburú yóò wọ́ wọn lọ,
    nítorí wọ́n kọ̀ láti ṣe ohun tí ó tọ́.

Ọ̀nà ẹlẹ́ṣẹ̀ kún fún ìwà ẹ̀ṣẹ̀
    ṣùgbọ́n iṣẹ́ onínú funfun jẹ́ títọ́.

Ó sàn láti máa gbé ní kọ̀rọ̀ orí òrùlé
    ju láti ṣe àjọpín ilé pẹ̀lú aya oníjà.

10 Ènìyàn búburú ń fẹ́ ibi
    aládùúgbò rẹ̀ kì í rí àánú kankan gbà lọ́dọ̀ rẹ̀.

11 Nígbà tí a bá ń fìyà jẹ ẹlẹ́gàn,
    òpè a máa kọ́gbọ́n,
    nígbà tí a bá sì kọ́ ọlọ́gbọ́n yóò ní ìmọ̀.

12 Olódodo ṣàkíyèsí ilé ènìyàn búburú
    ó sì mú ènìyàn búburú wá sí ìparun.

Ìṣúra ẹni tí o gbọ́n

13 Ẹnikẹ́ni tí ó bá ti di etí rẹ̀ sí igbe olùpọ́njú,
    òun tìkára rẹ̀ yóò ké pẹ̀lú;
    ṣùgbọ́n a kì yóò gbọ́.

14 Ọ̀rẹ́ ìkọ̀kọ̀, mú ìbínú kúrò:
    àti owó àbẹ̀tẹ́lẹ̀ láti ibi ìkọ̀kọ̀ wá,
    dẹ́kun ìbínú líle.

15 Ayọ̀ ni fún olódodo láti ṣe ìdájọ́:
    ṣùgbọ́n ìparun ni fún àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀.

16 Ẹni tí ó bá yà kúrò ní ọ̀nà òye,
    yóò máa gbé inú ìjọ àwọn òkú.

17 Ẹni tí ó bá fẹ́ afẹ́, yóò di tálákà:
    ẹni tí ó fẹ́ ọtí wáìnì pẹ̀lú òróró kò le lọ́rọ̀.

18 Ènìyàn búburú ni yóò ṣe owó ìràpadà fún olódodo,
    àti olùrékọjá fún ẹni dídúró ṣinṣin.

19 Ó sàn láti jókòó ní aginjù ju pẹ̀lú
    oníjà obìnrin àti òṣónú lọ.

20 Ìṣúra iyebíye àti òróró wà ní ibùgbé ọlọ́gbọ́n;
    ṣùgbọ́n òmùgọ̀ ènìyàn n bà á jẹ́.

21 Ẹni tí ó bá tẹ̀lé òdodo àti àánú yóò rí ìyè,
    òdodo, àti ọlá.

22 Ọlọ́gbọ́n gòkè odi ìlú àwọn alágbára,
    ó sì bi ibi gíga agbára ìgbẹ́kẹ̀lé wọn ṣubú.

23 Ẹnikẹ́ni tí ó bá pa ẹnu àti ahọ́n rẹ̀ mọ́,
    ó pa ọkàn rẹ̀ mọ́ kúrò nínú ìyọnu.

24 Agbéraga àti alágídí ènìyàn ń gan orúkọ ara rẹ̀ nítorí ó ń hùwà nínú ìwà ìgbéraga rẹ̀,
    àti nínú ìbínú púpọ̀púpọ̀.

25 Ẹlẹ́rìí èké yóò ṣègbé, àwọn tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀ yóò parun láé;
    nítorí tí ọwọ́ rẹ̀ kọ iṣẹ́ ṣíṣe.
26 Ó ń fi ìlara ṣe ojúkòkòrò ní gbogbo ọjọ́:
    ṣùgbọ́n olódodo a máa fi fún ni kì í sì í dáwọ́ dúró.

