Òwe 16
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
16 Ti ènìyàn ni ìgbèrò inú ọkàn
ṣùgbọ́n láti ọ̀dọ̀ Olúwa ni ìdáhùn ahọ́n ti ń wá.
2 Gbogbo ọ̀nà ènìyàn ni ó dàbí i pé ó dára lójú ara rẹ̀
ṣùgbọ́n Olúwa ló ń díwọ̀n èrò inú ọkàn.
3 Fi ohun gbogbo tí o bá ṣe lé Olúwa lọ́wọ́
Èrò rẹ yóò sì ṣe é ṣe.
4 Olúwa ti ṣe ohun gbogbo láti mú kí ó rí bí ó ṣe fẹ́
kódà ènìyàn búburú fún ọjọ́ ìpọ́njú.
5 Olúwa kórìíra gbogbo ẹni tí ń gbéraga lọ́kàn rẹ̀
mọ èyí dájú pé wọn kò ní lọ láìjìyà.
6 Nípasẹ̀ ìfẹ́ àti òtítọ́ a ṣe ètùtù ẹ̀ṣẹ̀
nípasẹ̀ ìbẹ̀rù Olúwa ènìyàn sá fún ibi.
7 Nígbà tí ọ̀nà ènìyàn bá tẹ́ Olúwa lọ́rùn,
yóò mú kí àwọn ọ̀tá rẹ̀ gàn án bá a gbé ní àlàáfíà.
8 Ó sàn kí ó kéré pẹ̀lú òdodo
ju èrè púpọ̀ pẹ̀lú èrú lọ.
9 Ènìyàn a máa pète ọ̀nà ara rẹ̀ lọ́kàn an rẹ̀
ṣùgbọ́n Olúwa ní í pinnu ìgbésẹ̀ rẹ̀.
10 Ètè ọba a máa sọ̀rọ̀ nípa àṣẹ sí i
ẹnu rẹ̀ kò gbọdọ̀ ṣèké.
11 Òdínwọ̀n àti òṣùwọ̀n òtítọ́ wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa;
gbogbo wíwúwo àpò jẹ́ láti ọwọ́ rẹ̀.
12 Àwọn ọba kórìíra ìwà àìtọ́
nítorí òdodo ní í fi ìdí ìtẹ́ múlẹ̀.
13 Àwọn ọba ní inú dídùn sí ètè tí ń ṣọ òtítọ́,
wọ́n sì fẹ́ ẹni tí ń sọ̀rọ̀ òtítọ́.
14 Ìránṣẹ́ ikú ni ìbínú ọba jẹ́
ṣùgbọ́n ọlọ́gbọ́n ènìyàn yóò tù ú nínú.
15 Nígbà tí ojú ọba bá túká, ó túmọ̀ sí ìyè;
ojúrere rẹ̀ dàbí i ṣíṣú òjò ní ìgbà òjò.
16 Ó ti dára tó láti ní ọgbọ́n ju wúrà lọ
àti láti yan òye dípò o fàdákà!
17 Òpópó ọ̀nà àwọn ẹni dídúró ṣinṣin yàgò fún ibi,
ẹni tí ó ṣọ́ ọ̀nà rẹ̀, ṣọ́ ẹnu ara rẹ̀.
18 Ìgbéraga ní í ṣáájú ìparun,
agídí ọkàn ní í ṣáájú ìṣubú.
19 Ó sàn láti jẹ́ onírẹ̀lẹ̀ ọkàn láàrín àwọn olùpọ́njú
jù láti máa pín ìpín pẹ̀lú àwọn agbéraga.
20 Ẹnikẹ́ni tí ó bá tẹ̀lé ẹ̀kọ́ yóò rí ìre,
ìbùkún sì ni fún ẹni tí ó gbẹ́kẹ̀lé Olúwa.
21 Àwọn tí ó gbọ́n nínú ọkàn là ń pè ní olóye
ọ̀rọ̀ ìtura sì ń mú ẹ̀kọ́ gbèrú.
22 Òye jẹ́ orísun ìyè fún àwọn tí ó ní i,
ṣùgbọ́n ìwà òmùgọ̀ ń kó ìyà jẹ aláìgbọ́n.
