Òwe 17
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
17 Òkèlè gbígbẹ tòun tàlàáfíà àti ìdákẹ́ jẹ́ẹ́ sàn
ju ilé tí ó kún fọ́fọ́ fún ẹran àti ìjà.
2 Ọlọ́gbọ́n ìránṣẹ́ yóò ṣàkóso adójútini ọmọ,
yóò sì pín ogún gẹ́gẹ́ bí ọ̀kan nínú àwọn ọmọ.
3 Iná ni a fi fọ́ Fàdákà àti wúrà
Ṣùgbọ́n Olúwa ló ń dán ọkàn wò.
4 Ènìyàn búburú ń tẹ́tí sí ètè tí ń sọ ibi
òpùrọ́ a máa fetí sí ahọ́n búburú.
5 Ẹnikẹ́ni tí ó bá sín olùpọ́njú jẹ, ó gan Ẹlẹ́dàá rẹ̀,
ẹnikẹ́ni tí ń yọ̀ sí ìyọnu kò ní lọ láìjìyà.
6 Ọmọ ọmọ ni adé orí arúgbó
ògo àwọn ọmọ sì ni òbí jẹ.
7 Ọ̀rọ̀ dídùn kò yẹ aṣiwèrè,
bẹ́ẹ̀ ni ètè èké kò yẹ ọmọ-aládé!
8 Òkúta iyebíye jẹ́ ẹ̀bùn ní ojú ẹni tí ó ni í,
ibikíbi tí ó yí sí, á ṣe rere.
9 Ẹni tí ó fojú fo ẹ̀ṣẹ̀ tí wọ́n ṣẹ̀ ẹ́ mú kí ìfẹ́ gbòòrò sí i.
Ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí ń tẹnumọ́ ọ̀rọ̀ yóò pín ọ̀rẹ́ tímọ́tímọ́ méjì ní yà.
10 Ọ̀rọ̀ ìbáwí dun olóye ènìyàn
ju ọgọ́rùn-ún pàṣán lọ lẹ́yìn òmùgọ̀.
11 Orí kunkun ni ènìyàn ìkà máa ń ṣe,
ìjòyè aláìláàánú ni a ó rán sí i.
12 Ó sàn kí ènìyàn pàdé beari tí a ti kó lọ́mọ
jù aláìgbọ́n nínú ìwà òmùgọ̀ rẹ̀.
13 Bí ènìyàn kan bá fi ibi san ìre,
ibi kì yóò kúrò nílé rẹ̀ láéláé.
14 Bíbẹ̀rẹ̀ ìjà dàbí ẹni tí ó dá ojú fún adágún omi
nítorí náà mẹ́nu kúrò nínú ọ̀rọ̀ kí ó tó di ìjà.
15 Gbígbé ẹ̀bi fún aláre àti dídá ẹni jàre lẹ́bi,
Olúwa kórìíra méjèèjì.
16 Kí ni ìwúlò owó lọ́wọ́ aṣiwèrè,
níwọ̀n bí kò ti ní èròǹgbà láti rí ọgbọ́n?
17 Ọ̀rẹ́ a máa fẹ́ni nígbà gbogbo,
arákùnrin sì wà fún ìgbà ìpọ́njú.
18 Ènìyàn aláìgbọ́n ṣe ìbúra,
ó sì ṣe onídùúró fún aládùúgbò rẹ̀.
19 Ẹni tí ó fẹ́ràn ìjà fẹ́ràn ẹ̀ṣẹ̀;
ẹni tí ó kọ́ ibodè gígàn ń wá ìparun.
20 Ènìyàn aláyídáyidà ọkàn kì í gbèrú,
ẹni tí ó ní ahọ́n ẹ̀tàn bọ́ sínú ìyọnu.
21 Láti bí aláìgbọ́n lọ́mọ a máa fa ìbànújẹ́ ọkàn,
kò sí ayọ̀ fún baba ọmọ tí kò gbọ́n.
22 Ọkàn tí ó túká jẹ́ oògùn gidi,
ṣùgbọ́n ọkàn tí ó bàjẹ́ a máa mú kí egungun gbẹ.
23 Ènìyàn búburú a gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀ ní ìkọ̀kọ̀
láti yí ìdájọ́ po.
24 Olóye ènìyàn gbójú wo ọgbọ́n níwájú,
ṣùgbọ́n ojú aláìgbọ́n ń wò káàkiri ilẹ̀ ayé.
25 Aṣiwèrè ọmọ mú ìbànújẹ́ bá baba rẹ̀
àti ìkorò fún ẹni tí ó bí i lọ́mọ.
26 Kò dára láti fìyà jẹ ènìyàn tí kò ṣẹ̀,
tàbí láti na ìjòyè lórí òtítọ́ inú wọn.
27 Ènìyàn tó ní ìmọ̀ máa ń ṣọ́ra fún àwọn ọ̀rọ̀ tí ó ń sọ,
ènìyàn olóye sì máa ń ní sùúrù.
28 Kódà aláìgbọ́n máa ń dàbí ọlọ́gbọ́n bí ó bá dákẹ́
àti bí olóye bí ó bá fètèmétè.
Proverbs 17
New International Version
17 Better a dry crust with peace and quiet
than a house full of feasting, with strife.(A)
2 A prudent servant will rule over a disgraceful son
and will share the inheritance as one of the family.
4 A wicked person listens to deceitful lips;
a liar pays attention to a destructive tongue.
5 Whoever mocks the poor(D) shows contempt for their Maker;(E)
whoever gloats over disaster(F) will not go unpunished.(G)
6 Children’s children(H) are a crown to the aged,
and parents are the pride of their children.
7 Eloquent lips are unsuited to a godless fool—
how much worse lying lips to a ruler!(I)
8 A bribe is seen as a charm by the one who gives it;
they think success will come at every turn.(J)
9 Whoever would foster love covers over an offense,(K)
but whoever repeats the matter separates close friends.(L)
10 A rebuke impresses a discerning person
more than a hundred lashes a fool.
11 Evildoers foster rebellion against God;
the messenger of death will be sent against them.
12 Better to meet a bear robbed of her cubs
than a fool bent on folly.(M)
14 Starting a quarrel is like breaching a dam;
so drop the matter before a dispute breaks out.(P)
16 Why should fools have money in hand to buy wisdom,
when they are not able to understand it?(S)
17 A friend loves at all times,
and a brother is born for a time of adversity.(T)
18 One who has no sense shakes hands in pledge
and puts up security for a neighbor.(U)
19 Whoever loves a quarrel loves sin;
whoever builds a high gate invites destruction.
20 One whose heart is corrupt does not prosper;
one whose tongue is perverse falls into trouble.
21 To have a fool for a child brings grief;
there is no joy for the parent of a godless fool.(V)
24 A discerning person keeps wisdom in view,
but a fool’s eyes(AA) wander to the ends of the earth.
25 A foolish son brings grief to his father
and bitterness to the mother who bore him.(AB)
26 If imposing a fine on the innocent is not good,(AC)
surely to flog honest officials is not right.
27 The one who has knowledge uses words with restraint,(AD)
and whoever has understanding is even-tempered.(AE)
28 Even fools are thought wise if they keep silent,
and discerning if they hold their tongues.(AF)
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.
Holy Bible, New International Version®, NIV® Copyright ©1973, 1978, 1984, 2011 by Biblica, Inc.® Used by permission. All rights reserved worldwide.
NIV Reverse Interlinear Bible: English to Hebrew and English to Greek. Copyright © 2019 by Zondervan.