27 Ẹbọ ènìyàn búburú, ìríra ni:
    mélòó mélòó ni nígbà tí ó mú un wá pẹ̀lú èrò ìwà ibi?

28 Ẹlẹ́rìí èké yóò ṣègbé:
    ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ ẹni tí ó gbọ́, yóò dúró.

29 Ènìyàn búburú mú ojú ara rẹ̀ le:
    ṣùgbọ́n ẹni ìdúró ṣinṣin ni ó ń mú ọ̀nà rẹ̀ tọ́.

30 Kò sí ọgbọ́n, kò sí ìmòye,
    tàbí ìmọ̀ràn tí ó le mókè níwájú Olúwa.

31 A ń múra ẹṣin sílẹ̀ de ọjọ́ ogun:
    ṣùgbọ́n ìṣẹ́gun jẹ́ ti Olúwa.

21 In the Lord’s hand the king’s heart is a stream of water
    that he channels toward all who please him.(A)

A person may think their own ways are right,
    but the Lord weighs the heart.(B)

To do what is right and just
    is more acceptable to the Lord than sacrifice.(C)

Haughty eyes(D) and a proud heart—
    the unplowed field of the wicked—produce sin.

The plans of the diligent lead to profit(E)
    as surely as haste leads to poverty.

A fortune made by a lying tongue
    is a fleeting vapor and a deadly snare.[a](F)

The violence of the wicked will drag them away,(G)
    for they refuse to do what is right.

The way of the guilty is devious,(H)
    but the conduct of the innocent is upright.

Better to live on a corner of the roof
    than share a house with a quarrelsome wife.(I)

10 The wicked crave evil;
    their neighbors get no mercy from them.

11 When a mocker is punished, the simple gain wisdom;
    by paying attention to the wise they get knowledge.(J)

12 The Righteous One[b] takes note of the house of the wicked
    and brings the wicked to ruin.(K)

13 Whoever shuts their ears to the cry of the poor
    will also cry out(L) and not be answered.(M)

14 A gift given in secret soothes anger,
    and a bribe concealed in the cloak pacifies great wrath.(N)

15 When justice is done, it brings joy to the righteous
    but terror to evildoers.(O)

16 Whoever strays from the path of prudence
    comes to rest in the company of the dead.(P)

17 Whoever loves pleasure will become poor;
    whoever loves wine and olive oil will never be rich.(Q)

18 The wicked become a ransom(R) for the righteous,
    and the unfaithful for the upright.

19 Better to live in a desert
    than with a quarrelsome and nagging wife.(S)

20 The wise store up choice food and olive oil,
    but fools gulp theirs down.

21 Whoever pursues righteousness and love
    finds life, prosperity[c](T) and honor.(U)

22 One who is wise can go up against the city of the mighty(V)
    and pull down the stronghold in which they trust.

23 Those who guard their mouths(W) and their tongues
    keep themselves from calamity.(X)

24 The proud and arrogant person(Y)—“Mocker” is his name—
    behaves with insolent fury.

25 The craving of a sluggard will be the death of him,(Z)
    because his hands refuse to work.
26 All day long he craves for more,
    but the righteous(AA) give without sparing.(AB)

27 The sacrifice of the wicked is detestable(AC)
    how much more so when brought with evil intent!(AD)

28 A false witness(AE) will perish,(AF)
    but a careful listener will testify successfully.

29 The wicked put up a bold front,
    but the upright give thought to their ways.(AG)

30 There is no wisdom,(AH) no insight, no plan
    that can succeed against the Lord.(AI)

31 The horse is made ready for the day of battle,
    but victory rests with the Lord.(AJ)

Footnotes

  1. Proverbs 21:6 Some Hebrew manuscripts, Septuagint and Vulgate; most Hebrew manuscripts vapor for those who seek death
  2. Proverbs 21:12 Or The righteous person
  3. Proverbs 21:21 Or righteousness