23 Ọkàn ọlọ́gbọ́n ènìyàn a máa ṣọ́ ẹnu rẹ̀
ètè rẹ̀ sì ń mú kí ẹ̀kọ́ dàgbà.
24 Ọ̀rọ̀ ìtura dàbí afárá oyin
ó dùn fún ọkàn, ó sì fi ìlera fún egungun.
25 Ọ̀nà kan tí ó dàbí i pé ó dára lójú ènìyàn
ṣùgbọ́n ní ìgbẹ̀yìn a ṣokùnfà ikú.
26 Ọkàn alágbàṣe ń ṣiṣẹ́ fún ara rẹ̀;
nítorí ebi rẹ̀ mú kí ó máa ṣiṣẹ́ lọ.
27 Ènìyàn búburú ń pète
ọ̀rọ̀ rẹ̀ sì dàbí i iná tí ń jóni.
28 Aláyídáyidà ènìyàn dá ìjà sílẹ̀
olófòófó a sì máa pín ọ̀rẹ́ kòríkòsùn ní yà.
29 Oníjàgídíjàgan ènìyàn tan aládùúgbò rẹ̀
ó sì mú un sọ̀kalẹ̀ lọ sí ọ̀nà tí kò dára.
30 Ẹni tí ń ṣẹ́jú ń pètekéte;
ẹni tí ó ṣu ẹnu jọ ń pète aburú.
31 Adé ògo ni ewú orí jẹ́,
ìgbé ayé òdodo ní í mú ni dé bẹ̀.
32 Ó sàn láti jẹ́ onísùúrù ju ajagun ènìyàn lọ,
ẹni tí ó pa ìbínú mọ́ra ju ajagun ṣẹ́gun ìlú lọ.
33 A ṣẹ́ kèké si ìṣẹ́po aṣọ,
ṣùgbọ́n gbogbo ìdájọ́ rẹ̀ wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa.
Proverbs 16
New International Version
16 To humans belong the plans of the heart,
but from the Lord comes the proper answer of the tongue.(A)
3 Commit to the Lord whatever you do,
and he will establish your plans.(E)
6 Through love and faithfulness sin is atoned for;
through the fear of the Lord(J) evil is avoided.(K)
7 When the Lord takes pleasure in anyone’s way,
he causes their enemies to make peace(L) with them.(M)
9 In their hearts humans plan their course,
but the Lord establishes their steps.(P)
10 The lips of a king speak as an oracle,
and his mouth does not betray justice.(Q)
11 Honest scales and balances belong to the Lord;
all the weights in the bag are of his making.(R)
12 Kings detest wrongdoing,
for a throne is established through righteousness.(S)
13 Kings take pleasure in honest lips;
they value the one who speaks what is right.(T)
17 The highway of the upright avoids evil;
those who guard their ways preserve their lives.(AA)
19 Better to be lowly in spirit along with the oppressed
than to share plunder with the proud.
20 Whoever gives heed to instruction prospers,[a](AE)
and blessed is the one who trusts in the Lord.(AF)
22 Prudence is a fountain of life to the prudent,(AH)
but folly brings punishment to fools.
26 The appetite of laborers works for them;
their hunger drives them on.
29 A violent person entices their neighbor
and leads them down a path that is not good.(AS)
30 Whoever winks(AT) with their eye is plotting perversity;
whoever purses their lips is bent on evil.
31 Gray hair is a crown of splendor;(AU)
it is attained in the way of righteousness.
32 Better a patient person than a warrior,
one with self-control than one who takes a city.
Footnotes
- Proverbs 16:20 Or whoever speaks prudently finds what is good
- Proverbs 16:21 Or words make a person persuasive
- Proverbs 16:23 Or prudent / and make their lips persuasive
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.
Holy Bible, New International Version®, NIV® Copyright ©1973, 1978, 1984, 2011 by Biblica, Inc.® Used by permission. All rights reserved worldwide.
NIV Reverse Interlinear Bible: English to Hebrew and English to Greek. Copyright © 2019 by Zondervan.